text target [Iroyin to tewa lowo] Luz Mely Reyes ti isele naa se ojuu re, fi to wa leti nipa bi awon Agbofinro SEBIN se ye ilee Diaz pelu ilee Soto naa wo. [Ìròyìn tó tẹ̀wá lọ́wọ́] Luz Mely Reyes tí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣe ojúu rẹ̀, fi tó wa létí nípa bí àwọn Agbófinró SEBIN ṣe yẹ ilée Díaz pẹ̀lú ilée Soto náà wò. Isokan awon Oniroyin naa fe oro naa loju: Ìsọ̀kan àwọn Oníròyìn náà fẹ ọ̀rọ̀ náà lójú: NI KIAKIA Ni dede asiko yii, ni dede agogo 3:00 owuro kutukutu, igbimo lati ajo Amuninipa de ile oniroyin ati aja-fun- etoo omo eniyan Luis Carlos Diaz, ti o ti di eni awati lati agogo 5:30 irole #NiboNiLuisCarlosWa. NÍ KÍÁKÍÁ Ní dédé àsìkò yìí, ní dédé agogo 3:00 òwúrọ̀ kùtùkùtù, ìgbìmọ̀ láti àjọ Amúninípá dé ilé oníròyìn àti ajà-fún- ẹ̀tọ́ọ ọmọ ènìyàn Luis Carlos Díaz, tí ó ti di ẹni àwátì láti agogo 5:30 ìrọ̀lẹ́ #NiboNiLuisCarlosWa. Awon ajafuneto omoniyan ati ajo ominira oro siso naa darapo mo ipolongo yii pelu #DondeEstaLuisCarlos (Nibo ni Luis Carlos wa?), ti o je pe, ni bayii, ni akole ti o gbajumo ni ori ikanni ayelujara Twitter ti Orile Ede Venezuela. Àwọn ajàfúnẹ̀tọ́ ọmọnìyàn àti àjọ òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ náà darapọ̀ mọ ìpolongo yìí pẹ̀lú #DondeEstaLuisCarlos (Níbo ni Luis Carlos wà?), tí ó jẹ́ pé, ní báyìí, ni àkọlé tí ó gbajúmọ̀ ní orí ìkànnì ayélujára Twitter ti Orílẹ̀ Èdè Venezuela. Diaz je ajabo iroyin ati a-ja-fun-eto-omo eniyan ti o je ogbologboo ajafuneto ominira oro siso ti won si mo ise re fun un l'orile ede Venezuela ati oke okun fun idasoro ati itako ijoba Nicholas Maduro. Díaz jẹ́ ajábọ̀ ìròyìn àti a-jà-fún-ẹ̀tọ́-ọmọ ènìyàn tí ó jẹ́ ògbólógbòó ajàfúnẹ̀tọ́ òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ tí wọ́n sì mọ ìṣe rẹ̀ fún un l'órílẹ̀ èdè Venezuela àti òkè òkun fún ìdásọ́rọ̀ àti ìtakò ìjọba Nicholas Maduro. O ti to igba die kan ti o ti n sise pelu iyawo re ati oludasoro oselu ti o gbajumo n ni, Naky Soto, ti won si n se igbejade awon fidio ati eto Igbohunsafefe lori ayelujara eyi ti o da lori iselu ati eto omo eniyan ni Venezuela. Ó ti tó ìgbà díẹ̀ kan tí ó ti ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ àti olùdásọ́rọ̀ òṣèlú tí ó gbajúmọ̀ n nì, Naky Soto, tí wọn sì ń ṣe ìgbéjáde àwọn fídíò àti ètò Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lórí ayélujára èyí tí ó dá lórí ìṣèlú àti ẹ̀tọ́ ọmọ ènìyàn ní Venezuela. O ti sise gege bi akoni ati olugbe-laruge idasile aye oto fun awon ara ilu ati awon akanse eto igbohun safefe ti ko lowo ijoba ninu. Ó ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí akọ́ni àti olùgbé-lárúgẹ ìdásílẹ̀ àyè ọ̀tọ̀ fún àwọn ará ìlú àti àwọn àkànṣe eto ìgbóhùn sáfẹ́fẹ́ tí kò lọ́wọ́ ìjọ̀ba nínú. Diaz tun je olukopa ninu egbe Ohun Agbaye fun odun mewaa. Díaz tún jẹ́ olùkópa nínú ẹgbẹ́ Ohùn Àgbáyé fún ọdún mẹ́wàá. Lodo temi, Luis Carlos je onilaakaye eda kan, o gbonju ninu iroyin gbigba ati ikansi-ara-eni ninu Venezuela ti wa yii ti ko fara ro. Lọ́dọ̀ tèmi, Luis Carlos jẹ́ onílàákàyè ẹ̀dá kan, ó gbọ́njú nínú ìròyìn gbígbà àti ìkànsì-ara-ẹni nínú Venezuela ti wa yìí tí kò fara rọ. O ti se awari ijapo ninu ilu (lati itako si ibi isese) #NiboniLuisCarlosWa. Ó ti ṣe àwárí ìjápọ̀ nínú ìlú (láti ìtakò sí ibi ìṣẹ̀ṣe) #NiboniLuisCarlosWa. Laarin ojo perete to siwaju ipooraa re, eto ikan-sara- eni ti ijoba Con el Mazo Dando safihan fidio ti Diaz soro ninuu re. Láàrin ọjọ́ péréte tó ṣíwájú ìpòóráa rẹ̀, ètò ìkàn-sára- ẹni ti ìjọba Con el Mazo Dando ṣàfihàn fídíò tí Díaz sọ̀rọ̀ nínúu rẹ̀. Atokun eto ohun, oloselu Diosdado Cabello, ro kan pe Diaz lowo si ifehonu han aisi inaa monamona ti o lo jakejado orile ede eyi ti o mu ki awon omo Venezuela maa gbe ninu okunkun fun o le ni wakati merin le logun lojo 7 ati 8 Osu Erena Atọ́kùn ètò ọ̀hún, olóṣèlú Diosdado Cabello, rò kàn pé Díaz lọ́wọ́ sí ìfẹ̀hónú hàn àìsí ináa mọ̀nàmọ̀nà tí ò lọ jákèjádò orílẹ̀ èdè èyí tí ó mú kí àwọn ọmọ Venezuela máa gbé nínú òkùnkùn fún ó lé ní wákàtí mẹ́rin lé lógún lọ́jọ́ 7 àti 8 Oṣù Ẹrẹ́nà Ko si eri ti o fi ese rinle. Kò sí ẹ̀rí tí ó fi ẹsẹ̀ rinlẹ̀. Wakati meje ti re koja lo ti Luis Carlos Diaz ti di awati. Wákàtí méje ti ré kọjá lọ tí Luis Carlos Díaz ti di àwátì. [Diaz] je oniroyin fun ile ise igbohunsafefe Union Radio Noticias , o si tun je ajafuneto omoniyan. [Díaz] jẹ́ oníròyìn fún ilé iṣẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Unión Radio Noticias , ó sì tún jẹ́ ajàfúnẹ̀tọ́ ọmọnìyàn. Awa ni olu ile isee SEBIN headquarters ati pe won ni awon ko ni i [ni ahamo awon] #NiboNiLuisCarlosWa. Àwa ní olú ilé iṣẹ́ẹ SEBIN headquarters àti pé wọ́n ní àwọn kò ní í [ní àhámọ́ àwọn] #NiboNiLuisCarlosWa. [Iroyin ti o te wa lowo: they won papa jewo wipe [Diaz wa ni akoloo won] [Ìròyìn tí ó tẹ̀ wá lọ́wọ́: they wọ́n pàpà jẹ́wọ́ wípé [Diaz wà ní akolóo wọn] Akoroyin Vladimir Villegas so wipe ko ri bee mo wipe ijoba ni o fi owo agbara mu u: Akọ̀ròyìn Vladimir Villegas sọ wípé kò rí bẹ́ẹ̀ mọ́ wípé ìjọba ni ó fi ọwọ́ agbára mú u: radionet Luis Carlos Diaz, ti wa ninu atimole agbofinro Ilu. radionet Luis Carlos Díaz, ti wà nínú àtìmọ́lé agbófinró Ìlú. A ba a kedun ipo ti o wa. A bá a kẹ́dùn ipò tí ó wà. A beere fun itosona nipa mimo ibi ti o wa, ati ibowo fun eto omoniyan-an re. A béèrè fún ìtọ́sọ́nà nípa mímọ ibi tí ó wà, àti ìbọ̀wọ̀ fún ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn-an rẹ̀. Egbe Ohun Agbaye duro sinsin pelu Luis Carlos, ebii re, ati oniroyin aladaasise gbogbo awon ti o n mu ijoba se bi o ti ye ni Venezuela. Ẹgbẹ́ Ohùn Àgbáyé dúró ṣinṣin pẹ̀lú Luis Carlos, ẹbíi rẹ̀, àti oníròyìn aládàáṣiṣẹ́ gbogbo àwọn tí ó ń mú ìjọba ṣe bí ó ti yẹ ní Venezuela. A n retii re ki o de kiakia ni alaafia ara ati emi, a o maa gbe awon iroyin sita nipa iroyin yii bi o ba se n te wa lowo. À ń retíi rẹ̀ kí ó dé kíákíá ní àlàáfíà ara àti ẹ̀mí, a ó máa gbé àwọn ìròyìn síta nípa ìròyìn yìí bí ó ba ṣe ń tẹ̀ wá lọ́wọ́. Iwe abadofin ilo ero alatagba yoo pa ominira oro siso lori ayelujara ni Naijiria Ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà yóò pa òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ lórí ayélujára ní Nàìjíríà Iwe abadofin naa yoo fi ase fun isanpa ero ayelujara ni Naijiriaj Ìwé àbádòfin náà yóò fi àṣẹ fún ìṣánpa ẹ̀rọ ayélujára ní Nàìjíríàj Asoju Mohammed Sani Musa ni agbateruu iwe abadofin ilo ero alatagba. Aworan ageku lati ibudo Channel Television You Tube . Aṣojú Mohammed Sani Musa ni agbátẹrùu ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà. Àwòrán àgékù láti ibùdó Channel Television You Tube . "Lojo 20 osu Belu, Iwe Abadofin ti o fi Aabo fun Iro ati Makaruru ti o ro mo on ti odun-un 2019, ti a mo si ""iwe abadofin ilo ero alatagba"", ti Asoju kan ti oruko re n je Mohammed Sani Musa se agbateruu re, ti di kika ninu igbimo fun igba keji." "Lọ́jọ́ 20 oṣù Belu, Ìwé Àbádòfin tí ó fi Ààbò fún Irọ́ àti Màkàrúrù tí ó rọ̀ mọ́ ọn ti ọdún-un 2019, tí a mọ̀ sí ""ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà"", tí Aṣojú kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mohammed Sani Musa ṣe agbátẹrùu rẹ̀, ti di kíkà nínú ìgbìmọ̀ fún ìgbà kejì." Erongba iwe abadofin ilo ero alatagba naa ni lati dekun awon aheso ati gbolohun ti ki i se otito lori ero ayelukara bi ajere. Èròńgbà ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà náà ni láti dẹ́kun àwọn àhesọ àti gbólóhùn tí kì í ṣe òtítọ́ lórí ẹ̀rọ ayélukára bí ajere. Bi-o-ti-le-je-wipe, ki i se lati fi ofin de ilo ero alatagba ni iwe abadofin naa da le lori, amo sa, o maa pa ominira oro siso lori ayelujara, iso alatako ijoba di odaran ati fifi atipa ero ayelujara fungba die sinu iwe ofin. Bí-ó-ti-lẹ̀-jẹ́-wípé, kì í ṣe láti fi òfin de ìlò ẹ̀rọ alátagbà ni ìwé àbádòfin náà dá lé lórí, àmọ́ ṣá, ó máa pa òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ lórí ayélujára, ìsọ alátakò ìjọba di ọ̀daràn àti fífi àtìpà ẹ̀rọ ayélujára fúngbà díẹ̀ sínú ìwé òfin. Atepa bi erin ba te koriko ni awon omo Naijiria te iru iwe abadofin bayii pa ni odun-un 2016. Àtẹ̀pa bí erín bá tẹ koríko ni àwọn ọmọ Nàìjíríà tẹ irú ìwé àbádòfin báyìí pa ní ọdún-un 2016. Ese ni bi o ba gbo ijoba lenu (tako ijoba) Ẹ̀ṣẹ̀ ni bí o bá gbó ìjọba lẹ́nu (tako ìjọba) "Gege bi Abala 1A ti se salaye, erongba iwe abadofin yii ni lati ""[maa je] ki igbejade oro ti ko ni otito kan ninu tabi eyi ti erii re ko f'ese rinle to o jade ni Naijiria""." "Gẹ́gẹ́ bí Abala 1A ti ṣe ṣàlàyé, èròńgbà ìwé àbádòfin yìí ni láti ""[máà jẹ́] kí ìgbéjáde ọ̀rọ̀ tí kò ní òtítọ́ kan nínú tàbí èyí tí ẹ̀ríi rẹ̀ kò f'ẹsẹ̀ rinlẹ̀ tó ó jáde ní Nàìjíríà""." "Yoo yo owo kilanko awon atejade iro ti o le ko orile edee Naijiria si ""iyonu"", lawo lai gbagbee awon oran bii eto ilera gbogboogbo, aaboo gbogboogbo, ""ibale-okan-an gbogboogbo tabi isuna owoo gbogboogbo"" ati ""awon ibasepo orile-edee Naijiria pelu awon orile ede miiran""." "Yóò yọ ọwọ́ kílàńkó àwọn àtẹ̀jáde irọ́ tí ó lè kó orílẹ̀ èdèe Nàìjíríà sí ""ìyọnu"", láwo láì gbàgbée àwọn ọ̀ràn bíi ètò ìlera gbogboògbò, ààbòo gbogboògbò, ""ìbalẹ̀-ọkàn-an gbogboògbò tàbí ìṣúná owóo gbogboògbò"" àti ""àwọn ìbáṣepọ̀ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà pẹ̀lú àwọn orílẹ̀ èdè mìíràn""." "Abala 1c so bi iwe abadofin naa yoo se ""mu, sakoso ati fi aabo bo ilonilokulo awon isamulo ati ero adanikansise ori ero ayelujara""." "Abala 1c sọ bí ìwé àbádòfin náà yóò ṣe ""mú, ṣàkóso àti fi ààbò bo ìlònílòkulò àwọn ìṣàmúlò àti ẹ̀rọ adánìkanṣiṣẹ́ orí ẹ̀rọ ayélujára""." Ni alaye siwaju si i, ko si ohun ti oju ofin tuntun naa ko lee to bi o ba ti je lori ayelujara — labe aburada a n gbogun ti aheso ati iro ponbele. Ní àlàyé síwájú sí i, kò sí ohun tí ojú òfin tuntun náà kò leè tó bí ó bá ti jẹ́ lórí ayélujára — lábẹ́ àbùradà à ń gbógun ti àhesọ àti irọ́ pọ́nbẹ́lẹ́. "Orun n ya bo ni iwe abadofin ilo ero alatagba naa, ko yo enikan sile, gbogbo omo orile edee Naijiria ni yoo ba, ko kan agbegbe tabi ibi ti eniyan fi se ibugbe, maa se e l'oogun maa mo, owo awon ologinni oju tole oju toko ni ""gbolohun iro ti ko ni eri"" ti o ba gba opopona ero ayelukara bi ajere Naijiria yoo bo si." "Ọ̀run ń ya bọ̀ ni ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà náà, kò yọ ẹnìkan sílẹ̀, gbogbo ọmọ orílẹ̀ èdèe Nàìjíríà ni yóò bá, kò kan agbègbè tàbí ibi tí ènìyàn fi ṣe ibùgbé, máà ṣe é l'oògùn máà mọ́, ọwọ́ àwọn ológìnní ojú tólé ojú tóko ni ""gbólóhùn irọ́ tí kò ní ẹ̀rí"" tí ó bá gba òpópónà ẹ̀rọ ayélukára bí ajere Nàìjíríà yóò bọ́ sí." Abala 3a si b(i) ti iwe abadofin ilo ero alatagba so wipe: Abala 3a sí b(i) ti ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà sọ wípé: Enikeni ko gbodo wu iwa kiwa kan ninu tabi leyin odi Naijiria lati tari gbolohun ti ko ni otito kan ti a ko lee fi erii re mule sita; ati agbesori afefe ayelujara gbolohun t'o le ko orile edee Naijiria sita bi omo ojo mejo nipa ti aabo ilu. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wu ìwà kíwà kan nínú tàbí lẹ́yìn odi Nàìjíríà láti tari gbólóhùn tí kò ní òtítọ́ kan tí a kò leè fi ẹ̀ríi rẹ̀ múlẹ̀ síta; àti àgbésórí afẹ́fẹ́ ayélujára gbólóhùn t'ó lè kó orílẹ̀ èdèe Nàìjíríà síta bí ọmọ ọjọ́ mẹ́jọ nípa ti ààbò ìlú. "Oran-an ti ""aabo orile-ede"" ni ori Esu ti ofin naa duro le lati pa eto si ominira oro siso mo." "Ọ̀ràn-an ti ""ààbò orílẹ̀-èdè"" ni orí Èṣù tí òfin náà dúró lé láti pa ẹ̀tọ́ sí òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ mọ́." Amo ko tan sibe, ko si eni to le tako ijoba Naijiria tabi gbo o lenu nitori ki i s'asise. Àmọ́ kò tán síbẹ̀, kò sí ẹní tó lè tako ìjọba Nàìjíríà tàbí gbó o lẹ́nu nítorí kì í ṣ'àṣìṣe. Ni Abala 3b(vi), gbolohun ti o ba yepere “ojuse tabi ise, ti o je ti ijoba loju ara ilu” ko lee la ori ayelujara koja. Ní Abala 3b(vi), gbólóhùn tí ó bá yẹpẹrẹ “ojúṣe tàbí ìṣe, tí ó jẹ́ ti ìjọba lójú ará ìlú” kò leè la orí ayélujára kọjá. "Gege bi Abala 3b(v) ti se fi han, eyi ni i se pelu gbolohun ti o: ""fa imunilotaa, ti a so si enikan tabi itara laaarin awon eniyan""." "Gẹ́gẹ́ bí Abala 3b(v) ti ṣe fi hàn, èyí ní í ṣe pẹ̀lú gbólóhùn tí ó: ""fa ìmúnilọ́tàá, tí a sọ sí ẹnìkan tàbí ìtara láàárín àwọn ènìyàn""." Eyi lewu nitori o fi aye gba awon onipo ase lati lo agbara nilokulo. Èyí léwu nítorí ó fi àyè gba àwọn onípò àṣẹ láti lo agbára nílòkulò. Ta ni i so boya gbolohun kan le fa rogbodiyan? Ta ní í sọ bóyá gbólóhùn kan lè fa rògbòdìyàn? Iyen tumo si wipe lilo inu kan tabi mimu awon oloseluu mu ilerii won se le ja si ikoriira lojuu won. Ìyẹn túmọ̀ sí wípé lílo inú kan tàbí mímú àwọn olóṣèlúu mú ìléríi wọn ṣe lè já sí ìkórìíra lójúu wọn. Owo itanran fun eni ti ile ejo ba da lebi to laaarin egberun 200 ati egbeegberun 10 owo naira [ti o to $556 si $28,000 owo orile edee United States], itimole fun odun meta tabi mejeeji. Owó ìtanràn fún ẹni tí ilé ẹjọ́ bá dá lẹ́bi tó láàárín ẹgbẹ̀rún 200 àti ẹgbẹẹgbẹ̀rún 10 owó naira [tí ó tó $556 sí $28,000 owó orílẹ̀ èdèe United States], ìtìmọ́lé fún ọdún mẹ́ta tàbí méjèèjì. Ase fun Ajo Agbofinro lati san ero ayelujara pa fungba die Àṣẹ fún Àjọ Agbófinró láti ṣán ẹ̀rọ ayélujára pa fúngbà díẹ̀ "Iwe abadofin ilo ero alatagba naa fun ijoba lagbara bi o se hu won lati san ero ayelukara bi ajere pa nigbakuugba ti o ba lero wipe o to, nipase ""Ase Idigaga Iraye"" lati lo ayelujara bi o ti se wa ni Abala 12, onkaye 3:" "Ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà náà fún ìjọba lágbára bí ó ṣe hù wọ́n láti ṣán ẹ̀rọ ayélukára bí ajere pa nígbàkúùgbà tí ó bá lérò wípé ó tọ́, nípasẹ̀ ""Àṣẹ Ìdígàgá Ìráyè"" láti lo ayélujára bí ó ti ṣe wà ní Abala 12, òǹkaye 3:" Eka Agbofinro lee fi ase fun Ajo Igbohunsafefe Naijiria NCC [Nigerian Communications Commission – ti o n se bonkari itakuroso ori ero ayarabiasa] lati pa a lase fun apese aye si ilo ero ayelujara ki o gbe igbese loju ese ti o ni mu awon onlo ri aye lo ayelujara ni Naijiria. Ẹ̀ka Agbófinró leè fi àṣẹ fún Àjọ Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Nàìjíríà NCC [Nigerian Communications Commission – tí ó ń ṣe bòńkárí ìtàkùrọ̀sọ orí ẹ̀rọ ayárabíàṣá] láti pa á láṣẹ fún apèsè àyè sí ìlò ẹ̀rọ ayélujára kí ó gbé ìgbésẹ̀ lójú ẹsẹ̀ tí ò ní mú àwọn òǹlò rí àyè lo ayélujára ní Nàìjíríà. Awon apese ayelujara gbodo tele ofin idigaga yii tabi ki won o sanwo itanran ti o to egbeegberun 5 si 10 owo naira [$14,000-28,000 USD]. Àwọn apèsè ayélujára gbọdọ̀ tẹ̀lé òfin ìdígàgá yìí tàbí kí wọ́n ó sanwó ìtanràn tí ó tó ẹgbẹẹgbẹ̀rún 5 sí 10 owó naira [$14,000-28,000 USD]. "Ni afikun, iwe abadofin naa fi aridaju aabo bo awon apese ise ero ayelujara ti ko ni mu wahala ""ara ilu tabi bee "" ti ko ba a le jade lati idajo kan ti enikeni ko ba pe won funope ""won tele ofin idigaga iraye"" si ayelujara, iyen bi abala 12, onkaye 5 se fi lele." "Ní àfikún, ìwé àbádòfin náà fi àrídájú ààbò bo àwọn apèsè iṣẹ́ ẹ̀rọ ayélujára tí kò ní mú wàhálà ""ará ìlú tàbí bẹ́ẹ̀ "" tí kò bá à lè jáde láti ìdájọ́ kan tí ẹnikẹ́ni kò bá pè wọ́n fúnopé ""wọ́n tẹ̀lé òfin ìdígàgá ìráyé"" sí ayélujára, ìyẹn bí abala 12, òǹkaye 5 ṣe fi lélẹ̀." Iteri eto omoniyan naa s'okunkun si i nitori wipe ofin naa gba awon olopaa laye labe ofin lati pa ase idigaga-aye bi o ti se hu won. Ìtẹ́rí ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn náà ṣ'ókùnkùn sí i nítorí wípé òfin náà gba àwọn ọlọ́pàá láyè lábẹ́ òfin láti pa àṣẹ ìdígàgá-àyè bí ó ti ṣe hù wọ́n. "Abala 15a so wipe “ise opolo” olopaa ni asiko ""isewadii eri to daju"" je koko lati fagile isanpa ero ayelujara ni orile ede naa." "Abala 15a sọ wípé “iṣẹ́ ọpọlọ” ọlọ́pàá ní àsìkò ""ìṣèwádìí ẹ̀rí tó dájú"" jẹ́ kókó láti fagilé ìṣánpá ẹ̀rọ ayélujára ní orílẹ̀ èdè náà." Ni ipari, “ko si aye fun ejoo ko temi lorun ni Ile-ejo Giga” [Abala 13(2)] ti eenikeni le fi ye idigaga sile lai maa koko to olopaa lo lati fagile ofin idigaga naa. Ní ìparí, “kò sí àyè fún ẹjọ́ọ kò tèmi lọ́rùn ní Ilé-ẹjọ́ Gíga” [Abala 13(2)] tí eẹnikẹ́ni lè fi yẹ ìdígàgá sílẹ̀ láì máà kọ́kọ́ tọ ọlọ́pàá lọ láti fagilé òfin ìdígàgá náà. Ipa eyi han gbagada — enikeni ko ni lee gba ile ejo lo fun igbeja ifeto eni dunni yii ti idigaga naa si wa. Ipa èyí hàn gbàgàdà — ẹnikẹ́ni kò ní leè gba ilé ẹjọ́ lọ fún ìgbèjà ìfẹ̀tọ́ ẹni dunni yìí tí ìdígàgá náà ṣì wà. Awon asoju-sofin ti o wa leyin iwe abadofin ero alatagba naa Àwọn aṣojú-ṣòfin tí ó wà lẹ́yìn ìwé àbádòfin ẹ̀rọ alátagbà náà Awon asoju-sofin meta kan ni o gbe iwe abadofin naa sori ninu igbimo, ile igbimo agba: Mohammed Sani Musa (agbateruu iwe abadofin), Abba Moro ati Elisha Abbo. Àwọn aṣojú-ṣòfin mẹ́ta kan ni ó gbé ìwé àbádòfin náà sórí nínú ìgbìmọ̀, ilé ìgbìmọ̀ àgbà: Mohammed Sani Musa (agbátẹrùu ìwé àbádòfin), Abba Moro àti Elisha Abbo. Ile-isee Mohammed Sani Musa, Activate Technologies Limited, ni o ko ero Iwe-pelebe Idibo Alalope (PVCs) ti a lo fun ibo odun-un 2019, nigba ti o je ondijedupo labe egbe oloseluu ti o n tuko eto iselu lowo All Progressives Congress (APC) fun Asoju Ila-Oorun Niger, iyen gege bi ile ise asewadii, Premium Times se te e jade. Ilé-iṣẹ́ẹ Mohammed Sani Musa, Activate Technologies Limited, ni ó kó ẹ̀rọ Ìwé-pélébé Ìdìbò Alálòpẹ́ (PVCs) tí a lò fún ìbò ọdún-un 2019, nígbà tí ó jẹ́ òǹdíjedupò lábẹ́ ẹgbẹ́ olóṣèlúu tí ó ń tukọ̀ ètò ìṣèlú lọ́wọ́ All Progressives Congress (APC) fún Aṣojú Ìlà-Oòrùn Niger, ìyẹn gẹ́gẹ́ bí ilé iṣẹ́ aṣèwádìí, Premium Times ṣe tẹ̀ ẹ́ jáde. Ajo Eleto (INEC) gba esun naa mora. Àjọ Elétò (INEC) gba ẹ̀sùn náà mọ́ra. Oran yii fi han pe awon alakooso ibo ti o koja ko sise lai lowo awon alagbara n'nu. Ọ̀ràn yìí fi hàn pé àwọn alákòóso ìbò tí ó kọjá kò ṣiṣẹ́ láì lọ́wọ́ àwọn alágbára ń'nú. Ishaku Elisha Abbo ti egbe alatako People’s Democratic Party (PDP) je asoju ti o n soju Ekun-un Ariwa Adamawa ni Ipinle Adamawa, ni ila-oorun ariwa orile edee Naijiria. Ishaku Elisha Abbo ti ẹgbẹ́ alátakò People’s Democratic Party (PDP) jẹ́ aṣojú tí ó ń ṣojú Ẹkùn-un Àríwá Adamawa ní Ìpínlẹ̀ Adamawa, ní ìlà-oòrùn àríwá orílẹ̀ èdèe Nàìjíríà. Ninu osu Agemo 2019, ni isoju olopaa, Abbo se asemase pelu osisebinrin kan ninu iso ohun ibalopo ni olu-ilu Naijiria ni Abuja. Nínú oṣù Agẹmọ 2019, ní ìṣojú ọlọ́pàá, Abbo ṣe àṣemáṣe pẹ̀lú òṣìṣẹ́bìnrin kan nínú ìsọ̀ ohun ìbálòpọ̀ ní olú-ìlú Nàìjíríà ní Abuja. Leyin ti aworan casemase naa fon ka sori ero alatagba, Abbo offered mo iwaa re lebi, o si bebe. Lẹ́yìn tí àwòrán càṣemáṣe náà fọ́n ká sórí ẹ̀rọ alátagbà, Abbo offered mọ ìwàa rẹ̀ lẹ́bí, ó sì bẹ̀bẹ̀. Abba Moro, ti i se omo egbee PDP, ni asoju fun eka Guusu Benue, aarin gbungbun ariwa Naijiria. Abba Moro, tí í ṣe ọmọ ẹgbẹ́ẹ PDP, ni aṣojú fún ẹ̀ka Gúúsù Benue, àárín gbùngbùn àríwá Nàìjíríà. Ni ojo 15, osu Erena, odun-un 2014, Moro, ti i se oga patapata eto abele, lo wa nidii isele abanilokanje Igbanisise Eso asobode Naijiria ti awon odolangba ti o to bii egbeegberun 6 to fe aye ise egberun 4 ti o si sile ninu ileese Eso Asobode Naijiria ti won kora jo nibi orisiirisii jakejado orile ede naa. Ní ọjọ́ 15, oṣù Ẹrẹ́nà, ọdún-un 2014, Moro, tí í ṣe ọ̀gá pátápátá ètò abélé, ló wà nídìí ìṣẹ̀lẹ̀ abanilọ́kànjẹ́ Ìgbanisíṣẹ́ Ẹ̀ṣọ̀ aṣọ́bodè Nàìjíríà tí àwọn ọ̀dọ́langba tí ó tó bíi ẹgbẹẹgbẹ̀rún 6 tó fẹ́ àyè iṣẹ́ ẹgbẹ̀rún 4 tí ó ṣí sílẹ̀ nínú iléeṣẹ́ Ẹ̀ṣọ̀ Aṣọ́bodè Nàìjíríà tí wọ́n kóra jọ níbi orísìírísìí jákèjádò orílẹ̀ èdè náà. Isele ti o buruku jai naa ti o seku pa ogun eniyan ati ipalara fun opo eeyan. Ìṣẹ̀lẹ̀ tí ó burúkú jáì náà tí ó ṣekú pa ogún ènìyàn àti ìpalára fún ọ̀pọ̀ èèyàn. Moro gba ninu of owo iwase ti awon awase san ti o n lo bii egbeegberun 675 owoo naira [ $1.8 USD]. Moro gbà nínú of owó ìwáṣẹ̀ tí àwọn awáṣẹ́ san tí ó ń lọ bíi ẹgbẹẹgbẹ̀rún 675 owóo naira [ $1.8 USD]. Moro ko owo sapoo re bee naa o fo ofin igbannkan Asobode da. Moro kó owó sápòo rẹ̀ bẹ́ẹ̀ náà ó fo òfin ìgbanǹkan Aṣọ́bodè dá. """Ko nilo idake jeje, iberu bojo tabi ikaaanu-araeni"" – #SayNoToSocialMediaBill!" """Kò nílò ìdákẹ́ jẹ́jẹ́, ìbẹ̀rù bojo tàbí ìkáàánú-araẹni"" – #SayNoToSocialMediaBill!" Nipa lilo ami #SayNoToSocialMediaBill, awon omo ori ayelujara orile edee Naijiria bo sorii Twitter lati so ero okan-an won: Nípa lílo àmì #SayNoToSocialMediaBill, àwọn ọmọ orí ayélujára orílẹ̀ èdèe Nàìjíríà bọ́ sóríi Twitter láti sọ èrò ọkàn-an wọn: "Ninu gbolohun kan, Amnesty International fajuro si lilo ""awon ofin ti o n fidii ifoju eto omoniyan gbole mule "" nitori pe ko ni pa awon omo Naijiria lenu mo ""lati maa so ero okan-an won"" ti yoo si tun ""ran won lo s'ewon fun wipe won se bee ""." "Nínú gbólóhùn kan, Amnesty International fajúro sí lílo ""àwọn òfin tí ó ń fìdìí ìfojú ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn gbolẹ̀ múlẹ̀ "" nítorí pé kò ní pa àwọn ọmọ Nàìjíríà lẹ́nu mọ́ ""láti máà sọ èrò ọkàn-an wọn"" tí yóò sì tún ""rán wọn lọ s'ẹ́wọ̀n fún wípé wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀ ""." Labe aburada a n dekun gbolohun iro ati oro aheso, n gbero isofin ti ko ni ife ara ilu lokan. Lábẹ́ àbùradà à ń dẹ́kun gbólóhùn irọ́ àti ọ̀rọ̀ àhesọ, ń gbèrò ìṣòfin tí kò ní ìfẹ́ ará ìlú lọ́kàn. O je ohun iyalenu, awon oloseluu lo lewaju nibi ka gbe gbolohun iro sori ayelujara. Ó jẹ́ ohun ìyàlẹ́nu, àwọn olóṣèlúu ló léwájú níbi ká gbé gbólóhùn irọ́ sórí ayélujára. Egbe oloseluu ti o n je lowo ati egbe alatako gboogi so Twitter di papa ogun fa oro ikoriira eleyameleya, iroyin ti ko poju osuwon ati oro etan lasiko idibo aare odun-un 2019. Ẹgbẹ́ olóṣèlúu tí ó ń jẹ lọ́wọ́ àti ẹgbẹ́ alátakò gbòógì sọ Twitter di pápá ogun fa ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹlẹ́yàmẹ́lẹ́yá, ìròyìn tí kò pójú òṣùwọ̀n àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn lásìkò ìdìbò ààrẹ ọdún-un 2019. Ka siwaju si i: Kà síwájú sí i: Ero alatagba fa oro ikoriira eleyameleya, iroyin ti ko poju osuwon ati oro etan lasiko idibo aare odun-un 2019 Ẹ̀rọ alátagbà fa ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹlẹ́yàmẹ́lẹ́yá, ìròyìn tí kò pójú òṣùwọ̀n àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn lásìkò ìdìbò ààrẹ ọdún-un 2019 Twitter di papa ogun fun gbolohun iro lasiko idibo orile-edee Naijiria odun-un 2019 Twitter di pápá ogun fún gbólóhùn irọ́ lásìkò ìdìbò orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ọdún-un 2019 Ni akoko bii ti ominira oro siso ni Naijiria ti a wa yii, oro olopolo lati enu onkowe orile-edee Amerika Toni Morrison ti o mu ireti dani: Ní àkókò bíi ti òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ ní Nàìjíríà tí a wà yìí, ọ̀rọ̀ ọlọ́pọlọ láti ẹnu òǹkọ̀wé orílẹ̀-èdèe Amẹ́ríkà Toni Morrison tí ó mú ìrétí dání: ‎Eyi ni igba ti awon ayaworan n sise. Ko saye fun isoretinu, ko saye fun ikaaanu-ara, ko nilo idake jeje, ko si aye fun iberu bojo. ‎Èyí ni ìgbà tí àwọn ayàwòrán ń ṣiṣẹ́. Kò sáyé fún ìsọ̀rètínù, kò sáyé fún ìkáàánú-ara, kò nílò ìdákẹ́ jẹ́jẹ́, kò sí àyè fún ìbẹ̀rù bojo. A so, a ko, a p'ede. A sọ, a kọ, a p'èdè. Iwe abadofin ilo ero alatagba naa ti je kika ni igba keji ninu igbimo Asoju-sofin. Ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà náà ti jẹ́ kíkà ní ìgbà kejì nínú ìgbìmọ̀ Aṣojú-ṣòfin. Ki o to di ofin, o gbodo gba igbimo kan ti awon asoju-sofin yoo ye e wo. Igbimooteekoto naa yoo si jabo abajade ayewoo re fun Igbimo agba, lati gbe e ye wo, ti won yoo te omiran jade fun ayewo ti o keyin, ki aare o to bu owo lu u. Kí ó tó di òfin, ó gbọdọ̀ gba ìgbìmọ̀ kan tí àwọn aṣojú-ṣòfin yóò yẹ̀ ẹ́ wò. Ìgbìmọ̀ọtẹ̀ẹ́kótó náà yóò sì jábọ̀ àbájáde àyẹ̀wòo rẹ̀ fún Ìgbìmọ̀ àgbà, láti gbé e yẹ̀ wò, tí wọn yóò tẹ òmíràn jáde fún àyẹ̀wò tí ó kẹ́yìn, kí ààrẹ ó tó bu ọwọ́ lù ú. A gbodo faju ro si igbese Igbimo ki won ba ju iwe abadofin ilo ero alatagba naa danu sigbo. A gbọdọ̀ fajú ro sí ìgbésẹ̀ Ìgbìmọ̀ kí wọ́n ba ju ìwé àbádòfin ìlò ẹ̀rọ alátagbà náà dànù sígbó. Nitori orile edee ti o gbajumo ju lo nile Adulawo yoo ye gere si ijoba ifipamunisin ni kete ti ominira oro siso ba di tite bole. Nítorí orílẹ̀ èdèe tí ó gbajúmọ̀ jù lọ nílẹ̀ Adúláwọ̀ yóò yẹ̀ gẹ̀rẹ̀ sí ìjọba ìfipámúnisìn ní kété tí òmìnira ọ̀rọ̀ sísọ bá di títẹ̀ bọlẹ̀. Ile ejo giga Tanzania pa a lase fun ifopinsi isoyigi laaarin agbalagba ati omode lai wo ti igbese imupadaa re Ilé ẹjọ́ gíga Tanzania pa á láṣẹ fún ìfòpinsí ìsoyìgì láàárín àgbàlagbà àti ọmọdé láì wo ti ìgbésẹ̀ ìmúpadàa rẹ̀ """Eyi ni ipinnu ti o dara ju lo ti ile-ejo yoo se""" """Èyí ni ìpinnu tí ó dára jù lọ tí ilé-ẹjọ́ yóò ṣe""" Awon Omoileewe omodebinrin ni Tanzania duro fun aworan lojo 10 osu Agemo odun-un, 2007. Fanny Schertzer ni o ya aworan, a lo o pelu ase lati Wikimedia Commons, CC BY 2.0. Àwọn Ọmọiléèwé ọmọdébìnrin ní Tanzania dúró fún àwòrán lọ́jọ́ 10 oṣù Agẹmọ ọdún-un, 2007. Fanny Schertzer ni ó ya àwòrán, a lò ó pẹ̀lú àṣẹ láti Wikimedia Commons, CC BY 2.0. Ninu osu Owara 2019, ile ejo giga Tanzania se idimu sinsin idajo odun-un 2016 ti o pase o kere ju, omobinrin ati omokunrin gbodo pe omo odun mejidinlogun ki o to se igbeyawo. Nínú oṣù Ọ̀wàrà 2019, ilé ẹjọ́ gíga Tanzania ṣe ìdímú ṣinṣin ìdájọ́ ọdún-un 2016 tí ó pàṣẹ ó kéré jù, ọmọbìnrin àti ọmọkùnrin gbọdọ̀ pé ọmọ ọdún méjìdínlógún kí ó tó ṣe ìgbéyàwó. Ajo oba orile edee Tanzania gbeegbese lati se imupada ipinnu yii, nitori wipe awon omodebinrin n yara balaga ati wipe aabo ni igbeyawo je fun odobinrin alaboyun. Àjọ ọba orílẹ̀ èdèe Tanzania gbéègbésẹ̀ láti ṣe ìmúpadà ìpinnu yìí, nítorí wípé àwọn ọmọdébìnrin ń yára bàlágà àti wípé ààbò ni ìgbéyàwó jẹ́ fún ọ̀dọ́bìnrin aláboyún. Amo ni ojo 23 osu Owara odun-un 2019, ijoba orile edee Tanzania padanu ejoo kotemilorunun re ti ase ile ejo giga si duro: ako atabo gbodo pe ojo ori mejidinlogun ki won o to se igbeyawo, ti eyi si n fi agbara kun igbese isoyigi omode ni Tanzania. Àmọ́ ní ọjọ́ 23 oṣù Ọ̀wàrà ọdún-un 2019, ìjọba orílẹ̀ èdèe Tanzania pàdánù ẹjọ́ọ kòtẹ́milọ́rùnun rẹ̀ tí àṣẹ ilé ẹjọ́ gíga ṣì dúró: akọ àtabo gbọdọ̀ pé ọjọ́ orí méjìdínlógún kí wọn ó tó ṣe ìgbéyàwó, tí èyí sì ń fi agbára kún ìgbẹ́sẹ̀ ìsoyìgì ọmọdé ní Tanzania. Gege bi United Nations Population Fund (UNFPA) ti se wi, Tanzania ni isoyigi omode po si ju lo lagbaaye. Gẹ́gẹ́ bí United Nations Population Fund (UNFPA) ti ṣe wí, Tanzania ni ìsoyìgì ọmọdé pọ̀ sí jù lọ lágbàáyé. Awon omo ori ayelujara sira lati fi idunnuu won han lorii idajo naa. Àwọn ọmọ orí ayélujára ṣíra láti fi ìdùnnúu wọn hàn lóríi ìdájọ́ náà. Awon kan ki Rebeca Z. Gyumi, alafisun ati eni ti o le waju ninu oran isoyigi awon omode naa. Àwọn kan kí Rebeca Z. Gyumi, aláfisùn àti ẹni tí ó lé wájú nínú ọ̀ràn ìsoyìgì àwọn ọmọdé náà. Gyumi ni oludasile ati alakooso agba Msichana Initiative (Eto fun awon Odomobinrin), ileese ti ki i se tijoba ti o n ro awon omodebinrin lagbara nipase ti eko iwe. Gyumi ni olùdásílẹ̀ àti alákòóso àgbà Msichana Initiative (Ètò fún àwọn Ọ̀dọ́mọbìnrin), iléeṣẹ́ tí kì í ṣe tìjọba tí ó ń ró àwọn ọmọdébìnrin lágbára nípasẹ̀ ti ẹ̀kọ́ ìwé. Igbese lati fopin si isoyigi omode ni Tanzania Ìgbésẹ̀ láti fòpin sí ìsoyìgì ọmọdé ní Tanzania Lodun-un 2016, Gyumi na owo ika abuku si agbara Ofin Igbeyawo; Law of Marriage Act, 2002 (LMA) ti o gba obinrin ti ko to omo odun mejidinlogun laye lati se igbeyawo. Lọ́dún-un 2016, Gyumi na ọwọ́ ìka àbùkù sí agbára Òfin Ìgbéyàwó; Law of Marriage Act, 2002 (LMA) tí ó gba obìnrin tí kò tó ọmọ ọdún méjìdínlógún láyè láti ṣe ìgbéyàwó. Gege bi iwadii nipa ilera Tanzania Demographic and Health Survey (TDHS) se ti salaye, ida 36 obinrin ti ojo orii won wa ni 25-49 ni i se igbeyawo ki won o to pe omo odun mejidinlogun, ti awon akegbee won lokunrin si je ida 5. Gẹ́gẹ́ bí ìwádìí nípa ìlera Tanzania Demographic and Health Survey (TDHS) ṣe ti ṣàlàyé, ìdá 36 obìnrin tí ọjọ́ oríi wọ́n wà ní 25-49 ní í ṣe ìgbéyàwó kí wọn ó tó pé ọmọ ọdún méjìdínlógún, tí àwọn akẹgbẹ́ẹ wọn lọ́kùnrin sí jẹ́ ìdá 5. Ofin LMA fi aye gba omodebinrin ti ojo orii won ko ju odun merinla lo lati se igbeyawo pelu ilowosi ile-ejo, ilowosi obi fun omo odun marun-un-dinlogun, nigba ti odun mejidinlogun je ojo ori ti o kere ju lo fun omokunrin. Òfin LMA fi àyè gba ọmọdébìnrin tí ọjọ́ oríi wọn kò ju ọdún mẹ́rìnlá lọ láti ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú ìlọ́wọ́sí ilé-ẹjọ́, ìlọ́wọ́sí òbí fún ọmọ ọdún márùn-ún-dínlógún, nígbà tí ọdún méjìdínlógún jẹ́ ọjọ́ orí tí ó kéré jù lọ fún ọmọkùnrin. Nipase awon asoju re, Gyumi salaye wipe alaale LMA ko iyan obinrin kere nitori pe o fun awon okunrin ni anfaani ju awon obinrin lo. Nípasẹ̀ àwọn aṣojú rẹ̀, Gyumi ṣàlàyé wípé àlàálẹ̀ LMA kọ iyán obìnrin kéré nítorí pé ó fún àwọn ọkùnrin ní àǹfààní ju àwọn obìnrin lọ. Nitesiwaju, won so wipe alaale naa fi eto didogba omo eniyan yi erefo ati pe won fi eto anfaani si eko iwe dun awon omodebinrin. Nítẹ̀síwájú, wọ́n sọ wípé àlàálẹ̀ náà fi ẹ̀tọ́ dídọ́gba ọmọ ènìyàn yí ẹrẹ̀fọ̀ àti pé wọn fi ẹ̀tọ́ àǹfààní sí ẹ̀kọ́ ìwé dun àwọn ọmọdébìnrin. Gyumi ro Ile-ejo Giga lati gbe alaale LMA ti segbee. Gyumi rọ Ilé-ẹjọ́ Gíga láti gbé àlàálẹ̀ LMA tì sẹ́gbẹ̀ẹ́. Ile-ejo Giga ko se bee. Ilé-ẹjọ́ Gíga kò ṣe bẹ́ẹ̀. Amo won ri i loooto wipe ko ba ofin mu won si fun ijoba lodun kan lati se atunse si ohun ti ko tona ninu alaale LMA. Àmọ́ wọ́n rí i lóòótọ́ wípé kò bá òfin mu wọ́n sì fún ìjọba lọ́dún kan láti ṣe àtúnṣe sí ohun tí kò tọ̀nà nínú àlàálẹ̀ LMA. Nipase asoju agba awon adajo, a pa ijoba lase lati gbe ojo ori igbeyawo si odun mejidinlogun fun obinrin ati okunrin. Nípasẹ̀ aṣojú àgbà àwọn adájọ́, a pa ìjọba láṣẹ láti gbé ọjọ́ orí ìgbéyàwó sí ọdún méjìdínlógún fún obìnrin àti ọkùnrin. Sibe, asoju agba ana banuje si idajo naa o si ko iwe atunpe-ejo si Ile-ejo Giga naa: Síbẹ̀, aṣojú àgbà àná banújẹ́ sí ìdájọ́ náà ó sì kọ ìwé àtúnpè-ẹjọ́ sí Ilé-ẹjọ́ Gíga náà: Pelu ifowosi ase ijoba: mo ti gba iwe atunpe-ejo lorii ejo #childmarriage. Ejo onkaye 204 ti osu Owewe odun-un 2017. Pẹ̀lú ìfọwọ́sí àṣẹ ìjọba: mo ti gba ìwé àtúnpè-ẹjọ́ lóríi ẹjọ́ #childmarriage. Ẹjọ́ òǹkaye 204 ti oṣù Ọ̀wẹwẹ̀ ọdún-un 2017. Ka siwaju si i: Mozambique so isoyigi omode di iwa odaran Kà síwájú sí i: Mozambique sọ ìsoyìgì ọmọdé di ìwà ọ̀daràn Aye fun atunpe-ejo Àyè fún àtúnpè-ẹjọ́ Laaarin osu merin igbejo, ijoba gbero lati se atunpe-ejo odun-un 2016 ti yo se atunse si alaale LMA eyi ti o fi aye gba omodebinrin olojo-ori marun-undinlogun gege bi eni ti o ti balaga fun igbeyawo. Láàárín oṣù mẹ́rin ìgbẹ́jọ́, ìjọba gbèrò láti ṣe àtúnpè-ẹjọ́ ọdún-un 2016 tí yó ṣe àtúnṣe sí àlàálẹ̀ LMA èyí tí ó fi àyè gba ọmọdébìnrin ọlọ́jọ́-orí márùn-úndínlógún gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ti bàlágà fún ìgbéyàwó. Atejope, ti o je asoju awon adajo ipinle, Mark Mulwambo ati Alesia Mbuya, se agbekale iyato iwa eda obinrin ati okunrin ti won si fi asa ibile ati ofin esin Imale gba atunpe-ejo naa nidii. Atẹ́jọ́pè, tí ó jẹ́ aṣojú àwọn adájọ́ ìpínlẹ̀, Mark Mulwambo àti Alesia Mbuya, ṣe àgbékalẹ̀ ìyàtọ̀ ìwà ẹ̀dá obìnrin àti ọkùnrin tí wọ́n sì fi àṣà ìbílẹ̀ àti òfin ẹ̀sìn Ìmàle gbá àtúnpè-ẹjọ́ náà nídìí. "Ms. Mbuya so wipe iyato iwa eda fi omodekunrin ati omodebinrin si ""isori otooto "" ati pe, ofin fi oju otooto wo won." "Ms. Mbuya sọ wípé ìyàtọ̀ ìwà ẹ̀dá fi ọmọdékùnrin àti ọmọdébìnrin sí ""ìsọ̀rí ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ "" àti pé, òfin fi ojú ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ wò wọ́n." O so siwaju si i wipe nitori awon omodebinrin maa n tete balaga ju omodekunrin lo ni ofin fi la alaale bee. O so wipe igbeyawo le fi aabo bo omodebinrin ti ko si nile oko ti o ti di abarameji lai to ojo ori ti o to. Ó sọ síwájú sí i wípé nítorí àwọn ọmọdébìnrin máa ń tètè bàlágà ju ọmọdékùnrin lọ ni òfin fi la àlàálẹ̀ bẹ́ẹ̀. Ó sọ wípé ìgbéyàwó lè fi ààbò bo ọmọdébìnrin tí kò sí nílé ọkọ tí ó ti di abaraméjì láì tó ọjọ́ orí tí ó tọ́. O so siwaju si i wipe ile ejo kuna bi o se “se imudogbandogba ojo ori omo ati ojo ori ti o ye fun igbeyawo”, eyi ti o tumo si wipe oto ni ti tolu oto ni ti toluu wo, oto ni o ye ki ile ejo o la kale fun ojo ori igbeyawo okunrin ati obinrin. Ó sọ síwájú sí i wípé ilé ẹjọ́ kùnà bí ó ṣe “ṣe ìmúdọ́gbandọ́gba ọjọ́ orí ọmọ àti ọjọ́ orí tí ó yẹ fún ìgbéyàwó”, èyí tí ó túmọ̀ sí wípé ọ̀tọ̀ ni ti tọ́lú ọ̀tọ̀ ni ti tọ́lùú wò, ọ̀tọ̀ ni ó yẹ kí ilé ẹjọ́ ó là kalẹ̀ fún ọjọ́ orí ìgbéyàwó ọkùnrin àti obìnrin. Awon omo ori ayelujara ti yara bu enu ate lu idi ti atejope fi sile ninu igbejo. Àwọn ọmọ orí ayélujára ti yára bu ẹnu àtẹ́ lu ìdí tí àtẹ́jọ́pè fi sílẹ̀ nínú ìgbẹ́jọ́. Ka siwaju si i: Mozambique, Cote d'Ivoire gbe igbese akoni fun eto awon obinrin ati omode Kà síwájú sí i: Mozambique, Cote d'Ivoire gbé ìgbésẹ̀ akọni fún ẹ̀tọ́ àwọn obìnrin àti ọmọdé Didogba abo atako Dídọ̀gba abo atakọ Idajo ile ejo naa je atoka si ifopinsi awon asa ti o n mu ipalara ba awon omodebinrin ati oniruuru eleyameya toun ifoworoseyin awon omodebinrin ni Tanzania. Ìdájọ́ ilé ẹjọ́ náà jẹ́ atọ́ka sí ìfòpinsí àwọn àṣà tí ó ń mú ìpalára bá àwọn ọmọdébìnrin àti onírúurú ẹlẹ́yàmẹyà tòun ìfọwọ́rọ́sẹ́yìn àwọn ọmọdébìnrin ní Tanzania. Ni ti ajo United Nations, ki a to le yege nibi ti didogba abo atako ni odun-un 2030, ijoba ni lati se ayipada ofin iyasotooto ati sise amulo isofin ti yoo mu imudogba ti a n so waye. Ní ti àjọ United Nations, kí a tó lè yege níbi ti dídọ́gba abo atakọ ní ọdún-un 2030, ìjọba ní láti ṣe àyípadà òfin ìyàsọ́tọ̀ọtọ̀ àti ṣíṣe àmúlò ìṣòfin tí yóò mú ìmúdọ́gba tí à ń sọ wáyé. Abajade iwadii se afihan-an re wipe ojo ori ti o to lati se igbeyawo ba ipele iwe ti eniyan ka ati oro ti eniyan ti ko jo (TDHS 201) tan. Àbájáde ìwádìí ṣe àfihàn-an rẹ̀ wípé ọjọ́ orí tí ó tọ́ láti ṣe ìgbéyàwó bá ìpele ìwé tí ènìyàn kà àti ọrọ̀ tí ènìyán ti kó jọ (TDHS 201) tan. Ni Tanzania, o ni iyato odun mefa ti o wa laaarin omodebinrin ti ko lo si ile iwe ati awon ti o ka iwe giga tabi iwe giga ju lo. Ní Tanzania, ó ní ìyàtọ̀ ọdún mẹ́fà tí ó wà láàárín ọmọdébìnrin tí kò lọ sí ilé ìwé àti àwọn tí ó ka ìwé gíga tàbí ìwé gíga jù lọ. Ni Tanzania, ohun ti ko ba ofin mu ni ki a fe tabi fun akekoobinrin loyun, ewon ogbon odun ni eni ba tase agere sofin yoo fi gbara. Ní Tanzania, ohun tí kò bá òfin mu ni kí a fẹ́ tàbí fún akẹ́kọ̀ọ́bìnrin lóyún, ẹ̀wọ̀n ọgbọ̀n ọdún ni ẹní bá tasẹ̀ àgẹ̀rẹ̀ sófin yóò fi gbára. Akekoobinrin ti o ba loyun ki i pada si ile iwe paapaa ti o ba bimo tan. Akẹ́kọ̀ọ́bìnrin tí ó bá lóyún kì í padà sí ilé ìwé pàápàá tí ó bá bímọ tán. Ifofinde isoyigi pelu omode maa n fi aabo fun awon omodebinrin, lai ro bi won se wo ile iwe. Ìfòfinde ìsoyìgì pẹ̀lú ọmọdé máa ń fi ààbò fún àwọn ọmọdébìnrin, láì ro bí wọ́n ṣe wọ ilé ìwé. Ni Tanzania, igbeyawo omodebinrin ki i je ki omodebinrin o kawe ti won ko si ni anfaani lati pari ekoo won, gege bi esi iwadii lati Tanzania National Survey, 2017 se ni i lakosile. Ní Tanzania, ìgbéyàwó ọmọdébìnrin kì í jẹ kí ọmọdébìnrin ó kàwé tí wọn kò sì ní àǹfààní láti parí ẹ̀kọ́ọ wọn, gẹ́gẹ́ bí èsì ìwádìí láti Tanzania National Survey, 2017 ṣe ní i lákọsílẹ̀. Ifofinde isoyigi yii se agbekale igbe aye to dara fun akekoobinrin lati pari ekoo won lai si idaduro. Ìfòfinde ìsoyìgì yìí ṣe àgbékalẹ̀ ìgbé ayé tó dára fún akẹ́kọ̀ọ́bìnrin láti parí ẹ̀kọ́ọ wọn láì sí ìdádúró. Pelu bee, akekoobinrin ti o ba feraku si n koju ofin ti o ni won ko gbodo pada wa sile iwe. Pẹ̀lú bẹ́ẹ̀, akẹ́kọ̀ọ́bìnrin tí ó bá fẹ́rakù ṣì ń kojú òfin tí ó ní wọn kò gbọdọ̀ padà wá sílé ìwé. Aami idanimo orile edee Jamaica ti Kanye West lo di awuyewuye ti o da firigbagboo lori ‘isaami’ Ààmì ìdánimọ̀ orílẹ̀ èdèe Jamaica tí Kanye West lò di awuyewuye tí ó dá fìrìgbagbòó lórí ‘ìsààmì’ Eru oja pelu akori nipa Jamaica di tita lori ayelujara Ẹrù ọjà pẹ̀lú àkórí nípa Jamaica di títà lórí ayélujára Kanye West n korin nibi ayeye olodoodun Ile-ona ti Ona Igbalode ni Garden benefit, New York City, ojo 10, osu karun-un, 2011. Aworan lati owoo Jason Persse, CC BY-SA 2.0. Kanye West ń kọrin níbi ayẹyẹ ọlọ́dọọdún Ilé-ọnà ti Ọnà Ìgbàlódé ní Garden benefit, New York City, ọjọ́ 10, oṣù karùn-ún, 2011. Àwòrán láti ọwọ́ọ Jason Persse, CC BY-SA 2.0. "Okorin takasufee ti o je omo orile edee Amerika Kanye West gbe ariya ""Isin Ojo Ose "" pop-up concert wa si Kingston, Jamaica, ni kete ti isinmi ojo ose fun Ayajo Ojo Awon Malegbagbe Omo Orile-ede naa (19-21, osu Owara odun-un 2019) yoo bere." "Ọ̀kọrin tàkasúfèé tí ó jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdèe Amẹ́ríkà Kanye West gbé àríyá ""Ìsìn Ọjọ́ Ọ̀sẹ̀ "" pop-up concert wá sí Kingston, Jamaica, ní kété tí ìsinmi ọjọ́ ọ̀sẹ̀ fún Àyájọ́ Ọjọ́ Àwọn Málegbàgbé Ọmọ Orílẹ̀-èdè náà (19-21, oṣù Ọ̀wàrà ọdún-un 2019) yóò bẹ̀rẹ̀." Eyi ni igba akoko ti okorin naa yoo ko egbe akorin iyinrere re kuro ni Amerika, ni ijepee ti agbe fun ijoba orile edee kan ti o Ja ki o gbe eto naa wa siluu oun. Èyí ni ìgbà àkọ́kọ́ tí ọ̀kọrin náà yóò kó ẹgbẹ́ akọrin ìyìnrere rẹ̀ kúrò ní Amẹ́ríkà, ní ìjẹ́pèe ti agbè fún ìjọba orílẹ̀ èdèe kan tí ó Ja kí ó gbé ètò náà wá sílùú òun. Sibe, ariya naa ti ri itako lati ibere pepe, ti o Ho fori sole pelu ami idanimoo orile-edee Jamaica ti West we lori oja ti o n ta lorii ibudo itakun agbayee re lai gba ase lati lo o. Síbẹ̀, àríyá náà tí rí ìtakò láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí ó Ho forí sọlẹ̀ pẹ̀lú àmì ìdánimọ̀ọ orílè-èdèe Jamaica tí West we lórí ọjà tí ó ń tà lóríi ibùdó ìtakùn àgbáyée rẹ̀ láì gba àṣẹ láti lò ó. Laaarin ojo meji ni ikede fi lo sita, inuu gbagede Emancipation Park to wa ni Kingston, olu ilu orile ede naa ni bebe ti waye — oju ibi ti o mu awon sorosoro kan wi tenu won latari awon oro to mu ariyanjiyan dani ti West so nipa owo eru ninu iforowanilenuwo kan bayii losu karun-un odun-un 2018. Láàárín ọjọ́ méjì ni ìkéde fi lọ síta, inúu gbàgede Emancipation Park tó wà ní Kingston, olú ìlú orílẹ̀ èdè náà ni bẹbẹ́ ti wáyé — ojú ibi tí ó mú àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ kan wí tẹnu wọn látàrí àwọn ọ̀rọ̀ tó mú àríyànjiyàn dání tí West sọ nípa òwò ẹrú nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan báyìí lóṣù karùn-ún ọdún-un 2018. "Odun-un 2002 ni gbagede naa di lilo ni ibowo fun ""ominira doju ami"" fun awon eru 300,000 ni Jamaica lojo 1, osu kejo odun-un 1838." "Ọdún-un 2002 ni gbàgede náà di lílò ní ìbọ̀wọ̀ fún ""òmìnira dójú àmì"" fún àwọn ẹrú 300,000 ní Jamaica lọ́jọ́ 1, oṣù kẹjọ ọdún-un 1838." O le je eyi gan-an ni oun akoko nipa ariya orin naa, sugbon oun ko ni o gbeyin. Ó lè jẹ́ èyí gan-an ni oun àkọ́kọ́ nípa àríyá orin náà, ṣùgbọ́n òun kọ́ ni ó gbẹ̀yìn. "Paapaa ju lo bi Olootu Eto Asa Olivia ""Babsy"" Grange se benu-ate lu awon alatako nigba ti o so wipe orile ede naa se abapin ninu ere ariya naa, ni eyi ti asagbateru orin kan lero wipe ariya naa ti o se e wo loju ese bi o se n lo lorii itakun agbayee Isin Ojo Ose, ""gba"" awon eto ti o ro mo asa ibile ti o je ti Isinmi awon Malegbagbe Omo orile ede segbee." "Pàápàá jù lọ bí Olóòtú Ètò Àṣà Olivia ""Babsy"" Grange ṣe bẹnu-àtẹ́ lu àwọn alátakò nígbà tí ó sọ wípé orílẹ̀ èdè náà ṣe àbápín nínú èrè àríyá náà, ní èyí tí aṣagbátẹrù orin kan lérò wípé àríyá náà tí ó ṣe é wò lójú ẹsẹ̀ bí ó ṣe ń lọ lóríi ìtakùn àgbáyée Ìsìn Ọjọ́ Ọ̀sẹ̀, ""gba"" àwọn ètò tí ó rọ̀ mọ́ àṣà ìbílẹ̀ tí ó jẹ́ ti Ìsinmi àwọn Málegbàgbé Ọmọ orílẹ̀ èdè sẹ́gbẹ̀ẹ́." Lafikun, awon olugbee Kingston, ti o ba sunkere fakere kodimu lose yen, fo afotele laasigbo ati rotiroti bi awon to siwo ise ba n dari lo sile nirole. Láfikún, àwọn olùgbée Kingston, tí ó bá súnkẹrẹ fàkẹrẹ kòdìmú lọ́sẹ̀ yẹn, fọ àfọ̀tẹ́lẹ̀ làásìgbò àti rọ̀tìrọti bí àwọn tó ṣíwọ́ iṣẹ́ bá ń darí lọ sílé nírọ̀lẹ́. Lai si ani-ani, ariya naa lo ni irowo-irose, egbeegberun lona egberun awon Nev orile-edee Jamaica gbadun-un ariya naa ti awon ileese agbohunsafefe orile edee Jamaica naa gba igboriyin fun ise takuntakun ti won se: Láì sí àní-àní, àríyá náà lọ ní ìrọwọ́-ìrọsẹ̀, ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún àwọn Nev orílẹ̀-èdèe Jamaica gbádùn-un àríyá náà tí àwọn iléeṣẹ́ agbóhùnsáfẹ́fẹ́ orílẹ̀ èdèe Jamaica náà gba ìgbóríyìn fún iṣẹ́ takuntakun tí wọ́n ṣe: Iroyin etiigbo igboro ni wipe o see se ki igbese wa lati (Isin Ojo-aiku) lati gba ase emi-ni-monii/eto onihun aami idanimoo Kingston, orile ede Jamaica ati ti eye olulana oniru gigun. Ìròyìn etíìgbọ́ ìgboro ni wípé ó ṣeé ṣe kí ìgbésẹ̀ wà láti (Ìsìn Ọjọ́-àìkú) láti gba àsẹ èmi-ni-monií/ẹ̀tọ́ oníhun ààmì ìdánimọ̀ọ Kingston, orílẹ̀ èdè Jamaica àti ti ẹyẹ olùlànà onírù gígùn. Mo ti se awon iwadii kan lori ayelujara ti mo si se awari lati fi ti eri leyin amo kadara ko se mi loore, mo salabaapade ojaa won ti won n ta lori ayelujara to ni awon aami idanimo wonyi, ti o si se dogba-n-dogba pelu ariya naa... Mo ti ṣe àwọn ìwádìí kan lórí ayélujára tí mo sì ṣe àwárí láti fi ti ẹ̀rí lẹ́yìn àmọ́ kádàrá kò ṣe mí lóore, mo ṣalábàápàdé ọjàa wọn tí wọ́n ń tà lórí ayélujára tó ní àwọn ààmi ìdánimọ̀ wọ̀nyí, tí ó sì ṣe dọ́gba-n-dọ́gba pẹ̀lú àríyá náà... Otito orile edee Jamaica ni wipe awon ijoba ana ko fi igbakan kobiara si igbero eto oro Ajee ‘Jamaica’ tabi awon aami idanimo to je ti won bii asia ati asia apata. Òtítọ́ orílẹ̀ èdèe Jamaica ni wípé àwọn ìjọba àná kò fi ìgbàkan kọbiara sí ìgbéró èto ọrọ̀ Ajée ‘Jamaica’ tàbí àwọn ààmi ìdánimọ̀ tó jẹ́ ti wọn bíi àsíá àti àsíá apata. Bakannaa ni o ri fun orin wa ati ohun ti o ro mo, Ska, Mento, Rock Steady, Reggae ati bee bee lo. Bákannáà ni ó rí fún orin wa àti ohun tí ó rọ̀ mọ́, Ska, Mento, Rock Steady, Reggae àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ile Jamaica ko tete laju si owo aso sise ti o ni aami pataki erekusu ti yoo mu awon eniyan ra a witiwiti. Ilẹ̀ Jamaica kò tètè lajú sí òwò aṣọ ṣíṣe tí ó ní ààmì pàtàkì erékùṣù tí yóò mú àwọn ènìyàn rà á wìtìwìtì. Bi a ba fi eto ariya se igbelaruge awon oja wonyi ninuu gbagede Emancipation Park ti o mu ilosiwaju ba ohun ti o ju aso lo lati odo ijoba ati awon omo orile edee Jamaica naa, pelu lilo awon aamii orile ede naa ni ona ara. Bí a bá fi ètò àríyá ṣe ìgbélárugẹ àwọn ọjà wọ̀nyí nínúu gbàgede Emancipation Park tí ó mú ìlọsíwájú bá ohun tí ó ju aṣọ lọ láti ọ̀dọ̀ ìjọba àti àwọn ọmọ orílẹ̀ èdèe Jamaica náà, pẹ̀lú lílo àwọn ààmìi orílẹ̀ èdè náà ní ọ̀nà àrà. Mo ti se akiyesi wipe Ileese Eto Asa ati Oludari iluu Kingston ti n gbe igbesee pajawiri lati ra nnkan pada. Ki awon mejeeji mo pe atunse ki i se nnkan to ma ya kiakia. Mo ti ṣe àkíyèsí wípé Iléeṣẹ́ Ètò Àṣà àti Olùdarí ìlúu Kingston ti ń gbé ìgbésẹ̀ẹ pàjáwìrì láti ra nǹkan padà. Kí àwọn méjèèjì mọ̀ pé àtúnṣe kì í ṣe nǹkan tó ma yá kíákíá. Mo lero wipe ijoba ni awon agbejoro to ka oju osuwon. Mo lérò wípé ìjọba ní àwọn agbẹjọ́rò tó ká ojú òṣùwọ̀n. Loooto, awon agbejoro si nise lati se lati tu koko awuyewuye eti aso ti lilo asia orile edee Jamaica. Lóòótọ́, àwọn agbẹjọ́rò ṣì níṣẹ́ láti ṣe láti tú kókó awuyewuye etí aṣọ ti lílo àsíá orílẹ̀ èdèe Jamaica. Irolu olopaa ti i mu iku ba ‘ni ni Guinea bi Aare Alpha Conde se ko lai gbe’ joba sile Ìrọ́lù ọlọ́pàá tí í mú ikú bá ‘ni ní Guinea bí Ààrẹ Alpha Condé ṣe kọ̀ láì gbé’ jọba sílẹ̀ """Opolopo ilu ti koyin sijoba lori igbese yii""" """Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìlú ti kọ̀yìn síjọba lórí ìgbésẹ̀ yìí""" Ageku ohun ti o n sele ni Guinea lati iroyin ranpe France 24 kan. Àgékù ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní Guinea láti ìròyìn ránpẹ́ France 24 kan. Iwa ipa be sile ni Guinea lojo 14 osu Owara, ti o ti fa iku opolopo eniyan ti won si n ko awon eniyan kiri leyin iyide ifehonuhan ti o tako ijoba aare ti o wa lori oye iyen Alpha Conde, eni ti o n gbero lati yi iwe-ofin pada ki o ba fi aaye gba oun lati lo fun igba keta. Ìwà ipá bẹ́ sílẹ̀ ní Guinea lọ́jọ́ 14 oṣù Ọ̀wàrà, tí ó ti fa ikú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tí wọ́n sì ń kó àwọn ènìyàn kiri lẹ́yìn ìyíde ìféhónúhàn tí ó tako ìjọba ààrẹ tí ó wà lórí oyè ìyẹn Alpha Condé, ẹni tí ó ń gbèrò láti yí ìwé-òfin padà kí ó bá fi ààyè gba òun láti lọ fún ìgbà kẹta. Ojuu popo olu ilu naa, Conakry, ati awon ilu to ku ti di oju ogun laaarin ajo agbofinro ati awon omo ilu to n fi ehonu han. Ojúu pópó olú ìlú náà, Conakry, àti àwọn ìlú tó kù ti di ojú ogun láàárín àjọ agbófinró àti àwọn ọmọ ìlú tó ń fi èhónú hàn. Ileese olopaa ti lo anfaani tuntun ti o fun won lase lati lo ohun ija asekupani bi o ba de oju e. Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ti lo àǹfààní tuntun tí ó fún wọn láṣẹ láti lo ohun ìjà aṣekúpani bí ó bá dé ojú ẹ̀. Awon afehonuhan ti ran eni mefa si orun ajanto, ni eyi ti o je pe olopaa kan wa ninuu awon ti o je Ogun nipe, opo eeyan lo si fi ara pa. Àwọn afẹ̀hónúhàn ti rán ẹni mẹ́fà sí ọ̀run àjànto, ní èyí tí ó jẹ́ pé ọlọ́pàá kan wà nínúu àwọn tí ó jẹ́ Ògún nípè, ọ̀pọ̀ èèyàn ló sì fi ara pa. Ka siwaju si i: Awon eso alaabo ni Guinea ti ni ase lati lo ohun ija asekupani Kà síwájú sí i: Àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò ní Guinea ti ní àṣẹ láti lo ohun ìjà aṣekúpani Awon afehonuhan ko lowo si kilanko ayipada si iwe-ofin ti won ri gege bi igbese aare lati wa lori ipo fun eleeketa. Àwọn afẹ̀hónúhàn kò lọ́wọ́ sí kílàńkó àyípadà sí ìwé-òfin tí wọ́n rí gẹ́gẹ́ bí ìgbésẹ̀ ààrẹ láti wà lórí ipò fún ẹlẹ́ẹ̀kẹ́ta. Ni tooto, iwe-ofin naa fi aaye odun meji gba eni ti o ba wa ni ipo aare lati sejoba. Conde, eni odun 81, ye ki saa re o pari ni osu Owara odun-un 2020. Ní tòótọ́, ìwé-òfin náà fi ààyè ọdún méjì gba ẹni tí ó bá wà ní ipò ààrẹ láti ṣèjọba. Condé, ẹni ọdún 81, yẹ kí sáà rẹ̀ ó parí ní oṣù Ọ̀wàrà ọdún-un 2020. Awon afehonuhan ni a le sa logbe ju lo nitori wipe won tase agere si ofin naa bi Human Rights Watch se pe fun akiyesi: Àwọn afẹ̀hónúhàn ni a lè ṣá lọ́gbẹ́ jù lọ nítorí wípé wọ́n tasẹ̀ àgẹ̀rẹ̀ sí òfin náà bí Human Rights Watch ṣe pè fún àkíyèsí: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an Human Rights Watch so lonii wipe, ijoba orile-edee Guinea ti gbese le ifehonuhan l'ojuu popo fun odun kan, o toka si idoju-ija-ko aabo ilu. Human Rights Watch sọ lónìí wípé, ìjọba orílẹ̀-èdèe Guinea ti gbẹ́sẹ̀ lé ìfèhònúhàn l'ójúu pópó fún ọdún kan, ó tọ́ka sí ìdojú-ìjà-kọ ààbò ìlú. Awon alase ijoba ibile ti fon o to bii ogun ifehonuhan egbe oselu ati awon miiran ka yanga. Àwọn aláṣẹ ìjọba ìbílẹ̀ ti fọ́n ó tó bíi ogún ìfèhònúhàn ẹgbẹ́ òṣèlú àti àwọn mìíràn ká yángá. Awon eso alaabo ti so tajutaju si aarin awon ti ko gboran lati tu won ka, won si ko aimoye eniyan. Àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò ti sọ tajútajú sí àárín àwọn tí kò gbọ́ràn láti tú wọn ká, wọ́n sì kó àìmọye ènìyàn. Ni ti isele oselu naa, ajo oba naa n kede ise-ije ti o n tako ara won: Ni ojo 13, osu Owara Aare Conde fe isoro-ni-tunbi-n-nubi: Ní ti ìṣẹ̀lẹ̀ òṣèlú náà, àjọ ọba náà ń kéde iṣẹ́-ìjẹ́ tí ó ń tako ara wọn: Ní ọjọ́ 13, oṣù Ọ̀wàrà Ààrẹ Condé fẹ́ ìsọ̀rọ̀-ní-tùnbí-ǹ-nùbí: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an Alpha Conde ti pe fun isoro ni tunbinnubi o si fe ki ijokoo gege bi tomotiya ti yoo fi peleputu yanju gbonmi-sii-omi-o-too ti o n sele ati ona abayo si awon ipenija ti o n koju orile-ede naa. Alpha Condé ti pè fún ìsọ̀rọ̀ ní tùnbíǹnùbí ó sì fẹ́ kí ìjókòó gẹ́gẹ́ bí tọmọtìyá tí yóò fi pẹ̀lẹ́pùtù yanjú gbọ́nmi-síi-omi-ò-tóo tí ó ń ṣẹlẹ̀ àti ọ̀nà àbáyọ sí àwọn ìpèníjà tí ó ń kojú orílẹ̀-èdè náà. Sibe, Ahmed Tidiane Traore, oludamoran ipo aare, so lojo ti o tele e, iyen ni ojo 12 osu Owara, — ojo meji ki ifehonuhan o to bere, — fun awon ero to je odo langba RPG egbe oloseluu [ruling Reunion of the People of Guinea]: Síbẹ̀, Ahmed Tidiane Traoré, olùdámọ̀ràn ipò ààrẹ, sọ lọ́jọ́ tí ó tẹ̀lé e, ìyẹn ní ọjọ́ 12 oṣù Ọ̀wàrà, — ọjọ́ méjì kí ìfẹ̀hònúhàn ó tó bẹ̀rẹ̀, — fún àwọn èrò tó jẹ́ ọ̀dọ́ langba RPG ẹgbẹ́ olóṣèlúu [ruling Reunion of the People of Guinea]: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an A ro awon odo egbe oselu naa lati kun fun isora ni ojuu popo. A rọ àwọn ọ̀dọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú náà láti kún fún ìṣọ́ra ní ojúu pópó. Awon [ti awon je ajijangbara alatako] ti fa isoro, a pe awon ipeere lati inu egbe naa lati wa ona abayo si isoro to wa nile, amo ki e maa doju ija ko enikeni, ki e maa ba dukia kankan je, ju idaabo bo ara yin lo. Àwọn [tí àwọn jẹ́ ajìjàngbara alátakò] ti fa ìṣòro, a pe àwọn ìpẹ́ẹ̀rẹ́ láti inú ẹgbẹ́ náà láti wá ọ̀nà àbáyọ sí ìṣòro tó wà nílẹ̀, àmọ́ kí ẹ máà dojú ìjà kọ ẹnikẹ́ni, kí ẹ máà ba dúkìá kankan jẹ́, ju ìdáàbò bo ara yín lọ. Gbogbo awon onise-ibi ni o di awari ti a o fi ojuu won han f'araye ri. Gbogbo àwọn oníṣẹ́-ibi ni ó di àwárí tí a ó fi ojúu wọn hàn f'áráyé rí. Enu meji awon ti o n tuko ilu ti tubo mu inu bi egbe alatako ati awon ajafetoo omoniyan, o ni bi itakun globalguinee.info se so: Ẹnu méjì àwọn tí ó ń tukọ̀ ìlú ti túbọ̀ mú inú bí ẹgbẹ́ alátakò àti àwọn àjàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọnìyàn, ó ní bí ìtakùn globalguinee.info ṣe sọ: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an Ojo 14 osu Owara odun-un 2019 je ojo Aje buruku Esu gbomi mu, ni ti ifesi si ipe ajo FNDC [Awon ti o n le waju n'nu Idaabo bo Iwe-ofin Orile-ede], awon omo Guinea tu yaya tu yaya si ojuu titi lati tako igbese atunse si iwe-ofin. Ọjọ́ 14 oṣù Ọ̀wàrà ọdún-un 2019 jẹ́ ọjọ́ Ajé burúkú Èṣù gbomi mu, ní ti ìfèsì sí ìpè àjọ FNDC [Àwọn tí ó ń lé wájú ń'nú Ìdáàbò bo Ìwé-òfin Orílẹ̀-èdè], àwọn ọmọ Guinea tú yáyá tú yàyà sí ojúu títì láti tako ìgbésẹ̀ àtúnṣe sí ìwé-òfin. Ikolu waye ni awon agbegbe ti o wa ni aarin olu ilu orile-ede naa. Ìkọlù wáyé ní àwọn agbègbè tí ó wà ní àárín olú ìlú orílẹ̀-èdè náà. Karakata denu kole ni aarin gbungbun ibi isakoso ilu ni Kalou. Káràkátà dẹnu kọlẹ̀ ní àárín gbùngbùn ibi ìṣàkóso ìlú ní Kalou. Awon ti o wa ni Aarin ati Odo orile ede Guinea naa gbo ipe, won si darapo mo awon omo ilu to ku. Àwọn tí ó wà ní Àárín àti Odò orílẹ̀ èdè Guinea náà gbọ́ ìpè, wọ́n sì darapọ̀ mọ́ àwọn ọmọ ìlú tó kù. Eniyan die ni o jade ni igberiko ati Okee Guinea. Ènìyàn díẹ̀ ni ó jáde ní ìgbèríko àti Òkèe Guinea. Amo sa, opolopo ilu ti koyin sijoba lori igbese yii. Àmọ́ ṣá, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìlú ti kọ̀yìn síjọba lórí ìgbésẹ̀ yìí. Ni orii benbere.org, gbagede itakuroso fun awon odo ni Mali, akoroyin buloogu Adam Thiam ko: Ní oríi benbere.org, gbàgede ìtàkùrọ̀sọ fún àwọn ọ̀dọ́ ní Mali, akọ̀ròyin búlọ́ọ̀gù Adam Thiam kọ: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an Nnkan kayeefi n lo lowo lowo bayii ni Guinea, pelu irogbamu ti o n waye, ota ibon ti fo si ara awon afehonuhan ti o si ti seku pa opolopoo won, eje ni ojuu popo, idigaga ni gbogbo, ina ese okoo sisun ati tajutaju ninu afefe. Nǹkan kàyèéfì ń lọ lọ́wọ́ lọ́wọ́ báyìí ní Guinea, pẹ̀lú ìrógbàmù tí ó ń wáyé, ọta ìbon ti fọ́ sí ara àwọn afẹ̀hónúhàn tí ó sì ti ṣekú pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ọ wọn, ẹ̀jẹ̀ ní ojúu pópó, ìdígàgá ní gbogbo, iná ẹsẹ̀ ọkọ̀ọ sísun àti tajútajú nínú afẹ́fẹ́. Awon omo ilu ori ayelujara fajuro si isele naa lori ero alatagba: Àwọn ọmọ ìlú orí ayélujára fajúro sí ìṣẹ̀lẹ̀ náà lórí ẹ̀rọ alátagbà: Bii ti Blaise Compaore [oloseluu Burkinabe] Alpha Conde n fori le ibi iparun, nje yo lee gbohun inubibi awon araa re bi? Bíi ti Blaise Compaoré [olóṣèlúu Burkinabé] Alpha Condé ń forí lé ibi ìparun, ǹjẹ́ yó leè gbóhùn inúbíbí àwọn aráa rẹ̀ bí? O di ojo iwaju ki a to mo. Ni bayii sa, oko oju omi ti n re. Ó di ọjọ́ iwájú kí á tó mọ̀. Ní báyìí ṣá, ọkọ̀ ojú omi ti ń ré. Lojo 15 osu Owara, akoroyin Guinea Bhiye Bary ko: Lọ́jọ́ 15 oṣù Ọ̀wàrà, akọ̀ròyin Guinea Bhiye Bary kọ: Ile itoogun Hamdallaye (#Conakry): awon olopaa lo ji awon omo ilu kan loju oorun ni owuro yii. Ilé ìtòògùn Hamdallaye (#Conakry): àwọn ọlọ́pàá ló jí àwọn ọmọ ìlú kan lójú oorun ní òwúrọ̀ yìí. Gege bi enikan ti se so, awon olopaa n jalekun ti won si n ko eru nile onile. Gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti ṣe sọ, àwọn ọlọ́pàá ń jálẹ̀kùn tí wọ́n sì ń kó ẹrù nílé onílé. S. Nkola Matamba, onkowe ati ajafetoo omoniyan ti o je omo Ilu Olominira Ijoba ara wa ti Congo, fi ibanuje okan han: S. Nkola Matamba, òǹkọ̀wé àti ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọnìyan tí ó jẹ́ ọmọ Ìlú Olómìnira Ìjọba ara wa ti Congo, fi ìbánújẹ́ ọkàn hàn: Omo egbe alatako igbakan, ti o wa fe yi ofin pada nitori ife ara re ki o ba sejoba fun igba keta, boya ki o ba je gaba titi ti Olojo yoo fi de, Alpha Conde gan-an ni apeere ibi ti o n fa ifaseyin fun Ile-Adulawo ! Ọmọ ẹgbẹ́ alátakò ìgbàkan, tí ó wá fẹ́ yí òfin padà nítorí ìfẹ́ ara rẹ̀ kí ó ba ṣèjòba fún ìgbà kẹta, bóyá kí ó bá jẹ gàba títí tí Ọlọ́jọ́ yóò fi dé, Alpha Condé gan-an ni àpẹẹrẹ ibi tí ó ń fa ìfàsẹ́yìn fún Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ! Eyin araa Guinea, e mu okan le! Ẹ̀yin aráa Guinea, ẹ mú ọkàn le! #GUINEE – o je ohun iyalenu. Ifehonuhan itako isejoba Conde fun igba keta ojo kan soso ti mu emi awon eniyan lo. #GUINÉE – ó jẹ́ ohun ìyàlẹ́nu. Ìfẹ̀hònúhàn ìtako ìṣèjọba Condé fún ìgbà kẹta ọjọ́ kan ṣoṣo tí mú ẹ̀mí àwọn ènìyàn lọ. Sisiwin awon oloselu ti o fe ku sori ipo aare yii ti n po ju Amoulanfe— Cheikh FallTM (@cypher007) ojo 14, osu Owara 2019 Sísíwín àwọn olóṣèlú tí ó fẹ́ kú sórí ipò ààrẹ yìí ti ń pọ̀ jù Amoulanfe— Cheikh Fall™ (@cypher007) ọjọ́ 14, oṣù Ọ̀wàrà 2019 Ajijangbara Guinea Macky Darsalam so ti igbese lati towo bo erongba awon ara ilu loju: Ajìjàǹgbara Guinea Macky Darsalam sọ ti ìgbésẹ̀ láti tọwọ́ bọ èròńgbà àwọn ará ìlú lójú: Egbe alatako Guinea naa ko ni aabo ti o le fi bo araa re lasiko ikolu: awon asoju alase egbe alatako gbogbo ko da si ariyanjiyan igbimo ijoba mo lati ojo 11, osu Owara 2019. Ẹgbẹ́ alátakò Guinea náà kò ní ààbò tí ó lè fi bo araa rẹ̀ lásìkò ìkọlù: àwọn aṣojú aláṣẹ ẹgbẹ́ alátakò gbogbo kò dá sí àríyànjiyàn ìgbìmọ̀ ìjọba mọ́ láti ọjọ́ 11, oṣù Ọ̀wàrà 2019. Iwa ipa si awon egbe oloselu wonyi ti gba ona ara, bee ni ibudo itakun mediaguinee.org se ko: Ìwà ipá sí àwọn ẹgbẹ́ olóṣèlú wọ̀nyí ti gba ọ̀nà àrà, bẹ́ẹ̀ ni ibùdó ìtakùn mediaguinee.org ṣe kọ: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an ...ni olu ileese Union of Republican Forces (URF) ti agbegbe Sidya Toure, ija waye laaarin awon omo egbe alatako kan ati awon ti o n fe ti ijoba ti o ti seto ti ko ni je ki iyide ifehonuhan naa o waye lojo kan si ojo ifehonuhan ni awon agbegbe ti won ti lenu. ...ní olú iléeṣẹ́ Union of Republican Forces (URF) tí agbègbè Sidya Touré, ìjá wáyé láàárín àwọn ọmọ ẹgbẹ́ alátakò kan àti àwọn tí ó ń fẹ́ ti ìjọba tí ó ti ṣètò tí kò ní jẹ́ kí ìyíde ìfẹ̀hónúhàn náà ó wáyé lọ́jọ́ kan sí ọjọ́ ìfẹ̀hónúhàn ní àwọn agbègbè tí wọ́n ti lẹ́nu. Ikolu naa wa si opin leyin-in ikolo ileese URF naa ti awon eniyan mefa ti ko si eni to mo oruko ati egbe oloselu ti won n ba se di ero atimole. Ìkọlù náà wá sí òpin lẹ́yìn-in ìkólọ iléeṣẹ́ URF náà tí àwọn ènìyàn mẹ́fà tí kò sí ẹni tó mọ orúkọ àti ẹgbẹ́ olóṣèlú tí wọ́n ń bá ṣe di èrò àtìmọ́lé. #SexForGrades: Eto Alalaye-aferihan tu asiiri iwa iyolenu ibalopo ni awon Ifasitii Iwo-oorun Ile-Adulawo #SexForGrades: Ètò Alálàyé-afẹ̀ríhàn tú àṣìírí ìwà ìyọlẹ́nu ìbálòpọ̀ ní àwọn Ifásitìi Ìwọ-oòrùn Ilẹ̀-Adúláwọ̀ Itiju mu awon ti isele sele si maa lee so Ìtìjú mú àwọn tí ìṣẹ̀lẹ̀ ṣẹlẹ̀ sí máà leè sọ Boniface Igbeneghu, ojogbon Ifasitii Eko, Naijiria ti ba eni ti o wo iboju yii se eree gele ni aimoye igba (Aworan lati BBC #SexForGrades) Boniface Igbeneghu, ọ̀jọ̀gbọ́n Ifásitìi Èkó, Nàìjíríà ti bá ẹni tí ó wọ ìbòjú yìí ṣe erée gélé ní àìmọye ìgbà (Àwòrán láti BBC #SexForGrades) #SexForGrades, eto alalaye aferihan-an BBC kan ti o da firigbagboo lorii asemase ere ife ti awon ojogbon ifasiti pelu awon akekoobirin ni Naijiria ati Ghana ti ran bii papa inu oye ni ori ayelujara ti o si ti fa awon ibeere olokanojokan nipa ona ti a lee gba dekun asemase ohun lawujo: #SexForGrades, ètò alálàyé afẹ̀ríhàn-an BBC kan tí ó dá fìrìgbagbòó lóríi àṣemáṣe eré ìfẹ́ tí àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n ifásitì pẹ̀lú àwọn akẹ́kọ̀ọ́bìrin ní Nàìjíríà àti Ghana ti ràn bíi pápá inú ọyẹ́ ní orí ayélujára tí ó sì ti fa àwọn ìbéèrè ọlọ́kanòjọ̀kan nípa ọ̀nà tí a leè gbà dẹ́kùn àṣemáṣe ọ̀hún láwùjọ: Agba ise iwadii naa, ti o di gbigbe jade ni ojo keje osu Owara 2019, ti akoroyin Kiki Mordi ti ko pari ekoo re latarii wipe ko fe se asemase pelu olukoni ifasiti re ti o n fi idii re remi ninu idanwo nitori wipe ko fun un se se atokun-un re: Àgbà iṣẹ́ ìwádìí náà, tí ó di gbígbé jáde ní ọjọ́ kéje oṣù Ọ̀wàrà 2019, tí akọ̀ròyin Kiki Mordi tí kò parí ẹ̀kọ́ọ rẹ̀ látàríi wípé kò fẹ́ ṣe àṣemáṣe pẹ̀lú olùkọ́ní ifásitì rẹ̀ tí ó ń fi ìdíi rẹ̀ rẹmi nínú ìdánwò nítorí wípé kò fún un ṣe ṣe atọ́kùn-un rẹ̀: Boniface Igbeneghu, Ifasiti Eko, ti a ka iwa asemase pelu awon akekoobirin ninu iwadii abele ti BBC se. Boniface Igbeneghu, Ifásitì Èkó, tí a ká ìwà àṣemáṣe pẹ̀lú àwọn akẹ́kọ̀ọ́bìrin nínú ìwádìí abẹ́lẹ̀ tí BBC ṣe. Aworan lati BBC #SexForGrades. Àwòrán láti BBC #SexForGrades. Iwadii ti o pe wakati kan tu asiiri iwa asemase ti “ere ife fun oju-ami eko” ni ifasiti Iwo-oorun Ile Adulawo meji: University of Lagos (UNILAG) ti Naijiria ati University of Ghana. Ìwádìí tí ó pé wákàtí kan tú àṣìírí ìwà àṣemáṣe ti “eré ìfẹ́ fún ojú-àmì ẹ̀kọ́” ní ifásitì Ìwọ̀-oòrùn Ilẹ̀ Adúláwọ̀ méjì: University of Lagos (UNILAG) ti Nàìjíríà àti University of Ghana. Boniface Igbeneghu, ti i se kofeso ni eka ise ona ti UNILAG, ti o si tun je alufaa Ijo Foursquare Gospel, ni Eko, n be ninu awon oluko ti okete boru mo lowo. Boniface Igbeneghu, tí í ṣe kòfẹ́sọ̀ ní ẹ̀ka iṣẹ́ ọnà ti UNILAG, tí ó sì tún jẹ́ àlùfáà Ìjọ Foursquare Gospel, ní Èkó, ń bẹ nínú àwọn olùkọ́ tí òkété bórù mọ́ lọ́wọ́. A ri Igbeneghu ninuu etoo BBC naa ti o ko enu ife si omodebinrin ti o dibon gege bi omo olojo ori metadinlogun ti o n wa igbanisile eko lai fura wipe ajabo iroyin ti o n se ise iwadii abele fun BBC ni o n se. Igbeneghu so bayii wipe: A rí Igbeneghu nínúu ètòo BBC náà tí ó kọ ẹnu ìfẹ́ sí ọmọdébìnrin tí ó díbọ́n gẹ́gẹ́ bí ọmọ ọlọ́jọ́ orí mẹ́tàdínlógún tí ó ń wà ìgbanisílé ẹ̀kọ́ láì fura wípé ajábọ̀ ìròyìn tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìwádìí abẹ́lẹ̀ fún BBC ni ó ń ṣe. Igbeneghu sọ báyìí wípé: Se o ko mo wipe omobinrin arewa ni o ? Ṣé o kò mọ̀ wípé ọmọbìnrin arẹwà ni ọ́ ? Nje o mo wipe alufaa ijo elesin igbagbo ni mo je, ati pe mo to eni aadota odun sugbon bi mo ba fe omo odun metadinlogun oro didun ati owo ni o maa je... Ǹjẹ́ o mọ̀ wípé àlùfáà ìjọ ẹlẹ́sìn ìgbàgbọ́ ni mo jẹ́, àti pé mo tó ẹni àádọ́ta ọdún ṣùgbọ́n bí mo bá fẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún ọ̀rọ̀ dídùn àti owó ni ó máa jẹ... Nibi ipade kan laaarin awon mejeeji, Igbeneghu se ina pa, o si ni ki omodebinrin naa o fenu ko ohun lenu, ti o si tun di mo on gbadigbadi ninuu iyaraa isee re ti o wa ni titi pa. Níbi ìpàdé kan láàárín àwọn méjèèjì, Igbeneghu ṣẹ́ iná pa, ó sì ní kí ọmọdébìnrin náà ó fẹ́nu ko òhun lẹ́nu, tí ó sì tún dì mọ́ ọn gbádígbádí nínúu iyàraa iṣẹ́ẹ rẹ̀ tí ó wà ní títì pa. "Ijo Ajihinrere Foursquare ti da Igbeneghu duro ""lenu ise ihin rere""." "Ìjọ Ajíhìnrere Foursquare ti dá Igbeneghu dúró ""lẹ́nu iṣẹ́ ìhìn rere""." "Bakan naa, Ifasiti Eko ti le Igbeneghu kuro ni ile iwe won si ti sun ipere si ehin ilekun ile osise ti won n pe ni ""yara tutu"", ti awon oga olukoni ti maa n se ariya nibi ti won ti maa n gba awon osoro omoge lalejo." "Bákan náà, Ifásitì Èkó ti lé Igbeneghu kúrò ní ilé ìwé wọ́n sì ti sún ìpèré sí ẹ̀hìn ilẹ̀kùn ilé òṣìṣẹ́ tí wọ́n ń pè ní ""yàrá tútù"", tí àwọn ọ̀gá olùkọ́ni ti máa ń ṣe àríyá níbi tí wọ́n ti máa ń gba àwọn ọ̀ṣọ́rọ̀ ọmọge lálejò." Awon isele ibanuje odun seyin Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ìbànújẹ́ ọdún sẹ́yìn Akara ti o tu sepo yii ti fi gongo fa komookun oro jade lenu ogoro omo orile-edee Naijiria ni ori ayelujara pelu amii #SexForGrades ni orii Twitter. Àkàrà tí ó tú sépo yìí ti fi gọ̀ngọ̀ fa kòmóòkùn ọ̀rọ̀ jáde lẹ́nu ọ̀gọ̀rọ̀ ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ní orí ayélujára pẹ̀lú àmìi #SexForGrades ní oríi Twitter. Pupo ninu awon onlo ti o je abo ni orii Twitter fi edun okan-an won han nipa iririi won lorii iwa eree gele ti ibalopo: Púpọ̀ nínú àwọn òǹlò tí ó jẹ́ abo ní oríi Twitter fi ẹ̀dùn ọkàn-an wọn hàn nípa ìríríi wọn lóríi ìwà erée gélé ti ìbálòpọ̀: "Lola Soneyin, alatinudaa ajodun iwe ati onkowe, salaye ""itiju nla"" ti ohun ri nigba ti amugbalegbee oga patapata ifasiti kan (DVC) fowo kan ibi ti ko ye ki o fowo kan lara oun:" "Lọlá Ṣónẹ́yìn, alátinúdáa àjọ̀dún ìwé àti òǹkọ̀wé, ṣàlàyé ""ìtìjú ńlá"" tí òhún rí nígbà tí amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀gá pátápátá ifásitì kan (DVC) fọwọ́ kan ibi tí kò yẹ kí ó fọwọ́ kàn lára òun:" Awon ojogbon onisina ile eko giga Naijiria ti ba ti awon obinrin je. Àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n oníṣìná ilé ẹ̀kọ́ gíga Nàìjíríà ti ba ti àwọn obìnrin jẹ́. Sibesibe, nitori itiju awon ti o fi ara pa ki i lee soro sita eyi ko si je ki o rorun lati da seria fun awon awuwa ibaje. Síbẹ̀síbẹ̀, nítorí ìtìjú àwọn tí ó fi ara pa kì í leè sọ̀rọ̀ síta èyí kò sì jẹ́ kí ó rọrùn láti dá sẹ̀ríà fún àwọn awùwà ìbàjẹ́. "Ni odun-un 2016, Igbimo Asofin mu aba ewon odun marun-un wa fun olukoni ti ile ejo ba da lebi asemase pelu akekoo ninu ""Iwe abadofin Ifopin si iwa ibaje ibalopo ni Ile Iwe Giga""." "Ní ọdún-un 2016, Ìgbìmọ̀ Àṣòfin mú àbá ẹ̀wọ̀n ọdún márùn-ún wá fún olùkọ́ní tí ilé ẹjọ́ bá dá lẹ́bi àṣemáṣe pẹ̀lú akẹ́kọ̀ọ́ nínú ""Ìwé àbádòfin Ìfòpin sí ìwà ìbàjẹ́ ìbálòpọ̀ ní Ilé Ìwé Gíga""." Sibe, Ajo Olukoni Ifasitii Naijiria ko eyin si iwe aba yii, won ni o ko iyan awon kere, nitori o koju ija si awon oluko ati wipe o yepere ase ati agbara ile eko giga. Síbẹ̀, Àjọ Olùkọ́ni Ifásitìi Nàìjíríà kọ ẹ̀yìn sí ìwé àbá yìí, wọ́n ní ó kọ iyán àwọn kéré, nítorí ó kọjú ìjà sí àwọn olùkọ́ àti wípé ó yẹpẹrẹ àṣẹ àti agbára ilé ẹ̀kọ́ gíga. Isotasi iwe aba naa pa ofin naa ni apaku fininfinfin — eyi ko si je ki aare o bu owo lu u. Ìsọtasí ìwé àbá náà pa òfin náà ní àpakú finínfinfín — èyí kò sì jẹ́ kí ààrẹ ó bu ọwọ́ lù ú. Se Ere ife fun oju-ami Eko #SexForGrades ni ijijangbara ile ijosin #ChurchToo tuntun? Ṣé Eré ìfẹ́ fún ojú-àmì Ẹ̀kọ́ #SexForGrades ni ìjìjàngbara ilé ìjọsìn #ChurchToo tuntun? Ninu osu keje odun yii, gbajugbaja ayaworan-an ni, Busola Dakolo, fi esun kan Biodun Fatoyinbo, alufaa agba ijo Commonwealth of Zion Assembly (COZA), wipe o fi ipa ba oun ni ajosepo nigba ti ohun wa ni omo odun merindinlogun. Nínú oṣù kéje ọdún yìí, gbajúgbajà ayàwòrán-an nì, Bùsọ́lá Dakolo, fi ẹ̀sùn kan Bíọ́dún Fátóyìnbó, àlùfáà àgbà ìjọ Commonwealth of Zion Assembly (COZA), wípé ó fi ipá bá òun ní àjọṣepọ̀ nígbà tí òhún wà ní ọmọ ọdún mẹ́rindínlógún. Ka siwaju si i: Alufaa tabi apanije bi epa? Kà síwájú sí i: Àlùfáà tàbí apanijẹ bí ẹ̀pa? Ajihinrere Oniwaasu ninuu wahala esun ifipabanilopo Ajíhìnrere Oníwàásù nínúu wàhálà ẹ̀sùn ìfipábánilòpọ̀ Fun odun mefa ti o re koja lo, Fatoyinbo arodede ti ri ifesunkan ifipabanilopo okan-o-jokan. Fún ọdún mẹ́fà tí ó ré kọjá lọ, Fátóyìnbó aródẹ́dẹ́ ti rí ìfẹ̀sùnkàn ìfipábánilòpọ̀ ọ̀kan-ò-jọ̀kan. Sibe, iforowanilenuwo ti Dakolo ti fesun kan Fatoyinbo da awuyewuye sile lori ayelukara bi ajere. Síbẹ̀, ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò tí Dakolo ti fẹ̀sùn kan Fátóyìnbó dá awuyewuye sílẹ̀ lórí ayélukára bí ajere. Fun ojo die, ile ijosin naa; #ChurchToo — ti i se apeere emi naa ni agbaye #MeToo — gba ayelujara kan ni Naijiria. Fún ọjọ́ díẹ̀, ilé ìjọsìn náà; #ChurchToo — tí í ṣe àpẹẹrẹ èmi náà ní àgbáyé #MeToo — gba ayélujára kan ní Nàìjíríà. Esun yii fo fere lati ori ayelujara si ifehonuhan lorii opopona ni awon ilu nla ni Naijiria bii Eko ati Abuja. Ẹ̀sùn yìí fò fẹ̀rẹ̀ láti orí ayélujára sí ìfẹ̀hónúhàn lóríi òpópónà ní àwọn ìlú ńlá ní Nàìjíríà bíi Èkó àti Abuja. Ipesi akiyesi ile ijosin naa #ChurchToo movement ro ijoba lati da “oran-an ijiya obinrin ati omodebinrin duro.” Ìpèsí àkíyèsí ilé ìjọsìn náà #ChurchToo movement rọ ìjọba láti da “ọ̀ràn-an ìjìyà obìnrin àti ọmọdébìnrin dúrò.” "Ile ijosin naa #ChurchToo sipaya idake roro amo ""ibaje asa ifipabanilopo ti o n gberu, paapaa ju lo ni agbo ijosin"" ni Naijiria." "Ilé ìjọsìn náà #ChurchToo ṣípayá ìdákẹ́ rọ́rọ́ àmọ́ ""ìbàjẹ́ àṣà ìfipábánilòpọ̀ tí ó ń gbèrú, pàápàá jù lọ ní agbo ìjọsìn"" ní Nàìjíríà." O fun awon obinrin ni anfaani lati wi ti enu won. Ó fún àwọn obìnrin ní àǹfààní láti wí ti ẹnu wọn. Bii ti #ChurchToo, ike tantan ere ife fun oju-ami eko #SexForGrades ti fe idi ilokulo agbara ti o bi iwa asemase ti ibanilajosepo ti awon obinrin ko fi tokantokan fe sita gbangba. Bíi ti #ChurchToo, ìké tantan eré ìfẹ́ fún ojú-àmì ẹ̀kọ́ #SexForGrades ti fẹ ìdí ìlòkulò agbára tí ó bí ìwà àṣemáṣe ti ìbánilájọ̀ṣepọ̀ tí àwọn obìnrin kò fi tọkàntọkàn fẹ́ síta gbangba. Nje ami ori ayelujara yii yoo se amonaa igbeja eto ti ki i se ti ori ayelujara ti yoo beere fun atunse ti yoo so ile eko giga ifasiti di ibi aabo fun awon obinrin bi? Ǹjẹ́ àmì orí ayélujára yìí yóò ṣe amọ̀nàa ìgbèjà ẹ̀tọ́ tí kì í ṣe ti orí ayélujára tí yóò béèrè fún àtúnṣe tí yóò sọ ilé ẹ̀kọ́ gíga ifásitì di ibi ààbò fún àwọn obìnrin bí? Igba ati akoko nikan ni yoo so. Ìgbà àti àkókò nìkan ni yóò sọ. Ile eko imo orin kiko kan soso ni Zanzibar ti fe di titi pa Ilé ẹ̀kọ́ ìmọ̀ orin kíkọ kan ṣoṣo ní Zanzibar ti fẹ́ di títì pa Ile-eko Orin Kiko Awon Orile-ede Dhow f'orin segbelaruge asaa Swahili Ilé-ẹ̀kọ́ Orin Kíkọ Àwọn Orílẹ̀-èdè Dhow f'orin ṣègbélárugẹ àṣàa Swahili Awon akekoo lati Ileewe Orin kiko Awon Orile-edee Dhow (DCMA) n fi qanun, fere, ilu ati duru ni Ile Awon Eso Asobode Atijo, ni Stone Town, Zanzibar, 2019. DCMA lo ni aworan. Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ láti Iléèwé Orin kíkọ Àwọn Orílẹ̀-èdèe Dhow (DCMA) ń fi qanun, fèrè, ìlù àti dùrù ní Ilé Àwọn Ẹ̀ṣọ́ Aṣọ́bodè Àtijọ́, ní Stone Town, Zanzibar, 2019. DCMA ló ni àwòrán. Egbeegberun alejo ti o n ro witiwiti wa si ilu Stone Town, Zanzibar ti o kun fun isele ateyinwa, ti tele iro orin Ileewe Orin kiko Awon Orile-edee Dhow (DCMA), ile eko orin kiko ti o n se igbelaruge ati ipamo awon asa orin erekusu naa ti o sun mo Swahili ni ebaa Omi Okun India. Ẹgbẹẹgbẹ̀rún àlejò tí ó ń rọ́ wìtìwìtì wá sí ìlú Stone Town, Zanzibar tí ó kún fún ìṣẹ̀lẹ̀ àtẹ̀yìnwá, ti tẹ̀lé ìró orin Iléèwé Orin kíkọ Àwọn Orílẹ̀-èdèe Dhow (DCMA), ilé ẹ̀kọ́ orin kíkọ tí ó ń ṣe ìgbélárugẹ àti ìpamọ́ àwọn àṣà orin erékùṣù náà tí ó sún mọ́ Swahili ní ẹ̀báa Omi Òkun India. Lati odun-un 2002, ile eko naa ti se igbelaruge ati ipamo akojopo orin Larubawa, India ati Ile Adulawo ti ko lelegbe. Láti ọdún-un 2002, ilé ẹ̀kọ́ náà ti ṣe ìgbélárugẹ àti ìpamọ́ àkójọpọ̀ orin Lárúbáwá, India àti Ilẹ̀ Adúláwọ̀ tí kò lẹ́lẹ́gbẹ́. Leyin-in odun ketadinlogun, ileewe naa ko ri owo ti o towo ninu apo ikowo si ti o si lee fa ki ileewe naa o di titi pa. Lẹ́yìn-in ọdún kẹtàdínlógún, iléèwé náà kò rí owó tí ó tówó nínú àpò ìkówó sí tí ó sì leè fa kí iléèwé náà ó di títì pa. Ninu iwe igberoyinjade ti awon alase DCMA te jade, ida aadorin ninu awon ogorin akekoo ni ko ri owo ileewe won ti o to bii $13 USD losu san. Nínú ìwé ìgbéròyìnjáde tí àwọn aláṣẹ DCMA tẹ̀ jáde, ìdá àádọ́rin nínú àwọn ọgọ́rin akẹ́kọ̀ọ́ ni kò rí owó iléèwé wọn tí ó tó bíi $13 USD lóṣù san. Pelu atileyin awon oninuure ti o ti dawo fun ileewe naa, owo ti o ku ni sisan si po to bee ti o fi je wipe, o se e se ki ilekun-un ileewe naa ti o wa ninu Ile Awon Eso Asobode Atijo. Pẹ̀lú àtìlẹ́yìn àwọn onínúure tí ó ti dáwó fún iléèwé náà, owó tí ó kù ní sísan ṣì pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ wípé, ó ṣe é ṣe kí ilẹ̀kùn-un iléèwé náà tí ó wà nínú Ilé Àwọn Ẹ̀ṣọ́ Aṣọ́bodè Àtijọ́. Laisi owo ti o towo nile lati tesiwaju, awon akekoo DCMA ati osise n foya ki iro amokanbale ti o n sun jade lati inuu gbongan olokiki ile eko yii ti o mu erekusu yii korin — lee wo okunkun. Láìsí owó tí ó tówó nílẹ̀ láti tẹ̀síwájú, àwọn akẹ́kọ̀ọ́ DCMA àti òṣìṣẹ́ ń fòyà kí ìró amọ́kànbalẹ̀ tí ó ń sun jáde láti inúu gbọ̀ngán olókìkí ilé ẹ̀kọ́ yìí tí ó mú erékùṣù yìí kọrin — leè wọ òkùnkùn. Orin ati igbelaruge asa ati ajogunba nikan ko ni ile eko naa fi gbajumo, amo o je ile fun awon odo ti o n wa ibi ti won yoo ti fi imo kun imo. Orin àti ìgbélárugẹ àṣà àti àjogúnbá nìkan kọ́ ni ilé ẹ̀kọ́ náà fi gbajúmọ̀, àmọ́ ó jẹ́ ilé fún àwọn ọ̀dọ́ tí ó ń wà ibi tí wọn yóò ti fi ìmọ̀ kún ìmọ̀. Akekoo DCMA kan n ko qanun, ohun elo orin ayedaade orin taarab. Aworan lati ileewe DCMA. Akẹ́kọ̀ọ́ DCMA kan ń kọ́ qanun, ohun èlò orin ayédáadé orin taarab. Àwòrán láti iléèwé DCMA. """A [ti bere] si i ni ri idojuko igba ti o nira"", alakooso agbaa DCMA, Alessia Lombardo so, ninuu aworan fidio DCMA kan." """A [ti bẹ̀rẹ̀] sí í ní rí ìdojúkọ ìgbà tí ó nira"", alákòóso àgbàa DCMA, Alessia Lombardo sọ, nínúu àwòrán fídíò DCMA kan." "Lati isinsinyi lo titi di osu mefa si asiko yii, a ko ri aridaju ti o rinle wipe a o lee san owo osu awon olukoni ati osisee""." "Láti ìsinsìnyí lọ títí di oṣù mẹ́fà sí àsìkò yìí, a kò rí àrídájú tí ó rinlẹ̀ wípé a ó leè san owó oṣù àwọn olùkọ́ni àti òṣìṣẹ́ẹ""." Ni akoko ti a wa yii, awon akawe-gboye oluko 19 ati awon osise miiran ti sise fun osu meta gbako lai gba owo lo sile nitori aisi owo ninuu kolo ileewe. Ní àkókò tí a wà yìí, àwọn àkàwé-gboyè olùkọ́ 19 àti àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn ti ṣiṣẹ́ fún oṣù mẹ́ta gbáko láì gba owó lọ sílé nítorí àìsí owó nínúu kóló iléèwé. Gege bi Ile Ifowopamo Agbaye se ti salaye wipe, pelu bi a ti se mo agbegbe ti ileewe naa wa fun ibi irin-ajo igbafe nitori awon etikun atijo ati ile itura olowo nlanla ti o kangun sibe, ogoro awon omo ibile lo n ba ainise lowo po o paapaa bi ise se ti gbe fuke ju ti igba kan lo. Gẹ́gẹ́ bí Ilé Ìfowópamọ́ Àgbáyé ṣe ti ṣàlàyé wípé, pẹ̀lú bí a ti ṣe mọ agbègbè tí iléèwé náà wà fún ibi ìrìn-àjò ìgbafẹ́ nítorí àwọn etíkun àtijọ́ àti ilé ìtura olówó ńláńlá tí ó kángun síbẹ̀, ọ̀gọ̀rọ̀ àwọn ọmọ ìbílẹ̀ ló ń bá àìníṣẹ́ lọ́wọ́ pò ó pàápàá bí ìṣẹ́ ṣe ti gbé fúkẹ́ ju ti ìgbà kan lọ. Fun odun metadinlogun, DCMA ti sise asekudorogbo nipa lilo orin se igbelaruge toun ipamo oro ajogunba ati asa Zanzibar. Fún ọdún mẹ́tàdínlógún, DCMA ti ṣiṣẹ́ àṣekúdórógbó nípa lílo orin ṣe ìgbélárugẹ tòun ìpamọ́ ọ̀rọ̀ àjogúnbá àti àṣà Zanzibar. Orirun awon olohun-iyo akorin taarab, Siti Binti Saad ati Fatuma Binti Baraka, ti a tun mo si Bi. Kidude, Zanzibar ni ile eyi-o-joyii orin ti o ti inuu ibasepapo asa ati ajose olodun gbogboro ti o wa laaarin awon adugbo eka Swahili. Orírun àwọn olóhùn-iyò akọrin taarab, Siti Binti Saad àti Fatuma Binti Baraka, tí a tún mọ̀ sí Bi. Kidude, Zanzibar ni ilé èyí-ò-jọ̀yìí orin tí ó ti inúu ìbàṣepapọ̀ àṣà àti àjọṣe ọlọ́dún gbọgbọrọ tí ó wà láàárín àwọn àdúgbò ẹ̀ka Swahili. Laye ode oni, akekoo lee ko orin ibile bii taarab, ngoma ati kidumbak, pelu afikun awon ohun elo ikorin bii ilu ni onirananran, qanun ati oud, gege bi alapamo — ati ongbifo — asa ati ise. Láyé òde òní, akẹ́kọ̀ọ́ leè kọ́ orin ìbílẹ̀ bíi taarab, ngoma àti kidumbak, pẹ̀lú àfikún àwọn ohun èlò ìkọrin bíi ìlù ní oníranànran, qanun àti oud, gẹ́gẹ́ bí alápamọ́ — àti òǹgbifọ̀ — àṣà àti ìṣe. Neema Surri, a ta violin ni DCMA, ti n ko bi a ti se n ta ohun eloo violin lati omodun mesan-an menu le oro ninu aworan fidio DCMA naa. Neema Surri, a ta violin ní DCMA, ti ń kọ́ bí a ti ṣe ń ta ohun èlòo violin láti ọmọdún mẹ́sàn-án mẹ́nu lé ọ̀rọ̀ nínú àwòrán fídíò DCMA náà. """Mo mo awon odomode ti o maa nifee si kiko orin sugbon won ko lee san owo imeko ti o je owo ileewe nitori wipe won kusee won ko si ni ise lowo ""." """Mo mọ àwọn ọ̀dọ́mọdé tí ó máa nífẹ̀ẹ́ sí kíkọ́ orin ṣùgbọ́n wọn kò leè san owó ìmẹ̀kọ tí ó jẹ́ owó iléèwé nítorí wípé wọn kúṣẹ̀ẹ́ wọn kò sì ní iṣẹ́ lọ́wọ́ ""." Awon akekooo DCMA n fi ohun elo ikorin olokun tin-in-rin korin ninu Ile Awon Eso Asobode Atijo, nibiti iileewe naa fi ikale si, ni Stone Town, Zanzibar, lodun-un 2019. Aworan je ti ileewee DCMA. Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ọ DCMA ń fi ohun èlò ìkọrin olókùn tín-ín-rín kọrin nínú Ilé Àwọn Ẹ̀ṣọ́ Aṣọ́bodè Àtijọ́, níbití iiléèwé náà fi ìkàlẹ̀ sí, ní Stone Town, Zanzibar, lọ́dún-un 2019. Àwòrán jẹ́ ti iléèwée DCMA. Ni ipari awon idanilekooo DCMA, ti won ti gba iwe eri ati ni opin eko olodun kan, pupo ninu awon akekooo DCMA ni o ti di agba oje ti won si i sere lori itage kari aye. Ní ìparí àwọn ìdánilẹ́kọ̀ọ́ọ DCMA, tí wọ́n ti gba ìwé ẹ̀rí àti ní òpin ẹ̀kọ́ ọlọ́dún kan, púpọ̀ nínú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ọ DCMA ni ó ti di àgbà ọ̀jẹ́ tí wọ́n sì í ṣeré lórí ìtàgé kárí ayé. "Omo bibii Zanzibar, ti o je akekooo DCMA nigba kan ri, ti o je olukoni ni ileewe kan naa bayii, Amina Omar Juma toun ti ilu mooka egbe akorin re, ti o n ""fi asa iro orin ibile "" taarab papo mo ti igbalodelonigbanlo korin, iyen ""Siti ati Egbe "", sese pada wolu lati irinajo orin kiko kan ni orile-edee South Africa." "Ọmọ bíbíi Zanzibar, tí ó jẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ọ DCMA nígbà kan rí, tí ó jẹ́ olùkọ́ni ní iléèwé kan náà báyìí, Amina Omar Juma tòun ti ìlú mọ̀ọ́ká ẹgbẹ́ akọrin rẹ̀, tí ó ń ""fi àṣà ìró orin ìbílẹ̀ "" taarab papọ̀ mọ́ ti ìgbàlódélonígbàńlò kọrin, ìyẹn ""Siti àti Ẹgbẹ́ "", ṣẹ̀ṣẹ̀ padà wọ̀lú láti ìrìnàjò orin kíkọ kan ní orílẹ̀-èdèe South Africa." "Oun, awon die ninu egbe akorin re ati apapo awon akekoo DCMA ni igba kan ri se agbejade awo orin won akoko, ""Fusing the Roots"", ni odun-un 2018, ti o mu won oi ng o onworan lara ya ni Sauti za Busara, ti i se ajodun orin kiko ti o gbarada ju lo ni Ila-oorun Ile Adulawo." "Òun, àwọn díẹ̀ nínú ẹgbẹ́ akọrin rẹ̀ àti àpapọ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ DCMA ní ìgbà kan rí ṣe àgbéjáde àwo orin wọn àkọ́kọ́, ""Fusing the Roots"", ní ọdún-un 2018, tí ó mú wọn oi ng o òǹwòran lára yá ní Sauti za Busara, tí í ṣe àjọ̀dún orin kíkọ tí ó gbàràdá jù lọ ní Ìlà-oòrùn Ilẹ̀ Adúláwọ̀." Hihayin ni orin Siti ati Egbe “Nielewe” (“Gbo mi yeke”) ati aworan orin naa, ti o se afihan-an aworan-an, ti o so itan obinrin kan ti o n ri idojuko abe-ile, ti o si n daro ara re. Itan naa jo ti Omar Juma funra re: Híhàyín ni orin Siti àti Ẹgbẹ́ “Nielewe” (“Gbó mi yéké”) àti àwòrán orin náà, tí ó ṣe àfihàn-an àwòrán-an, tí ó sọ ìtàn obìnrin kan tí ó ń rí ìdojúkọ abẹ̀-ilé, tí ó sì ń dárò ara rẹ̀. Ìtàn náà jọ ti Omar Juma fúnra rẹ̀: Ka siwaju si i: Awon akorin lobinrin Ila-Oorun Ile Adulawo korin tako aifaaye gba obinrin awon okunrin. Kà síwájú sí i: Àwọn akọrin lóbìnrin Ìlà-Oòrùn Ilẹ̀ Adúláwọ̀ kọrin tako àìfààyè gba obìnrin àwọn ọkùnrin. Itan nipa ayalo asa ati ajosepo Ìtàn nípa àyálò àṣà àti àjọṣepọ̀ O to egberun meeedogun alejo ni o ti wo ere, gba idanilekoo ati ba awon akorin lorisiirisi ojo ola ni ileewe olokiki naa ni gbolohun ri. Ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àlejò ni ó ti wo eré, gba ìdánilẹ́kọ̀ọ́ àti bá àwọn akọrin lóríṣiírísí ọjọ́ ọ̀la ní iléèwé olókìkí náà ní gbólóhùn rí. "Ileewe naa ti se ayalo ati amupapo okan-o-jokan asa ""awon orile-ede dhow"", ti o wa ni itosii Okun India ati Ogbun-un Persia." "Iléèwé náà ti ṣe àyálò àti àmúpapọ̀ ọ̀kan-ò-jọ̀kan àṣà ""àwọn orílẹ̀-èdè dhow"", tí ó wà ní ìtòsíi Òkun India àti Ọ̀gbùn-un Persia." "Agbegbee Omani Sultanate, ti o je "" ibi gboogi awon alagbara atuko ori omi ni ogorun-un Odun-un ketadinlogun si kokandinlogun seyin"", gbe aga agbara re lati Muscat si Zanzibar ni odun-un 1840." "Agbègbèe Omani Sultanate, tí ó jẹ́ "" ibi gbòógì àwọn alágbára atukọ̀ orí omi ní ọgọ́rùn-ún Ọdún-un kẹtàdínlógún sí kọkàndínlógún sẹ́yìn"", gbé àga agbára rẹ̀ láti Muscat sí Zanzibar ní ọdún-un 1840." Lati Stone Town, awon oba Omani n tukoo okowo ori omi igba naa ti o feju, titi kan kanafuru, wura, ati aso , latari awon iji lile ti n tu awon oko ibilee Larubawaa — dhows — ni orii Okun Indian, lati India si Oman titi lo de Ila-Oorun Ile Adulawo. Láti Stone Town, àwọn ọba Omani ń tukọ̀ọ okòwò orí omi ìgbà náà tí ó fẹjú, títí kan kànáfùrù, wúrà, àti aṣọ , látàrí àwọn ìjì líle tí ń tu àwọn ọkọ̀ ìbílẹ̀ẹ Lárúbáwáa — dhows — ní oríi Òkun Indian, láti India sí Oman títí lọ dé Ìlà-Oòrùn Ilẹ̀ Adúláwọ̀. Awon odo ni Zanzibar mo ririi isele ateyinwa ti o ni ohun nla ni i se fun ojo ola won, ni won fi n se adalu eyi ti a ri ninu awon orin ode oni ti won n gbe jade. Àwọn ọ̀dọ́ ní Zanzibar mọ rírìi ìṣẹ̀lẹ̀ àtẹ̀yìnwá tí ó ní ohun ńlá ní í ṣe fún ọjọ́ ọ̀la wọn, ni wọ́n fi ń ṣe àdàlù èyí tí a rí nínú àwọn orin òde òní tí wọn ń gbé jáde. "Awon akekoo ati olukoni DCMA se idasilee ""TaraJazz"" lai pe yii, eyi ti o je adalu orin ibile taarab ati orin Jazz ode oni." "Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àti olùkọ́ni DCMA ṣe ìdásílẹ̀ẹ ""TaraJazz"" láì pẹ́ yìí, èyí tí ó jẹ́ àdàlù orin ìbílẹ̀ taarab àti orin Jazz òde òní." Ata violin, Felician Mussa, omo ogun odun, ti n ko ohun elo ikorin olokun tin-in-rin naa fun odun meta ataabo; TaraJazz je okan ninu awon egbe akorin ti o awon eniyan maa n pe si ode ju lo ni awon erekusu naa, ni o wa ninu aworan ti ayaworan ti Aline Coquelle ya: Ata violin, Felician Mussa, ọmọ ogún ọdún, ti ń kọ́ ohun èlò ìkọrin olókùn tín-ín-rín náà fún ọdún mẹ́ta àtààbọ̀; TaraJazz jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹgbẹ́ akọrin tí ó àwọn ènìyàn máa ń pè sí òde jù lọ ní àwọn erékùṣù náà, ni ó wà nínú àwòrán tí ayàwòrán tí Aline Coquelle yà: Agbegbee Swahili so itan pasipaaro asa ibile ti DCMA si n tesiwaju ninuu re pelu ajosepo awon orin-in re . Agbègbèe Swahili sọ ìtàn pàṣípààrọ àṣà ìbílẹ̀ tí DCMA ṣì ń tẹ̀síwájú nínúu rẹ̀ pẹ̀lú àjọṣepọ̀ àwọn orin-in rẹ̀ . "Lodoodun, ileewe naa maa n gbalejo fun eto ti a pe ni ""Ikolu Swahili"", ti o mu agbarijopoo agba akorin lati Ile-Adulawo, Ilu Abe-akoso Larubawa, Ile Eroopu ati Ariwa Amerika pelu awon akekoo DCMA lati se orin laaarin ose kan." "Lọ́dọọdún, iléèwé náà máa ń gbàlejò fún ètò tí a pè ní ""Ìkọlù Swahili"", tí ó mú àgbárijọpọ̀ọ àgbà akọrin láti Ilẹ̀-Adúláwọ̀, Ìlú Abẹ́-àkóso Lárúbáwá, Ilẹ̀ Éróòpù àti Àríwá Amẹ́ríkà pẹ̀lú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ DCMA láti ṣe orin láàárín ọ̀sẹ̀ kan." "Ni igbeyingbeyin ""ikolu"" naa, agbarijopo tuntun naa yoo ta bi elegbe ni Sauti za Busara, ti ajosepo wonyi yoo si di ibasepo olojo pipe ti ko mo iyato ede ati asa, ti o fi han gbangba walia wipe ede kan naa ti gbogbo aye gbo ni orin." "Ní ìgbẹ̀yìngbẹ́yín ""ìkọlù"" náà, àgbárijọpọ̀ tuntun náà yóò ta bí elégbé ní Sauti za Busara, tí àjọṣepọ̀ wọ̀nyí yóò sì di ìbáṣepọ̀ ọlọ́jọ́ pípẹ́ tí kò mọ ìyàtọ̀ èdè àti àṣà, tí ó fi hàn gbangba wálíà wípé èdè kan náà tí gbogbo ayé gbọ́ ni orin." DCMA maa n se agbekale eto orin kiko ti o n se igbelaruge ebun orin kiko awon akekoo ati afihan ajosepo pelu okorin alejo han ni, Stone Town, Zanzibar, 2019. DCMA ni o ni aworan. DCMA máa ń ṣe àgbékalẹ̀ ètò orin kíkọ tí ó ń ṣe ìgbélárugẹ ẹ̀bùn orin kíkọ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àti àfihàn àjọṣepọ̀ pẹ̀lú ọ̀kọrin àlejò hàn ní, Stone Town, Zanzibar, 2019. DCMA ni ó ni àwòrán. DCMA mo riri orin gege bi ohun ti o lee ro awon eniyan lagbara ati gege bi ohun ti o le mu isokan ati irepo ba awon eniyan lai wo ti asa — o si tun n pese anfaani ise fun awon odo ti o ni ebun amo ti o n tiraka lati je. DCMA mọ rírì orin gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó leè ró àwọn ènìyàn lágbára àti gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó lè mú ìṣọ̀kan àti ìrẹ́pọ̀ bá àwọn ènìyàn láì wo ti àṣà — ó sì tún ń pèsè àǹfààní iṣẹ́ fún àwọn ọ̀dọ́ tí ó ní ẹ̀bùn àmọ́ tí ó ń tiraka láti jẹ. Fun awon akekoo 1,800 ti o ti gba idanilekoo ni DCMA, eyi nikan ni ibi ile orin ti won mo, nibi ti won ti n ko eko ti won si ti n ni alekun imo nipa ise orin kiko ati bi a se n di onkorin. Fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ 1,800 tí ó ti gba ìdánilẹ́kọọ́ ní DCMA, èyí nìkan ni ibi ilé orin tí wọ́n mọ̀, níbi tí wọ́n ti ń kọ́ ẹ̀kọ́ tí wọ́n sì ti ń ní àlékún ìmọ̀ nípa iṣẹ́ orin kíkọ àti bí a ṣe ń di òǹkọrin. "Arinrin-ajo kan lati Spain, to be DCMA wo ni ko pe yii, ko si orii TripAdvisor: ""Ni temi, isalabaapadee awon akorin ni igba ti o meet ju lo fun mi ni erekusu yii""." "Arìnrìn-àjò kan láti Spain, tó bẹ DCMA wò ní kò pẹ́ yìí, kọ sí oríi TripAdvisor: ""Ní tèmi, ìṣalábàápàdée àwọn akọrin ni ìgbà tí ó meet jù lọ fún mi ní erékùṣù yìí""." Bi eka irin-ajo afee Zanzibar se n gbero si i, DCMA nigbagbo wipe orin ni ipa kan gboogi ni i se ninu ajoyo, ipamo ati igbelaruge toun ipolongo asa, ajogunba ati isele ateyinwaa Swahili. Bí ẹ̀ka ìrìn-àjò afẹ́ẹ Zanzibar ṣe ń gbèrò sí i, DCMA nígbàgbọ́ wípé orin ní ipa kan gbòógì ní í ṣe nínú àjọyọ̀, ìpamọ́ àti ìgbélárugẹ tòun ìpolongo àṣà, àjogúnbá àti ìṣẹ̀lẹ̀ àtẹ̀yìnwáa Swahili. Zanzibar ju awon etikun ati ile itura olowo iyebiye re lo — o je ibi ti o kun fun awon eniyan olopolo ti o ni ebun ni poolo ori won latari ajosepo olojo pipe ti o mu agbegbe naa da yato gedegbe. Zanzibar ju àwọn etíkun àti ilé ìtura olówó iyebíye rẹ̀ lọ — ó jẹ́ ibi tí ó kún fún àwọn ènìyàn ọlọ́pọlọ tí ó ní ẹ̀bùn ní poolo orí wọn látàrí àjọṣepọ̀ ọlọ́jọ́ pípẹ́ tí ó mú agbègbè náà dá yàtọ̀ gedegbe. Ifiyesi Alakooso Iwe Tite: Onkowe atejade yii ti sise ofe pelu DCMA. Ìfiyèsí Alákòóso Ìwé Títẹ̀: Òǹkọ̀wé àtẹ́jádé yìí ti ṣiṣẹ́ ọ̀fẹ́ pẹ̀lú DCMA. Isode-aje si n gba emi awon eniyan ni igberiko India Ìṣọdẹ-àjẹ́ ṣì ń gba ẹ̀mí àwọn ènìyàn ní ìgbèríko India Superstition and lack of awareness behind witch-hunting in India Superstition and lack of awareness behind witch-hunting in India Ileto kan ni ebaa Jamshedpur ni Jharkhand. Aworan lati owoo Anumeha Verma Ìletò kan ní ẹ̀báa Jamshedpur ní Jharkhand. Àwòrán láti ọwọ́ọ Anumeha Verma Ni ojo 20 osu Agemo, agbajo awon eniyankeenia gba emi awon agbalagba merin kan lai da won lejo ni agbegbee Gumla ni Jharkhand, India leyin ti a fi esun-un aje kan won. Ní ọjọ́ 20 oṣù Agẹmọ, àgbájọ àwọn ènìyànkéènìà gba ẹ̀mí àwọn àgbàlagbà mẹ́rin kan láì dá wọn lẹ́jọ́ ní agbègbèe Gumla ní Jharkhand, India lẹ́yìn tí a fi ẹ̀sùn-un àjẹ́ kàn wọ́n. Gege bi ijabo iroyin, awon agbalagba wonyi se iku pa okunrin kan, ni igbimo abulee Panchayat se da won lebi. Gẹ̀gẹ̀ bí ìjábọ̀ ìròyìn, àwọn àgbàlagbà wọ̀nyí ṣe ikú pa ọkùnrin kan, ni ìgbìmọ̀ abúlée Panchayat ṣe dá wọn lẹ́bi. Won wo awon agbalagba merin wonyi jade sita ilee won, awon okunrin ti o boju si fi igi lu won titi ti emi fi bo lara won. Wọ́n wọ́ àwọn àgbàlagbà mẹ́rin wọ̀nyí jáde síta ilée wọn, àwọn ọkùnrin tí ó bòjú sì fi igi lù wọ́n títí tí ẹ̀mí fi bọ́ lára wọn. Mejo ninu awon eniyankeenia wonyi ti wa ni akolo olopaa. Mẹ́jọ nínú àwọn ènìyànkéènìà wọ̀nyí ti wà ní akóló ọlọ́pàá. Gege bi akosile olopaa ti Times of India tejade, isode-aje ni Jharkhand ti ran awon eniyan 123 sorun apapandodo ni aarin-in osu Ebibi odun-un 2016 si osu Ebibi odun-un 2019. Gẹ̀gẹ̀ bí àkọsílẹ̀ ọlọ́pàá tí Times of India tẹ̀jáde, ìṣọdẹ-àjẹ́ ní Jharkhand ti rán àwọn ènìyàn 123 sọ́run àpàpàǹdodo ní àárín-in oṣù Èbìbí ọdún-un 2016 sí oṣù Èbìbí ọdún-un 2019. Jakejado, eniyan 134 di eni ebora-n-ba-jeun latari esun-un lilo “ogungun” ni odun-un 2016, iyen gege bi Ajo Asakosile Ese Orile-ede naa se ko o sile. Jákèjádò, ènìyàn 134 di ẹni ẹbọra-ń-bá-jẹun látàrí èsùn-un lílo “ògùngùn” ní ọdún-un 2016, ìyẹn gẹ̀gẹ̀ bí Àjọ Aṣàkọsílẹ̀ Ẹ̀ṣẹ̀ Orílẹ̀-èdè náà ṣe kọ́ ọ sílẹ̀. Arun T’o N Peleke Si i Àrùn T’ó Ń Peléke Sí i """Isode-aje ko je tuntun ni Jharkhand"", Prem Chand, Oludasile ati Alaga Free Legal Aid Committee (FLAC) ni Jharkhand, so ninuu iforowanilenuwo ori ero-ibanisoro kan." """Ìṣọdẹ-àjẹ́ kò jẹ́ tuntun ní Jharkhand"", Prem Chand, Olúdásílẹ̀ àti Alága Free Legal Aid Committee (FLAC) ní Jharkhand, sọ nínúu ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò orí ẹ̀ro-ìbánisọ̀rọ̀ kan." FLAC ti n se atonaa isofin ti o tako isode-aje ni Jharkhand. FLAC ti ń ṣe àtọ́nàa ìṣòfin tí ó tako ìṣọdẹ-àjẹ́ ní Jharkhand. Ileese naa bere ise ni agbegbe yii ni odun-un 1991 nigba ti awon aladuugbo fi esun kan obinrin kan pe o lowo ninu iku omodekunrin kan. Iléeṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ní agbègbè yìí ní ọdún-un 1991 nígbà tí àwọn aládùúgbò fi ẹ̀sùn kan obìnrin kan pé ó lọ́wọ́ nínú ikú ọmọdékùnrin kan. Agbajo awon eniyankeenia kan digbo lu u, won si pa oko ati omo re okunrin. Àgbájọ àwọn ènìyànkéènìà kan dìgbò lù ú, wọ́n sì pa ọkọ àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin. Oun fi ara pa. Òún fi ara pa. Nigbati Prem Chand ati awon elegbee re se ibewo si awon elese wonyi ninuu tubu, won ba ipenija: Nígbàtí Prem Chand àti àwọn ẹlẹgbẹ́ẹ rẹ̀ ṣe ìbẹ̀wò sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ wọ̀nyí nínúu túbú, wọ́n bá ìpèníjà: Won so fun won wipe awon duro le orii esun ti won fi kan awon. Wọ́n sọ fún wọn wípé àwọn dúró lé oríi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan àwọn. Won si tun gbagbo wipe bi ejee eni ti a pe ni aje ba kan ile ogere, yoo padanu agbara eleye re. Wọ́n sì tún gbàgbọ́ wípé bí ẹ̀jẹ̀ẹ ẹni tí a pè ní àjẹ́ bá kan ilẹ̀ ọ̀gẹ́rẹ́, yóò pàdánù agbára ẹlẹyẹ rẹ̀. Prem Chand so wipe o kan apa kan ninu awon omo ilu: Prem Chand sọ wípé ó kan apá kan nínú àwọn ọmọ ìlú: Nigbagbogbo, awon obinrin ti ko lara ti o talaka ni i maa n fi ara kaasa. Nígbàgbogbo, àwọn obìnrin tí kò lárá tí ó tálákà ní í máa ń fi ara kááṣá. Awon ti o f’ara kaasa wonyi ni awon Adivasis, Harijans ati Dalits. Àwọn tí ó f’ara kááṣá wọ̀nyí ni àwọn Adivasis, Harijans àti Dalits. Ifoju iyi awon obinrin ati itase agere si ofin eto si aye iyi fun gbogbo omo eniyan. Ìfojú iyì àwọn obìnrin àti ìtasẹ̀ àgẹ̀rẹ̀ sí òfin ẹ̀tọ́ sí ayé iyì fún gbogbo ọmọ ènìyàn. Otito Awujo ati Iselu Òtítọ́ Àwùjọ àti Ìṣèlú Awon ajijangbara so wipe igbagbo-asan ti o rinle ni igberiko ni o n fa iwa palapala naa. Àwọn ajìjàngbara sọ wípé ìgbàgbọ́-asán tí ó rinlẹ̀ ní ìgbèríko ni ó ń fa ìwà pálapalà náà. Aigbeko, eto ilera ti o poju osuwon ati kolakosagbe ti o n gb’agbegbe ti iwa palapala wonyi ti gbale bi i itakun ni o fi wopo. Àìgbẹ̀kọ́, ètò ìlera tí ò pójú òṣùwọ̀n àti kòlàkòṣagbe tí ó ń gb’àgbègbè tí ìwà pálapalà wọ̀nyí ti gbalẹ̀ bí i ìtàkùn ni ó fi wọ́pọ̀. Oran wonyi ti fi han wipe aheso ni o maa fi n bere . Ọ̀ràn wọ̀nyí ti fi hàn wípé àhesọ ni ó máa fi ń bẹ̀rẹ̀ . Pelu ofin awon ipinle India ti o ka isode-aje si ohun ti o lodi sofin, awon akopa oran wonyi ri i gege bi ona idaaabo-ara-eni. Pẹ̀lú òfin àwọn ìpínlẹ̀ India tí ó ka ìṣọdẹ-àjẹ́ sí ohun tí ó lòdì sófin, àwọn akópa ọ̀ràn wọ̀nyí rí i gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ìdáààbò-ara-ẹni. Bakan naa ni won n wi awawi fun gbigba ohun ini awon obinrin, fi agbara gbesan tabi fi ipa ba obinrin lo po. Bákan náà ni wọ́n ń wí àwáwí fún gbígba ohun ìní àwọn obìnrin, fi agbára gbẹ̀san tàbí fi ipá bá obìnrin lò pọ̀. Gege bi Prem Chand se ti so: Gẹ́gẹ́ bí Prem Chand ṣe ti sọ: Ateterotele ni wipe ni kete ti o ba ti pe obinrin ni aje, o le terii re ba fun ilokulo. Àtètèròtẹ́lẹ̀ ni wípé ní kété tí o bá ti pe obìnrin ní àjẹ́, o lè tẹríi rẹ̀ ba fún ìlòkulò. Sibesibe, o se koko lati mo wipe won maa n lo iwa palapala yii fi gba tara awon obinrin, ko si kii se idi ti o n fa a pato. Síbẹ̀síbẹ̀, ó ṣe kókó láti mọ̀ wípé wọn máa ń lo ìwà pálapàla yìí fi gba tara àwọn obìnrin, kò sì kìí ṣe ìdí tí ó ń fà á pàtó. Ni ti efe, lai wi to, panchayat naa saba maa n lowo si ipeniyan ni aje paapaa bi ko ba pase ijiya t'o to. Ní ti ẹ̀fẹ̀, láì wí tó, panchayat náà sábà máa ń lọ́wọ́ sí ìpènìyàn ní àjẹ́ pàápàá bí kò bá pàṣẹ ìjìyà t'ó tọ́. Ni afikun si panchayat ti ibo yan, awon kan nbe ti won pe ara won ni panchayat ipo-isale lai ni ase kankan ti o fun won lagbara nibikibi ni orile-ede. Ní àfikùn sí panchayat tí ìbó yàn, àwọn kan ńbẹ tí wọ́n pe ara wọn ní panchayat ipò-ìsàlẹ̀ láì ní àṣẹ kankan tí ó fún wọn lágbara níbikíbi ní orílẹ̀-èdè. Awon egbe yii maa n dajo ati fi iya je eniyan ti ko si si eni ti o ka won lapa ko. Àwọn ẹgbẹ́ yìí máa ń dájọ́ àti fi ìyà jẹ ènìyàn tí kò sì sí ẹni tí ó ká wọn lápá kò. Isele kan ni agbegbee Ajmer ni Rajasthan lodun-un 2017 jabo ilowosi panchayat ipo-isale ti o s’okunfa iku obinrin ogoji odun kan. Ìṣẹ̀lẹ̀ kan ní agbègbèe Ajmer ní Rajasthan lọ́dún-un 2017 jábọ̀ ìlọ́wọ́sí panchayat ipò-ìsàlẹ̀ tí ó ṣ’okùnfa ikú obìnrin ogójì ọdún kan. Gege bi ofin, ile ejo le gbe igbese ti o tako iruu idajo bawonyi yala lati odo awon panchayat ti ibo yan ati panchayat ipo-isale. Gẹ́gẹ́ bí òfin, ilé ẹjọ́ lé gbé ìgbésẹ̀ tí ó tako irúu ìdájọ́ báwọ̀nyí yálà láti ọ̀dọ̀ àwọn panchayat tí ìbó yàn àti panchayat ipò-ìsàlẹ̀. Sibesibe, awon ti o fara kaasa o tile ni anfaani si ile-ejo ofin ki agbajo-awon-eniyankeenia o to kojuu won. Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn tí ó fara kááṣá ò tilẹ̀ ní àǹfààní sí ilé-ẹjọ́ òfin kí àgbájọ-àwọn-ènìyànkéènìà ó tó kojúu wọn. Isode-aje jakejado India Ìṣọdẹ-àjẹ́ jákèjádò India Jharkhand ti se akosile iye ese awon eniyan se ti o po ju lo ti o tan mo isode-aje amo ki i se ipinle naa nikan. Jharkhand ti ṣe àkọsílẹ̀ iye ẹṣẹ̀ àwọn ènìyán ṣẹ̀ tí ó pọ̀ jù lọ tí ó tan mọ́ ìṣọdẹ-àjẹ́ àmọ́ kì í ṣe ìpínlẹ̀ náà nìkan. Oran-an isode-aje ti wa l’akosile ni Chattisgarh, Odisha, Gujarat, West Bengal Assam, Bihar, Maharashtra ati Rajasthan pelu. Ọ̀ràn-an ìṣọdẹ-àjẹ́ ti wà l’ákọsílẹ̀ ní Chattisgarh, Odisha, Gujarat, West Bengal Assam, Bihar, Maharashtra àti Rajasthan pẹ̀lú. Nigba isele kan ni 2014, Debjani Bora, elese ehoro omo bibii orile-edee India ti fi ara kaasa ri. Nígbà ìṣẹ̀lẹ̀ kan ní 2014, Debjani Bora, ẹlẹ́sẹ̀ ehoro ọmọ bíbíi orílẹ̀-èdèe India ti fi ara kááṣá rí. Gege bi oroo Debjani, a f’esun-un igbemi eniyan pupo kan an ni abulee Cherekali ti o wa ni kilomita 180 lati Guwahati, olu-iluu India ti apaa ila-oorun. Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ọ Debjani, a f’ẹ̀sùn-un ìgbẹ̀mí ènìyàn púpọ̀ kàn án ní abúlée Cherekali tí ó wà ní kìlómità 180 láti Guwahati, olú-ìlúu India ti apáa ìlà-oòrùn. Olorii gbogan adura abule l’o daruko re ti awon ara abule si fi iya je e. Olóríi gbọ̀gán àdúrà abúlé l’ó dárúkọ rẹ̀ tí àwọn ará abúlé sí fi ìyà jẹ́ ẹ. Isele 2017 ni ipinle Rajasthan. Ìṣẹ̀lẹ̀ 2017 ní ipínlẹ̀ Rajasthan. Lara eyi ni, omobinrin ogoji odun kan Kanya Devi ri ikolu ti a si lu u pa leyin ti molebii re fi esun kan an ni agbegbee Ajmer. Lára èyí ni, ọmọbìnrin ogójì ọdún kan Kanya Devi rí ìkọlù tí a sì lù ú pa lẹ́yìn tí mọ̀lẹ́bíi rẹ̀ fi ẹ̀sùn kàn án ní agbègbèe Ajmer. Awon Eni-to-fara-kaasa ati Eni-tori-ko-yo Àwọn Ẹni-tó-fara-kááṣá àti Ẹni-tórí-kó-yọ Awon eniyan n f’esun kan awon eleye fun ise-ibi owoo won: iku eniyan tabi eranko, oda ojo, aiso jingbinni irugbin, ati beebee lo. Àwọn ènìyàn ń f’ẹ̀sùn kan àwọn ẹlẹyẹ fún iṣẹ́-ibi ọwọ́ọ wọn: ikú ènìyàn tàbí ẹranko, ọ̀dá òjò, àìso jìngbìnnì irúgbìn, àti bẹ́èbẹ́è lọ. Ikolu ti o ko lu awon obinrin wonyi (ati awon okunrin kan) roro bi eranko ehanna. Ìkọlù tí ó kọ lu àwọn obìnrin wọ̀nyí (àti àwọn ọkùnrin kan) rorò bí ẹranko ẹhànnà. Nigba miiran, awon esun naa ati ijiya ese maa wa lati odo molebii won. Nígbà mìíràn, àwọn èsùn náà àti ìjìyà ẹṣé máa wá láti ọ̀dọ̀ mọ̀lébíi wọn. Awon kan n gbe ti won si n so itan-an won ti won si n ja fun etoo won. Àwọn kan ń gbé tí wọ́n sì ń sọ ìtàn-an wọn tí wọ́n sì ń jà fún ẹ̀tọ́ọ wọn. Chutni Mahato ti Saraikela ni Jharkhand je okan lara won. Chutni Mahato ti Saraikela ní Jharkhand jẹ́ ọ̀kan lára wọn. "Awon eniyan lati agbegbe naa maa n pe e ni ""tigress""." "Àwọn ènìyàn láti agbègbè náà máa ń pè é ní ""tigress""." Won fi esun-un aje kan-an ni odun-un 1995. Lati igba naa, o ti yirapada di ajijangbara olutako ifiyaje awon obinrin pelu atileyin Ile-ise-ti-kii-se-tijoba. Wọ́n fi ẹ̀sùn-un àjẹ́ kàn-án ní ọdún-un 1995. Láti ìgbà náà, ó ti yírapadà di ajìjàǹgbara olùtako ìfìyàjẹ àwọn obìnrin pẹ̀lú àtìléyìn Ilé-iṣẹ́-tí-kìí-ṣe-tìjọba. Chutni so bi aisi atileyin to kesejari se mu u nira lati ja tako iwa palapala yii. Chutni sọ bí àìsí àtìlẹ́yìn tó késejárí ṣe mú u nira láti jà tako ìwà pálapàla yìí. Ibajepe atileyin to to wa lati owo awon oniseoba ati ijoba fun ise ti a n se nibi. Ìbájẹ́pé àtìlẹ́yìn tó tó wá láti ọwọ́ àwọn oníṣẹọba àti ìjọba fún iṣẹ́ tí à ń ṣe níbí. Sibesibe, mo ti jiya nitori iwa palapala yii. Síbẹ̀síbẹ̀, mo ti jìyà nítorí ìwà pálapàla yìí. Bi eniyan ba to mi wa fun iranlowo, mo maa duro ti won gbagbagba, o so ninuu iforowanilenuwo ori ero-ibanisoro kan. Bí ènìyàn bá tọ̀ mí wá fún ìrànlọ́wọ́, mo máa dúró tì wọ́n gbágbágbá, ó sọ nínúu ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò orí ẹ̀ro-ìbánisọ̀rọ̀ kan. Dida Ohun Gbogboogbo Si i Dídá Ohùn Gbogboògbò Sí i Awon eni-tori-ko-yo ati ajafetoo-eniyan ro wipe awon eniyan gbogbo ko ti ifopin si isode-aje leyin. Àwọn ẹni-tórí-kó-yọ àti ajàfẹ́tọ̀ọ́-ènìyàn rò wípé àwọn ènìyàn gbogbo kò ti ìfòpin sí ìṣọdẹ-àjẹ́ lẹ́yìn. Awon ajafetoo-eniyan ti a foro wa lenu wo lori isele yii je ki a mo wipe abuku iranwo ijoba ati awon onimo ni ko mu iwa aibojumu naa sira kase nle. Àwọn ajàfẹ́tọ̀ọ́-ènìyàn tí a fọ̀rọ̀ wá lẹ́nu wò lórí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí jẹ́ kí á mọ̀ wípé àbùkù ìrànwọ́ ìjọba àti àwọn onímọ̀ ni kò mú ìwà àìbójúmu náà ṣíra kásẹ̀ ńlẹ̀. Ohun ti o dara ju lo ni wipe awon ti o n tako iwa buruku yii gbagbo wipe ayipada le de. Ohun tí ó dára jù lọ ni wípé àwọn tí ó ń tako ìwà burúkú yìí gbàgbọ́ wípé àyípadà lè dé. Ni oroo Prem Chand: Ní ọ̀rọ̀ọ Prem Chand: Akitiyan lati f’opin si isode-aje le tele ilana ti ijoba fi polongo eto mimoo-ko-ati-mimoo-ka. Akitiyan láti f’òpin sí ìṣọdẹ-àjẹ́ lè tẹ̀lé ìlànà tí ìjọba fi polongo ètò mímọ̀ọ-kọ-àti-mímọ̀ọ-kà. Bakan naa, awon onimo ni lati f’owo si i k’awon eniyan o ba f’ohun si i. Bákan náà, àwọn onímọ̀ ní láti f’ọwọ́ sí i k’áwọn ènìyàn ó ba f’ohùn sí i. B. Vijay Murty, akoroyin ati olugbe Jharkhand ni o gboro sile lenu awon ti oro kan. B. Vijay Murty, akọ̀ròyìn àti olùgbé Jharkhand ni ó gbọ̀rọ̀ sílẹ̀ lẹ́nu àwọn tí ọ̀rọ́ kàn. Itoju awon erin alailobiii Myanmar Ìtọ́jú àwọn erin aláìlóbìíi Myanmar Osise ago kan n ro Ayeyar Maung ni ounje. / Aung Kyaw Htet / The Irrawaddy Òṣìṣẹ́ àgọ̀ kan ń rọ Ayeyar Maung ní oúnjẹ. / Aung Kyaw Htet / The Irrawaddy Apileko je ti Aung Kyaw Htet ti o ko fun The Irrawaddy, ileese oniroyinin ori ayelujara ni Myanmar, ti Ohun Agbaye se atuntejadee re ni ibamu pelu adehun ibasepo ti o wa laaarin won. Àpilẹ̀kọ jẹ́ ti Aung Kyaw Htet tí ó kọ́ fún The Irrawaddy, iléeṣẹ́ oníròyìnin orí ayélujára ní Myanmar, tí Ohùn Àgbáyé ṣe àtúntẹ̀jádée rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú àdéhùn ìbáṣepọ̀ tí ó wà láàárín wọn. Nigba ti awon osise alaboojuto igbo ri i ninu iju ti o sun mo Eti-omi Irrawaddy, osu meta ni Ayeyar Sein nigba naa. Nígbà tí àwọn òṣìṣẹ́ alábòójútó igbó rí i nínú ijù tí ó sún mọ́ Etí-omi Irrawaddy, oṣù mẹ́ta ni Ayeyar Sein nígbà náà. Esee re kan ti lu pampe awon ajerangbepa. Ẹsẹ̀ẹ rẹ̀ kan ti lu páḿpẹ́ àwọn ajérangbépa. Awon onigedu ijoba lo doola emii re, won si gbe e lo si ago erin kan ni Agbegbee Bago fun itoju. Àwọn onígẹdú ìjọba ló dóòlà ẹ̀míi rẹ̀, wọ́n sì gbé e lọ sí àgọ́ erin kan ní Agbègbèe Bago fún ìtọ́jú. Ohun ni odo erin kejo ti yoo ri aabo ni Wingabaw, ibi aabo fun awon erin Myanmar ti ko lobii. Òhun ni ọ̀dọ̀ erin kẹjọ tí yóò rí ààbò ní Wingabaw, ibi ààbò fún àwọn erin Myanmar tí kò lóbìí. Odo erin miiran, Ayeyar Maung naa ri nnkan. Ọ̀dọ́ erin mìíràn, Ayeyar Maung náà rí nǹkan. Ki o to di eroo ago naa, erin osu mefa naa ti lu okun. Kí ó tó di èròo àgọ́ náà, erin oṣù mẹ́fà náà ti lu okùn. O si ha si aarin awon okuta ninu iju kan naa ti a ti ri Ayeyar Sein, awon owoo re to ku fi i sile lo. Ó sì há sí àárín àwọn òkúta nínú ijù kan náà tí a ti rí Ayeyar Sein, àwọn ọ̀wọ́ọ rẹ̀ tó kù fi í sílẹ̀ lọ. Sibe, awon alaboojuto iju tu u sile, o si di araa ago naa ni odun to koja. Síbẹ̀, àwọn alábòójútó ijù tú u sílẹ̀, ó sì di aráa àgọ́ náà ní ọdún tó kọjá. Awon mejeeji ni erin alailobiii ti o kere ju lo ninu ago naa; odun merin ni erin ti o dagba ju gba lowoo won. Àwọn méjèèjì ni erin aláìlóbìíi tí ó kéré jù lọ nínú àgọ́ náà; ọdún mẹ́rin ni erin tí ó dàgbà jù gbà lọ́wọ́ọ wọn. Gbogbo won ni o ni itan kan tabi omiran ti o je mo ijiya lati owo eda omo eniyan adarihununrun. Gbogbo wọn ni ó ní ìtàn kan tàbí òmíràn tí ó jẹ mọ́ ìjìyà láti ọwọ́ ẹ̀dá ọmọ ènìyàn adáríhununrun. Awon kan ko ri owoo won ti won jo n je mo, awon miii di alailobiii leyin ti awon ti o n pa eran ninu igbe nipakupa pa obii won. Àwọn kan kò rí ọ̀wọ́ọ wọn tí wọ́n jọ ń jẹ̀ mọ́, àwọn mìíì di aláìlóbìíi lẹ́yìn tí àwọn tí ó ń pa ẹran nínú ìgbẹ́ nípakúpa pa òbíi wọn. Ni ago ti o wa ni Wingabaw, awon odo erin ti ko ni obi naa gbekele ounje omo ikoko ti awon alaboojuto iju n pese fun won lojoojumo. Ní àgọ́ tí ó wà ní Wingabaw, àwọn ọ̀dọ́ erin tí kò ní òbí náà gbẹ́kẹ̀lé oúnjẹ ọmọ ìkókó tí àwọn alábòójútó ijù ń pèsè fún wọn lójoojúmọ́. Aaye gba won lati je ninu iju ni owuro, won yoo si we ninu odo kekere kan nitosi ki won o to pada si ago. Ààyé gbà wọ́n láti jẹ̀ nínú ijù ní òwúrò, wọn yóò sì wẹ̀ nínú odò kékeré kan nítòsí kí wọn ó tó padà sí àgọ́. Lowo lowo bayii, Myanmar yoo feree ni to erin egan 1,500. Lọ́wọ́ lọ́wọ́ báyìí, Myanmar yóò fẹ́rẹ̀ẹ́ ní tó erin ẹgàn 1,500. Amo o je ohun ti o bani lokan je nitori pe awon ti o n da emii won legbodo ko je ki won o gbe aye, erin kan lose kan ni won n pa. Àmọ́ ó jẹ́ ohun tí ó bani lọ́kàn jẹ́ nítorí pé àwọn tí ó ń dá ẹ̀míi wọn légbodò kò jẹ́ kí wọn ó gbé ayé, erin kan lọ́sẹ̀ kan ni wọ́n ń pa. Iyun Tobago ti o ti n pawoda fi han gbagadagbagada pe ko si ona miiran ju kikoju ayipada oju-ojo Iyùn Tobago tí ó ti ń pàwọ̀dà fi hàn gbàgàdàgbagada pé kò sí ọ̀nà mìíràn ju kíkojú àyípadà ojú-ọjọ́ "The island's reefs are on ""Bleaching Alert Level One""" "The island's reefs are on ""Bleaching Alert Level One""" Iyun bi iwo agbonrin ti o ti pawoda. Aworan lati owoo Matt Kieffer, CC BY-SA 2.0. Iyùn bí ìwo àgbọ̀nrín tí ó ti pàwọ̀dà. Àworán láti ọwọ́ọ Matt Kieffer, CC BY-SA 2.0. Iyun-un abe okuta okun je ohun ti a o lee fowo ro seyin ninu awon amusoro ti o n mu oro Aje Tobago ati awon ayika erekusu naa gbooro. Iyùn-un abẹ́ òkúta òkun jẹ́ ohun tí a ò leè fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nínú àwọn àmúṣọrọ̀ tí ó ń mú ọrọ̀ Ajé Tobago àti àwọn àyíká erékùṣù náà gbòòrò. Ibugbe okan-ojokan eya eda inu omi (ati ibi eja pipa fun awon apeja ibile), ti o si tun n da aabo bo ebute, eyi ti ko mu ki awon iji lile eti omi o po koja ala ni a n so. Ibùgbé ọ̀kan-òjọ̀kan ẹ̀yà ẹ̀dá inú omi (àti ibi ẹja pípa fún àwọn apẹja ìbílẹ̀), tí ó sì tún ń dá ààbò bo èbúté, èyí tí kò mú kí àwọn ìjì líle etí omi ó pọ̀ kọjá àlà ni à ń sọ. Okuta inu okun Buccoo Reef ti o gbajumo bi isana eleta ti awon arinrin-ajo afe maa n wo tuurutu nibe naa ko gbeyin. Òkúta inú òkun Buccoo Reef tí o gbajúmọ̀ bí ìṣáná ẹlẹ́ta tí àwọn arìnrìn-àjò afẹ́ máa ń wọ́ tùùrùtù níbẹ̀ náà kò gbẹ́yìn. "Amo leyin atejade kan si ile iroyin ti Ajo ti o n sakoso Omi orile ede naa (IMA) te jade ni ojo 22, osu Ogun odun-un 2019, eyi ti o kilo wipe – iwadiii National Oceanic and Atmospheric Administration (NOAA) Coral Reef Watch so wipe — iyun abe okuta okun Tobago ti bo si abe iso lati se ofintoto ""Ikede Ipawodaa Ipele Ikini"", gbogbo oju lo n wo erekusu naa." "Àmọ́ lẹ́yìn àtẹ̀jáde kan sí ilé ìròyìn tí Àjọ tí ó ń ṣàkóso Omi orílẹ̀ èdè náà (IMA) tẹ̀ jáde ní ọjọ́ 22, oṣù Ògún ọdún-un 2019, èyí tí ó kìlọ̀ wípé – ìwádìíi National Oceanic and Atmospheric Administration (NOAA) Coral Reef Watch sọ wípé — iyùn abẹ́ òkúta òkun Tobago ti bọ́ sì abẹ́ ìṣọ́ láti ṣe òfíntótó ""Ìkéde Ìpàwọ̀dàa Ìpele Ìkíni"", gbogbo ojú ló ń wo erékùṣù náà." A i i se e mo, ipawoda naa le fo fere si ipele keji laaarin ose die, ti yoo si fa akoba fun iwalaaye awon iyun wonyi, awon eda inu omi miiran ati awon olugbe erekusu naa. A ì í ṣe é mọ̀, ìpàwọ̀dà náà lè fò fẹ̀rẹ̀ sí ìpele kejì láàárín ọ̀sẹ̀ díẹ̀, tí yóò sì fa àkóbá fún ìwàláàyè àwọn iyùn wọ̀nyí, àwọn ẹ̀dá inú omi mìíràn àti àwọn olùgbé erékùṣù náà. Ki ni ohun ti n pawoda ni pato? Kí ni ohun tí ń pàwọ̀dà ní pàtó? Alabaagbe ati alajose iyun ni awon ewe inu omi ti o maa n ba a ko ohun asaraloore pamo ati da eeri ara nu. Alábàágbé àti alájọṣe iyùn ni àwọn ewé inú omi tí ó máa ń bá a kó ohun aṣaralóore pamọ́ àti da èérí ara nù. Ewe wonyi yoo si fun iyun ni okun ti o nilo fun idagbasoke, amo ayipada igbona inu omi n di ajosepo yii lowo. Ewé wọ̀nyí yóò sì fún iyùn ní okun tí ó nílò fún ìdàgbàsókè, àmọ́ àyípadà ìgbóná inú omi ń dí àjọṣepọ̀ yìí lọ́wọ́. Bi omi ba gbona ju bi o se ye lo (tabi bi o ba tutu ju) awon iyun yoo le ewe omi — ti yoo si padanu owo ti o n fi ounje nu un. Bí omi bá gbóná ju bí ó ṣe yẹ lọ (tàbí bí ó bá tutù jù) àwọn iyùn yóò lé ewé omi — tí yóò sì pàdánù ọwọ́ tí ó ń fi oúnjẹ nù ún. Aseyinwa aseyinbo, ebi yoo pa iyun ku; awo ara ti yoo yi pada ni ami ti a o fi mo, ipawoda lati awo olomi-oka ati eweko si funfun egungun. Àṣèyìnwá àṣẹ̀yìnbọ̀, ebi yóò pa iyùn kú; àwọ̀ ara tí yóò yí padà ni àmì tí a ó fi mọ̀, ìpàwọ̀dà láti àwọ̀ olómi-ọkà àti ewéko sí funfun egungun. Ikede Ipawoda Ipele Kiini n kede wipe bi a ko ba wa nnkan se si i, awon iyun naa yoo bere si i pawoda. Ìkéde Ìpàwọ̀dà Ìpele Kìíní ń kéde wípé bí a kò bá wá nǹkan ṣe sí i, àwọn iyùn náà yóò bẹ̀rẹ̀ sí í pàwọ̀dà. IMA dabaa wipe ki awon onimo iseda ati omo ilu o maa so awon eda inu omi naa fun awon ami ipawoda ni aarin-in ose mesan-an si mejila ti o n bo. IMA dábàá wípé kí àwọn onímọ̀ ìṣẹ̀dá àti ọmọ ìlú ó máa ṣọ́ àwọn ẹ̀dá inú omi náà fún àwọn àmì ìpàwọ̀dà ní àárín-in ọ̀sẹ̀ mẹ́sàn-án sí méjìlá tí ó ń bọ̀. Ipele ipawoda keji yoo je itoka si ipawoda iyun kari aye ati iku iyun. Ìpele ìpàwọ̀dà kejì yóò jẹ́ ìtọ́ka sí ìpàwọ̀dà iyùn kárí ayé àti ikú iyùn. Ki lo fa sababi? Kí ló fa sábàbí? Gege bi onimo ayika ibile Anjani Ganase ti se salaye, odada ti o da ipawoda iyun-un Tobago ni iwon igbona omi ti o re oke — ti i se arapa ayipada oju-ojo. Gẹ́gẹ́ bí onímọ̀ àyíká ìbílẹ̀ Anjani Ganase ti ṣe ṣàlàyé, ọ̀dádá tí ó dá ìpàwọ̀dà iyùn-un Tobago ni ìwọ̀n ìgbóná omi tí ó re òkè — tí í ṣe arapa àyípadà ojú-ọjọ́. Ninu imeeli, Ganase salaye wipe okun maa n fa eyi ti o po ninu ooru inu afefe mu, ti o si n fa ki omi — paapaa ju lo awon ibu omi jinjin gbungbunrungbun bii Osaa Caribbean — o gbona janjan. Nínú ímeèlì, Ganase ṣàlàyé wípé òkun máa ń fa èyí tí ó pọ̀ nínú ooru inú afẹ́fẹ́ mu, tí ó sì ń fa kí omi — pàápàá jù lọ àwọn ibú omi jínjìn gbungbunrungbun bíi Ọ̀sàa Caribbean — ó gbóná janjan. Koda, iso olose mejilaa NOAA Tobago tan pinpin ayipada yii de iyun Lesser Antilles. Kódà, ìṣọ́ ọlọ́sẹ̀ méjìláa NOAA Tobago tan pinpin àyípadà yìí dé iyùn Lesser Antilles. Awon okuta ti o wa ni agbegbe naa, bii Greater Antilles ati Cuba, ti wa ni Ipele Keji Ikede Ipawoda: Àwọn òkúta tí ó wà ní agbègbè náà, bíi Greater Antilles àti Cuba, ti wà ní Ìpele Kejì Ìkéde Ìpàwọ̀dà: Ki ni arapa re? Kí ni arapa rẹ̀? Ohun ti o lewu ni ipawodaa iyun. Ohun tí ó léwu ni ìpàwọ̀dàa iyùn. Nitori wipe iyun maa fun eja ni ounje, oun naa ni o duro gege bi ile fun awon eja ati fun awon omo eja ti koi tii le we ninu alagbalugbu omi, nitori idi eyi, bi a ba padanuu won, eja naa yoo ba won lo. Nítorí wípé iyùn máa fún ẹja ní oúnjẹ, òun náà ni ó dúró gẹ́gẹ́ bí ilé fún àwọn ẹja àti fún àwọn ọmọ ẹja tí kòì tíì lè wẹ̀ nínú alagbalúgbú omi, nítorí ìdí èyí, bí a bá pàdánùu wọn, ẹja náà yóò bá wọn lọ. Bi eja ba si tan lomi, ise bo lowo awon apeja niyen. Bí ẹjá bá sì tán lómi, iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ àwọn apẹja nìyẹn. Tobago gbekele ileese irinajo afe ibile; ida 40 awon arinrin-ajo afe erekusu yii ni o maa n wa lati wo awon iyun omi wonyi. Tobago gbẹ́kẹ̀lé iléeṣẹ́ ìrìnàjò afẹ́ ìbílẹ̀; ìdá 40 àwọn arìnrìn-àjò afẹ́ erékùṣù yìí ni ó máa ń wá láti wo àwọn iyùn omi wọ̀nyí. Bi ipawoda ba tesiwaju, awon eniyan ko ni ri okuta iyun, owo dollar irinajo afe yoo fidi jale, ti yoo si ko ba awon ileese agbalejo bii: ile itura, ile ijeun, ise igbokegbodo oko ati ile ise asakoso irinajo. Bí ìpàwọ̀dà bá tẹ̀síwájú, àwọn ènìyàn kò ní rí òkúta iyùn, owó dollar ìrìnàjò afẹ́ yóò fìdí jálẹ̀, tí yóò sì kó bá àwọn iléeṣẹ́ agbàlejò bíi: ilé ìtura, ilé ìjẹun, iṣẹ́ ìgbòkègbodò ọkọ̀ àti ilé iṣẹ́ aṣàkóso ìrìnàjò. Bi iji lile ba n po si i latari segesege oju-ojo, okuta iyun-un nise pataki ni sise lati fa agbara awon igbe omi ati iduro gege bi alarina laaarin okun ati eti okun — amo igbona agbanla aye n di i lowo lati sisee re. Bí ìjì líle bá ń pọ̀ sí i látàrí ségesège ojú-ọjọ́, òkúta iyùn-ún níṣẹ́ pàtàkì ní ṣíṣe láti fa agbára àwọn ìgbé omi àti ìdúró gẹ́gẹ́ bí alárinà láàárín òkun àti etí òkun — àmọ́ ìgbóná àgbáńlá ayé ń dí i lọ́wọ́ láti ṣiṣẹ́ẹ rẹ̀. Iwadii ti fi idii re mule wipe okuta iyun ni n gba ida 90 etido Tobago sile-lowo ogbara ti igbe omi n fa. Ìwádìí ti fi ìdíi rẹ̀ múlẹ̀ wípé òkúta iyùn ní ń gba ìdá 90 etídò Tobago sílẹ̀-lọ́wọ́ ọ̀gbàrá tí ìgbé omi ń fà. Ni ibi eto Ayajo Odun Okuta iyun ni Ifasiti West Indies ni odun-un 2018, Ojogbon John Agard so wipe ise yii yoo po si i bi iji se n po si i ati bi osa se n kun soke. Ní ibi ètò Àyájọ́ Ọdún Òkúta iyùn ní Ifásitì West Indies ní ọdún-un 2018, Ọ̀jọ̀gbọ́n John Agard sọ wípé iṣẹ́ yìí yóò pọ̀ sí i bí ìjì ṣe ń pọ̀ sí i àti bí ọ̀sà ṣe ń kún sókè. Ki ni a le se lati dekun re? Kí ni a lè ṣe láti dẹ́kun rẹ̀? Ganase ni pe aimojuto omi wonyi bi o ti to lo fa eja pipa koja ala ati ibaje ayika ni eku eda ti o fa ipawoda iyun-un Tobago. Ganase ní pé àìmójútò omi wọ̀nyí bí ó ti tọ́ ló fa ẹja pípa kọjá àlà àti ìbàjẹ́ àyíká ni eku ẹdá tí ó fa ìpàwọ̀dà iyùn-un Tobago. Bi o ba n ba a lo bee, titempele mo isakoso ati aabo okuta iyun nikan lo le mu ki won o pada bo sipo ati dagba: Bí ó bá ń bá a lọ bẹ́ẹ̀, títẹmpẹlẹ mọ́ ìṣàkóso àti ààbò òkúta iyùn nìkan ló lè mú kí wọn ó padà bọ̀ sípò àti dàgbà: O ye ki okuta iyun o di ohun ti yoo pamo fun awon ero, ki ise irapada o fese mule ki owo eja onilera ati omi ti o dara ti yoo mu ki iyun o dagba o pada. Ó yẹ kí òkúta iyùn ó di ohun tí yóò pamọ́ fún àwọn èrò, kí iṣẹ́ ìràpadà ó fẹsẹ̀ múlẹ̀ kí ọ̀wọ́ ẹja onílera àti omi tí ó dára tí yóò mú kí iyùn ó dàgbà ó padà. O so siwaju si i: Ó sọ síwájú sí i: Ojuse onikaluku ni lati din eefin inu ayika ku, bee naa ni omo araye ni eto lati beere fun ise ilosiwaju lati odo awon ijoba ki won o pese ohun ti yoo mu nnkan sun peli, ohun elo ati idanilekoo nipa ipamo ati ifikora. Ojúṣe oníkálukú ni láti dín èéfín inú àyíká kù, bẹ́ẹ̀ náà ni ọmọ aráyé ní ẹ̀tọ́ láti béèrè fún iṣẹ́ ìlọsíwájú láti ọ̀dọ̀ àwọn ìjọba kí wọn ó pèsè ohun tí yóò mú nǹkan sún pẹ́lí, ohun èlò àti ìdánilẹ́kọ̀ọ́ nípa ìpamọ́ àti ìfikọ́ra. O pon dandan ki a sakoso ati ipamo ohun alumooni wa, boya ijoba ni o tabi ileese nlanla ti o n lo awon alumooni wonyi. Ó pọn dandan kí a ṣàkóso àti ìpamọ́ ohun àlùmọ́ọ́nì wa, bóyá ìjọba ni o tàbí iléeṣẹ́ ńláńlá tí ó ń lo àwọn àlùmọ́ọ́nì wọ̀nyí. O ti di sise fun ijoba ti erekusu agbegbe kan naa lati kede nipa ojuse agbaye ni ti igbogunti isoro ayipada oju-ojo. Ó ti di ṣíṣe fún ìjọba ti erékùṣù agbègbè kan náà láti kéde nípa ojúṣe àgbáyé ní ti ìgbógunti ìṣòro àyípadà ojú-ọjọ́. Ni ojo 11, osu Owewe, odun-un 2019, Oludari Barbadia Mia Mottley menu le isoro yii ni olu ileese Ajo Agbaye ni Geneva, o n ro awon orile-ede nla ki won o gbe igbese akin lati kojuu ayipada oju-ojo. Ní ọjọ́ 11, oṣù Ọ̀wẹwẹ̀, ọdún-un 2019, Olùdarí Barbadia Mia Mottley mẹ́nu lé ìṣòro yìí ní olú iléeṣẹ́ Àjọ Àgbáyé ní Geneva, ó ń rọ àwọn orílẹ̀-èdè ńlá kí wọn ó gbé ìgbésẹ̀ akin láti kọjúu àyípadà ojú-ọjọ́. "O so wipe, erekusu Caribbean, ""ko ni asiko ti o po nitori [a] n sise iye lowo ""." "Ó sọ wípé, erékùṣù Caribbean, ""kò ní àsìkò tí ó pọ̀ nítorí [à] ń ṣiṣẹ́ ìyè lọ́wọ́ ""." Ganase gba wipe oran naa gba atunse ni kiakia. Ganase gbà wípé ọ̀ràn náà gba àtúnṣe ní kíákíá. "Ohun gbogbo ti o ba gba lati gba oromodie oju-ojo lowo ayipada ati idekun ipawoda iyun ni ki a fi fun un, o so wipe, paapaa ju lo ""ise n be"" fun awon ti o n se oselu:" "Ohun gbogbo tí ó bá gbà láti gba òròmọdìẹ ojú-ọjọ́ lọ́wọ́ àyípadà àti ìdẹ́kun ìpàwọ̀dà iyùn ni kí á fi fún un, ó sọ wípé, pàápàá jù lọ ""iṣẹ́ ń bẹ"" fún àwọn tí ó ń ṣe òṣèlú:" Bi a se n wo o, ko ni je ohun ti o rorun, amo ona abayo miiran n be. Bí a ṣe ń wò ó, kò ní jẹ́ ohun tí ó rọrùn, àmọ́ ọ̀nà àbáyọ mìíràn ń bẹ. Irin-ajo: Ipekun ere-idaraya fun Omo-adulawo Ìrìn-àjò: Ìpẹ̀kun eré-ìdárayá fún Ọmọ-adúláwọ̀ Isebeere fun iwe irinna da bii ebo fun awon oosa Ìṣèbéèrè fún ìwé ìrìnnà dà bíi ẹbọ fún àwọn òòsà Aworan olojiji lati owoo Natasha Sinegina (CC BY-SA 4.0). Àwòràn olójìjì láti ọwọ́ọ Natasha Sinegina (CC BY-SA 4.0). Aworan oju-ewe iwe irinna latowoo Jon Evans (CC BY 2.0). Àwòrán ojú-ewé ìwé ìrìnnà látọwọ́ọ Jon Evans (CC BY 2.0). Atunto aworan-an latowoo Georgia Popplewell. Àtúntò àwòrán-an látọwọ́ọ Georgia Popplewell. Ni odun-un 2019, a ko fun Temitayo Olofinlua, onkowe ati omowe omobibi orile-edee Naijiria, ni iwe irinna lati lo si Apero Lori Eko Ile Adulawo ni Eroopu ti o waye ni Edinburgh, UK. Ní ọdún-un 2019, a kò fún Tèmítáyọ̀ Ọlọ́finlúà, òǹkọ̀wé àti ọ̀mọ̀wé ọmọbíbí orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, ní ìwé ìrìnnà láti lọ sí Àpérò Lórí Ẹ̀kọ́ Ilẹ̀ Adúláwọ̀ ní Éróòpù tí ó wáyé ní Edinburgh, UK. Igbimo Agba Sorile-ede Britain ni Naijiria so wipe awon ko “si aridaju” ti o te awon lorun wipe Olofinlua yoo fi UK sile leyin ti eto ba pari. Ìgbìmọ̀ Àgbà Sórílẹ̀-èdè Britain ní Nàìjíríà sọ wípé àwọn kò “sí àrídájú” tí ó tẹ̀ àwọn lọ́rùn wípé Ọlọ́finlúà yóò fi UK sílẹ̀ lẹ́yìn tí ètó bá parí. Ile-ise UK Nile pe aifuni ni iwe irinna naa pada. Olofinlua lo, o bo pada si Naijiria, ko b'omo je. Ilé-iṣẹ́ UK Nílé pe àìfúni ní ìwé ìrìnnà náà padà. Ọlọ́finlúà lọ, ó bọ̀ padà sí Nàìjíríà, kò b'ọmọ jẹ́. Awon miiran ko ri anfaani bayii. Ninuu osuu Igbe odun-un 2019, awon alase iwe irinna UK ko je ki omo adulawo 24 ninuu awon onimo ijinle 25 ti o n sise lorii arun akoran o darapo mo awon akegbee won nibi apero London School of Economics Africa Summit. Àwọn mìíràn kò rí àǹfààní báyìí. Nínúu oṣùu Igbe ọdún-un 2019, àwọn aláṣẹ ìwé ìrìnnà UK kò jẹ́ kí ọmọ adúláwọ̀ 24 nínúu àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ 25 tí ó ń ṣiṣẹ́ lóríi àrùn àkóràn ó darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́ẹ wọn níbi àpérò London School of Economics Africa Summit. Awon onimo ti won lakaki ti won si ni imo pipe lati kojuu arun ti o n ba ile adulawo finra, ko ri iwe irinna ti yoo mu won kopa ninuu apero nipa “ipenija iponmisile-de-ongbe ajakale arun” gba. Àwọn onímọ̀ tí wọ́n lakakì tí wọ́n sì ní ìmọ̀ pípé láti kojúu àrùn tí ó ń bá ilẹ̀ adúláwọ̀ fínra, kò rí ìwé ìrìnnà tí yóò mú wọn kópa nínúu àpérò nípa “ìpèníjà ìpọnmisílẹ̀-de-oǹgbẹ àjàkálẹ̀ àrùn” gbà. ‘O ko ni pada!’ ‘O kò ní padà!’ Kekere nikan ko ni idojuti ti aifayegba Omo-adulawo lati wo awon illu kan n mu dani — bee naa ni o n toka si igbekale eleyameya ti o n se atilleyin fun igbagbo wipe awon akosemose Omo-adulawo ati alatinuda o se e fi okan tan lo titi ni ti ibowo fun ofin de. Kékeré nìkan kọ́ ni ìdójútì tí àìfàyègba Ọmọ-adúláwọ̀ láti wọ àwọn illú kan ń mú dání — bẹ́ẹ̀ náà ni ó ń tọ́ka sí ìgbékalẹ̀ ẹlẹ́yàmẹyà tí ó ń ṣe àtillẹ́yìn fún ìgbàgbọ́ wípé àwọn akọ́ṣẹ́mọṣẹ Ọmọ-adúláwọ̀ àti alátinúdá ò ṣe é fi ọkàn tàn lọ títí ni ti ìbọ̀wọ̀ fún òfín dé. "Abala 13 ti Ikede Kariaye Fun ETo Omoniyan wipe ""Eni kookan lo ni eto lati kuro lorile‐ede yoowu ko je, to fi mo orile‐ede tire, ki o si tun pada si orile‐ede tire nigba to ba wu u""." "Abala 13 ti Ìkéde Káríayé Fún È̩Tó̩ O̩mo̩nìyàn wípé ""E̩nì kọ̀ọ̀kan ló ní ẹ̀tọ́ láti kúrò lórìlẹ̀‐èdè yòówù kó jẹ́, tó fi mọ́ orílẹ̀‐èdè tirẹ̀, kí ó sì tún padà sí orílẹ̀‐èdè tirẹ̀ nígbà tó bá wù ú""." Otito ibe, sibesibe, bi ko ba si iwe-ase-omoilu-fun-irinna ati iwe irinna ti o wulo, ko rorun lati lo. Òtítọ́ ibẹ̀, síbẹ̀síbẹ̀, bí kò bá sí ìwé-àṣẹ-ọmọìlú-fún-ìrìnnà àti ìwé ìrìnnà tí ó wúlò, kò rọrùn láti lò. Irorun ni ibeere fun iwe irinna ni awon orile-ede kan, ko si ri bee ni orile-ede miiran. Ìrọ̀rùn ni ìbéèrè fún ìwé ìrìnnà ní àwọn orílẹ̀-èdè kan, kò sì rí bẹ́ẹ̀ ní orílẹ̀-èdè mìíràn. Ni orii 2019 Henley Passport Index, Japan ati Singapore ni orile-ede ti o rorun fun ju lo lati riwee gba wolu orisiirisi, nigbati Angola, Egypt ati Haiti wa ni isale. Ní oríi 2019 Henley Passport Index, Japan àti Singapore ni orílẹ̀-èdè tí ó rọrùn fún jù lọ láti ríwèé gbà wọ̀lú oríṣìíríṣi, nígbàtí Angola, Egypt àti Haiti wà ní ìsàlẹ̀. Ka siwaju si i: ‘Ko Si Apopo Iwe Irinna': Awon irawo olorin orile-ede Tanzania o ri iwe irinna wo ajodun orin ni US Kà síwájú sí i: ‘Kò Sí Àpòpọ̀ Ìwé Ìrìnnà': Àwọn ìràwọ̀ olórin orílẹ̀-èdè Tanzania ò rí ìwé ìrìnnà wọ àjọ̀dún orin ní US "Onkowee omobibii Kenya Ciku Kimeria se alaye gbigbe laisi iyi ""eto si iwe-eri-omoilu-fun-irinna""." "Òǹkọ̀wée ọmọbíbíi Kenya Ciku Kimeria ṣe àlàyé gbígbé láìsí iyì ""ẹ̀tọ́ sí ìwé-ẹ̀rí-ọmọìlú-fún-ìrìnnà""." "Obinrin naa so wipe iwe irinna nikan ko gbe eniyan wo orile-ede miiran nitori pe ""o ni lati dahun awon ibeere bii, ‘Ki lo wa sibi wa se?""" "Obìnrin náà sọ wípé ìwé ìrìnnà nìkan kò gbé ènìyàn wọ orílẹ̀-èdè mìíràn nítorí pé ""o ní láti dáhùn àwọn ìbéèrè bíi, ‘Kí ló wa síbí wá ṣe?""" ti awon osise ibode yoo beere, bi esi ibeere ko ba te won lorun, arinrin-ajo le ba ara re ni enu iloro alo. tí àwọn òṣìṣẹ́ ibodè yóò béèrè, bí èsì ìbéèrè kò bá tẹ́ wọn lọ́rùn, arìnrìn-àjó lè bá ara rẹ̀ ní ẹnu ìloro àlọ. Fun awon Omo-adulawo ti o fe se irinajo jade lo si orile-ede ti kii se ti adulawo, ibeere fun iwe irinna iwolu maa n da bii sise ebo fun oosa ti ebi n pa. Fún àwọn Ọmọ-adúláwọ̀ tí ó fẹ́ ṣe ìrìnàjò jáde lọ sí orílẹ̀-èdè tí kìí ṣe ti adúláwọ̀, ìbéèrè fún ìwé ìrìnnà ìwọ̀lú máa ń dà bíi ṣíṣe ẹbọ fún òòṣà tí ebi ń pa. Adesina Ayeni (Omo Yooba), alakooso Ohun Agbaye ni edee Yoruba, so iririi re nigba ti o se ibeere fun iwe irinna iwoluu Lisbon, Portugal, fun aperoo awon alatinuda 2019 Creative Commons Summit: Adéṣínà Ayẹni (Ọmọ Yoòbá), alákòóso Ohùn Àgbáyé ní èdèe Yorùbá, sọ ìríríi rẹ̀ nígbà tí ó ṣe ìbéèrè fún ìwé ìrìnnà ìwọ̀lúu Lisbon, Portugal, fún àpéròo àwọn alátinúdá 2019 Creative Commons Summit: Idunnu nla gba okan-an mi nigba ti mo gba iroyin tel mi lowo wipe n o maa soro akori eto nibi Apero CC odun-un 2019 ni Lisbon. . . . Ìdùnnù ǹlá gba ọkàn-an mi nígbà tí mo gba ìròyìn tẹl mí lọ́wọ́ wípé n ó máa sọ̀rọ̀ àkórí ètò níbi Àpérò CC ọdún-un 2019 ní Lisbon. . . . Lojo 18 osu Igbe, 2019, ojo die si ayajo ojo ibii mi, mo ko awon ohun ti won beere fun iwe irinna lati woluu Lisbon ki n ba kopa ninuu apero naa sile ni ile-isee VFS Global ni idado Lekki, ni Eko. Lọ́jọ́ 18 oṣù Igbe, 2019, ọjọ́ díẹ̀ sí àyájọ́ ọjọ́ ìbíì mi, mo kó àwọn ohun tí wọn béèrè fún ìwé ìrìnnà láti wọ̀lúu Lisbon ki n ba kópa nínúu àpérò náà sílẹ̀ ní ilé-iṣẹ́ẹ VFS Global ní ìdádò Lekki, ní Èkó. Ojo 9 si 11 odun-un 2019 ni apero naa sugbon ojo marunundinlogun ni yo gba fun iwe irinna lati jade fun gbigba. Ọjọ́ 9 sí 11 ọdún-un 2019 ni àpérò náà ṣùgbọ́n ọjọ́ márùnúndínlógún ni yó gbà fún ìwé ìrìnnà láti jáde fún gbígbà. Lojo ti o ye ki n kuro nile fun Portugal, n koi ti i ri iwe-eri-omoilu-fun-irinna mi gba pada... Lọ́jọ́ tí ó yẹ kí n kúrò nílé fún Portugal, n kòì tí ì rí ìwé-ẹ̀rí-ọmọìlú-fún-ìrìnnà mi gbà padà... ojo mokanla leyin ti apero ti di afiseyin ti eegun alare n fiso, mo gba ise-ije ki n wa gba iwe-eri-omoilu-fun-irinna mi ni VFS. ọjọ́ mọ́kànlá lẹ́yìn tí àpérò ti di àfìsẹ́yìn ti eégún aláré ń fiṣọ, mo gba iṣẹ́-ìjẹ́ kí n wá gba ìwé-ẹ̀rí-ọmọìlú-fún-ìrìnnà mi ní VFS. Awon agba bo, inu didun l’o n mu ori ya. Awọn àgbá bọ̀, inú dídùn l’ó ń mú orí yá. Isoro kan ni ti airi iwe irinna gba, omiran ni ti owo irinajo ofe goboi ti o wole nitori n ko le e lo si apero. Ìṣòro kan ni ti àìrí ìwé ìrìnnà gbà, òmíràn ni ti owó ìrìnàjò ọ̀fẹ́ gọbọi tí ó wọlẹ̀ nítori n kò le è lọ si àpérò. Ibanuje gba okan mi poo latarii alaale Ile-Ifowopamo Agba orile-ede Naijiria ti ko mu ifowo ranse si oke okun rorun; n ko le e da owo irinajo ofe ti o pon dandan lati da pada pada fun awon ti o ni owo. Ìbànújẹ́ gba ọkàn mi poo látàríi àlàálẹ̀ Ilé-Ìfowópamọ́ Àgbà orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí kò mú ìfowó ránṣẹ́ sí òkè òkun rọrùn; n kò le è dá owó ìrìnàjò ọ̀fẹ́ tí ó pọn dandan láti dá padà padà fún àwọn tí ó ni owó. O dun mi wo akinyemi ara wipe won gbese le etoo mi gege bi olominira lati darapo mo awon akegbee mi. Ó dùn mí wọ akínyẹmí ara wípé wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ẹ̀tọ́ọ mi gẹ́gẹ́ bí olómìnira láti darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́ẹ̀ mi. Won pa ohun mo mi lenu! Wọ́n pa ohùn mọ́ mi lẹ́nu! Isoro: Fun awon Omo-adulawo ti o n se irinajo ninuu Ile-adulawo Ìṣòro: Fún àwọn Ọmọ-adúláwọ̀ tí ó ń ṣe ìrìnàjò nínúu Ilẹ̀-adúláwọ̀ O soro fun omo-adulawo lati se irinajo jade kuro ni Ile-adulawo — sugbon bee naa ni o nira lati se irinajo nile naa. Ó ṣòro fún ọmọ-adúláwọ̀ láti ṣe ìrìnàjò jáde kúrò ní Ilẹ̀-adúláwọ̀ — ṣùgbọ́n bẹ́ẹ̀ náà ni ó nira láti ṣe ìrìnàjò nílẹ̀ náà. Awon omo oniluu aimoye orile-ede ti o wa ni Ariwa agbanla aye le se irinajo lo si opo orile-ede ni ile-adulawo lai ni iwe irinna, tabi pelu hihamo ti o to nnkan, amo opolopo Omo-adulawo ni o niloo iwe irinna iwolu lati se irinajo si idaji awon orile-ede ti o ku. Àwọn ọmọ onílùú àìmọye orílẹ̀-èdè tí ó wà ní Àríwá àgbáńlá ayé lè ṣe ìrìnàjò lọ sí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ní ilẹ̀-adúláwọ̀ láì ní ìwé ìrìnnà, tàbí pẹ̀lú hìhámọ́ tí ò tó nǹkan, àmọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ Ọmọ-adúláwọ̀ ni ó nílòo ìwé ìrìnnà ìwọ̀lú láti ṣe ìrìnàjò sí ìdajì àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù. "Aladaasi Ohun Agbaye omobibi orile-ede Naijiria Rosemary Ajayi se apejuwe ""ilakaka awon omo-adulawo ti o n se irinajo ni aarin ile-adulawo "":" "Aládàásí Ohùn Àgbáyé ọmọbíbí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Rosemary Àjàyí ṣe àpèjúwe ""ìlàkàkà àwọn ọmọ-adúláwọ̀ tí ó ń ṣe ìrìnàjò ní àárín ilẹ̀-adúláwọ̀ "":" Inuu mi dun nitori wipe a n gbe oran ohun ti oju awon omo-adulawo maa n ri ni won ba beere fun iwe irinna wo Orile-ede oyinbo ati ohun ti o tan mo on ye wo. Inúu mi dùn nítorí wípé à ń gbé ọ̀ràn ohun tí ojú àwọn ọmọ-adúláwọ̀ máa ń rí ní wọ́n bá béèrè fún ìwé ìrìnnà wọ Orílẹ̀-èdè òyìnbó àti ohun ti ó tan mọ́ ọn yè wò. Eyi ko gbe mi lokan bii ti ilakaka awon omo-adulawo ti o n se irinajo ninuu ile-adulawo. Èyí kò gbé mi lọ́kàn bíi ti ìlàkàkà àwọn ọmọ-adúláwọ̀ tí ó ń ṣe ìrìnàjò nínúu ilẹ̀-adúláwọ̀. Ni RightsCon ti o waye ni Tunis, ati GlobalFact ti o waye ni Cape Town, mo bi awon Omo-adulawo boya won ti niloo iwe irinna. Ní RightsCon tí ó wáyé ní Tunis, àti GlobalFact tí ó wáyé ní Cape Town, mo bi àwọn Ọmọ-adúláwọ̀ bóyá wọ́n ti nílòo ìwé ìrìnnà. Ni ojo isinmi ti a wa yii, mo gbo wipe onise-iroyin omo Naijiria kan ko le e wa nibi GlobalFact nitori wipe ko ni iwe irinna. Ní ọjọ́ ìsinmi tí a wà yìí, mo gbọ́ wípé oníṣẹ́-ìròyìn ọmọ Nàìjíríà kan kò le è wà níbí GlobalFact nítorí wípé kò ní ìwé ìrìnnà. Ki a maa so ti awon omo-adulawo ti o fo kuro nile-adulawo ki won o to le wo Tunis. Kí a máà sọ ti àwọn ọmọ-adúláwọ̀ tí ó fò kúrò nílẹ̀-adúláwọ̀ kí wọn ó tó lè wọ Tunis. Ni osu ti o koja, mo se alabaapade onise-iroyin ti o wa lati Ila-oorun Ile-adulawo ti o n se ibeere fun iwe irinna wo Naijiria. Won ni ki o pesee iwe-eri iwakoo ti akosemose awako ti yoo wa gbe e bi o ba bale ni papa-oko-ofuurufu! Ní oṣù ti ó kojá, mo ṣe alábàápàdé oníṣẹ́-ìròyìn tí ó wá láti Ìlà-oòrùn Ilẹ̀-adúláwọ̀ tí ó ń ṣe ìbéèrè fún ìwé ìrìnnà wọ Nàìjíríà. Wọ́n ní kí ó pèsèe ìwé-ẹ̀rí ìwákọ̀ọ ti akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ awakọ̀ tí yóò wá gbé e bí ó bá balẹ̀ ní pápá-ọkọ̀-òfuurufú! Bi Rosemary ti so, irinajo ninuu ile-adulawo maa n gba siserinajo kuro ni ile-adulawo ki aserinajo o to le e de ibi ti o n lo ni aarin Ile-adulawo. Bí Rosemary ti sọ, ìrìnàjò nínúu ilẹ̀-adúláwọ̀ máa ń gba ṣíṣèrìnàjò kúrò ní ilẹ̀-adúláwọ̀ kí aṣèrìnàjò ó tó le è dé ibi tí ó ń lọ ní àárín Ilẹ̀-adúláwọ̀. Ni ibi apero osise oko-ofuurufu agbegbe ti Ajo Igbokegbodo Oko-ofuurufu Agbaye (IATA) gbe kale ti o waye ni Accra ninuu osu Okudu, Igbakeji Aare Orile-edee Ghana, Onisegun Mahamudu Bawumia pohunrere-ekun latarii wipe “o ye onisowo lati Freetown [Sierra Leone], fun apeere, lati se irinajo fun ojo meji gbako lati lo si Banjul (nipasee orile-ede keta) fun irinajo ti ko ju wakati kan lo.“ Ní ibi àpérò òṣìṣẹ́ ọkọ̀-òfuurufú agbègbè tí Àjọ Ìgbókègbódò Ọkọ̀-òfuurufú Àgbáyé (IATA) gbé kalẹ̀ tí ó wáyé ní Accra nínúu oṣù Òkúdù, Igbákejì Ààrẹ Orílẹ̀-èdèe Ghana, Oníṣègùn Mahamudu Bawumia pohùnréré-ẹkún látàríi wípé “ó yẹ oníṣòwò láti Freetown [Sierra Leone], fún àpẹẹrẹ, láti ṣe ìrìnàjò fún ọjọ́ méjì gbáko láti lọ sí Banjul (nípasẹ̀ẹ orílẹ̀-èdè kẹ́ta) fún ìrìnàjò tí kò ju wákàtí kan lọ.“ Ipoyi lori ofuurufu naa gbomo pon pelu owo kanangu fifo loke laaarin Ile-adulawo. Ìpòyì lórí òfuurufú náà gbọ́mọ pọn pẹ̀lú owó kanangú fífò lókè láàárín Ilẹ̀-adúláwọ̀. Nje otito ni wipe o seese ki Omo-adulawo o maa pada wale? Ǹjẹ́ òtítọ́ ni wípé ó ṣeéṣe kí Ọmọ-adúláwọ̀ ó máà padà wálé? Ise idoola-emi ni orii omi Erekusu Canary ni 2006. Iṣẹ́ ìdóòlà-ẹ̀mí ní oríi omi Erékùsù Canary ní 2006. Aworan lati owoo Noborder Network. (CC BY 2.0) Àwòrán láti ọwọ́ọ Noborder Network. (CC BY 2.0) Ni aarin-n odun-un 2010-2017, awon asipokiri lati awon orile-ede ti o wa labe Ilu Guusu Asale Sahara ni o sepo ti o tele Syria gege bi ilu ti o ni eniyan to po ju ninu awon asipokiri lagbaaye. Ni àárín-n ọdún-un 2010-2017, àwọn aṣípòkiri láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lábẹ́ Ìlú Gúúsù Aṣálẹ̀ Sahara ni ó ṣepò tí ó tẹ̀lé Syria gẹ́gẹ́ bí ìlú tí ó ní ènìyàn tó pọ̀ jù nínú àwọn aṣípòkiri lágbàáyé. Opolopo Omo-adulawo n sa kuro niluu nitori ebi ati rogbodiyan, lati wabi foripamosieek, didi ogunlemidebi tabi didi agbeluu ni Arewa Amerika tabi ni Eroopu. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Ọmọ-adúláwọ̀ ń sá kúrò nílùú nítorí ebi àti rògbòdìyàn, láti wábi forípamọ́síeek, didi ogúnlémidébí tàbí didi agbélùú ní Àréwá Amẹ́ríkà tàbí ní Éróòpù. "Abajade Iwadii Pew odun-un 2018 so wipe iye awon asipokiri lati Ilu Guusu Asale Sahara ""ti fi ida 50 lo soke tabi ju bee lo ni aarin-in odun-un 2010 ati 2017, ju gbogbo re lo won ju ida 17 lo kariaye ni asiko kan naa""." "Àbájáde Ìwádìí Pew ọdún-un 2018 sọ wípé iye àwọn aṣípòkiri láti Ìlú Gúúsù Aṣálẹ̀ Sahara ""ti fi ìdá 50 lọ sókè tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ ní àárín-in ọdún-un 2010 àti 2017, ju gbogbo rẹ̀ lọ wọn ju ìdá 17 lọ káríayé ní àsìkò kan náà""." Awon omo-adulawo ti o wa lati Ilu Guusu Asale Sahara naa n si kiri orile-ede jakejado agbaye. Awọn ọmọ-adúláwọ̀ tí ó wá láti Ìlú Gúúsù Aṣálẹ̀ Sahara náà ń ṣí kiri orílẹ̀-èdè jákèjádò àgbáyé. Ni odun-un 2014, o to asikiri 170,000 ti o ni iwe-ase labe ofin ni o n wo oko gba ori okun Mediterranean lo si orile-ede Italy. Ní ọdún-un 2014, ó tó aṣíkiri 170,000 tí ò ní ìwé-àṣẹ lábẹ́ òfin ni ó ń wọ ọkọ̀ gba orí òkun Mediterranean lọ sí orílẹ̀-èdè Italy. Ogoro lo wa lati awon Ilu Guusu Asale Sahara. Ọ̀gọ̀rọ̀ ló wá láti àwọn Ìlú Gúúsù Aṣálẹ̀ Sahara. "Ni osu Ope odun-un 2018, Olopaa Brazil doola emi eeyan 25 omo-adulawo ti o wa lati Ilu Guusu Asale Sahara ""ti o ti wa lori omi okun Atlantic fun osu kan gbako""." "Ní oṣù Ọ̀pẹ ọdún-un 2018, Ọlọ́pàá Brazil dóòlà ẹ̀mí èèyàn 25 ọmọ-adúláwọ̀ tí ó wá láti Ìlú Gúúsù Aṣálẹ̀ Sahara ""tí ó ti wà lọ́rí omi òkun Atlantic fún oṣù kan gbáko""." "Awon arinrinajoo san ""egbelemuku owo lowo enikookan"" fun irinajo lati Cape Verde. Ni osu Okudu odun-un 2019, US Customs Ajo Asobode ati Aabo Ibode US ni Del Rio, Texas, USA, fi owoo sikun ofin mu awon omo-adulawo 500 ti o wa lati Ile-olominira Congo, Democratic Republic of Congo, ati Angola, ti won n fe gba omi Odo Rio Grande wo USA." "Àwọn arìnrìnàjòó san ""ẹgbẹlẹmùkù owó lọ́wọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan"" fún ìrìnàjò láti Cape Verde. Ní oṣù Òkúdù ọdún-un 2019, US Customs Àjọ Aṣọ́bodè àti Ààbò Ibodè US ní Del Rio, Texas, USA, fi ọwọ́ọ ṣìkún òfin mú àwọn ọmọ-adúláwọ̀ 500 tí ó wà láti Ilẹ̀-olómìnira Congo, Democratic Republic of Congo, àti Angola, tí wọn ń fẹ́ gba omi Odò Rio Grande wọ USA." Oniruuru iroyin ni o ti ro o wipe Ile-adulawo ni aarin-in gbungun otosi ati ogun, sibesibe, Marie-Laurence Flahaux ati Hein De Haas, awon onimo lati Ifasiti ti Oxford ati Ifasiti ti Amsterdam, ni sisentele, ko gba pe bee ni o ri. Onírúurú ìròyìn ni ó ti rò ó wípé Ilẹ̀-adúláwọ̀ ni àárín-ín gbùngùn òtòṣì àti ogun, síbẹ̀síbẹ̀, Marie-Laurence Flahaux àti Hein De Haas, àwọn onímọ̀ láti Ifásitì ti Oxford àti Ifásitì ti Amsterdam, ní ṣísẹ̀ntèlé, kò gbà pé bẹ́ẹ̀ ní ó rí. "Flahaux ati De Haas jiyan wipe ko ri bi iroyin ti se ro o si etigboo omo araye paapaa ""awon ile ise ati olosolu"" ati awon ologbon naa." "Flahaux àti De Haas jiyàn wípé kò rí bí ìròyín ti ṣe rò ó sí etígbọ̀ọ́ ọmọ aráyé pàápàá ""àwọn ilé iṣẹ́ àti olóṣòlú"" àti àwọn ọlọ́gbọ́n náà." "Ise iwadii fi ye wipe awon isipokiri lati Ile-adulawo ko deedee waye, ohun ti o fa a ni ""ilana idagbasoke ati iyipada awujo"" eyi ti o n mu sisikiri lo si awon agbegbe agbaye wu Omo-adulawo — ti ko yato si asipokiri lati ibomiiran lagbaaye." "Iṣẹ́ ìwádìí fi yé wípé àwọn ìṣípòkiri láti Ilẹ̀-adúláwọ̀ kò déédéé wáyé, ohun tí ó fà á ni ""ìlànà ìdàgbàsókè àti ìyípadà àwùjọ"" èyí tí ó ń mú ṣíṣíkiri lọ sí àwọn agbègbè àgbáyé wu Ọmọ-adúláwọ̀ — tí kò yàtọ̀ sí aṣípòkiri láti ibòmìíràn lágbàáyé." Awon iroyin abanilorukoje wonyi, ni o n fa sababi ilana-ise iwe irinna: Àwọn ìròyìn abanilórúkọjẹ́ wọ̀nyí, ni ó ń fa sábàbí ìlànà-iṣẹ́ ìwé ìrìnnà: Opolopo orile-ede ni o nigbagbo wipe gbogbo arinrinajo ti o ba je Omo-adulawo ni ko ni pada si orile-edee re, afi bi arinrinajo ba ni eri ti o yanranti to ni o le ri iwe irinna iwolu gba. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni ó nígbàgbọ́ wípé gbogbo arìnrìnàjò tí ó bá jẹ́ Ọmọ-adúláwọ̀ ni kò ní padà sí orílẹ̀-èdèe rẹ̀, àfi bí arìnrìnàjó bá ní ẹ̀rí tí ó yanrantí tó ni ó lè rí ìwé ìrìnnà ìwọ̀lú gbà. Ko rorun lati si oju awon ti ki i se omo-adulawo loju nipa oruko buburu ti won ti so orile-ede ti o wa lati Ile-adulawo. Kò rọrùn láti ṣí ojú àwọn tí kì í ṣe ọmọ-adúláwọ̀ lójú nípa orúkọ búburú tí wọn ti sọ orílẹ̀-èdè tí ó wá láti Ilẹ̀-adúláwọ̀. Nibayii, awon orile-ede Ile-adulawo nise lati se si eto lilo-ati-bibo awon omoadulawo. Iwe-eri-omoilu-fun-irinna kan soso fun gbogbo orile-ede ni Ile-adulawo je ona abayo — amo ko to. Níbàyìí, àwọn orílẹ̀-èdè Ilẹ̀-adúláwọ̀ níṣẹ́ láti ṣe sí ètò lílọ-àti-bíbọ̀ àwọn ọmọadúláwọ̀. Ìwé-ẹ̀rí-ọmọìlú-fún-ìrìnnà kan ṣoṣo fún gbogbo orílẹ̀-èdè ní Ilẹ̀-adúláwọ̀ jẹ́ ọ̀nà àbáyọ — àmọ́ kò tó. Single African Air Transport market naa (SAATM), ati Continental Free Trade Agreement naa, ti a fi lole lodun ti o koja, ti se alaale igbese wonyi, sugbon imuse si ku die kaato. Single African Air Transport market náà (SAATM), àti Continental Free Trade Agreement náà, tí a fi lọ́lẹ̀ lọ́dún tí ó kọjá, ti se àlàálẹ̀ ìgbésẹ̀ wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ìmúṣẹ ṣì kù díẹ̀ káàtó. Lasiko yii, gege bii Omo-adulawo, iyanju lati rinrinajo ni lati ni iriri irenisile ti awon ti o n se irinajo lo si oke-okun n ri — tabi je titaji ninu ala isokan Ile-adulawo ti ko si. Lásìkò yìí, gẹ́gẹ́ bíi Ọmọ-adúláwọ̀, ìyànjú láti rìnrìnàjò ni láti ní ìrírí ìrẹnisílẹ̀ tí àwọn tí ó ń se ìrìnàjò lọ sí òkè-òkun ń rí — tàbí jẹ́ títají nínú àlà ìsọ̀kan Ilẹ̀-adúláwọ̀ tí kò sí. Eyi keyii ti o baa je, oosa iwe irinna n beere ebo si i, ti ko si ye e gbebo. Èyí kéyìí tí ò báà jẹ́, òòsà ìwé ìrìnnà ń béèrè ẹbọ sí i, tí kọ̀ sì yé é gbẹbọ. Ero Alatagba ni a fi gbe awon iroyin iro ati oro eleyameya jade lasiko idibo orile-edee Naijiria Ẹ̀rọ Alátagbà ni a fi gbé àwọn ìròyìn irọ́ àti ọ̀rọ̀ ẹlẹ́yàmẹyà jáde lásìkò ìdìbò orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà Iro ti o ti ara eleyameya su yo lori ero alatagba lasiko ibo Irọ́ tí ó ti ara ẹlẹ́yàmẹyà sú yọ lórí ẹ̀rọ alátagbà lásìkò ìbò Ibo aare ti ojo 28, osu keta odun-un 2015 bi o se n lo lowo ni Abuja, Naijiria. Aworan lati Ileese Asojuu Eto Irinajo si orile-edee US ni Naijiria/ Idika Onyukwu [Igboriyin fun onlaworan: Aisi-foro-aje 2.0 Ailami (CC BY-NC 2.0)] Ìbò ààrẹ ti ọjọ́ 28, oṣù kẹta ọdún-un 2015 bí ó ṣe ń lọ lọ́wọ́ ní Abuja, Nàìjíríà. Àwòrán láti Iléeṣẹ́ Aṣojúu Ètò Ìrìnàjò sí orílẹ̀-èdèe US ní Nàìjíríà/ Idika Onyukwu [Ìgbóríyín fún òǹlàwòrán: Àìsí-fọ̀rọ̀-ajé 2.0 Àìlámì (CC BY-NC 2.0)] Eyi ni akoko ninu iroyin onisisentele eleka-meji ti o da firigbagboo lorii oro ikoriira eni, iroyin eleje ati iro lori ayelujara ni Naijiria lasiko ibo odun-un 2019. Èyí ni àkọ́kọ́ nínú ìròyìn oníṣísẹ̀ntẹ̀lé ẹlẹ́ka-méjì tí ó dá fìrìgbagbòó lóríi ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹni, ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀ àti irọ́ lórí ayélujára ní Nàìjíríà lásìkò ìbò ọdún-un 2019. O lee ka apa keji iroyin naa nibi. O leè ká apá kejì ìròyìn náà níbí. Ojo 23, osu keji odun-un 2019 ni awon omo orile-edee Naijiria gba eka idibo lo lati dibo yan aare ati omo igbimo tuntun sipo. Ọjọ́ 23, oṣù kejì ọdún-un 2019 ni àwọn ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà gba ẹ̀ka ìdìbò lọ láti dìbò yan ààrẹ àti ọmọ ìgbìmọ̀ tuntun sípò. "Awon meji gboogi ondijedupo si ipo aare, Aare ti o wa lori alefa ko ibo egbeegberun 15 ti o mu u bori olorogun-un re pekipeki, Atiku Abubakar, pelu ""alafo ida 56 si ida 41""." "Àwọn méjì gbòógì òǹdíjedupò sí ipò ààrẹ, Ààrẹ tí ó wà lórí àléfà kó ìbò ẹgbẹẹgbẹ̀rún 15 tí ó mú u borí olórogún-un rẹ̀ pẹ́kípẹ́kí, Atiku Abubakar, pẹ̀lú ""àlàfo idà 56 sí ìdá 41""." A se ibura fun Buhari fun saa keji olodun merin lojo 29, osu karun-un, 2019. A ṣe ìbúra fún Buhari fún sáà kejì ọlọ́dún mẹ́rin lọ́jọ́ 29, oṣù karùn-ún, 2019. Ka si i: #NigeriaDecides2019: Ohun gbogbo ti o ye ki o mo nipa idibo gbogboogbo ti odun nii Kà sí i: #NigeriaDecides2019: Ohun gbogbo tí ó yẹ kí o mọ̀ nípa ìdìbò gbogboògbò ti ọdún nìí Sibe, ohun gbogbo ti o gba ni won fi se ipolongo ibo naa, lai yo bibe ero alatagba lowe sile. Síbẹ̀, ohun gbogbo tí ó gbà ni wọ́n fi ṣe ìpolongo ìbò náà, láì yọ bíbẹ ẹ̀rọ alátagbà lọ́wẹ̀ sílẹ̀. Oro ikoriira tegbintegbin toun iwa eleyameya ati iroyin iro ran bii papa inu oye ni ori ero ayelujara, pabambari lorii gbagede Twitter. Ọ̀rọ̀ ìkórìíra tẹ̀gbintẹ̀gbin tòun ìwà ẹlẹ́yàmẹyà àti ìròyìn irọ́ ràn bíi pápá inú ọyẹ́ ní orí ẹ̀rọ ayélujára, pabambarì lóríi gbàgede Twitter. Ikoriira Eya ni Naijiria Ìkórìíra Ẹ̀yà ní Nàìjíríà Eya oniruuru – ti o to bii 250 ati ede 500 – ti fi igba kan je orisun aibaleokan dipoo ifokanbale. Ẹ̀yà onírúurú – tí ó tó bíi 250 àti èdè 500 – ti fi ìgbà kan jẹ́ orísun àìbalẹ̀ọkàn dípòo ìfọ̀kànbalẹ̀. Eyi fi oju han lasiko ibo nigbati awon oloselu lo eleyameleya fi polongo ibo. Èyí fi ojú hàn lásìkò ìbò nígbàtí àwọn olóṣèlú lo ẹlẹ́yàmẹ́lẹ́yá fi polongo ìbò. Lati ile, itakuroso lori ayelujara ni Naijiria ko lo lai si ikoriira. Láti ilẹ̀, ìtàkùrọ̀sọ lórí ayélujára ní Nàìjíríà kò lọ láì sí ìkórìíra. Ka si i: Naijiria: Gbigbogun ti apoju ikoriira eya tegbintegbin — lojukoroju ati lori ayelujara Kà sí i: Nàìjíríà: Gbígbógun ti àpọ̀jù ìkórìíra ẹ̀yà tẹ̀gbintẹ̀gbin — lójúkorojú àti lórí ayélujára Lasiko ibo odun-un 2015, fun apeere, gbagede Twitter ni orile-edee Naijiria di ibi ikoro ati ibi idije ijuwo laaarin awon alatileyin awon ondije meji igba naa, Goodluck Jonathan (PDP, omo leyin Kristi to je omo Ijaw) ati Muhammadu Buhari (APC, Imale, Hausa, Fulani). Lásìkò ìbò ọdún-un 2015, fún àpẹẹrẹ, gbàgede Twitter ní orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà di ibi ìkorò àti ibi ìdíje ìjuwọ́ láàárín àwọn alátìlẹ́yìn àwọn òǹdíje méjì ìgbà náà, Goodluck Jonathan (PDP, ọmọ lẹ́yìn Krístì tó jẹ́ ọmọ Ijaw) àti Muhammadu Buhari (APC, Ìmàle, Hausa, Fulani). Twitter di irinse fun igberoyin ikoriira eya tegbintegbin jade ati ohun elo fun egbe oloselu. Twitter di irinṣẹ́ fún ìgbéròyìn ìkórìíra ẹ̀yà tẹ̀gbintẹ̀gbin jáde àti ohun èlò fún ẹgbẹ́ olóṣèlú. Awon kan lero wipe odun-un 2019 yoo yato nitori pe Buhari ti egbee Ajo Itesiwaju Gbogboogbo (APC) ati Abubakar lati Egbe oloselu Ijoba-tiwantiwa Awon Eniyan (PDP) ti awon mejeeji si je Hausa, Fulani Imale, amo bee ko lo ri. Àwọn kan lérò wípé ọdún-un 2019 yóò yàtọ̀ nítorí pé Buhari ti ẹgbẹ́ẹ Àjọ Ìtẹ̀síwájú Gbogboògbò (APC) àti Abubakar láti Ẹgbẹ́ olóṣèlú Ìjọba-tiwantiwa Àwọn Ènìyàn (PDP) tí àwọn méjèèjì sì jẹ́ Hausa, Fulani Ìmàle, àmọ́ bẹ́ẹ̀ kọ́ ló rí. Awon amugbalegbee won – Yemi Osinbajo (APC), omo Yoruba, ati Peter Obi (PDP), omo Igbo, je Omo-leyin-in-kristi — amo lati eya otooto. Àwọn amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn – Yẹmí Ọṣìńbàjò (APC), ọmọ Yoruba, àti Peter Obi (PDP), ọmọ Igbo, jẹ́ Ọmọ-lẹ́yìn-in-krístì — àmọ́ láti ẹ̀yà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. O fe jo atunwaye isele 2015 sugbon pelu atakanangbon miiran. Ó fẹ́ jọ àtúnwáyé ìṣẹ̀lẹ̀ 2015 ṣùgbọ́n pẹ̀lú atakànàngbọ̀n mìíràn. Ohun gbogbo nipa iselu Naijiria woso eleyameleya ni 2017, odun meji ki ibo o to bere, ti o si fa aigbagbo ninu eto iselu. Ohun gbogbo nípa ìṣèlú Nàìjíríà wọṣọ ẹlẹ́yàmẹ́lẹ́yá ní 2017, ọdún méjì kí ìbò ó tó bẹ̀rẹ̀, tí ó sì fa àìgbàgbọ́ nínú ètò ìṣèlú. Egbe ajijangbara omo ibile Biafra Indigenous People of Biafra (IPOB), ti o je agbarijopo awon omo ibile ila-oorun orile-edee Naijiria ti Nnamdi Kanu je olori, da kun rogbodiyan ti o n ro titi. Ẹgbẹ́ ajìjàngbara ọmọ ìbílẹ̀ Biafra Indigenous People of Biafra (IPOB), tí ó jẹ́ àgbáríjọpọ̀ àwọn ọmọ ìbílẹ̀ ìlà-oòrùn orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà tí Nnamdi Kanu jẹ́ olórí, dá kún rògbòdìyàn tí ó ń rọ́ tìtì. Ka si i: Bi oro ikoriira tegbintegbin se n peleke si i, awon onkowee Naijiria naa muse se Kà sí i: Bí ọ̀rọ̀ ìkórìíra tẹ̀gbintẹ̀gbin ṣe ń peléke sí i, àwọn òǹkọ̀wée Nàìjíríà náà múṣẹ́ ṣe Idi-asale-ile ni ariwa Naijiria lo mu ki awon olosin-eran ti o je darandaran ti o n ba awon agbe ja o wa si apa guusu. Ìdi-aṣálẹ̀-ilẹ̀ ní àríwá Nàìjíríà ló mú kí àwọn ọlọ́sìn-ẹran tí ó jẹ́ darandaran tí ó ń bá àwọn àgbẹ̀ jà ó wà sí apá gúúsù. Awon Omo-leyin-in-kristi kan “ri gbigba awon Fulani darandaran ti o je Imale towotese wole si apaa guusu gege bii igbese lati 'Sonidimale' ni tipatipa. Àwọn Ọmọ-lẹ́yìn-in-krístì kan “rí gbígba àwọn Fulani darandaran tí ó jẹ́ Ìmàle tọwọ́tẹsẹ̀ wọlé sí apáa gúúsù gẹ́gẹ́ bíi ìgbésẹ̀ láti 'Sọnidìmàlè' ní tipátipá. "Ikojale ijoba Naijiria lati se iwadii si awon ikolu ti o n waye ati ""fifimu awon ti o se sofin danrin"", ti ikolu naa si fa iku awon eniyan ti o to bii egberun 4 lati odun-un 2015 si 2018, gege bi ileese Amnesty International ti se ni i lakosile." "Ìkọ̀jálẹ́ ìjọba Nàìjíríà láti ṣe ìwádìí sí àwọn ìkọlù tí ó ń wáyé àti ""fífimú àwọn tí ó ṣẹ̀ sófin dánrin"", tí ìkọlù náà sì fa ikú àwọn ènìyàn tí ó tó bíi ẹgbẹ̀rún 4 láti ọdún-un 2015 sí 2018, gẹ́gẹ́ bí iléeṣẹ́ Amnesty International ti ṣe ní i lákọsílẹ̀." Lati ihin lo, eleyameya ti n peleke si i ki o to di asiko ibo aare odun-un 2019. Láti ìhín lọ, ẹlẹ́yàmẹyà ti ń peléke sí i kí ó tó di àsìkò ìbò ààrẹ ọdún-un 2019. Ainigbagbo ti o wa nile lo fi aye gba igbejade iroyin iro – lojukoroju ati lori ayelujara – lasiko ibo. Àìnígbàgbọ́ tí ó wà nílẹ̀ ló fi àyè gba ìgbéjáde ìròyìn irọ́ – lójúkorojú àti lórí ayélujára – lásìkò ìbò. Ibo ati igbagbo oro ori ero ayelujara ni Naijiria Ìbò àti ìgbàgbọ́ ọ̀rọ̀ orí ẹ̀rọ ayélujára ní Nàìjíríà Iye awon onlo ero ayelujara ni Naijiria fo fere soke lati egbeegberun 98.3 ni odun-un 2017 si egbeegberun 100.5 ni 2018. Iye àwọn òǹlò ẹ̀rọ ayélujára ní Nàìjíríà fò fẹ̀rẹ̀ sókè láti ẹgbẹẹgbẹ̀rún 98.3 ní ọdún-un 2017 sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún 100.5 ní 2018. Facebook lo lewaju gege bi i gbagede aayo opo omo orile-edee Naijiria pelu onlo egbeegberun 22, ti gbagede aworan-atohun YouTube (egbeegberun 7 ati ju bee lo) tele e, Twitter (egbeegberun 6) ati Instagram (egbeegberun 5.7). Facebook ló léwájú gẹ́gẹ́ bí i gbàgede ààyò ọ̀pọ̀ ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà pẹ̀lú òǹlò ẹgbẹẹgbẹ̀rún 22, tí gbàgede àwòrán-àtohùn YouTube (ẹgbẹẹgbẹ̀rún 7 àti jù bẹ́ẹ̀ lọ) tẹ̀lé e, Twitter (ẹgbẹẹgbẹ̀rún 6) àti Instagram (ẹgbẹẹgbẹ̀rún 5.7). Odo ni opolopo awon oludibo orile-edee Naijiria. Lara egbeegberun 84 awon oludibo ti o forukosile fun Ibo Apapo odun-un 2019, ti idaji — ida 51 — je odo ondibo ti ojo orii won to odun 18 ati 35, ti ida 30 si je eni odun 36 ati 50. Ọ̀dọ́ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn olùdìbò orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Lára ẹgbẹẹgbẹ̀rún 84 àwọn olùdìbò tí ó forúkọsílẹ̀ fún Ìbò Àpapọ̀ ọdún-un 2019, tí ìdajì — ìdá 51 — jẹ́ ọ̀dọ́ òǹdìbò tí ọjọ́ oríi wọ́n tó ọdún 18 àti 35, tí ìdá 30 sì jẹ́ ẹni ọdún 36 àti 50. Awon ojo-ori mejeeji yii, ti o ni onimo nipa ilo ero ayarabiasa ati awon asipo sori ero ayarabiasa, ni o po ju lo ninu awon oludiboo Naijiria. Àwọn ọjọ́-orí méjèèjì yìí, tí ó ní onímọ̀ nípa ìlò ẹ̀rọ ayárabíàṣá àti àwọn aṣípò sórí ẹ̀rọ ayárabíàṣá, ni ó pọ̀ jù lọ nínú àwọn olùdìbòo Nàìjíríà. Tori idi eyi, ko yanilenu wipe ero ayarabiasa je gbagede kan gboogi fun fifi ipolongo ibo odun-un 2019 sota ija lura eni. Torí ìdí èyí, kò yanilẹ́nu wípé ẹ̀rọ ayárabíàṣá jẹ́ gbàgede kan gbòógì fún fífi ìpolongo ìbò ọdún-un 2019 sọta ìjà lura ẹni. Latari eyi, o mu u soro lati gbokan te awon iroyin ori ayelukara-bi-ajere lasiko eto idibo to waye lodun-un 2019. Látàrí èyí, ó mú u ṣòro láti gbọ́kàn tẹ àwọn ìròyìn orí ayélukára-bí-ajere lásìkò ètò ìdìbò tó wáyé lọ́dún-un 2019. Iroyin iro ti ko ni gbongbon ninu ni won polongo gege ihin rere tooto, ti awon alatileyin egbe oloselu mejeeji ti o gbajumo ju lo ni orile-edee Naijiria si lukoro re: Ajo Itesiwaju Gbogboogbo All Progressive Congress (APC) ati Egbe oloselu Ijoba-tiwantiwa Awon Eniyan People's Democratic Party (PDP). Ìròyìn irọ́ tí kò ní gbọ́ngbọ́n nínú ni wọ́n polongo gẹ́gẹ́ ìhìn rere tòótọ́, tí àwọn alátìlẹ́yìn ẹgbẹ́ olóṣèlú méjèèjì tí ó gbajúmọ̀ jù lọ ní orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà sì lukoro rẹ̀: Àjọ Ìtẹ̀síwájú Gbogboògbò All Progressive Congress (APC) àti Ẹgbẹ́ olóṣèlú Ìjọba-tiwantiwa Àwọn Ènìyàn People's Democratic Party (PDP). Gege bi ikiyesi eya ti o waye laaarin ojo 28 osu kewaa, 2018, ati ojo 29, osu karun-un 2019, oro ikoriira eya tegbintegbin je irinse fun iroyin ti ko ni gbongbon n'nu ti o kun fun iro lati sakani egbe oloselu mejeeji ni orii Twitter ti Naijiria lasiko ibo aare 2019. Gẹ́gẹ́ bí ìkíyèsí ẹ̀yà tí ó wáyé láàárín ọjọ́ 28 oṣù kẹwàá, 2018, àti ọjọ́ 29, oṣù karùn-ún 2019, ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹ̀yà tẹ̀gbintẹ̀gbin jẹ́ irinṣẹ́ fún ìròyìn tí kò ní gbọ́ngbọ́n ń'nú tí ó kún fún irọ́ láti sàkání ẹgbẹ́ olóṣèlú méjèèjì ní oríi Twitter ti Nàìjíríà lásìkò ìbò ààrẹ 2019. A ka awon ikiyesi yii sile lati ori ayelujara ni asiko yii. A ká àwọn ìkíyèsí yìí sílẹ̀ láti orí ayélujára ní àsìkò yìí. Ti a ba so nipa iroyin iro nipa ti eleyameya, awon agbaruku ti egbe oloseluu APC yo enu iwosi si Obi lara nitori pe o da awon ara oke Oya pada nigba ti o wa lori ipo gege bi alase Ipinle Anambra, ni ila-oorun guusu orile-edee Naijiria. Tí a bá sọ nípa ìròyìn irọ́ nípa ti ẹlẹ́yàmẹyà, àwọn agbárùkù ti ẹgbẹ́ olóṣèlúu APC yọ ẹnu ìwọ̀sí sí Obi lára nítorí pé ó dá àwọn ará òkè Ọya padà nígbà tí ó wà lórí ipò gẹ́gẹ́ bí aláṣẹ Ìpínlẹ̀ Anambra, ní ìlà-oòrùn gúúsù orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Tuwiiti tan kari ile kari oko ti o so pe awon omo Yoruba n tina bo iso awon onisowo ti o je eya Igbo ni Eko. Iro funfun balawu ni awon iroyin wonyi, a o gbe e ye wo siwaju si i ninu Apa keji aroko yii. Túwíìtì tàn kárí ilé kárí oko tí ó sọ pé àwọn ọmọ Yorùbá ń tiná bọ ìsọ̀ àwọn oníṣòwò tí ó jẹ́ ẹ̀yà Igbo ní Èkó. Irọ́ funfun báláwú ni àwọn ìròyìn wọ̀nyí, a ó gbé e yẹ̀ wò síwájú sí i nínú Apá kejì àròkọ yìí. Aworan 1: Tuwiiti iro ti Festus Keyamo Àwòrán 1: Túwíìtì irọ́ ti Festus Keyamo Aworan 2: Asiri bi ti aworan ti Keyamo tari sita wa ni ti otito. Àwòrán 2: Àṣírí bi tí àwòrán tí Keyamo tari síta wà ní ti òtítọ́. Fun apeere omiran, a lo aworan kan bayii lona ti ko ye. Lojo 28, osu kewaa, odun-un, 2018, Festus Keyamo, oludari eto ikede ana fun Ileese Ipolongo fun Buhari, tuwiiti aworan kan (Aworan 1) ti igi kan ti o n wu laaarin oju irin kan ti o ti di apati: Fún àpẹẹrẹ òmíràn, a lo àwòrán kan báyìí lọ́nà tí kò yẹ. Lọ́jọ́ 28, oṣù kẹwàá, ọdún-un, 2018, Festus Keyamo, olùdarí ètò ìkéde àná fún Iléeṣẹ́ Ìpolongo fún Buhari, túwíìtì àwòrán kan (Aworan 1) ti igi kan tí ó ń wù láàárín ojú irin kan tí ó ti di àpatì: Bi igi se n wu si aarin oju irin ni 1999 si 2015... Bí igí ṣe ń wù sí àárín ojú irin ní 1999 sí 2015... Bayii, ‘Saa Ipari ise’ re e, awon oju irin naa ti n ji pada saye.” Ijoba PDP lo n tuko eto ni 1999 si 2015. Báyìí, ‘Sáà Ìparí iṣẹ́’ rè é, àwọn ojú irin náà ti ń jí padà sáyé.” Ìjọba PDP ló ń tukọ̀ ètò ní 1999 sí 2015. Leyin-o-reyin, onlo Twitter kan ti o je omo orile-edee Naijiria to ipasee aworan naa si tuwiiti kan ledee Larubawa (Aworan 2) ti enikan tari sita ninu osu yen. Lẹ́yìn-ò-rẹyìn, òǹlò Twitter kan tí ó jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà tọ ipasẹ̀ẹ àwòrán náà sí túwíìtì kan lédèe Lárúbáwá (Àwòrán 2) tí ẹnìkan tari síta nínú oṣù yẹn. Tuwiiti naa jerii wipe Lebanon ni aworan ohun ti se wa. Túwíìtì náà jẹ́rìí wípé Lebanon ni àwòrán ọ̀hún ti ṣẹ̀ wá. Ohun ti Keyamo fe se ni lati fi han wipe isakoso ijoba Buhari ti gbe igbese atunse si awon ona okoo oju irin ti ijoba ana pa ti. Ohun tí Keyamo fẹ́ ṣe ni láti fi hàn wípé ìṣàkóso ìjọba Buhari ti gbé ìgbésẹ̀ àtúnṣe sí àwọn ọ̀nà ọkọ̀ọ ojú irin tí ìjọba àná pa tì. "Amo sa, aworan orile-ede miiran ti o lo lati fi so ""itesiwaju"" naa, fo gbogbo re loju." "Àmọ́ ṣá, àwòrán orílẹ̀-èdè mìíràn tí ó lò láti fi sọ ""ìtẹ̀síwájú"" náà, fọ́ gbogbo rẹ̀ lójú." Aworan 3: Oro ikoriira eya tegbintegbin Àwòrán 3: Ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹ̀yà tẹ̀gbintẹ̀gbin Aworan 4: El-Rufai toro aforiji fun tuwiiti “ti o le da wahala sile” naa ti o wa n'nu Aworan 3. Àwòrán 4: El-Rufai tọrọ àforíjì fún túwíìtì “tí ó lè dá wàhálà sílẹ̀” náà tí ó wà ń'nú Àwòrán 3. Oro ikoriira eya tegbintegbin se yo ki ojo ibo o to ko, lasiko ibo ati leyin ibo. Ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹ̀yà tẹ̀gbintẹ̀gbin ṣẹ́ yọ kí ọjọ́ ìbò ó tó kò, lásìkò ìbò àti lẹ́yìn ìbò. Tuwiiti eleyameya kan (Aworan 3) Bashir El-Rufai, omo Alase Ipinle Kaduna, wi pe eya Igbo lo fi ibinu tan ina ote ti o fa Ogun Abelee Naijiria. Túwíìtì ẹlẹ́yàmẹyà kan (Àwòrán 3) Bashir El-Rufai, ọmọ Aláṣẹ Ìpínlẹ̀ Kaduna, wí pé ẹ̀yà Igbo ló fi ìbínú tan iná ọ̀tẹ̀ tí ó fa Ogun Abẹ́lée Nàìjíríà. Laaarin 1967 si 1970, orile-edee Naijiria ja ogun kikoro kan pelu iluu Biafra ti i se awon eya Igbo ti o wa ni apa ila-oorun guusu, ti o n gbero lati pin ya kuro labe isakoso ijoba Naijiria. Láàárín 1967 sí 1970, orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ja ogun kíkorò kan pẹ̀lú ìlúu Biafra tí í ṣe àwọn ẹ̀yà Igbo tí ó wà ní apá ìlà-oòrùn gúúsù, tí ó ń gbèrò láti pín yà kúrò lábẹ́ ìṣàkóso ìjọba Nàìjíríà. Sibe, gege bi Bashir El-Rufai ti se so, abajade ibo odun-un 2019 ti egbee re, APC, gbegba-oroke. O ye ki a ri i bii “esan” lati apa odo awon eya Hausa, Fulani. Síbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Bashir El-Rufai ti ṣe sọ, àbájáde ìbò ọdún-un 2019 tí ẹgbẹ́ẹ rẹ̀, APC, gbégbà-orókè. Ó yẹ kí a rí i bíi “ẹ̀san” láti apá ọ̀dọ̀ àwọn ẹ̀yà Hausa, Fulani. "O pada wa a toro aforiji, leyin ti a ti bu enu ate lu u, fun tuwiiti ""ti o le da wahala sile "" bi a ti ri i ninu Aworan." "Ó padà wá á tọrọ àforíjì, lẹ́yìn tí a ti bu ẹnu àtẹ́ lù ú, fún túwíìtì ""tí ó lè dá wàhálà sílẹ̀ "" bí a ti rí i nínú Àwòrán." Bakan naa ni o mu tuwiiti isokuso naa wale (Aworan 3). Bákan náà ni ó mú túwíìtì ìsọkúsọ náà wálẹ̀ (Àwòrán 3). Iroyin iro ti o ti ara eleyameya wa lori ero-alatagba lasiko ibo se e pin sabe eka meji: iroyin ti ko ni gbongbon ninu ati iroyin iro. Ìròyìn irọ́ tí ó ti ara ẹlẹ́yàmẹyà wá lórí ẹ̀rọ-alátagbà lásìkò ìbò ṣe é pín sábẹ́ ẹ̀ka méjì: ìròyìn tí kò ní gbọ́ngbọ́n nínú àti ìròyìn irọ́. "Miroslav Tudjman ati Nives Mikelic, omowe nipa itakuroso ni Ifafiti ti Zagreb, Croatia, tumo iroyin ti ko ni gbongbon ninu si ""iroyin amoomo tari sita lati si awon eniyan lokan""." "Miroslav Tudjman àti Nives Mikelic, ọ̀mọ̀wé nípa ìtàkùrọ̀sọ ní Ifáfitì ti Zagreb, Croatia, túmọ̀ ìròyìn tí kò ní gbọ́ngbọ́n nínú sí ""ìròyìn àmọ̀ọ́mọ̀ tari síta láti ṣi àwọn ènìyàn lọ́kàn""." Ete titari iroyin iro sita bi otito, lo ya iroyin ti o n sini lokan ati iroyin iro soto. Ète títari ìròyìn irọ́ síta bí òtítọ́, ló ya ìròyìn tí ó ń ṣini lọ́kàn àti ìròyìn irọ́ sọ́tọ́. Tudjman ati Mikelic so wipe ona itankale iroyin feju ju iroyin amoomo tari sita lati sini lokan tabi iroyin iro lo. Tudjman àti Mikelic sọ wípé ọ̀nà ìtànkálẹ̀ ìròyìn fẹ̀jú ju ìròyìn àmọ̀ọ́mọ̀ tari síta láti ṣini lọ́kàn tàbí ìròyìn irọ́ lọ. "Idi ni pe ona itankale iroyin ""maa n yi ihuwasi eni pada"" nipase ""isele airotele kan tabi igbese amoomo da lasiko itari itakuroso [naa] sita""." "Ìdí ni pé ọ̀nà ìtànkálẹ̀ ìròyìn ""máa ń yí ìhùwàsí ẹni padà"" nípasẹ̀ ""ìṣẹ̀lẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀ kan tàbí ìgbésẹ̀ àmọ̀ọ́mọ̀ dá lásìkò ìtari ìtàkùrọ̀sọ [náà] síta""." Bi iru eyi, ona itankale iroyin maa n tesi apa kan tabi aipe iroyin fun anfaani oro oselu ati yiyi ironu pada nipari. Bí irú èyí, ọ̀nà ìtànkálẹ̀ ìròyìn máa ń tẹ̀sí apá kan tàbí àìpé ìròyìn fún àǹfààní ọ̀rọ̀ òṣèlú àti yíyí ìrònú padà níparí. "Iberubojo okan be sile latari ibo odun-un 2019 nitori iroyin iro ati ona itankale iroyin n se agbedide aibale okan ti o ti oro ibo bere amo ti o n fa ""ideruba fun ipari-ija ti iboo ba kase nle ""." "Ìbẹ̀rùbojo ọkàn bẹ́ sílẹ̀ látàrí ìbò ọdún-un 2019 nítorí ìròyìn irọ́ àti ọ̀nà ìtànkálẹ̀ ìròyìn ń ṣe àgbédìde àìbalẹ̀ ọkàn tí ó ti ọ̀rọ̀ ìbò bẹ̀rẹ̀ àmọ́ tí ó ń fa ""ìdẹ́rùbà fún ìparí-ìjà tí ìbòó bá kásẹ̀ ńlẹ̀ ""." Apa keji aroko yii yoo se agbeyewo bi eyi se waye lori ayelujara, paapaa lorii gbagede Twitter, pelu awon apeere meloo kan. Apá kejì àròkọ yìí yóò ṣe àgbéyẹ̀wò bí èyí ṣe wáyé lórí ayélujára, pàápàá lóríi gbàgede Twitter, pẹ̀lú àwọn àpẹẹrẹ mélòó kan. Apileko yii je ara atejade iroyin onisisentele ti o n se agbeyewo isusi pelu eto ilo ero-ayarabiasa nipa awon ilana bii isanpa isasopo ero ayelukara-bi-ajere ati iroyin eleje lasiko eto iselu ti o pon dandan ni orile-ede meje ni Ile-Adulawo: Algeria, Ethiopia, Mozambique, Naijiria, Tunisia, Uganda, ati Zimbabwe. Àpilẹ̀kọ yìí jẹ́ ara àtẹ̀jádé ìròyìn oníṣísẹ̀ntẹ̀lé tí ó ń ṣe àgbéyẹ̀wò ìṣúsí pẹ̀lú ẹ̀tọ́ ìlò ẹ̀rọ-ayárabíàṣá nípa àwọn ìlànà bíi ìṣánpa ìṣàsopọ̀ ẹ̀rọ ayélukára-bí-ajere àti ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀ lásìkò ètò ìṣèlú tí ó pọn dandan ní orílẹ̀-èdè méje ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀: Algeria, Ethiopia, Mozambique, Nàìjíríà, Tunisia, Uganda, àti Zimbabwe. Africa Digital Rights Fund ati The Collaboration on International ICT Policy for East and Southern Africa (CIPESA) ni agbateru ise akanse yii. Africa Digital Rights Fund àti The Collaboration on International ICT Policy for East and Southern Africa (CIPESA) ni agbátẹrù iṣẹ́ àkànṣe yìí. Ni Kenya ati Ethiopia, awon okunrin wonyi riran ‘aworan-itona’ at'orun wa lati gbe iho nisale ile Ní Kenya àti Ethiopia, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ríran ‘àwòrán-ìtọ́nà’ àt'ọ̀run wá láti gbẹ́ ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ Awon okunrin mejeeji so wipe Olorun lo yo si awon Àwọn ọkùnrin méjèèjì sọ wípé Ọlọ́run ló yọ sí àwọn Iho nisale ilee Dunbar ni guusu Ethiopia ti Mohammed Yiso Banatah gbe jade pelu owoo re lai lo ohunkohun. Ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ẹ Dunbar ní gúúsù Ethiopia tí Mohammed Yiso Banatah gbẹ́ jáde pẹ̀lú ọwọ́ọ rẹ̀ láì lo ohunkóhun. Allah l'o pa a lase lati gbe ile Olorun fun eto igbeyawo sisale ile. Allah l'ó pa á láṣẹ láti gbẹ́ ilé Ọlọ́run fún ètò ìgbéyàwó sísàlẹ̀ ilẹ̀. Aworan lati owoo Amanda Leigh Lichtenstein, a fi ase lo o. Àwòrán láti ọwọ́ọ Amanda Leigh Lichtenstein, a fi àṣẹ lò ó. Lojo 26 osu Ope, BBC Swahili gbe aworan-atohun kan ti o se afihan-an Francisco Ouma, eni agba kan lati Busia, ila-oorunun Kenya, eni ti o gbo ohun Olorun lati gbe iho nisale ile jade. Lọ́jọ́ 26 oṣù Ọ̀pẹ, BBC Swahili gbé àwòrán-àtohùn kan tí ó ṣe àfihàn-an Francisco Ouma, ẹni àgbà kan láti Busia, ìlà-oòrùnun Kenya, ẹni tí ó gbọ́ ohùn Ọlọ́run láti gbẹ́ ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ jáde. Iran naa wa nipase aworan itona ti o ri loju awon alaa re. Ìran náà wá nípasẹ̀ àwòrán ìtọ́nà tí ó rí lójú àwọn àláa rẹ̀. Lati inu osu keji odun-un 1967, ni Ouma ti n to ipasee itona latorun wa naa ti o gba Ioju alaa re. Láti inú oṣù kejì ọdún-un 1967, ni Ouma ti ń tọ ipasẹ̀ẹ ìtọ́nà látọ̀run wá náà tí ó gbà Iójú àláa rẹ̀. Lonii, iho nisale ilee re ti ni yara 24 ti o si n le si i. Lónìí, ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ẹ rẹ̀ ti ní yàrá 24 tí ó sì ń lé sí i. Ageku aworan-an Francis Ouma, ti o gbo ohun Olorun lati gbe iho sisale ile ti o ni 24 iyara lorii BBC Swahili / Instagram. Àgékù àwòrán-an Francis Ouma, tí ó gbọ́ ohùn Ọlọ́run láti gbẹ́ ihò sísàlẹ̀ ilẹ̀ tí ó ní 24 ìyàrá lóríi BBC Swahili / Instagram. Lati ayebaye, opo eniyan lo ti ni ko si eri ti o daju wipe iran at'orun wa ni awon iru ala bawonyi, ti won n dejaa ilera opolo iru eni bee ti o pe oun riran loju ala. Láti ayébáyé, ọ̀pọ̀ ènìyàn ló ti ní kò sí ẹ̀rí tí ó dájú wípé ìran àt'ọ̀run wá ni àwọn irú àlá báwọ̀nyí, tí wọn ń dẹ́jàá ìlera ọpọlọ irú ẹni bẹ́ẹ̀ tí ó pé òún ríran lójú àlá. Amo awon ojise esin Imale, Juu ati Onigbagbo gbogboo ti jerii si iran lati odo Olorun ent ti o wa loju ala fun egbeegberun odun. Àmọ́ àwọn òjíṣẹ́ ẹ̀sìn Ìmàle, Júù àti Onígbàgbọ́ gbogboó ti jẹ́rìí sí ìran láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ent tí ó wá lójú àlá fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ọdún. """Olorun fi nnkankan bi aworan-itona han mi"", Ouma so fun BBC Swahili." """Ọlọ́run fi nǹkankan bí àwòrán-ìtọ́nà hàn mí"", Ouma sọ fún BBC Swahili." Nigba yen, nigba ti mo n wa ile, aworan-itona yii ni mo tele. Nígbà yẹn, nígbà tí mò ń wa ilẹ̀, àwòrán-ìtọ́nà yìí ni mo tẹ̀lé. Ki i se nigba ti mo n wale nikan, o dara ju ki n maa wale lo, rara. Kì í ṣe nígbà tí mò ń walẹ̀ nìkan, ó dára jù kí n máa walẹ̀ lọ, rárá. Itule ati owoo re mejeeji ni o lo, Ouma kan awon okuta abele ti ko mu iwale naa rorun fun un. Ìtúlẹ̀ àti ọwọ́ọ rẹ̀ méjèèjì ni ó lò, Ouma kan àwọn òkúta abẹ́lẹ̀ tí kò mú ìwalẹ̀ náà rọrùn fún un. Aseyinwa aseyinbo o ri ibi ti yoo ti mu aworan-itona iho nisale ilee Olorun ti o wa ni okan-an re wa si imuse. Àṣẹ̀yìnwá àṣẹ̀yìnbọ ó rí ibi tí yóò ti mú àwòrán-ìtọ́nà ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ẹ Ọlọ́run tí ó wà ní ọkàn-an rẹ̀ wá sí ìmúṣẹ. Ninu iyewu kan, o ni okuta kan ti a ko oroo Jesu si lara. Nínú ìyẹ̀wù kan, ó ní òkúta kan tí a kọ ọ̀rọ̀ọ Jésù sí lára. Jesu Kristi ni eni ti o mu iroyin yii wa fun mi, Ouma so, o si salayee re fun mi gege bi o ti se se fun Mose. Jésù Kristì ni ẹni tí ó mú ìròyìn yìí wá fún mi, Ouma sọ, ó sì ṣàlàyée rẹ̀ fún mi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ṣe fún Mósè. Ouma gbagbo wipe oun n mu majemu miiran pelu Olorun pada wa sile aye. Ouma gbàgbọ́ wípé òun ń mú májẹ̀mú mìíràn pẹ̀lú Ọlọ́run padà wá sílé ayé. Ipele keji n bo lona. Ìpele kejì ń bọ̀ lọ́nà. Eyi ni ipele akoko ti majemu naa. Èyí ni ìpele àkọ́kọ́ ti májẹ̀mú náà. Ikeji n bo lona. Ìkejì ń bọ̀ lọ́nà. Mi o lee so ni pato ohun ti yoo je bayii nitori bi mo ba kedee re, mo le maa yan iseda eda omo eniyan je. Mi ò leè sọ ní pàtó ohun tí yóò jẹ́ báyìí nítorí bí mo bá kédee rẹ̀, mo lè máa yan ìṣẹ̀dá ẹ̀dá ọmọ ènìyàn jẹ. Torii bee, mo maa duro fun ijabo naa bi o ba to asiko, Ouma wi fun BBC Swahili. Toríi bẹ́ẹ̀, mo máa dúró fún ìjábọ̀ náà bí ó bá tó àsìkò, Ouma wí fún BBC Swahili. Aworan-atohun-un BBC Swahili ti di wiwo fun igba 50,000 pelu esi ti o to 100 ti o si n le si i. Àwòrán-àtohùn-un BBC Swahili ti di wíwò fún ìgbà 50,000 pẹ̀lú èsì tí ó tó 100 tí ó sì ń lé sí í. Niwon-on bi awon kan ti so nipa ailera opolo awon t'o n so pe awon gbohun Olorun loju ala, ti opolopo esi adasi gbe leyin awon eni Olorun ti o so si iran oju ala. Níwọ̀n-ọn bí àwọn kan ti sọ nípa àìlera ọpọlọ àwọn t'ó ń sọ pé àwọn gbọ́hùn Ọlọ́run lójú àlá, tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ èsì àdásí gbè lẹ́yìn àwọn ẹni Ọlọ́run tí ó sọ sí ìran ojú àlá. Onloo Instagram kan ko: Òǹlòo Instagram kan kọ: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an Fun emi, awon eniyan bayii, mo maa n gba won gbo gidi gan-an, ju awon ti o maa n fi oro Olorun [ro] wa nile ijosin, fun odun 52 eeyan-an wa ile — bi ko ba tele okan-an re, se ko ye ki adugboo re ati ijoba o da a mo? Fún èmi, àwọn ènìyàn báyìí, mo máa ń gbà wọ́n gbọ́ gidi gan-an, ju àwọn tí ó máa ń fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run [rọ] wá nílé ìjọsìn, fún ọdún 52 èèyàn-án wa ilẹ̀ — bí kò bá tẹ̀lé ọkàn-an rẹ̀, ṣé kò yẹ kí àdúgbòo rẹ̀ àti ìjọba ó dá a mọ̀? Ko tile beere fun iranwo fun katakata tabi owo fun laalaaa re. A ko gbodo dajo eni yii. Kò tilẹ̀ béèrè fún ìrànwọ́ fún katakata tàbí owó fún làálàáa rẹ̀. A kò gbọdọ̀ dájọ́ ẹni yìí. Mohammed Yiso Banatah lodun-un 2012 salaye ala mewaa ti Allah yo si oun loju ala lati gbe ile Olorun fun igbeyawo sabe ile. Mohammed Yiso Banatah lọ́dún-un 2012 ṣàlàyé àlá mẹ́wàá tí Allah yọ sí òun lójú àlá láti gbẹ́ ilé Ọlọ́run fún ìgbéyàwó sábẹ́ ilẹ̀. Aworan lati owoo Amanda Leigh Lichtenstein. Àwòrán láti ọwọ́ọ Amanda Leigh Lichtenstein. Ile Olorun fun eto igbeyawo Ethiopia Ilé Ọlọ́run fún ètò ìgbéyàwó Ethiopia Ni guusu Ethiopia, eri ti o jora a wa lati agbalagba kan ti oruko re n je Mohammed Yiso Banatah, ti o ni lodun-un 2012 wipe Allah yo si oun ni odun 33 seyin loju ala leemewaa otooto. Ní gúúsù Ethiopia, ẹ̀rí tí ó jọra á wá láti àgbàlagbà kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mohammed Yiso Banatah, tí ó ní lọ́dún-un 2012 wípé Allah yọ sí òun ní ọdún 33 sẹ́yìn lójú àlá lẹ́ẹ̀mẹwàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Loju awon ala naa, o gbo ohun-un Allah lati gbe iho ile Olorun fun eto igbeyawo nisale ile. Lójú àwọn àlá náà, ó gbọ́ ohùn-un Allah láti gbẹ́ ihò ilé Ọlọ́run fún ètò ìgbéyàwó nísàlẹ̀ ilẹ̀. Iho nisale ilee Dunbar ni a mo o si, ile Olorun fenfe wonyi wa ni eba onaa Banatah ti i se ilaji onaa Hawassa ati Shashamene. Ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ẹ Dunbar ni a mọ̀ ọ́ sí, ilé Ọlọ́run fẹ̀nfẹ̀ wọ̀nyí wà ní ẹ̀bá ọ̀nàa Banatah tí í ṣe ìlàjì ọ̀nàa Hawassa àti Shashamene. Banatah so wipe ninu alaa re keta ni o ti ri awose fun awon ile Olorun wonyi. Banatah sọ wípé nínú àláa rẹ̀ kẹ́ta ni ó ti rí àwòṣe fún àwọn ilé Ọlọ́run wọ̀nyí. O le ka ekunrere akosile alaa Banatah ni sise-n-tele ati ohun ti o gun un ki o to bere ise iwale ayee re nibi: O lè ka ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àkọsílẹ̀ àláa Banatah ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé àti ohun tí ó gùn ún kí ó tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìwalẹ̀ ayée rẹ̀ níbí: Loju alaa asekagbaa re, eyi ti o je ikewaa ninu akosile onisisentele odun-un 1979, okunrin kan fara han ti o mu Mohammed lo si ibi igi kekere kan ninuu ogbaa re, o si toka si egboo re. Lójú àláa àsèkágbáa rẹ̀, èyí tí ó jẹ́ ìkẹwàá nínú àkọsílẹ̀ oníṣísẹ̀ntẹ̀lé ọdún-un 1979, ọkùnrin kan fara hàn tí ó mú Mohammed lọ sí ibi igi kékeré kan nínúu ọgbàa rẹ̀, ó sì tọ́ka sí egbòo rẹ̀. Okunrin naa fi oju ibi ti yoo ti bere iwale, o si tun so fun un pe lori ise iwale naa ni yoo ti la. Ọkùnrin náà fi ojú ibi tí yóò ti bẹ̀rẹ̀ ìwalẹ̀, ó sì tún sọ fún un pé lórí iṣẹ́ ìwalẹ̀ náà ni yóò ti là. Ni oganjo, o riran ri wura. Ní ọ̀gànjọ́, ó ríran rí wúrà. Agbegbe ti o sun mo jina, awon ohun ti o jina di fifa sun mo o. Agbègbè tí ó sún mọ́ jìnà, àwọn ohun tí ó jìnà di fífà sún mọ́ ọ. A so ibi ti yoo ti bere iwale, igba ti yo bere ati bi yoo se bere . A sọ ibi tí yóò ti bẹ̀rẹ̀ ìwalẹ̀, ìgbà tí yó bẹ̀rẹ̀ àti bí yóò ṣe bẹ̀rẹ̀ . Lojo keji, nigba ti o laju saye, o bere sii gbele pelu owoo re nikan lai lo itule. Lọ́jọ́ kejì, nígbà tí ó lajú sáyé, ó bẹ̀rẹ̀ síí gbẹ́lẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ọ rẹ̀ nìkan láì lo ìtúlẹ̀. Iho nisale ile ti imole oorun tan sinuu re wonyi ti di ibi igbafe olowo kekere fun awon eeyan lati se irinse maili merin labe ile ti o pa lolo. Ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ tí ìmọ́lẹ̀ oòrùn tán sínúu rẹ̀ wọ̀nyí ti di ibi ìgbafẹ́ olówó kékeré fún àwọn èèyàn láti ṣe ìrinsẹ̀ máìlì mẹ́rin lábẹ́ ilẹ̀ tí ó pa lọ́lọ́. Awon afesona kan ti se eto igbeyawo nibe. Àwọn àfẹ́sọ́nà kan ti ṣe ètò ìgbéyàwó níbé. Bi a se ko awon iyewu wonyi fi ise opolo ati itu owoo Mohammed han – o ti fi ifarabale lo opolopo wakati fun gbigbe, didan, ati sise ise ona si gbogbo kolofin inu iyara ati ogiri, pelu awon timutimu, ati pepe ti a fi iyepe mo ninuu re, ti awon yara miiran ni ferese ti imole oorun n tan gba lati ibi ti enikan ko mo. Bí a ṣe kọ́ àwọn ìyẹ̀wù wọ̀nyí fi iṣẹ́ ọpọlọ àti itú ọwọ́ọ Mohammed hàn – ó ti fi ìfarabalẹ̀ lọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ wákàtí fún gbígbẹ́, dídán, àti ṣíṣe iṣẹ́ ọnà sí gbogbo kọ́lọ́fín inú iyàrá àti ògiri, pẹ̀lú àwọn tìmùtìmù, àti pẹpẹ tí a fi iyẹ̀pẹ̀ mọ nínúu rẹ̀, tí àwọn yàrá mìíràn ní fèrèsé tí ìmọ́lẹ̀ oòrùn ń tàn gbà láti ibi tí ẹnìkan kò mọ̀. Lati ayebaye ni iho nisale ile ti je ibi apeere ti a ka si gege bi ibi ti emi. Láti ayébáyé ni ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ ti jẹ́ ibi àpẹẹrẹ tí a kà sí gẹ́gẹ́ bí ibi ti ẹ̀mí. "Odindin iwe kan gbako ti a pe ni ""Al Kahf"" tabi ""Iho nisale ile "" jeyo ninuu iwe mimoo Kuran." "Odindin ìwé kan gbáko tí a pè ní ""Al Kahf"" tàbí ""Ihò nísàlẹ̀ ilẹ̀ "" jẹyọ nínúu ìwé mímọ́ọ Kuran." "Ninuu re ni a ti ba itan Esin igbagbo kan ti a mo si ""Awon eni Iho-okuta"", which ninu eyi ti awon odo, jiya aise nitori igbagboo won sa kuro niluu, won si wa ibi iho-okuta kan sun si." "Nínúu rẹ̀ ni a ti bá ìtàn Ẹ̀sìn ìgbàgbọ́ kan tí a mọ̀ sí ""Àwọn ẹni Ihò-òkúta"", which nínú èyí tí àwọn ọ̀dọ́, jìyà àìṣẹ̀ nítorí ìgbàgbọ́ọ wọ́n sá kúrò nílùú, wọ́n sì wá ibi ihò-òkúta kan sùn sí." Nigba ti won ji, won pada sile, won si sakiyesi wipe gbogbo omo ilu ti di onigbagbo. Nígbà tí wọ́n jí, wọ́n padà sílé, wọ́n sì ṣàkíyèsí wípé gbogbo ọmọ ìlú ti di ònígbàgbọ́. Kini idi ire ti Donald Trump se l'okiki ni Naijiria? Kíni ìdí irẹ̀ tí Donald Trump ṣe l'ókìkí ní Nàìjíríà? Trump ni opolopo ololufe ni guusu orile-edee Naijiria Trump ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ olólùfẹ́ ní gúúsù orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà Aare Donald Trump pada si Ile Agbara Funfun ni Washington lojo 19 osu Ogun, odun-un 2018. Ààrẹ Donald Trump padà sí Ilé Agbára Funfun ní Washington lọ́jọ́ 19 oṣù Ògún, ọdún-un 2018. Aworan lati owoo Samira Bouaou/The Epoch Times, CC BY 2.0. Àwòrán láti ọwọ́ọ Samira Bouaou/The Epoch Times, CC BY 2.0. Aare orile-edee Amerika Donald Trump ti re si ipo isale loju awon eniyan kari aye latari awon ofin re ati bi o se n se isakoso oran ti o je mo orile-edee okeere — amo ko ri bee ni awon orile-ede bii Naijiria. Ààrẹ orílẹ̀-èdèe Amẹ́ríkà Donald Trump ti ré sí ipò ìsàlẹ̀ lójú àwọn ènìyàn kárí ayé látàrí àwọn òfin rẹ̀ àti bí ó ṣe ń ṣe ìṣàkóso ọ̀ràn tí ó jẹ mọ́ orílẹ̀-èdèe òkèèrè — àmọ́ kò rí bẹ́ẹ̀ ní àwọn orílẹ̀-èdè bíi Nàìjíríà. "Ni ko pe ko pe yii ni iwadii ayewo ti Pew Research Centre sagbateruu re fi han wipe ogoro omo Naijiria ""fi Ogun-un re gbari"" wipe Trump ""yoo gbe igbese ti o laamilaka nipa ti oran agbaye""." "Ní kò pẹ́ kò pẹ́ yìí ni ìwádìí àyẹ̀wò tí Pew Research Centre ṣagbátẹrùu rẹ̀ fi hàn wípé ọ̀gọ̀rọ̀ ọmọ Nàìjíríà ""fi Ògún-un rẹ̀ gbárí"" wípé Trump ""yóò gbé ìgbésẹ̀ tí ó lààmìlaka nípa ti ọ̀ràn àgbáyé""." Ori ero-ibanisoro ati iforowanilenuwo ojukoroju ni Gallup – ileese asagbeyewo finnifinni ati ileese oludamoran ti o wa ni Washington, DC fi gba esi jo ninu iwadii ayewo ero awon eniyan-an fun Pew. Orí ẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ àti ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò ojúkorojú ni Gallup – iléeṣẹ́ aṣàgbéyẹ̀wò fínnífínní àti iléeṣẹ́ olùdámọ̀ràn tí ó wà ní Washington, DC fi gba èsì jọ nínú ìwádìí àyẹ̀wò èrò àwọn ènìyàn-an fún Pew. Agbeyewo Tweepsmap kan ti o da lorii iye awon ti o n tele Trump lorii ero alatagba Twitter se ofofo wipe ipo karun-un ni Naijiria duro si ninu awon orile-ede marun-un lagbaaye: Àgbéyẹ̀wò Tweepsmap kan tí ó dá lóríi iye àwọn tí ó ń tẹ̀lé Trump lóríi ẹ̀rọ alátagbà Twitter ṣe òfófó wípé ipò karùn-ún ni Nàìjíríà dúró sí nínú àwọn orílẹ̀-èdè márùn-ún lágbàáyé: "Onkowe ti i se omo bibi orile-edee Naijiria Adaobi Tricia Nwaubani ladii re fun agbaye lori eto ero agbohunsafefe kan ti o je abasepo pelu BBC, wipe irisii Trump gege bi ""okunrin alagidi"" mu ki awon omo orile-ede ti o kun fun eniyan ju lo ni Ile-Adulawo o feran-an re de gongo:" "Òǹkọ̀wé tí í ṣe ọmọ bíbí orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà Adaobi Tricia Nwaubani làdíi rẹ̀ fún àgbáyé lórí ètò ẹ̀rọ agbóhùnsáfẹ́fẹ́ kan tí ó jẹ́ àbáṣepọ̀ pẹ̀lú BBC, wípé ìrísíi Trump gẹ́gẹ́ bí ""ọkùnrin alágídí"" mú kí àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè tí ó kún fún ènìyàn jù lọ ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ó fẹ́ràn-an rẹ̀ dé góńgó:" Awon eniyan feran-an ihuwasi alagidii re ati pe aiforo sabe ahon-on re dun un gbo seti. Àwọn ènìyàn fẹ́ràn-an ìhùwàsí alágídíi rẹ̀ àti pé àìfọ̀rọ̀ sábẹ́ ahọ́n-ọn rẹ̀ dùn ún gbọ́ sétí. Awon omo Amerika ri i bi akanda eniyan. Àwọn ọmọ Amẹ́ríkà rí i bí àkàndá ènìyàn. Ihuwasii re ko ba taye mu. Ìhùwàsíi rẹ̀ kò bá tayé mu. Ki i se eni ti won so pe o je. Kì í ṣe ẹni tí wọ́n sọ pé ó jẹ́. Amo iru olori ti ki i lora soro bi o ti wu u ko je tuntun si wa. Àmọ́ irú olórí tí kì í lọ́ra sọ̀rọ̀ bí ó ti wù ú kò jẹ́ tuntun sí wa. Tori idi eyi, ihuwasii re ko baje to bee bi awon omo Amerika se n ri i. Torí ìdí èyí, ìhùwàsíi rẹ̀ kò bàjẹ́ tó bẹ́ẹ̀ bí àwọn ọmọ Amẹ́ríkà ṣe ń rí i. Idi miiran ni esin. Ìdí mìíràn ni ẹ̀sìn. Awon Omo leyin-in Kristi nifeee Trump Àwọn Ọmọ lẹ́yìn-in Krístì nífẹ̀ẹ́ẹ Trump Cheta Nwanze, Olori Iwadii ni SBM Intelligence so fun Ohun Agbaye: Cheta Nwanze, Olórí Ìwádìí ní SBM Intelligence sọ fún Ohùn Àgbáyé: O hun mi lati mo IBI ti won ti se iwadii-ayewo yii ni Naijiria. Ó hùn mí láti mọ IBI tí wọ́n ti ṣe ìwádìí-àyẹ̀wò yìí ní Nàìjíríà. Mo mo daju wipe ki i se karii guusu orile-edee Naijiria, ti o salaye ife ti omo Naijiria ni si Trump. Mo mọ̀ dájú wípé kì í ṣe káríi gúúsù orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, tí ó ṣàlàyé ìfẹ́ tí ọmọ Nàìjíríà ní sí Trump. Opo ninu awon ololufee re l'o je Onigbagbo, ti won n gboju soke wo o bi awokose rere. Ọ̀pọ̀ nínú àwọn olólùfẹ́ẹ rẹ̀ l'ó jẹ́ Onígbàgbọ́, tí wọ́n ń gbójú sókè wò ó bí àwòkọ́ṣe rere. Naijiria, pelu iye eniyan ilu ti o to egbeegberun 200 eeyan, ni esin meji ti awon eniyan-an n se ju: esin Igbagbo ati Imale. Nàìjíríà, pẹ̀lú iye ènìyàn ìlú tí ó tó ẹgbẹẹgbẹ̀rún 200 èèyàn, ní ẹ̀sìn méjì tí àwọn ènìyàn-án ń ṣe jù: ẹ̀sìn Ìgbàgbọ́ àti Ìmàle. Imale ati Igbagbo ko ida 50 ati ida 48 iye gbogbo eniyan t'o n gbe Naijiria. Ìmàle àti Ìgbàgbọ́ kó ìdá 50 àti ìdá 48 iye gbogbo ènìyàn t'ó ń gbé Nàìjíríà. "Ilana iwadii naa fi han wipe ""ileese ijoba Ipinle ti won si pin awon eniyan si agbegbe"" ni won ti se iwadii ayewo yii." "Ìlànà ìwádìí náà fi hàn wípé ""iléeṣẹ́ ìjọba Ìpínlẹ̀ tí wọ́n sì pín àwọn ènìyàn sí agbègbè"" ni wọ́n ti ṣe ìwádìí àyẹ̀wò yìí." Bi o ti wu kio ri, ko si ohun awon Adamawa, Borno, ati ipinle Yobe ni ariwa ila-oorun Naijiria ninu abajade iwadii naa nitori oro aabo. Bí ó ti wù kíó rí, kò sí ohùn àwọn Adamawa, Borno, àti ìpínlẹ̀ Yobe ní àríwá ìlà-oòrùn Nàìjíríà nínú àbájáde ìwádìí náà nítorí ọ̀rọ̀ ààbò. Naijiria ni ijoba ibile 774, ti i se eka alase ijoba ibile. Bakan naa ni o ni eka akoso mefaa. Nàìjíríà ní ìjọba ìbílẹ̀ 774, tí í ṣe ẹ̀ka aláṣẹ ìjọba ìbílẹ̀. Bákan náà ni ó ní ẹ̀ka àkóso mẹ́fàá. Aarin gbungbun Ariwa, Ariwa Ila-oorun, Ariwa Iwo-oorun, Ajindo-guusu, Iwo-oorun guusu, ati Ila-oorunun guusu. Àárín gbùngbùn Àríwá, Àríwá Ìlà-oòrùn, Àríwá Ìwọ̀-oòrùn, Àjìǹdò-gúúsù, Ìwọ̀-oòrùn gúúsù, àti Ìlà-oòrùnun gúúsù. Oroo Nwanze pe awon Onigbagbo ni guusu Naijiria lo po ju lo ninu iwadii ayewo Pew Research ko se e ma gbagbo. Ọ̀rọ̀ọ Nwanze pé àwọn Onígbàgbọ́ ní gúúsù Nàìjíríà ló pọ̀ jù lọ nínú ìwádìí àyẹ̀wò Pew Research kò ṣe é má gbàgbọ́. "Iwadii ayewo naa tun fi han pe opo omo leyin Kristi ni Naijiria ""ri orile-edee US bi ilu ti o dara (ida 69) ju bi awon Imale se ri i lo (ida 54)""." "Ìwádìí àyẹ̀wò náà tún fi hàn pé ọ̀pọ̀ ọmọ lẹ́yìn Krístì ní Nàìjíríà ""rí orílẹ̀-èdèe US bí ìlú tí ó dára (ìdá 69) ju bí àwọn Ìmàlé ṣe rí i lọ (ìdá 54)""." "Leyin ti orile-edee Amerika pa Ogagun omo Iran Qasem Soleimani, oga olopaa te ikede isora eni jakejado orile-edee Naijiria jade ki o ba ti ilekun ""ogun""." "Lẹ́yìn tí orílẹ̀-èdèe Amẹ́ríkà pa Ọ̀gágun ọmọ Iran Qasem Soleimani, ọ̀gá ọlọ́pàá tẹ ìkéde ìṣọ́ra ẹni jákèjádò orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà jáde kí ó ba ti ilẹ̀kùn ""ogun""." "Egbe Esin Imale ni Naijiria sapejuwe iku oro ojo ota ibon lati oke wa ti US fi pa Soleimani gege bi ""ipe ogun si Iran""." "Ẹgbẹ́ Ẹ̀sìn Ìmàle ní Nàìjíríà ṣàpèjúwe ikú oró òjò ọta ìbọn láti òkè wá tí US fi pa Soleimani gẹ́gẹ́ bí ""ìpè ogun sí Ìran""." A ti se apejuwe Trump gege bi “okan lara awon olori agbaye saa ti a wa yii ti o ni okan lile.” A ti ṣe àpèjúwe Trump gẹ́gẹ́ bí “ọ̀kan lára àwọn olórí àgbáyé sáà tí a wà yìí tí ó ní ọkàn líle.” Sibe, opo omo Naijiria lo feran-an Trump. Síbẹ̀, ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ló fẹ́ràn-an Trump. Twitter di papa iroyin ayederu lasiko Idibo odun-un 2019 ni Naijiria Twitter di pápá ìròyìn ayédèrú lásìkò Ìdìbò ọdún-un 2019 ní Nàìjíríà Oro Ikoriira Eya ati Ayederu Iroyin tan ka lori Twitter Ọ̀rọ̀ Ìkórìíra Ẹ̀yà àti Ayédèrú Ìròyìn tàn ká lórí Twitter Atopo aworan lati owo Nwachukwu Egbunike Àtòpọ̀ àwòrán láti ọwọ́ Nwachukwu Egbunike Eyi ni apa keji iroyin ninu akosile eleka meji lori oro ikoriira eya lori ayelujara, iroyin ayederu ati isokiri lasiko idibo odun-un 2019 lorile-edee Naijiria. Èyí ni apá kejì ìròyìn nínú àkọsílẹ̀ ẹlẹ́ka méjì lórí ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹ̀yà lórí ayélujára, ìròyìn ayédèrú àti ìsọkiri lásìkò ìdìbò ọdún-un 2019 lórílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. O le ka apa kiini nibi. O lè ka apá kìíní níbí. Ni orile-edee Naijiria, awujo ibanisoro ori ayelujara je ibi ti iroyin itakora-eya tegbintegbin ati isokiri ti maa n gbile bii seleru lasiko idibo. Ní orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, àwùjọ ìbánisọ̀rọ̀ orí ayélujára jẹ́ ibi tí ìròyìn ìtakora-ẹ̀yà tẹ̀gbintẹ̀gbin àti ìsọkiri ti máa ń gbilẹ̀ bíi ṣẹ́lẹ̀rú lásìkò ìdìbò. Ni asiko idibo odun-un 2015, Twitter Naijiria ko si ija ati isoro-takora laaarin awon alatileyin oludije-dupo mejeeji ti o lero leyin ju lo lasiko naa, iyen Goodluck Jonathan (omo egbee PDP ti o je kirisiteni ati omo Ijaw) ati Muhammadu Buhari (omo egbe APC ti o je Musulumi ati omo Hausa-Fulani). Ní àsìkò ìdìbò ọdún-un 2015, Twitter Nàìjíríà kó sí ìjà àti ìsọ̀rọ̀-takora láàárín àwọn alátilẹyìn olùdíje-dupò méjèèjì tí ó lérò lẹ́yìn jù lọ lásìkò náà, ìyẹn Goodluck Jonathan (ọmọ ẹgbẹ́ẹ PDP tí ó jẹ́ kìrìsìtẹ́nì àti ọmọ Ijaw) àti Muhammadu Buhari (ọmọ ẹgbẹ́ APC tí ó jẹ́ Mùsùlùmí àti ọmọ Hausa-Fulani). Tuwita di ohun elo fun isokiri oro ikoriira eya ati oro egbe oselu. Túwítà di ohun èlò fún ìsọkiri ọ̀rọ̀ ìkórìíra ẹ̀yà àti ọ̀rọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú. Asiko idibo odun 2019 o yato rara. Àsìkò ìdìbò ọdún 2019 ò yàtọ̀ rárá. "Ni ojo 15, osu Erele egbe Ajabo Iroyin Laisi Ala (RSF) se akosile kan ti o n se afihan eroo won lori ipolongo idibo ti ""iroyin ayederu ti mu baje ""." "Ní ọjọ́ 15, oṣù Èrèlé ẹgbẹ́ Ajábọ̀ Ìròyìn Láìsí Àlà (RSF) ṣe àkọsílẹ̀ kan tí ó ń ṣe àfihàn èròo wọn lórí ìpolongo ìdìbò tí ""ìròyìn ayédèrú ti mú bàjẹ́ ""." Awon omo orile-edee Naijiria naa fi eroo won han. Àwọn ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà náà fi èròo wọn hàn. Akoroyin Abdulbaqi Jari tuwiiti pe: Akọ̀ròyìn Abdulbaqi Jari túwíìtì pé: Iroyin ayederu ati iselu ni awon orile-ede ile Adulawo Ìròyìn ayédèrú àti ìṣèlú ní àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ Adúláwọ̀ "Iwadii odun-un 2019 kan lati owo Dani Madrid-Morales ni Ile-eko giga Huston ati Herman Wasserman ni ile-eko giga Cape Town fenuko pe ""iroyin iro ati iroyin ayederu ni won ti maa n lo lati fi mu ife-inu awon oloselu se"" ni orile-edee Naijiria, Kenya ati South Africa." "Ìwádìí ọdún-un 2019 kan láti ọwọ́ Dani Madrid-Morales ní Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Huston àti Herman Wasserman ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga Cape Town fẹnukò pé ""ìròyìn irọ́ àti ìròyìn ayédèrú ni wọ́n ti máa ń lò láti fi mú ìfẹ́-inú àwọn olóṣèlú ṣẹ"" ní orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, Kenya àti South Africa." "Opo Iroyin ayederu lori awon awujo ibanisoro ori ayelujara paapaa lasiko ipolongo ibo maa n fa ""aigbara-eni-gbo "" laaarin awon ti won n lo awujo ibanisoro ori ayelujara ""nitori pe ibe ni won ti n ri 'iroyin ayederu' lopo igba"", Madrid-Morales soro." "Ọ̀pọ̀ Ìròyìn ayédèrú lórí àwọn àwùjọ ìbánisọ̀rọ̀ orí ayélujára pàápàá lásìkò ìpolongo ìbò máa ń fa ""àìgbara-eni-gbọ́ "" láàárín àwọn tí wọ́n ń lo àwùjọ ìbánisọ̀rọ̀ orí ayélujára ""nítorí pé ibẹ̀ ni wọ́n ti ń rí 'ìròyìn ayédèrú' lọ́pọ̀ ìgbà"", Madrid-Morales sọ̀rọ̀." Iwadii mi lori oniruuru eya laaarin ojo 28, osu Owara odun-un 2018 ati ojo 29 osu Ebibi, odun-un 2019 lori idibo odun-un 2019 lorile-edee Naijiria to waye ni ojo 23, osu Erele (lati dibo yan aare ati asofin si ile igbimo asofin ti orile-ede) ati ojo 9, osu Erena (lati yan gomina ati asofin si ile-igbimo asofin ti ijoba ipinle) se afihan isele iroyin ayederu meji pataki kan: iroyin ayederu to tako eya kan ati isokiri lati mu ero inu awon oloselu se. Ìwádìí mi lórí onírúurú ẹ̀yà láàárín ọjọ́ 28, oṣù Ọ̀wàrà ọdún-un 2018 àti ọjọ́ 29 oṣù Èbìbí, ọdún-un 2019 lórí ìdìbò ọdún-un 2019 lórílẹ̀-èdèe Nàìjíríà tó wáyé ní ọjọ́ 23, oṣù Èrèlé (láti dìbò yan ààrẹ àti aṣòfin sí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ti orílẹ̀-èdè) àti ọjọ́ 9, oṣù Erénà (láti yan gómìnà àti aṣòfin sí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ti ìjọba ìpínlẹ̀) ṣe àfihàn ìṣẹ̀lẹ̀ ìròyìn ayédèrú méjì pàtàkì kan: ìròyìn ayédèrú tó tako ẹ̀yà kan àti ìsọkiri láti mú èrò inú àwọn olóṣèlú ṣẹ. Iroyin Ayederu to tako eya Ìròyìn Ayédèrú tó tako ẹ̀yà Peter Obi, igba keji Atiku Abubakar ti o je ondije-dupo egbe oselu (PDP) je eni ti o doju ko ipalara iroyin ayederu to tako eya lasiko idibo to koja. Peter Obi, igbá kejì Atiku Abubakar tí ó jẹ́ òǹdíje-dupò ẹgbẹ́ òṣèlú (PDP) jẹ́ ẹni tí ó dojú kọ ìpalára ìròyìn ayédèrú tó tako ẹ̀yà lásìkò ìdìbò tó kọjá. Obi je gomina igba kan ri ni ipinle Anambra ni guusu-ila oorun Naijiria. Obi jẹ́ gómìnà ìgbà kan rí ní ìpínlẹ̀ Anambra ní gúúsù-ìlà oòrùn Nàìjíríà. Ikanni Tuwita kan ti o n se atileyin ipolongo fun Buhari-Osinbajo, Coalition of Buhari-Osinbajo Movement pin Tuwiiti kan (Atoka 1) ti o n fesun kan Obi pe o “le awon ara ariwa orile-edee Naijiria kuro ni ipinle Anambra nigba ti o je gomina. Ìkànni Túwítà kan tí ó ń ṣe àtìlẹyìn ìpolongo fún Buhari-Osinbajo, Coalition of Buhari-Osinbajo Movement pín Túwíìtì kan (Atọ́ka 1) tí ó ń fẹ̀sùn kan Obi pé ó “lé àwọn ará àríwá orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà kúrò ní ìpínlẹ̀ Anambra nígbà tí ó jẹ́ gómìnà. Aworan 1: Aworan Tuwiiti kan lati owo Coalition of Buhari-Osibanjo Movement ti o n fesun kan obi pe o se ‘idapada’ awon ara ariwa si iluu won. Àwòrán 1: Àwòrán Túwíìtì kan láti ọwọ́ Coalition of Buhari-Osibanjo Movement tí ó ń fẹ̀sùn kan òbí pé ó ṣe ‘ìdápadà’ àwọn ará àríwá sí ìlúu wọn. Atoka 2: Aworan Tuwiiti kan lati owo Nasir El-Rufia Atọ́ka 2: Àwòrán Túwíìtì kan láti ọwọ́ Nasir El-Rufia "Gomina ipinle-e Kaduna ati omo egbe oselu ti o n se ijoba lowo, Nasir El-Rufai, mu esun yii rinle si i, o tuwiiti (Atoka 2) pe Obi je ""eni ti o n se iyatooto eya""." "Gómìnà ìpínlẹ̀-ẹ Kaduna àti ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú tí ó ń ṣè ìjọba lọ́wọ́, Nasir El-Rufai, mú ẹ̀sùn yìí rinlẹ̀ sí i, ó túwíìtì (Atọ́ka 2) pé Obi jẹ́ ""ẹni tí ó ń ṣe ìyàtọ̀ọ̀tọ̀ ẹ̀yà""." Ohun ti El-Rufai so yii o mu ki ipo igbakeji aare to fun Obi. Ohun tí El-Rufai sọ yìí ò mú kí ipò igbákejì ààrẹ tọ́ fún Obi. Ka si i: Gomina kan ni Naijiria kilo fun ijoba ile okeere: E da si oro idibo wa ki 'e pada si ilu yin ni oku' Kà sí i: Gómìnà kan ní Nàìjíríà kìlọ̀ fún ìjọba ilẹ̀ òkèèrè: Ẹ dá sí ọ̀rọ̀ ìdìbò wa kí 'ẹ padà sí ìlú yín ní òkú' Ki ni ohun ti o sele gan-an? Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ gan-an? "Ile-ise iwe iroyin Vanguard jabo wipe ni osu Agemo odun-un 2013, omo Naijiria 67 ti opolopo won wa lati ile-e Igbo ni ""won da pada lati Eko ti won si pa won ti si ibi kan naa ni agbegbe Upper Iweka"" ti o gbajumo ni Onitsha, Ipinle Anambra." "Ilé-iṣẹ́ ìwé ìròyìn Vanguard jábọ̀ wípé ní oṣù Agẹmọ ọdún-un 2013, ọmọ Nàìjíríà 67 tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn wá láti ilẹ̀-ẹ Igbo ni ""wọ́n dá padà láti Èkó tí wọ́n sì pa wọ́n tì sí ibi kan náà ní agbègbè Upper Iweka"" tí ó gbajúmọ̀ ní Onitsha, Ìpínlẹ̀ Anambra." "Obi, ti o je gomina ipinle Anambra ni igba naa, sapejuwe ihuwasi yii ti akegbe-e ‘e Tunde Fasola ni ipinle Eko hu gege bi ""ohun ti ko ba ofin mu ati irufin eto omoniyan awon eni ti o di ero iluu won""." "Obi, tí ó jẹ́ gómìnà ìpínlẹ̀ Anambra ní ìgbà náà, ṣàpèjúwe ìhùwàsí yìí tí akẹgbẹ́-ẹ ‘ẹ̀ Túndé Fáṣọlá ní ìpínlẹ̀ Èkó hù gẹ́gẹ́ bí ""ohun tí kò bá òfin mu àti ìrúfin ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn àwọn ẹni tí ó di èrò ìlúu wọn""." Leyin ibinuu gbogboogbo ti oro yii fa, Premium Times jabo pe Obi naa jebi iru oro bee: Lẹ́yìn ìbínúu gbogboògbò tí ọ̀rọ̀ yìí fà, Premium Times jábọ̀ pé Obi náà jẹ̀bi irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀: Ni 2011, o le awon atorobara to je omode pada si ipinle Ebonyi ati Akwa Ibom, ni apa guusu orile-edee Naijiria. Ní 2011, ó lé àwọn atọrọbárà tó jẹ́ ọmọdé padà sí ìpínlẹ̀ Ebonyi àti Akwa Ibom, ní apá gúúsù orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Atoka 3: Aworan Tuwiiti kan lati owo Jubril A. Gawat Atọ́ka 3: Àwòrán Túwíìtì kan láti ọwọ́ Jubril A. Gawat Nigba ti Obi da awon onibara pada si awon ipinle ni Guusu Naijiria loooto, ko le awon ara Ariwa, esun ti isamulo-o Twitter egbe alatileyin-in Coalition of Buhari-Osinbajo Movement tuwiiti (Atoka 1) ko gun rege. Nígbà tí Obi dá àwọn oníbárà padà sí àwọn ìpínlẹ̀ ní Gúúsù Nàìjíríà lóòótọ́, kò lé àwọn ará Àríwá, ẹ̀sùn tí ìṣàmúlò-o Twitter ẹgbẹ́ alátìlẹ́yìn-in Coalition of Buhari-Osinbajo Movement túwíìtì (Atọ́ka 1) kò gún régé. "Koda Tunde Fasola ti egbe APC ni o ""se idapada awon ara Ariwa 70 si ipinle-e Kano nitori won toro bara"" gege bi iwe iroyin asewadii lori ayelujara Sahara Reporters se jabo." "Kódà Túndé Fáṣọlá ti ẹgbẹ́ APC ni ó ""ṣe ìdápadà àwọn ará Àríwá 70 sí ìpínlẹ̀-ẹ Kano nítorí wọ́n tọrọ bárà"" gẹ́gẹ́ bí ìwé ìròyìn aṣèwádìí lórí ayélujára Sahara Reporters ṣẹ jábọ̀." Bee awon agbeseyin egbe oselu APC ni won samulo iroyin ayederu to tako eya kan yii lati fi bu enu ate lu ondije-dupo labe asia egbe to tako egbee won. Bẹ́ẹ̀ àwọn agbèsẹ́yìn egbẹ́ òṣèlú APC ni wọ́n ṣàmúlò ìròyìn ayédèrú tó tako ẹ̀yà kan yìí láti fi bu ẹnu àtẹ́ lu òǹdíje-dupò lábẹ́ àsíá ẹgbẹ́ tó tako ẹ̀gbẹ́ẹ wọn. Fun apeere, Jubril Gawat ti won sese yan sipo aseranwo Gomina pataki lori ero igberoyinjade igbalode tuntun tuwiiti pe (Atoka 3) ibo kan fun ondije-dupo egbe atako Atiku Abubakar “je ibo fun eya Igbo.” Fún àpẹẹrẹ, Jubril Gawat tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ yàn sípò aṣèrànwọ́ Gómìnà pàtàkì lórí ẹ̀rọ ìgbéròyìnjáde ìgbàlódé tuntun túwíìtì pé (Atọ́ka 3) ìbò kan fún òǹdíje-dupò ẹgbẹ́ atako Atiku Abubakar “jẹ́ ìbò fún ẹ̀yà Igbo.” Naijiria je orile-ede kan ti oro eya ti rinle gan-an. Nàìjíríà jẹ́ orílẹ̀-èdè kan tí ọ̀rọ̀ ẹ̀yà ti rinlẹ̀ gan-an. "Awon oloselu si maa n sa eyameya yii bi oogun ni asiko idibo nitori won maa n nilo lati pin awon eniyan si egbe “awa” pelu ""won""." "Àwọn olóṣèlú sì máa ń sa ẹ̀yàmẹyà yìí bí oògùn ní àsìkò ìdìbò nítorí wọ́n máa ń nílò láti pín àwọn ènìyàn sí ẹgbẹ́ “àwa” pẹ̀lú ""wọn""." Nitori naa, won ni i lokan lati fi esun ti won fi kan Obi pe o le awon ara Ariwa pada si ilu won ru inunibini ti o ti wa tele laaarin eya Igbo ati Hausa ti o fa Ogun Abelee Naijiria. Nítorí náà, wọ́n ní í lọ́kàn láti fi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Obi pé ó lé àwọn ará Àríwá padà sí ìlú wọn rú inúnibíni tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ láàárín ẹ̀yà Igbo àti Hausa tí ó fa Ogun Abẹ́lée Nàìjíríà. Erongba won pelu ipolongo awon iroyin ayederu yii ni lati se afihan Obi gege bi ajijangbara fun eya Biafra. Èròǹgbà wọn pẹ̀lú ìpolongo àwọn ìròyìn ayédèrú yìí ni láti ṣe àfihàn Obi gẹ́gẹ́ bí ajìjàǹgbara fún ẹ̀yà Biafra. Eya to wa ni Guusu-iwo oorun Naijiria, ti opolopo won je omo Igbo gbiyanju lati ya kuro lara orile-ede nipase ogun abele ti o waye fun odun meta laaarin odun 1967 si 1970. Ẹ̀yà tó wà ní Gúúsù-ìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà, tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn jẹ́ ọmọ Igbo gbìyànjú láti ya kúrò lára orílẹ̀-èdè nípasẹ̀ ogun abẹ́lé tí ó wáyé fún ọdún mẹ́ta láàárín ọdún 1967 sí 1970. "Fun idi eyi, won ni i lokan lati lo akosile inu atoka 3 ti o so pe ""Ibo kan fun Atiku je ibo fun eya Igbo..."" fi ji oku ikoriira eya tegbintegbin ti o ti wa laaarin eya Hausa ati Igbo." "Fún ìdí èyí, wọ́n ní í lọ́kàn láti lo àkọsílẹ̀ inú atọ́ka 3 tí ó sọ pé ""Ìbò kan fún Atiku jẹ́ ibo fún ẹ̀yà Igbo..."" fi jí òkú ìkórìíra ẹ̀yà tẹ̀gbintẹ̀gbin tí ó ti wà láàárín ẹ̀yà Hausa àti Igbo." Ni asiko idibo odun-un 2019, eyi tumo si pe Atiku je agbeseyin eya Igbo ti won ti figba kan gbiyanju lati pinya kuro ninu orile-edee Naijiria. Ní àsìkò ìdìbò ọdún-un 2019, èyí túmọ̀ sí pé Atiku jẹ́ agbèsẹ́yìn ẹ̀yà Igbo tí wọ́n ti fìgbà kan gbìyànjú láti pínyà kúrò nínú orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Akosile inu atoka 1 de 3 n se afihan awon ero ti o lagbara lati ji isele atijo ti o ti rele, ti koi ti i tan ninu awon eya mejeeji. Àkọsílẹ̀ inú atọ́ka 1 dé 3 ń ṣe àfihàn àwọn èrò tí ó lágbára láti jí ìṣẹ̀lẹ̀ àtijọ́ tí ó ti relẹ̀, tí kòì tí ì tán nínú àwọn ẹ̀yà méjèèjì. "Ajo UNESCO so pe iroyin ayederu bayii maa n lapa lara awon “ti o mo die kaato ti ipalara le ba ti o n gba a” yoo si so won di ""alariwo ati alapiinka iroyin naa""." "Àjọ UNESCO sọ pé ìròyìn ayédèrú báyìí máa ń lapa lára àwọn “tí ó mọ̀ díẹ̀ káàtó tí ìpalára lè bá tí ó ń gbà á” yóó sì sọ wọ́n di ""aláriwo àti alápìínká ìròyìn náà""." Ipolongo ibo ti o ba ti n tako eya kan maa n fi etanu to rinle sinu okan awon ti o n gbo o, o si maa n so awon olugbo yii di alapiinka iroyin ayederu. Ìpolongo ìbò tí ó bá ti ń tako ẹ̀yà kan máa ń fi ẹ̀tanú tó rinlẹ̀ sínú ọkàn àwọn tí ó ń gbọ́ ọ, ó sì máa ń sọ àwọn olùgbọ́ yìí di alápìínká ìròyìn ayédèrú. Iro ti won pa pe awon Yoruba n tina bo iso awon omo Igbo niluu Eko Irọ́ tí wọ́n pa pé àwọn Yorùbá ń tiná bọ ìsọ̀ àwọn ọmọ Igbo nílùú Èkó Atoka 4: Aworan Tuwiiti kan [ti Twitter lodi si ti won si yo kuro] lati owo Chioma ti o n se itanka iroyin ayederu pe awon Yoruba n dana sun iso awon Igbo niluu Eko. Atọ́ka 4: Àwòrán Túwíìtì kan [ti Twitter lòdì sí tí wọ́n sì yọ kúrò] láti ọwọ́ Chioma tí ó ń ṣe ìtànká ìròyìn ayédèrú pé àwọn Yorùbá ń dáná sun ìsọ̀ àwọn Igbo nílùú Èkó. Bakan naa, awon agbeseyin egbee PDP naa lo oro idojuko eya yii lati ko ibo ju egbee APC lo ni ipinle Eko. Bákan náà, àwọn agbèsẹ́yìn ẹgbẹ́ẹ PDP náà lo ọ̀rọ̀ ìdójúkọ ẹ̀yà yìí láti kó ìbò ju ẹgbẹ́ẹ APC lọ ní ìpínlẹ̀ Èkó. Atoka 4 ati 5 n safihan aworan Tuwiiti lati owo abanikedun PDP kan ti o n so pe awon Yoruba ti n ti ina bo iso awon omo Igbo niluu Eko. Atọ́ka 4 àti 5 ń ṣàfihàn àwòrán Túwíìtì láti ọwọ́ abánikẹ́dùn PDP kan tí ó ń sọ pé àwọn Yorùbá ti ń ti iná bọ ìsọ̀ àwọn ọmọ Igbo nílùú Èkó. Iro ni awon iroyin naa, Ajo Olopaa ipinle Eko si tete fi otito han lati pa a re. Irọ́ ni àwọn ìròyìn náà, Àjọ Ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Èkó sì tètè fi òtítọ́ hàn láti pa á rẹ́. Akosile ori Facebook kan ti o feree samulo gbogbo oro inu aworan atoka 4, pelu aworan ibi ti won ti fi taya to n jo di ona naa se apinka iroyin iro naa. Àkọsílẹ̀ orí Facebook kan tí ó fẹ́rẹ̀ẹ́ ṣàmúlò gbogbo ọ̀rọ̀ inú àwòrán atọ́ka 4, pẹ̀lú àwòrán ibi tí wọ́n ti fi táyà tó ń jó dí ọ̀nà náà ṣe àpínká ìròyìn irọ́ náà. African Check jabo pe aworan ti won lo yii je aworan kan lati ibi ifehonuhan kan ni ojo 24 osu Erele odun 2017 ti o waye ni agbegbe kan nitosi Pretoria ni orile ede South Africa. African Check jábọ̀ pé àwòrán tí wọ́n lò yìí jẹ́ àwòrán kan lati ibi ìfẹ̀hónúhàn kan ni ọjọ́ 24 oṣù Èrèlé ọdún 2017 tí ó wáyé ní agbègbè kan nítòsí Pretoria ní orílẹ̀ èdè South Africa. Atoka 5: Aworan Tuwiiti kan ti o n se itanka iroyin ayederu kan pe awon Yoruba n tina bo iso awon omo Igbo niluu Eko II Atọ́ka 5: Àwòrán Túwíìtì kan tí ó ń ṣe ìtànká ìròyìn ayédèrú kan pé àwọn Yorùbá ń tiná bọ ìsọ̀ àwọn ọmọ Igbo nílùú Èkó II Isokiri lati mu ero inu awon oloselu se Ìsọkiri láti mú èrò inú àwọn olóṣèlú ṣẹ Ni ojo 13 osu Erele, olusamulo Tuwita kan Souljah tuwiiti (Atoka 6) pe Ballard Partners, ti o je ileese Alukoro kan ti won gba sise ti o kale si Washington DC, lati se ipolongo fun Abubakar gege bi Aare, se iwadii ayewo labele kan ti o ti sapeere ifidiremi ondije-dupo labe asia egbe alatako, iyen PDP. Ní ọjọ́ 13 oṣù Èrèlé, olùṣàmúlò Túwítà kan Souljah túwíìtì (Atọ́ka 6) pé Ballard Partners, tí ó jẹ́ iléeṣẹ́ Alukoro kan tí wọ́n gbà síṣẹ́ tí ó kalẹ̀ sí Washington DC, láti ṣe ìpolongo fún Abubakar gẹ́gẹ́ bí Ààrẹ, ṣe ìwádìí àyẹ̀wò lábẹ́lẹ̀ kan tí ó ti ṣàpẹẹrẹ ìfìdírẹmi òǹdíje-dupò lábẹ́ àsiá ẹgbẹ́ alátakò, ìyẹn PDP. Ni ojo 5, osu Erele, iwe abajade iwadii naa ti Brian Ballard, adariileese Ballard Partners buwolu te Olusola Saraki, ti o je adari patapata fun ipolongo ibo Abubakar lowo. Ní ọjọ́ 5, oṣù Èrèlé, ìwé àbájáde ìwádìí náà tí Brian Ballard, adaríiléeṣẹ́ Ballard Partners buwọ́lù tẹ Olúṣọlá Saraki, tí ó jẹ́ adarí pátápátá fún ìpolongo ìbò Abubakar lọ́wọ́. Tuwiiti Souljah tan kaakiri ti eniyan egbeegberun kan feran-an re, ti egbeegberun eniyan-an si se atunpin-in re fun idi ti o f'ara sin. Túwíìtì Souljah tàn káàkiri tí ènìyàn ẹgbẹẹgbẹ̀rún kan fẹ́ràn-an rẹ̀, tí ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn-án sì ṣe àtúnpín-in rẹ̀ fún ìdí tí ò f'ara sin. Won gbe ojo idibo lati yan aare si ojo 16 osu Erele (ti won pada sun un siwaju si ojo 23 osu Erele), nnkan o ba baje fun egbe asatako PDP pelu abajade iwadii ti o n fara han ni ojo meta ki idibo o to waye yii.. Wọ́n gbé ọjọ́ ìdìbò láti yan ààrẹ sí ọjọ́ 16 oṣù Èrèlé (tí wọ́n padà sún un síwájú sí ọjọ́ 23 oṣù Èrèlé), nǹkan ò bá bàjẹ́ fún ẹgbẹ́ asàtakò PDP pẹ̀lú àbájáde ìwádìí tí ó ń fara hàn ní ọjọ́ mẹ́ta kí ìdìbò ó tó wáyé yìí.. Ka si i: Naijiria sun idibo gbogboogbo odun-un 2019 siwaju nigba ti idibo ku iwon-on wakati nitori oro 'eto ati ilana imusese' Kà sí i: Nàìjíríà sún ìdìbò gbogboògbò ọdún-un 2019 síwájú nígbà tí ìdìbò kú ìwọ̀n-ọn wákàtí nítorí ọ̀rọ̀ 'ètò àti ìlànà ìmúṣẹ́ṣe' Atoka 6: Aworan Tuwiiti kan lati owo Souljah Atọ́ka 6: Àwòrán Túwíìtì kan láti ọwọ́ Souljah "Sugbon ni irole ojo 13 osu Erele, Ballard Partners ni abajade iwadii naa ko ri bee (Atoka 7) ti won se apejuwe re gege bi i ""jibiti"", won si fi idii re mule pe awon ko ""se iwadii kankan fun egbe oselu PDP""." "Sùgbọ́n ní ìrólẹ́ ọjọ́ 13 oṣù Èrèlé, Ballard Partners ní àbájáde ìwádìí náà kò rí bẹ́ẹ̀ (Atọ́ka 7) tí wọ́n ṣe àpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i ""jìbìtì"", wọ́n sì fi ìdíi rẹ̀ múlẹ̀ pé àwọn kò ""ṣe ìwádìí kankan fún ẹgbẹ́ òṣèlú PDP""." "Ose Anenih, ti o je agbeseyin egbe PDP se ifisun lara awon ara APC ori Tuwita ti won se itanka abajade iwadii naa si ikanni awon olopaa orile-edee Naijiria ati ajo ti o n se amojuto oro idibo, INEC fun “iwa odaran ati ohun ti o lodi sofin” ti o n gbiyanju ""lati di idibo ti o ye ki o lo nirorun lowo ""." "Ose Anenih, tí ó jẹ́ agbèsẹ́yìn ẹgbẹ́ PDP ṣe ìfisùn lára àwọn ará APC orí Túwítà tí wọ́n ṣe ìtànká àbájáde ìwádìí náà sí ìkànni àwọn ọlọ́pàá orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà àti àjọ tí ó ń ṣe àmójútó ọ̀rọ̀ ìdìbò, INEC fún “ìwà ọ̀daràn àti ohun tí ó lòdì sófin” tí ó ń gbìyànjú ""láti dí ìdìbò tí ó yẹ kí ó lọ nírọ̀rùn lọ́wọ́ ""." Sugbon eyi ki i se igba akoko ti won maa fi iroyin ayederu mu ero inu awon oloselu se lori ayelujara ni asiko idibo. Ṣùgbọ́n èyí kì í ṣe ìgbà àkọ́kọ́ tí wọ́n máa fi ìròyìn ayédèrú mú èrò inú àwọn olóṣèlú ṣẹ lórí ayélujára ní àsìkò ìdìbò. Atoka 7: Aworan Tuwiiti kan lati owo ileese Ballard and Partners ti i se ayederu iwadii ti won puro mo won pe won se. Atọ́ka 7: Àwòrán Túwíìtì kan láti ọwọ́ iléeṣẹ́ Ballard and Partners tí í sẹ́ ayédèrú ìwádìí tí wọ́n purọ́ mọ́ wọn pé wọ́n ṣe. Opolopo iro oluranlowo aare Ọ̀pọ̀lọpọ̀ irọ́ olùrànlọ́wọ́ ààrẹ Atoka 8: Aworan Tuwiiti kan by Lauretta Onochie, lati owo Lauretta Onochie, ti o je oluranlowo fun aare Atọ́ka 8: Àwòrán Túwíìtì kan by Lauretta Onochie, láti ọwọ́ Lauretta Onochie, tí ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ fún ààrẹ Ni ojo 4, osu Ope, odun-un 2018 Lauretta Onochie, ti o je oluranlowo fun Buhari [ti o je ondije-dupo aare lasiko naa] tuwiiti (Atoka 8) aworan kan pelu ounje ati owoo naira 500 ti won ni won pin fun awon ero lojo keji irinde ipolongo idibo fun Abubakar gege bi aare ni Sokoto, apa ariwa-ila oorun orile-edee Naijiria ni ana ojo naa. Ní ọjọ́ 4, oṣù Ọ̀pẹ, ọdún-un 2018 Lauretta Onochie, tí ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ fún Buhari [tí ó jẹ́ òǹdíje-dupò ààrẹ lásìkò náà] túwíìtì (Atọ́ka 8) àwòrán kan pẹ̀lú oúnjẹ àti owóo náírà 500 tí wọ́n ní wọ́n pín fún àwọn èrò lọ́jọ́ kejì ìrìnde ìpolongo ìdìbò fún Abubakar gẹ́gẹ́ bí ààrẹ ní Sokoto, apá àríwá-ìlà oòrùn orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ní àná ọjọ́ náà. Iro patapata ni awon esun Onochie. Koda, nibi ode kan ti ko tan mo “oro idibo” ni a ti ya aworan naa ninu “osu Erele odun-un 2017′′, Chuba Ugwu tan imole si eyi ninu esi si tuwiiti re kan. Irọ́ pátápátá ni àwọn ẹ̀sùn Onochie. Kódà, níbi òde kan tí kò tan mọ́ “ọ̀rọ̀ ìdìbò” ni a ti ya àwòrán náà nínú “oṣù Èrèlé ọdún-un 2017″, Chuba Ugwu tan ìmọ́lẹ̀ sí èyí nínú èsì sí túwíìtì rẹ̀ kan. "Onochie je ogbontarigi nibi ka maa se apinka iroyin ayederu. Ileese agberoyinjade ori ayelujara kan ti o n se iwadii ijabo iroyin (ICIR), ti se agbeyewo aworan to ju 1,000 lo ti Onochie ti pin sori Twitter laaarin ojo 1, osu Ogun odun-un 2018 ati ojo 31, osu Agemo odun-un 2019. Agbeyewo naa fi han pe o kere tan ""igba mejila"" ni Onochie ""ti lo aworan ti ko ye""." "Onochie jẹ́ ògbóǹtarìgì níbi ká máa ṣe àpínká ìròyìn ayédèrú. Iléeṣẹ́ agbéròyìnjáde orí ayélujára kan tí ó ń ṣe ìwádìí ìjábọ̀ ìròyìn (ICIR), ti ṣe àgbéyẹ̀wò àwòrán tó ju 1,000 lọ tí Onochie ti pín sórí Twitter láàárín ọjọ́ 1, oṣù Ògún ọdún-un 2018 àti ọjọ́ 31, oṣù Agẹmọ ọdún-un 2019. Àgbéyẹ̀wò náà fi hàn pé ó kéré tán ""ìgbà méjìlá"" ni Onochie ""ti lo àwòrán tí kò yẹ""." Oro Atako lori Ayelujara: oran ni Naijiria Ọ̀rọ̀ Àtakò lórí Ayélujára: ọ̀ràn ní Nàìjíríà "Abala 26 ofin Naijiria nipa oran ori ayelujara ko ""lileri ija ati lilo oro eebu si awon eeyan nitori eyaa won, esin-in won, awo-o won, iran-an won tabi orile-edee won""." "Abala 26 òfin Nàìjíríà nípa ọ̀ràn orí ayélujára kọ ""lílérí ìjà àti lílo ọ̀rọ̀ èébú sí àwọn èèyàn nítorí ẹ̀yàa wọn, ẹ̀sìn-in wọn, àwọ̀-ọ wọn, ìràn-an wọn tàbí orílẹ̀-èdèe wọn""." Awon eni ti ade iwa naa ba si mo lori a fi ewon olodun-marun-un gbara tabi ki won san owo itanran ti ko din ni egbeegberun 10 owoo naira [ti o n lo bi i $28,000] tabi mejeeji. Àwọn ẹni tí adé ìwà náà bá ṣí mọ́ lórí á fi ẹ̀wọ̀n ọlọ́dún-márùn-ún gbára tàbí kí wọ́n san owó ìtanràn tí kò dín ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún 10 owóo naira [tí ó ń lọ bí i $28,000] tàbí méjèèjì. Ni osu Erena odun yii, Enough is Enough Nigeria (EIE), ti o je akojopo awon odo kan ati Paradigm Initiative (PI), ti o je egbe asofin ati ajafetoo eni lori ero-ayarabiasa, se ifilole ipelejo Onochie ati Gbenga Olorunpomi ti o je oluranlowo gomina ipinle-e Kogi lejo ni Ile-ejo kan ni Abuja. Ní oṣù Ẹrẹ́nà ọdún yìí, Enough is Enough Nigeria (EIE), tí ó jẹ́ àkójọpọ̀ àwọn ọ̀dọ́ kan àti Paradigm Initiative (PI), tí ó jẹ́ ẹgbẹ́ aṣòfin àti ajàfẹ́tọ̀ọ́ ẹni lórí ẹ̀rọ-ayárabíàṣá, ṣe ìfilọ́lẹ̀ ìpèlẹ́jọ́ Onochie àti Gbénga Ọlọ́runpomi tí ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ gómìnà ìpínlẹ̀-ẹ Kogi lẹ́jọ́ ní Ilé-ẹjọ́ kan ní Abuja. "Ajo mejeeji yii ""se akopo awon oro atako ti o je oro Onochie ati Olorunpomi lori ayelujara"" ti won ri i pe o ru ofin orile-edee Naijiria nipa oran ori ayelujara ti 2015." "Àjọ méjèèjì yìí ""ṣe àkópọ̀ àwọn ọ̀rọ̀ àtakò tí ó jẹ́ ọ̀rọ̀ Onochie àti Ọlọ́runpomi lórí ayélujára"" tí wọ́n rí i pé ó rú òfin orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà nípa ọ̀ràn orí ayélujára ti 2015." Ka si i: Bawo ni isokiri yoo se to idibo aare orile-edee Naijiria ti 2019? Kà sí i: Báwo ni ìsọkiri yóò ṣe to ìdìbò ààrẹ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ti 2019? Akojopo awon ajagun ori Twitter ti won n se apinka iro Àkójọpọ̀ àwọn ajagun orí Twitter tí wọ́n ń ṣe àpínká irọ́ Pupo ninu awon apeere ti a se loke yii ki i se ohun ti won ko mo-on-mo se. Won diidi gbiyanju lati se apinka iro bi i pe ooto ni. Púpọ̀ nínú àwọn àpẹẹrẹ tí a ṣe lókè yìí kì í ṣe ohun tí wọn kò mọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe. Wọ́n dìídì gbìyànjú láti ṣe àpínká irọ́ bí i pé òótọ́ ni. "Eyi ko yani lenu rara nitori a ri i pe APC ati PDP ni won di ajagun ori ayelujara lati le se ""imuwale ijabo buburu"" lori ayelujara nipa won tabi lati “gbeja” nibi idojuko lasiko ipolongo ibo." "Èyí kò yani lẹ́nu rárá nítorí a rí i pé APC àti PDP ni wọ́n di ajagun orí ayélujára láti lè ṣe ""ìmúwálẹ̀ ìjábọ̀ búburú"" lórí ayélujára nípa wọn tàbí láti “gbèjà” níbi ìdojúkọ lásìkò ìpolongo ìbò." "Egbe mejeeji ni o se amulo ""ajagun ori ayelujara"" — ""awon akopa ninu ijoba tabi egbe oselu ti won fun ni ise lati towobo opolo awon ara ilu lati yi eroo won pada lori ayelujara""." "Ẹgbẹ́ méjèèjì ni ó ṣe àmúlò ""ajagun orí ayélujára"" — ""àwọn akópa nínú ìjọba tàbí ẹgbẹ́ òṣèlú tí wọ́n fún ní iṣẹ́ láti tọwọ́bọ ọpọlọ àwọn ará ìlú láti yí èròo wọn padà lórí ayélujára""." Idibo odun yii je asetunse ti 2015, nibi ti APC ati PDP ti kopa ninu itanka iroyin ayederu ati iro pelu isokiri lati mu ero awon oloselu se “ninu awon ipolongo won lori awujo ayelujara ti won “fara bale seto lati fi tan awon oludibo ti ko fura, “bayii ni Eshemokha Austin Maho, ti o je omowe Naijiria kan nipa ikede ati igberoyinjade se so. Ìdìbò ọdún yìí jẹ́ àṣẹtúnṣe ti 2015, níbi tí APC àti PDP ti kópa nínú ìtànká ìròyìn ayédèrú àti irọ́ pẹ̀lú ìsọkiri láti mú èrò àwọn olóṣèlú ṣẹ “nínú àwọn ìpolongo wọn lórí àwùjọ ayélujára tí wọ́n “fara balẹ̀ ṣètò láti fi tan àwọn olùdìbò tí kò fura, “báyìí ni Eshemokha Austin Maho, tí ó jẹ́ ọ̀mọ̀wé Nàìjíríà kan nípa ìkéde àti ìgbéròyìnjáde ṣe sọ. "Won ri eyi se nipase “idasile awon ikanni iro lori ayelujara ""nibi ti won ti n pin “oro ibanilorukoje "" ati ""iroyin ti ko se e fokan tan pelu isokiri lati mu ero awon oloselu se""." "Wọ́n rí èyí ṣe nípasẹ̀ “ìdásílẹ̀ àwọn ìkànnì irọ́ lórí ayélujára ""níbi tí wọ́n ti ń pín “ọ̀rọ̀ ibanilórúkọjẹ́ "" àti ""ìròyìn tí kò ṣe é fọkàn tán pẹ̀lú ìsọkiri láti mú èrò àwọn olóṣèlú ṣẹ""." Abajade ti ipa won ko ni pe Twitter di papa iroyin ayederu ti o n se eleyameya ati isokiri lati mu ero awon oloselu se saaju asiko idibo, ni asiko idibo ati leyin idibo odun-un 2019 lorile-edee Naijiria. Àbájáde tí ipa wọn kó ni pé Twitter di pápá ìròyìn ayédèrú tí ó ń ṣe ẹlẹ́yàmẹyà àti ìsọkiri láti mú èrò àwọn olóṣèlú ṣẹ ṣáájú àsìkò ìdìbò, ní àsìkò ìdìbò àti lẹ́yìn ìdìbò ọdún-un 2019 lórílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Aroko yii je apa kan ninu owoo awon akosile ti o n se agbeyewo ikolura pelu eto eni lori ayelujara nipase awon ilana bi i pipa opo ibanisoro ati iroyin ayederu ni asiko ti oro iselu pataki ba n waye ni orile-ede ile Adulawo meje: Algeria, Ethiopia, Mozambique, Nigeria, Tunisia, Uganda, and Zimbabwe. Àròkọ yìí jẹ́ apá kan nínú ọ̀wọ̀ọ́ àwọn àkọsílẹ̀ tí ó ń ṣe àgbéyẹ̀wò ìkọlura pẹ̀lú ẹ̀tọ́ ẹni lórí ayélujára nípasẹ̀ àwọn ìlànà bí i pípa òpó ìbánisọ̀rọ̀ àti ìròyìn ayédèrú ní àsìkò tí ọ̀rọ̀ ìṣèlú pàtàkì bá ń wáyé ní orílẹ̀-èdè ilẹ̀ Adúláwọ̀ méje: Algeria, Ethiopia, Mozambique, Nigeria, Tunisia, Uganda, and Zimbabwe. Ajo ti o n samojuto eto eni lori ero Africa Digital Rights Fund ti The Collaboration on International ICT Policy for East and Southern Africa (CIPESA) ni o se agbateru ise yii. Àjọ tí ó ń ṣàmójútó ẹ̀tọ́ ẹni lórí ẹ̀rọ Africa Digital Rights Fund ti The Collaboration on International ICT Policy for East and Southern Africa (CIPESA) ni ó ṣe agbátẹrù iṣẹ́ yìí. Ile-Adulawo ri abo egbeegberun-lona-egberun owoo dollar lati odo Ile-ifowopamosi nlanla fun igbefuke Ileese ogbon atinuda Ilẹ̀-Adúláwọ̀ rí àbọ̀ ẹgbẹẹgbẹ̀rún-lọ́nà-ẹgbẹ̀rún owóo dollar láti ọ̀dọ̀ Ilé-ìfowópamọ́sí ńláńlá fún ìgbéfúkẹ́ Iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá Awon ologbon atinuda Ile-Adulawo gbodo 'ka eso oro ti o po ti o n duro fun kika' Àwọn ọlọ́gbọ́n àtinudá Ilẹ̀-Adúláwọ̀ gbọdọ̀ 'ká èso ọrọ̀ tí ó pọ̀ tí ó ń dúró fún kíká' Ageku aworan okorin omo orile-edee Naijiria D'banj n soro nibi eto Ojo Isinmi CAX ni Cairo, Egypt, odun-un 2018. Dbanj so fun oludokoowo wipe “ise atinuda ni epo robi ti opon sun kan” ti o si ye ki a bu iyin fun. Àgékù àwòrán ọ̀kọrin ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà D'banj ń sọ̀rọ̀ níbi ètò Ọjọ́ Ìsinmi CAX ní Cairo, Egypt, ọdún-un 2018. Dbanj sọ fún olùdókoòwò wípé “iṣẹ́ àtinúdá ni epo rọ̀bì tí ọpọ́n sún kàn” tí ó sì yẹ kí a bu ìyìn fún. O ti pe ti awon ileese igbelaruge asa ati ogbon atinuda ti n se ohun meremere ni ti idagbasoke oro Aje, ni ti ipa ti won n ko ati agbara ti o wa nikaawo won lati mu ayipada de ba awujo ati ipasipaaro asa. Ó ti pẹ́ tí àwọn iléeṣẹ́ ìgbélárugẹ àṣà àti ọgbọ́n àtinudá ti ń ṣe ohun mèremère ní ti ìdàgbàsókè ọrọ̀ Ajé, ní ti ipa tí wọ́n ń kó àti agbára tí ó wà níkàáwọ́ wọn láti mú àyípadà dé bá àwùjọ àti ìpàṣípààrọ̀ àṣà. Lodun-un 2013, ileese igbelaruge asa ati ogbon atinuda (CCI) ri owo egbeegberun-lona-egberun 2,250 dollar ti Isokan Orile-edee Amerika ati ise ti egbeegberun 29.5 kari aye [amo] ida 3 awon ise wonyi wa lati Ile-Adulawo ati Aarin gbungbun Ila-Oorun ti o je agbegbe awon araa Larubawa, iyen gege bi iwadii ayewo finnifinni Ajo Isokan Agbaye fun Eko, Iwadii Ijinle ati Asa (UNESCO) odun-un 2013 ti a pe ni “Asiko Asa” kan ti se fi han. Lọ́dún-un 2013, iléeṣẹ́ ìgbélárugẹ àṣà àti ọgbọ́n àtinudá (CCI) rí owó ẹgbẹẹgbẹ̀rún-lọ́nà-ẹgbẹ̀rún 2,250 dollar ti Ìṣọ̀kan Orílẹ̀-èdèe Amẹ́ríkà àti iṣẹ́ tí ẹgbẹẹgbẹ̀rún 29.5 kárí ayé [àmọ́] ìdá 3 àwọn iṣẹ́ wọ̀nyí wá láti Ilẹ̀-Adúláwọ̀ àti Àárín gbùngbùn Ìlà-Oòrùn tí ó jẹ́ agbègbè àwọn aráa Lárúbáwá, ìyẹn gẹ́gẹ́ bí ìwádìí àyẹ̀wò fínnífínní Àjọ Ìṣọ̀kan Àgbáyé fún Ẹ̀kọ́, Ìwádìí Ìjìnlẹ̀ àti Àṣà (UNESCO) ọdún-un 2013 tí a pè ní “Àsìkò Àṣà” kan ti ṣe fi hàn. "Tori idi eyi, Ile-ifowopamosi Oja tita soke okun-ati-kiko oja wole (Afreximbank) pelu abasepoo UNESCO ati Egbe Ile-ifowopamosi Idagbasoke Ile-Adulawo, se agbekale Ipasipaaro Ogbon Atinuda Ile-Adulawo – Creative Africa Exchange (CAX) ti yoo ""duro gege bii ohun ti yoo se amupapo awon nnkan oro ati alumoni ti o wa ninu ileese ogbon atinuda"" ti yoo se agbero, mu owo wole ati lapa rere lara awon ologbon atinuda ati awon onise asa, bi ibudo itakun agbaye CAX se ni i lakosile." "Torí ìdí èyí, Ilé-ìfowópamọ́sí Ọjà títa sókè òkun-àti-kíkó ọjà wọlé (Afreximbank) pẹ̀lú àbáṣepọ̀ọ UNESCO àti Ẹgbẹ́ Ilé-ìfowópamọ́sí Ìdàgbàsókè Ilẹ̀-Adúláwọ̀, ṣe àgbékalẹ̀ Ìpàṣípààrọ̀ Ọgbọ́n Àtinudá Ilẹ̀-Adúláwọ̀ – Creative Africa Exchange (CAX) tí yóò ""dúró gẹ́gẹ́ bíi ohun tí yóò ṣe àmúpapọ̀ àwọn nǹkan ọrọ̀ àti àlùmọ́nì tí ó wà nínú iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá"" tí yóò ṣe àgbéró, mú owó wọlé àti lapa rere lára àwọn ọlọ́gbọ́n àtinudá àti àwọn oníṣẹ́ àṣà, bí ibùdó ìtakùn àgbáyé CAX ṣe ní i lákọsílẹ̀." Odun-un 2018 ni ifilole CAX waye ni ibi Ipate Oja Inu Ile-Adulawo ni iluu Cairo, orile-edee Egypt, ninu osu Ope odun-un 2018. Ọdún-un 2018 ni ìfilọ́lẹ̀ CAX wáyé ní ibi Ìpàtẹ Ọjà Inú Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ní ìlúu Cairo, orílẹ̀-èdèe Egypt, nínú oṣù Ọ̀pẹ̀ ọdún-un 2018. Awon ologbon atinuda gbogbo lati eka orin kiko, ise ona, awose, eso, ewi, iwe tite, aworan-olohun ati osise ero amohunmaworan parojo fun Ojo Isinmi Ipasipaaro Ogbon Atinuda ni Kigali, ni orile-edee Rwanda, ni ojo 16-18 osu kiini, Odun-un 2020. Àwọn ọlọ́gbọ́n àtinudá gbogbo láti ẹ̀ka orin kíkọ, iṣẹ́ ọnà, àwòṣe, ẹ̀ṣọ́, ewì, ìwé títẹ̀, àwòrán-olóhùn àti òṣìṣẹ́ ẹ̀rọ amóhùnmáwòràn parojọ fún Ọjọ́ Ìsinmi Ìpàṣípààrọ̀ Ọgbọ́n Àtinudá ní Kigali, ní orílẹ̀-èdèe Rwanda, ní ọjọ́ 16-18 oṣù kìíní, Ọdún-un 2020. "O polowo araa re gege bii ""ayeye akoko ti yoo ko awon omo ile adulawo jo ti n se igbelaruge ipasipaaro laaarin awon ologbon atinuda ati asagbelaruge asa ni Ile-Adulawo "", ti o ni awon akopa ti o to bii 2,000 lati orile-ede 68." "Ó polówó araa rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi ""ayẹyẹ àkọ́kọ́ tí yóò kó àwọn ọmọ ilẹ̀ adúláwọ̀ jọ tí ń ṣe ìgbélárugẹ ìpàṣípààrọ̀ láàárín àwọn ọlọ́gbọ́n àtinudá àti aṣàgbélárugẹ àṣà ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ "", tí ó ní àwọn akópa tí ó tó bíi 2,000 láti orílẹ̀-èdè 68." "Ni ojo keji ayeye naa ni Kigali, ojogbon Benedict Oramah, aare Ile-ifowopamosi Oja tita soke okun-ati-kiko wole (Afreximbank) kede owo iranwo egbeegberun 500 owo dollar Amerika ""ti yoo se atileyin igbejade ati karakata nnkan ti o je mo ti asa ati ogbon atinuda Ile-Adulawo "" fun odun meji gbako, New Times Rwanda jiyin irohin." "Ní ọjọ́ kejì ayẹyẹ náà ní Kigali, ọ̀jọ̀gbọ́n Benedict Oramah, ààrẹ Ilé-ìfowópamọ́sí Ọjà títa sókè òkun-àti-kíkó wọlé (Afreximbank) kéde owó ìrànwọ́ ẹgbẹẹgbẹ̀rún 500 owó dollar Amẹ́ríkà ""tí yóò ṣe àtìlẹ́yìn ìgbéjáde àti káràkátà nǹkan tí ó jẹ mọ́ ti àṣà àti ọgbọ́n àtinudá Ilẹ̀-Adúláwọ̀ "" fún ọdún méjì gbáko, New Times Rwanda jíyìn ìròhìn." Omarah gbe e si awon alejo ti o wa nikale nibi ayeye naa leti wipe owo iranwo naa, ti yoo bu kun ise ti Ile-ifowopamosi naa ti n se tele, yoo wa ni arowoto ni awon Ile-ifowopamosi, ti yoo je lilo fun awon ti o fe e. Omarah gbé e sí àwọn àlejò tí ó wà níkàlẹ̀ níbi ayẹyẹ náà létí wípé owó ìrànwọ́ náà, tí yóò bù kún iṣẹ́ tí Ilé-ìfowópamọ́sí náà ti ń ṣe tẹ́lẹ̀, yóò wà ní àrọ̀wọ́tó ní àwọn Ilé-ìfowópamọ́sí, tí yóò jẹ́ lílò fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ. O so wipe bi Ile-Adulawo ti se ni opolopo ologbon atinuda to, ko si ohun elo ti yoo mu ki won o ka eso oro ti o po ti o n duro fun kika, iyen bi Afreximbank ti se salaye. Ó sọ wípé bí Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ti ṣe ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọlọ́gbọ́n àtinudá tó, kò sí ohun èlò tí yóò mú kí wọn ó ká èso ọrọ̀ tí ó pọ̀ tí ó ń dúró fún kíká, ìyẹn bí Afreximbank ti ṣe ṣàlàyé. O soro siwaju si i : Ó sọ̀rọ̀ síwájú sí i : Nitori aito idokoowo ninu ileese ogbon atinuda ati asa, Ile-Adulawo ko si ninu oja ise opolo, ati idaraawo pupo gege bi a ti fi han ninu orin, ere itage, ewi, aworan-atohun ati eto ori ero amohunmaworan agbaye. Nítorí àìtó ìdókoòwò nínú iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá àti àṣà, Ilẹ̀-Adúláwọ̀ kò sí nínú ọjà iṣẹ́ ọpọlọ, àti ìdáraáwò púpọ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti fi hàn nínú orin, eré ìtàgé, ewì, àwòrán-àtohùn àti ètò orí ẹ̀rọ amóhùnmáwòrán àgbáyé. Awon orile-ede Ile-Adulawo maa n ko oja ogbon atinuda wole ju eyi ti won ta soke okun tabi laaarin ara won. Àwọn orílẹ̀-èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ máa ń kó ọjà ọgbọ́n àtinudá wọlé ju èyí tí wọ́n tà sókè òkun tàbí láàárin ara wọn. "O gbosubaa sandakata fun orile-edee Egypt ni ti “idagbasokee itasoke okun ogbon atinuda laaarin odun mewaa ti o re koja""." "Ó gbóṣùbàa sàńdákátà fún orílẹ̀-èdèe Egypt ní ti “ìdàgbàsókèe ìtàsókè òkun ọgbọ́n àtinudá láàárín ọdún mẹ́wàá tí ó ré kọjá""." Ninu osu Ope odun-un 2019, a da Afreximbank lola nibi Ifamieyedanilola Isaralosoo Agbaye International Fashion Awards (IFA) ni Cairo fun ipa ti o n ko nibi ti itileyin-in ileese ogbon atinuda Ile-Adulawo. Nínú oṣù Ọ̀pẹ̀ ọdún-un 2019, a dá Afreximbank lọ́lá níbi Ìfàmìẹ̀yẹdánilọ́lá Ìṣaralọ́ṣọ̀ọ́ Àgbáyé International Fashion Awards (IFA) ní Cairo fún ipa tí ó ń kó níbi ti ìtìlẹ́yìn-in iléeṣẹ́ ọgbọ́n àtinudá Ilẹ̀-Adúláwọ̀. Bakan naa ni Omarah gboriyin fun ileese ere ori itage Nollywood ti Naijiria. Bákan náà ni Omarah gbóríyìn fún iléeṣẹ́ eré orí ìtàgé Nollywood ti Nàìjíríà. Lorii gbagede Twitter, awon osere to wa nibi apero naa dupe fun apejo naa ti o waye ni gbongan Intare ti o wa ni Kigali: Lóríi gbàgede Twitter, àwọn òṣèré tó wà níbi àpérò náà dúpẹ́ fún àpéjọ náà tí ó wáyé ní gbọ̀ngan Intare tí ó wà ní Kigali: Ninu oro-o re nibi ayeye Ojo Isinmi CAX 2018 ni Cario, okorin omo orile-edee Naijiria D'Banj so fun awon osise Ile-ifowopamosi ati oludokoowo: Nínú ọ̀rọ̀-ọ rẹ̀ níbi ayẹyẹ Ọjọ́ Ìsinmi CAX 2018 ní Cario, ọ̀kọrin ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà D'Banj sọ fún àwọn òṣìṣẹ́ Ilé-ìfowópamọ́sí àti olùdókoòwò: Ohun ti a nilo lati odoo yin ni fun un yin lati loye wipe ise atinuda ni epo robi ti opon sun kan ti o si ye ki a bu iyin fun ileese naa. Ohun tí a nílò láti ọ̀dọ̀ọ yín ní fún un yín láti lóye wípé iṣẹ́ àtinudá ni epo rọ̀bì tí ọpọ́n sún kàn tí ó sì yẹ kí a bu ìyìn fún iléeṣẹ́ náà. Ose-e CAX ti yoo se peki-n-reki pelu Ipate Oja Inu Ile-Adulawo (IATF2020) lati Ojo 1-7 kesan-an ni Kigali, yoo tele Ojo Isinmi CAX 2020 ti o sese tenu bo epo. Ọ̀sẹ̀-ẹ CAX tí yóò ṣe pẹ̀kí-ǹ-rẹ̀kí pẹ̀lú Ìpàtẹ Ọjà Inú Ilẹ̀-Adúláwọ̀ (IATF2020) láti Ọjọ́ 1-7 kẹsàn-án ní Kigali, yóò tẹ̀lé Ọjọ́ Ìsinmi CAX 2020 tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ tẹnu bọ epo. Sorosoro ni Naijiria darapo mo awon akegbe-e won lati saami ayeye Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye odun-un 2020 Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ ní Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn akẹgbẹ́-ẹ wọn láti sààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020 Redio — ohun elo fun idagbasoke ti ko han, ti o si se e gbe kiri. Rédíò — ohun èlò fún ìdàgbàsókè tí kò hàn, tí ó sì ṣe é gbé kiri. Okunrin kan gbe ero-igbohunsafefe ti maa n rin ona jinjin dani. Aworan lati owoo Muhammadtaha Ibrahim Ma'aji ti o je ase ilo CC BY 2.0. Ọkùnrin kan gbé ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí máa ń rin ọ̀nà jínjìn dání. Àwòrán láti ọwọ́ọ Muhammadtaha Ibrahim Ma'aji tí ó jẹ́ àṣẹ ìlò CC BY 2.0. Ko si iro kan nibe wipe Ero-igbohunsafefe je ohun elo igberoyin ka ti o ti sise ribiribi fun idagbasoke agba-nla aye. Kò sí irọ́ kan níbẹ̀ wípé Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ jẹ́ ohun èlò ìgbéròyìn ká tí ó ti ṣiṣẹ́ ribiribi fún ìdàgbàsókè àgbà-ńlá ayé. "Awon Yoruba ni, ki a gbe oye fun oloye, ki a gbade fun eni ti o ni ade"", eyi lo mu Ajo Isokan Agbaye ti o n ri si Eto Eko, Imo Ijinle ati Asa (UNESCO) ya ojo 13 osu Erele soto gege bii Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye." "Àwọn Yorùbá ní, kí a gbé oyè fún olóyè, kí á gbádé fún ẹni tí ó ni adé"", èyí ló mú Àjọ Ìṣọ̀kan Àgbáyé tí ó ń rí sí Ètò Ẹ̀kọ́, Ìmọ̀ Ìjìnlẹ̀ àti Àṣà (UNESCO) ya ọjọ́ 13 oṣù Èrèlé sọ́tọ̀ gẹ́gẹ́ bíi Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé." UNESCO ya ojo yii soto lati si oju awon eniyan si ipa ti ero-igbohunsafefe n ko ni igbesi aye — ti o je ona igberoyinka ti ko han, ti o si se e gbe kiri. UNESCO yà ọjọ́ yìí sọ́tọ̀ láti ṣí ojú àwọn ènìyàn sí ipa tí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ń kó ní ìgbésí ayé — tí ó jẹ́ ọ̀nà ìgbéròyìnká tí kò hàn, tí ó sì ṣe é gbé kiri. Awon sorosoro-o orile-edee Naijiria darapo mo awon sorosoro ori ero-igbohunsafefe lagbaaye lati saami ojo naa ati lati fon rere ise idagbasoke agba-nla aye ti ero-igbohunsafefe n se. Àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀-ọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà darapọ̀ mọ́ àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ orí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ lágbàáyé láti sààmì ọjọ́ náà àti láti fọn rere iṣẹ́ ìdàgbàsókè àgbà-ńlá ayé tí ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ń ṣe. """Ero igberoyinjade n yi bi a ti se n se nnkan pada, sibesibe ero-igbohunsafefe si ni o si wulo ju lo fun ogoro eniyan lati gbo iroyin ohun ti o n lo lowo, ohun si ni ohun elo ti o maa n lapa ti o po ju ninuu gbogbo ona ti awon oniroyin maa n lo nitori o lagbara lati de ibi jinjin ati igberiko ti o je ibi kolofin... "" Alufaa George Bako soro, nigba ti o n side eto nibi Apero Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye. Bako ti fi igba kan ri je Oga-Agba patapata fun Ileese Alajosepo Igbohunsafefe Ijoba Apapo Orile-edee Naijiria (FRCN)." """Ẹ̀rọ ìgbéròyìnjáde ń yí bí a ti ṣe ń ṣe nǹkan padà, síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ṣì ni ó ṣì wúlò jù lọ fún ọ̀gọ̀rọ̀ ènìyàn láti gbọ́ ìròyìn ohun tí ó ń lọ lọ́wọ́, òhun ṣì ni ohun èlò tí ó máa ń lapa tí ó pọ̀ jù nínúu gbogbo ọ̀nà tí àwọn oníròyìn máa ń lò nítorí ó lágbára láti dé ibi jínjìn àti ìgbèríko tí ó jẹ́ ibi kọ́lọ́fín… "" Àlùfáà George Bako sọ̀rọ̀, nígbà tí ó ń ṣíde ètò níbi Àpérò Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé. Bako ti fi ìgbà kan rí jẹ́ Ọ̀gá-Àgbà pátápátá fún Iléeṣẹ́ Alájọṣepọ̀ Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Ìjọba Àpapọ̀ Orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà (FRCN)." Alufaa George Bako soro nibi apero Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye ni Eko, orile-edee Naijiria. Àlùfáà George Bako sọ̀rọ̀ níbi àpérò Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ní Èkó, orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Aworan lati owoo Omo Yooba, ti a gba ase lati lo. Àwòrán láti ọwọ́ọ Ọmọ Yoòbá, tí a gba àṣẹ láti lò. FRCN — ti a tun n pe ni Radio Nigeria — ni o lewaju ninuu isee ero-igbohunsafefe ni orile-edee Naijiria, pelu egbelemuku awon ololufe ti o n gbo o jakejado Ipinle Eko th orii ikanni meta otooto, ti oruko won je: Radio One 103.5 FM, Metro 97.7 FM ati alaraa gbayida inuu won Bond 92.9 FM. FRCN — tí a tún ń pè ní Radio Nigeria — ni ó léwájú nínúu iṣẹ́ẹ ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ní orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, pẹ̀lú ẹgbẹlẹmùkù àwọn olólùfẹ́ tí ó ń gbọ́ ọ jákèjádò Ìpínlẹ̀ Èkó th oríi ìkànnì mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, tí orúkọ wọ́n jẹ́: Radio One 103.5 FM, Metro 97.7 FM àti aláràa gbàyídá inúu wọn Bond 92.9 FM. Okookan ikanni yii — ni awon ololufee re ati awon ti o n gbo o — ti o n fi edee Geesi, Adalumo-Geesi, Hausa, Igbo ati edee Yoruba. Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìkànnì yìí — ní àwọn olólùfẹ́ẹ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń gbọ́ ọ — tí ó ń fi èdèe Gẹ̀ẹ́sì, Àdàlùmọ́-Gẹ̀ẹ́sì, Hausa, Igbo àti èdèe Yorùbá. Ero-igbohunsafefe si ni ona ti o dara ju lo fun ifonka iroyin ni Naijiria. FM (Igbohunsafefe Alaseeyipada) ni o wopo ju lo, AM (Igbohunsafefe Titobi) tele e gbongbongbon, gege bi ileese Media Landscape ti European Journalism Centre ni i lakosile — ti igbohunsafefe ori ero ayelujara si ti di gbajumo. Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ṣì ni ọ̀nà tí ó dára jù lọ fún ìfọ́nká ìròyìn ní Nàìjíríà. FM (Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Aláṣeéyípadà) ni ó wọ́pọ̀ jù lọ, AM (Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Títóbi) tẹ̀lé e gbọ̀ngbọ̀ngbọn, gẹ́gẹ́ bí iléeṣẹ́ Media Landscape ti European Journalism Centre ní i lákọsílẹ̀ — tí ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ orí ẹ̀rọ ayélujára sì ti di gbajúmọ̀. Ni odun-un 2019, Nigeria Diary Radio Stations Ratings ti osu Ogun fi han wipe Bond FM lo di ipo kiini mu ni Ipinle Eko gege bi ikanni ti o ni olugbo ju lo. Ní ọdún-un 2019, Nigeria Diary Radio Stations Ratings ti oṣù Ògún fi hàn wípé Bond FM ló di ipò kìíní mú ní Ìpínlẹ̀ Èkó gẹ́gẹ́ bí ìkànnì tí ó ní olùgbọ́ jù lọ. Latari ayeye naa, awon sorosoro jakejado orile-edee Naijiria fi gbagede Twitter kede ife e won fun redio: Látàrí ayẹyẹ náà, àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ jákèjádò orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà fi gbàgede Twitter kéde ìfẹ́ ẹ wọn fún rédíò: "Dan Manjang, alakooso fun ooro igbohunsafefe ati ikede ti Ipinle Plateau, ki awon sorosoro nibi gbogbo fun ""gbogbo akitiyan, igbiyanju ati asiko"" ti won fi n kede iroyin ati oniruuru eto akonilogbon:" "Dan Manjang, alákòóso fún oọ̀rọ̀ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ àti ìkéde ti Ìpínlẹ̀ Plateau, kí àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ níbi gbogbo fún ""gbogbo akitiyan, ìgbìyànjú àti àsìkò"" tí wọ́n fi ń kéde ìròyìn àti onírúurú ètò akọ́nilọ́gbọ́n:" Igbohunsafefe ni Naijiria bere ni odun-un 1933 pelu Itan kaakiri Redio Ijoba Amunisin (RDS), ti o je wipe gbe awon ero-gbohungbohun si ita gbangba nibi ti awon eniyan yoo ti teti si iroyin okeere ti Ileese Igbohunsafefe Ijoba Geesi. Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ní Nàìjíríà bẹ̀rẹ̀ ní ọdún-un 1933 pẹ̀lú Ìtàn káàkiri Rédíò Ìjọba Amúnisìn (RDS), tí ó jẹ́ wípé gbé àwọn ẹ̀rọ-gbohùngbohùn sí ìta gbangba níbi tí àwọn ènìyàn yóò ti tẹ́tí sí ìròyìn òkèèrè ti Iléeṣẹ́ Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Ìjọba Gẹ̀ẹ́sì. Ni odun-un 1950, RDS gbe aso tuntun wo — o di Ileese Igbohunsafefe Orile-edee Naijiria (NBS) — nigba ti o se, o di Ileese Alajosepo Igbohunsafefe Orile-edee Naijiria (NBC), pelu ikanni igbohunsafefe ni awon eka ti Naijiria pin si. NBC papa parada di Ileese Alajosepo Igbohunsafefe Ijoba Apapo Orile-edee Naijiria (FRCN) lodun-un 1978. Ní ọdún-un 1950, RDS gbé aṣọ tuntun wọ̀ — ó di Iléeṣẹ́ Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà (NBS) — nígbà tí ó ṣe, ó di Iléeṣẹ́ Alájọṣepọ̀ Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà (NBC), pẹ̀lú ìkànnì ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ní àwọn ẹ̀ka tí Nàìjíríà pín sí. NBC pàpà paradà di Iléeṣẹ́ Alájọṣepọ̀ Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Ìjọba Àpapọ̀ Orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà (FRCN) lọ́dún-un 1978. """Ileese Redio akoko ni Naijiria ti a da sile ni Ibadan ni odun-un 1939." """Iléeṣẹ́ Rédíò àkọ́kọ́ ní Nàìjíríà tí a dá sílẹ̀ ní Ìbàdàn ní ọdún-un 1939." "Ikanni-i Kano lo telee ni 1944,"" gege bi ileese iroyin oriaayelujara Legit ti se salaye." "Ìkànnì-i Kano ló tẹ̀lée ní 1944,"" gẹ́gẹ́ bí iléeṣẹ́ ìròyìn oríaayélujára Legit ti ṣe ṣàlàyé." Legit salaye wipe RayPower FM, ni redio aladaani akoko ni orile-edee Naijiria, odun-un 1994 ni a da a sile, nigbati o mmaa fi di odun-un 2007, awon olugbo ti n gbo iroyin kari aye. Legit ṣàlàyé wípé RayPower FM, ni rédíò aládàáni àkọ́kọ́ ní orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, ọdún-un 1994 ni a dá a sílẹ̀, nígbàtí ó mmáa fi di ọdún-un 2007, àwọn olùgbọ́ ti ń gbọ́ ìròyìn kárí ayé. Redio ti sise gege bii ohun elo ayewo fun awon ti o wa nipo ase, ifidirinle ofin ati ipese ikede ti yoo lapa daadaa lara awon eniyan. Rédíò ti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bíi ohun èlò àyẹ̀wò fún àwọn tí ó wà nípò àṣẹ, ìfìdírinlẹ̀ òfin àti ìpèsè ìkéde tí yóò lapa dáadáa lára àwọn ènìyàn. Ni odun-un 2019, Igbimo Eto Igbohunsafefe Orile-edee Naijiria (NBC) san African Independent Television ati RayPower FM pa nitori wipe o se agbejade eto ti o tako ijoba. Ní ọdún-un 2019, Ìgbìmọ̀ Ètò Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà (NBC) ṣán African Independent Television àti RayPower FM pa nítorí wípé ó ṣe àgbéjáde ètò tí ó tako ìjọba. Bakan naa ni odun- 2019, Jay FM tio wa ni Port Harcourt di sisanpa leyin ti a fi esun itako ijoba kan an. Bákan náà ní ọdún- 2019, Jay FM tíó wà ní Port Harcourt di ṣíṣánpa lẹ́yìn tí a fi ẹ̀sùn ìtako ìjọba kàn án. "Okoo Radio Nigeria se ipolowo ara re gege bii ""ileese igbohunsafefe egbeegberun odun,"" ti o si darapo mo awon osise redio kari aye fun isaami ayeye Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye odun-un 2020." "Ọkọ̀ọ Radio Nigeria ṣe ìpolówó ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi ""iléeṣẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ẹgbẹẹgbẹ̀rún ọdún,"" tí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn òṣìṣẹ́ rédíò kárí ayé fún ìsààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020." Aworan lati owoo Muhammadtaha Ibrahim Ma'aji, ti a gba ase lati lo o ni ibamu pelu ase CC BY 2.0. Àwòrán láti ọwọ́ọ Muhammadtaha Ibrahim Ma'aji, tí a gba àṣẹ láti lò ó ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ CC BY 2.0. Redio ti o n mu isodokan ati igbega waye Rédíò tí ó ń mú ìsọdọ̀kan àti ìgbéga wáyé UNESCO ro ilu gbogbo lati saami ayeye Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye nipase sise awon eto ajose pelu ileese igbohunsafefe, ileese ijoba, ileese aladaani ati ileese ti ki i se ti ijoba kari aye. UNESCO rọ ìlú gbogbo láti sààmì ayẹyẹ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé nípasẹ̀ ṣíṣe àwọn ètò àjọṣe pẹ̀lú iléeṣẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́, iléeṣẹ́ ìjọba, iléeṣẹ́ aládàáni àti iléeṣẹ́ tí kì í ṣe ti ìjọba kárí ayé. "Akori Ayajo Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye ti odun yii, ti i se ikerinla iru e ni ""Ero-igbohunsafefe ati Oniruuru.""" "Àkórí Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ti ọdún yìí, tí í ṣe ìkẹrìnlá irú ẹ̀ ni ""Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ àti Onírúurú.""" Redio elero-amititi orile-edee Naijiria n ji giri si oro asaroo re ti o ni igbesoke awon eniyan ati sise isodokan eto afuniloye, akonilekoo ati asinileti to n ro awon omo orile-edee Naijiria lagbara lati ni ife ilu eni. Rédíò ẹlẹ́rọ-amìtìtì orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ń jí gìrì sí ọ̀rọ̀ àṣàròo rẹ̀ tí ó ní ìgbésókè àwọn ènìyàn àti ṣíṣe ìsọdọ̀kan ètò afúnilóye, akọ́nilẹ́kọ̀ọ́ àti aṣínilétí tó ń ró àwọn ọmọ orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà lágbára láti ní ìfẹ́ ìlú ẹni. Eyi wulo ni asiko ti ipinya ati iyapa eya, aibale-okan latari oro oselu to n kojuu orile-edee Naijiria. Èyí wúlò ní àsìkò tí ìpínyà àti ìyapa ẹ̀yà, àìbalẹ̀-ọkàn látàrí ọ̀rọ̀ òṣèlú tó ń kojúu orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Ipin ipo Ilu ti o rorun lati fo odun-un 2019 fi Naijiria si ipo kerinla lagbaaye, ikesan-an ni Ile-Adulawo. Ìpín ipò Ìlú tí ó rọrùn láti fọ́ ọdún-un 2019 fi Nàìjíríà sí ipò kẹrìnlá lágbàáyé, ìkẹsàn-án ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀. Lati odun-un 2011, Boko Haram, ajijangbara esin Imale ni Ila-oorun arewa orile-edee Naijiria, ti fi eru si okan awon eniyan ati bi awon ikolu to roro won ti se fa iku lai ro tele ipi awon eniyan, ti opoo si ti di awati. Láti ọdún-un 2011, Boko Haram, ajìjàǹgbara ẹ̀sìn Ìmàle ní Ìlà-oòrùn àréwá orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, ti fi ẹ̀rù sí ọkàn àwọn ènìyàn àti bí àwọn ìkọlù tó rorò wọ́n ti ṣe fa ikú láì rò tẹ́lẹ̀ ìpí àwọn ènìyàn, tí ọ̀pọ̀ọ́ sì ti di àwátì. Ka siwaju si i: Naijiria: Ilu ti o kuna — ooto tabi iwoye? Kà síwájú sí i: Nàìjíríà: Ìlú tí ó kùnà — òótọ́ tàbí ìwòye? Ni itesiwaju igbesoke orile-edee Naijiria, awon alase FRCN Eka ti Eko se agbekale okanojokan eto lati saami Ayajo Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye odun-un 2020. Ní ìtẹ̀síwájú ìgbésókè orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, àwọn aláṣẹ FRCN Ẹ̀ka ti Èkó ṣe àgbékalẹ̀ ọkànòjọ̀kan ètò láti sààmì Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé ọdún-un 2020. "Ere gbogboo bere pelu idije aroko oloro 1,200 ti o da lorii ""idi ti mo fi nifee si lati maa gbo redio"" fun awon akekoo ileewe giga." "Eré gbogboó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìdíje àròkọ ọlọ́rọ̀ 1,200 tí ó dá lóríi ""ìdí tí mo fi nífẹ̀ẹ́ sí láti máa gbọ́ rédíò"" fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ iléèwé gíga." Awon akekoo imo ise iroyin naa se eto alalaye oniseeju 5 ti o da firigbagboo lorii patakii ero-igbohunsafefe fun imuse awon ilepa imuduro idagbasoke. Awon akopa meji lo jawe olubori. Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ìmọ̀ iṣẹ́ ìròyìn náà ṣe ètò alálàyé oníṣẹ̀ẹ́jú 5 tí ó dá fìrìgbagbòó lóríi pàtàkìi ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ fún ìmúṣẹ àwọn ìlépa ìmúdúró ìdàgbàsókè. Àwọn àkópa méjì ló jáwé olúborí. Olubori idije aroko Ilori Oluwatobi ti ileewe Mater Christi Catholic Girls' High School, Igede Ekiti, Ipinle Ekiti, mu u wa si iranti igba akoko ti oun-un salabaapadee redio nigba ti oun-un wa ni omo odun 5: Olúborí ìdíje àròkọ Ìlọ̀rí Olúwatóbi ti iléèwé Mater Christi Catholic Girls' High School, Ìgede Èkìtì, Ìpínlẹ̀ Èkìtì, mú u wá sí ìrántí ìgbà àkọ́kọ́ tí òùn-ún ṣalábàápàdée rédíò nígbà tí òùn-ún wà ní ọmọ ọdún 5: O da bi eni pe omo odun 5 ni mi nigba ti mo koko ni ero-igbohunsafefee mi. Ó dà bí ẹni pé ọmọ ọdún 5 ni mí nígbà tí mo kọ́kọ́ ní ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ẹ̀ mi. Mo te awon ohun-ate-ase ara re, o si tan. Mo tẹ àwọn ohun-àtẹ̀-àṣẹ ara rẹ̀, ó sì tàn. "Iyalenu lo je fun mi bi mo se n gbo ohun ti o n ti inuu ""apoti"" yii jade ti mo si ro wipe awon eeyan lo wa ninuu re." "Ìyàlẹ́nu ló jẹ́ fún mi bí mo ṣe ń gbọ́ ohùn tí ó ń ti inúu ""àpótí"" yìí jáde tí mo sì rò wípé àwọn èèyàn ló wà nínúu rẹ̀." Eru ba mi mo si beere lowoo babaa mi ohun ti o je, o si salaye ohun ti redio je fun mi. Ẹ̀rú bá mi mo sì béèrè lọ́wọ́ọ bàbáà mi ohun tí ó jẹ́, ó sì ṣàlàyé ohun tí rédíò jẹ́ fún mi. Ni ojo 12 osu Erele, awon akekoo ile eko giga, akekoo imo ise iroyin, oje sorosoro ati awon alenuloro ninu ise iroyin ati awon ololufee redio pejupese si Lekki Coliseum ni Eko fun apero lati jiroro nipa patakii ero-igbohunsafefe fun idagbasoke. Ní ọjọ́ 12 oṣù Èrèlé, àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga, akẹ́kọ̀ọ́ ìmọ̀ iṣẹ́ ìròyìn, ọ̀jẹ̀ sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ àti àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ nínú iṣẹ́ ìròyìn àti àwọn olólùfẹ́ẹ̀ rédíò péjúpésẹ̀ sí Lekki Coliseum ní Èkó fún àpérò láti jíròrò nípa pàtàkìi ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ fún ìdàgbàsókè. Ni ojo 12 osu Erele, awon akekoo ile eko giga, akekoo imo ise iroyin, oje sorosoro ati awon alenuloro ninu ise iroyin ati awon ololufee redio pejupese si Lekki Coliseum ni Eko fun apero lati jiroro nipa patakii ero-igbohunsafefe fun idagbasoke. Ní ọjọ́ 12 oṣù Èrèlé, àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga, akẹ́kọ̀ọ́ ìmọ̀ iṣẹ́ ìròyìn, ọ̀jẹ̀ sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ àti àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ nínú iṣẹ́ ìròyìn àti àwọn olólùfẹ́ẹ̀ rédíò péjúpésẹ̀ sí Lekki Coliseum ní Èkó fún àpérò láti jíròrò nípa pàtàkìi ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ fún ìdàgbàsókè. Aworan lati owoo Omo Yooba, a gba ase lati lo o. Àwòrán láti ọwọ́ọ Ọmọ Yoòbá, a gba àṣẹ láti lò ó. Ni igbati ojo ro, awon ogbontarigi sorosoro, awon asoju the Oba Eko, Otunba Gani Adams, Aare Ona Kakanfo ilee Yoruba ati awon alejo miiran pejo si Lekki Coliseum fun apeje ale ati ifamieye danilola Ayajo Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye. Ní ìgbàtí ọjọ́ rọ̀, àwọn ògbóǹtarìgì sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀, àwọn aṣojú the Ọba Èkó, Ọ̀túnba Gani Adams, Ààrẹ Ọ̀nà Kakanfò ilẹ̀ẹ Yorùbá àti àwọn àlejò mìíràn péjọ sí Lekki Coliseum fún àpèjẹ alẹ́ àti ìfàmìẹ̀yẹ dánilọ́lá Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé. Awon agba ojee sorosoro bii Cordelia Okpei ati awon to ku wa si ayeye naa. Àwọn àgbà ọ̀jẹ̀ẹ sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ bíi Cordelia Okpei àti àwọn tó kù wá sí ayẹyẹ náà. Ami-eyee fun akikanju lenu ise ati isisesinlu lo si odo awon eni ti o to si. Àmì-ẹ̀yẹ̀ẹ̀ fún akíkanjú lẹ́nu iṣẹ́ àti ìṣiṣẹ́sìnlú lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹni tí ó tọ́ sí. Okan-o-jokan eto naa wa sopin pelu isoju opo sile lati gba ipe awon olugbo wole sori afefe, nibi ti won ti ni ki awon eniyan o so wipe “e ku Ayajo Ojo Ero-igbohunsafefe Agbaye” ni awon oniruuru okan-o-jokan ede ati ahon: Ọ̀kan-ò-jọ̀kan ètò náà wá sópin pẹ̀lú ìṣójú òpó sílẹ̀ láti gba ìpè àwọn olùgbọ́ wọlé sórí afẹ́fẹ́, níbi tí wọ́n ti ní kí àwọn ènìyàn ó sọ wípé “ẹ kú Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àgbáyé” ní àwọn onírúurú ọ̀kan-ò-jọ̀kan èdè àti ahọ́n: Ko seni ti ko kopa ninu ayeye naa. Ohun awon iko Ohun Agbaye naa bo sori afefe ni ori ikanni Metro 97.7FM. Awon sorosoro ti o ti feyinti lo ka iroyin ti won si tokun eto. Kò sẹ́ni tí kò kópa nínú ayẹyẹ náà. Ohùn àwọn ikọ̀ Ohùn Àgbáyé náà bọ́ sórí afẹ́fẹ́ ní orí ìkànnì Metro 97.7FM. Àwọn sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ tí ó ti fẹ̀yìntì ló ka ìròyìn tí wọ́n sì tọ́kùn ètò. Akoko iru ‘e ni Ayajo Ojo Ero-igbohunsafefe Redio Orile-edee Naijiria odun-un 2020 amo awon osise ati ololufee redio lero wipe ayeye naa yoo maa waye lodoodun. Àkọ́kọ́ irú ‘ẹ̀ ni Àyájọ́ Ọjọ́ Ẹ̀rọ-ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Rédíò Orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ọdún-un 2020 àmọ́ àwọn òṣìṣẹ́ àti olólùfẹ́ẹ̀ rédíò lérò wípé ayẹyẹ náà yóò máa wáyé lọ́dọọdún. Oloye yii nireti wi pe awon omo Yoruba yoo tewo gba 'alifabeeti t'o n soro ' ti oun hu imo re Olóyè yìí nírètí wí pé àwọn ọmọ Yorùbá yóò tẹ́wọ́ gba 'alífábẹ́ẹ̀tì t'ó ń sọ̀rọ̀ ' tí òun hu ìmọ̀ rẹ̀ Nje ilana isowoko Yoruba tuntun yoo di lilo lojo iwaju bi? Ǹjẹ́ ìlànà ìṣọwọ́kọ Yorùbá tuntun yóò di lílò lọ́jọ́ iwájú bí? Oloye Tolulase Oguntosin duro legbee oba ile-Yoruba kaafata, Ooni ti Ile-Ife, lori ijokoo. Olóyè Tolúlàṣẹ Ògúntósìn dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọba ilẹ̀-Yorùbá káàfàtà, Ọọ̀ni ti Ilé-Ifẹ̀, lórí ìjókòó. Oloye Oguntosin lo yanda aworan. Olóyè Ògúntósìn ló yànda àwòrán. Leyin ipolongo kari aye nipa Odun Ede Ibile Agbaye ni odun 2019 ati ikede Odun mewaa Ede Ibile Agbaye 2022-2032, pupo ninu awon omo Ile-Adulawo lo ti bere okan-o-jokan akanse ise to ni se pelu idagbasoke awon ede Ile-Adulawo. Lẹ́yìn ìpolongo kárí ayé nípa Ọdún Èdè Ìbílẹ̀ Àgbáyé ní ọdún 2019 àti ìkéde Ọdún mẹ́wàá Èdè Ìbílẹ̀ Àgbáyé 2022-2032, púpọ̀ nínú àwọn ọmọ Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ló ti bẹ̀rẹ̀ ọ̀kan-ò-jọ̀kan àkànṣe iṣẹ́ tó ní ṣe pẹ̀lú ìdàgbàsókè àwọn èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀. Lilo ayalo ilana Latiini fun kiko ede Yoruba yoo di afiseyin ti eegun alare n fiso lai pe ni eyi ti omo Kaaaro-o-o-ji-ire kan, Oloye Tolulase Oguntosin, eni ti o n gbe ni Ile Olominira Bene, Iwo-oorun Ile-Adulawo, ti hu imo ilana ti a o maa lo fun kiko ede Yoruba. Lílo àyálò ìlànà Látíìnì fún kíkọ èdè Yorùbá yóò di àfìsẹ́yìn tí eégún aláré ń fiṣọ láì pẹ́ ní èyí tí ọmọ Káàárọ̀-o-ò-jí-ire kan, Olóyè Tolúlàṣẹ Ògúntósìn, ẹni tí ó ń gbé ní Ilẹ̀ Olómìnira Bẹ̀nẹ̀, Ìwọ̀-oòrùn Ilẹ̀-Adúláwọ̀, ti hu ìmọ̀ ìlànà tí a ó máa lò fún kíkọ èdè Yorùbá. Alifabeeti Yoruba tuntun naa ti n gbalu kan pelu ireti wi pe yoo paaro ti Latiini ti o ti je lilo fun ogorun-un odun ati ju bee lo. Alífábẹ́ẹ̀tì Yorùbá tuntun náà ti ń gbàlú kan pẹ̀lú ìrètí wí pé yóò pààrọ ti Látíìnì tí ó ti jẹ́ lílò fún ọgọ́rùn-ún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ. Gege bi Oloye Oguntosin ti se ro fun Ohun Agbaye ninu iforowanilenuwo lori WhatsApp, oju ala ni alifabeeti aramanda wonyi ti f'ara han si oun. Gẹ́gẹ́ bí Olóyè Ògúntósìn ti ṣe rò fún Ohùn Àgbáyé nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò lórí WhatsApp, ojú àlá ni alífábẹ́ẹ̀tì àràmàndà wọ̀nyí ti f'ara hàn sí òun. "Ni bayii, nise ni o maa n se irinajo jakejado Ile-Yoruba — lati Bene titi de Naijiria — lati polongo ""alifabeeti ti o n soro "" re bi awon alale ti se fi ran an." "Ní báyìí, níṣe ni ó máa ń ṣe ìrìnàjò jákèjádò Ilẹ̀-Yorùbá — láti Bẹ̀nẹ̀ títí dé Nàìjíríà — láti polongo ""alífábẹ́ẹ̀tì tí ó ń sọ̀rọ̀ "" rẹ̀ bí àwọn alálẹ̀ ti ṣe fi rán an." Oloye Oguntosin nigbagbo wi pe Oduduwa, ti o je baba-nla iran Yoruba lo alifabeeti naa ni aye atijo — amo o ti di ohun igbagbe. Olóyè Ògúntósìn nígbàgbọ́ wí pé Odùduwà, tí ó jẹ́ bàbá-ńlá ìran Yorùbá lo alífábẹ́ẹ̀tì náà ní ayé àtijọ́ — àmọ́ ó ti di ohun ìgbàgbé. 25 ni gbogbo awon ami wonyi lapapo. 25 ni gbogbo àwọn àmì wọ̀nyí lápapọ̀. Awon onimo nipa ede ni Ile-Adulawo so wi pe ki ilosiwaju o to de ba Ile Adulawo, o pon dandan ki o ni ilana isowo ko ede tabi ilana kiko ti o je tire. Àwọn onímọ̀ nípa èdè ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ sọ wí pé kí ìlọsíwájú ó tó dé bá Ilẹ̀ Adúláwọ̀, ó pọn dandan kí ó ní ìlànà ìṣọwọ́ kọ èdè tàbí ìlànà kíkọ tí ó jẹ́ tirẹ̀. Ede ti o wa labe isori Niger-Congo ti o je ede iran ti o ti wa lojo to ti pe ti o si laju bi ede Yoruba o gbodo gbokan te ilana ayalo fun kiko ero ati imo iriri aye re. Èdè tí ó wà lábẹ́ ìsọ̀rí Niger-Congo tí ó jẹ́ èdè ìran tí ó ti wà lọ́jọ́ tó ti pẹ́ tí ó sì lajú bí èdè Yorùbá ò gbọdọ̀ gbọ́kàn tẹ ìlànà àyálò fún kíkọ èrò àti ìmọ̀ ìrírí ayé rẹ̀. Ka si i: Oro ayalo ninu ede Yoruba: Bi ede se yi pada Kà sí i: Ọ̀rọ̀ àyálò nínú èdè Yorùbá: Bí èdè ṣe yí padà Ni odun 1843, Alufaa Samueli Ajayi Crowther osise Egbe Ise Iranse Esin Igbagbo (CMS) se agbekale ilana isowoko ede Yoruba nipa yiya ilana Latiini lo pelu afikun awon ami ohun — tabi ami iro oro. Ní ọdún 1843, Àlùfáà Sámúẹ́lì Àjàyí Crowther òṣìṣẹ́ Ẹgbẹ́ Iṣẹ́ Ìránṣẹ́ Ẹ̀sìn Ìgbàgbọ́ (CMS) ṣe àgbékalẹ̀ ìlànà ìṣọwọ́kọ èdè Yorùbá nípa yíya ìlànà Látíìnì lò pẹ̀lú àfikún àwọn àmì ohùn — tàbí àmì ìró ọ̀rọ̀. Lati igba naa, egbeegberun iwe ti je tite jade ni ede Yoruba nipase lilo ilana kiko Latiini dipo Ajami, ti i se ilana isowoko Larubawa ti o ti je lilo teletele ri fun kiko ede Iwo-oorun Ile-Adulawo bi i ede Yoruba ati Hausa ki o to di 1843. Láti ìgbà náà, ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìwé ti jẹ́ títẹ̀ jáde ní èdè Yorùbá nípasẹ̀ lílo ìlànà kíkọ Látíìnì dípò Ajami, tí í ṣe ìlànà ìṣọwọ́kọ Lárúbáwá tí ó ti jẹ́ lílò tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ́ rí fún kíkọ èdè Ìwọ̀-oòrùn Ilẹ̀-Adúláwọ̀ bí i èdè Yorùbá àti Haúsá kí ó tó di 1843. Awon alagbawi ede gba wi pe lilo ilana Latiini, ti o je isowoko lati ile okeere, fun kiko awon ede Ile-Adulawo sile, fi ile naa sinu ipo eru. Àwọn alágbàwí èdè gbà wí pé lílo ìlànà Látíìnì, tí ó jẹ́ ìṣọwọ́kọ láti ilẹ̀ òkèèrè, fún kíkọ àwọn èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ sílẹ̀, fi ilẹ̀ náà sínú ipò ẹrú. Ipolongo ilana isowoko tuntun yii waye ni ibamu pelu awon isowoko ayebaye Ile-Adulawo, bi i hieroglyphics ti Ijipiti, Akojo Adrinka ti iran Akan ni Ghana, Ge'ez ti Ethiopia, isowoko iyaworan Nsibidi ti Aarin Gbungbun Iwo-oorun Ile-Adulawo ti o ti wa fun bi 5000 odun k'a to bi Jesu, ati alifabeeti Vai ni Ile-Adulawo je orisun won. Ìpolongo ìlànà ìṣọwọ́kọ tuntun yìí wáyé ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ìṣọwọ́kọ ayébáyé Ilẹ̀-Adúláwọ̀, bí i hieroglyphics ti Íjípìtì, Àkójọ Adrinka ti ìran Akan ní Ghana, Ge'ez ti Ethiopia, ìṣọwọ́kọ ìyàwòrán Nsibidi ti Àárín Gbùngbùn Ìwọ̀-oòrùn Ilẹ̀-Adúláwọ̀ tí ó ti wà fún bí 5000 ọdún k'á tó bí Jésù, àti alífábẹ́ẹ̀tì Vai ni Ilẹ̀-Adúláwọ̀ jẹ́ orísun wọn. Isayewo 'alifabeeti to n soro ' Ìṣàyèwò 'alífábẹ́ẹ̀tì tó ń sọ̀rọ̀ ' Alakooso Ohun Agbaye lede Yoruba, Omo Yooba fi oro wa Oloye Oguntosin lenu wo, nipase ise-ije ohun lori ero iitakuroso WhatsApp, lati mo si i nipa bi o ti se ri alifabeeti tuntun yii. Alákòóso Ohùn Àgbáyé lédè Yorùbá, Ọmọ Yoòbá fi ọ̀rọ̀ wá Olóyè Ògúntósìn lẹ́nu wò, nípasẹ̀ iṣẹ́-ìjẹ́ ohùn lórí ẹ̀rọ iìtàkùrọ̀sọ WhatsApp, láti mọ̀ sí i nípa bí ó ti ṣe rí alífábẹ́ẹ̀tì tuntun yìí. Oloye Oguntosin, to je omo odun 43 bayii, salaye wi pe oun ko le ka ju ile giga lo leyin ipapoda baba oun ni odun 1997, ti oun si ni lati se ojuse bi baba gege bi akobi lati toju awon aburo re. Olóyè Ògúntósìn, tó jẹ́ ọmọ ọdún 43 báyìí, ṣàlàyé wí pé òun kò lè ka ju ilé gíga lọ lẹ́yìn ìpapòdà bàbá òun ní ọdún 1997, tí òun sì ní láti ṣe ojúṣe bí bàbá gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí láti tọ́jú àwọn àbúrò rẹ̀. Sibe, bi oloye Yoruba ti o je, ise igbelaruge asa re da lori isokan awon omo Oduduwa je ohun ti o gbe e lokan gidi gan-an, ti o si n se bi olulaja laaarin won. Síbẹ̀, bí olóyè Yorùbá tí ó jẹ́, iṣẹ́ ìgbélárugẹ àṣà rẹ̀ dá lórí ìṣọ̀kan àwọn ọmọ Odùduwà jẹ́ ohun tí ó gbé e lọ́kàn gidi gan-an, tí ó sì ń ṣe bí olùlàjà láàárín wọn. Bi ise igbelaruge asa yii se n gbooro si i, ko te e lorun to bi o se fe. Bí iṣẹ́ ìgbélárugẹ àṣà yìí ṣe ń gbòòrò sí i, kò tẹ́ ẹ lọ́rùn tó bí ó ṣe fẹ́. Lodun 2011, o fi eeji kun eeji, o fi eeta kun eeta, o gba oko alawo lo. Lọ́dún 2011, ó fi eéjì kún eéjì, ó fi ẹẹ́ta kún ẹẹ̀ta, ó gba oko aláwo lọ. Babalawo naa, Olokun Awopetu, wi fun un pe ki o lo si ojubo idile re ti o wa ni agbegbe Farasinmi ni Agbadarigi (Badagry), Ipinle Eko, orile ede Naijiria, wi pe yoo ri atona ti yoo toka si ohun ti Eledumare ran an wa se laye ni ojubo naa. Babaláwo náà, Olókun Awópẹ̀tu, wí fún un pé kí ó lọ sí ojúbọ ìdílé rẹ̀ tí ó wà ní agbègbè Farasìnmí ní Àgbádárìgì (Badagry), Ìpínlẹ̀ Èkó, orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, wí pé yóò rí atọ́nà tí yóò tọ́ka sí ohun tí Elédùmarè rán an wá ṣe láyé ní ojúbọ náà. Ni ojubo naa, o ri “nnkan ajeji” kan ti o mu pada si ile re ni Porto-Novo, Bene. Ní ojúbọ náà, ó rí “nǹkan àjèjì” kan tí ó mú padà sí ilé rẹ̀ ní Porto-Novo, Bẹ̀nẹ̀. Nigba ti o dele, okunkun bo iyara birimubirimu. Nígbà tí ó délé, òkùnkùn bo iyàrá birimùbirimù. Ko si ina amororo ninu yara igbalejo, imole itansan ero amohunmaworan ni o maa n fi riran. Kò sí iná amọ́roro nínú yàrá ìgbàlejò, ìmọ́lẹ̀ ìtànṣán ẹ̀rọ àmóhùnmáwòrán ni ó máa ń fi ríran. O gbe nnkan ajeji naa si ori aga igbennkanle, o si tan ero amohunmaworan, kayefi lo je fun un, ohun ti o gbe sori aga di awati. Ó gbé nǹkan àjèjì náà sí orí àga ìgbénǹkanlé, ó sì tan ẹ̀rọ àmóhùnmáwòrán, kàyéfì ló jẹ́ fún un, ohun tí ó gbé sórí àga di àwátì. O tu gbogbo ile ki o to wa ri i ni koro ile. Ó tú gbogbo ilé kí ó tó wá rí i ní kọ̀rọ̀ ilé. Lale ojo yen, o fi nnkan ajeji naa sabe igberi sun. O so fun Ohun Agbaye: Lálẹ́ ọjọ́ yẹn, ó fi nǹkan àjèjì náà sábẹ́ ìgbèrí sùn. Ó sọ fún Ohùn Àgbáyé: Mo lalaa wi pe mo lo si inu oorun. Mo lálàá wí pé mo lọ sí inú oòrùn. Nigba ti mo debe, o okunkun su bole, a si fi alifabeeti naa han mi ni apeere imole. Nígbà tí mo débẹ̀, ó òkùnkùn ṣú bolẹ̀, a sì fi alífábẹ́ẹ̀tì náà hàn mí ní àpẹẹrẹ ìmọ́lẹ̀. Igbakuugba ti mo ba sun, ala yii kan naa ni ni ona ara, mo n lo lati agbegbe kan si agbegbe miiran, ti mo si n ko awon eniyan bi a ti se n lo isowoko tuntun naa... Ìgbàkúùgbà tí mo bá sùn, àlá yìí kan náà ni ní ọ̀nà àrà, mò ń lọ láti agbègbè kan sí agbègbè mìíràn, tí mo sì ń kọ́ àwọn ènìyàn bí a ti ṣe ń lo ìṣọwọ́kọ tuntun náà... Fun odun meta, ko ye lalaa nipa alifabeeti naa, ko ye riran leralera, sibe ko se nnkankan si i. Fún ọdún mẹ́ta, kò yé lálàá nípa alífábẹ́ẹ̀tì náà, kò yé ríran léraléra, síbẹ̀ kò ṣe nǹkankan sí i. Lasiko yii, ni odun 2016, mo tun lo si inu oorun, mo salabaapade okunrin kan, Lamurudu, ti o ko mi ni iro alifabeeti naa, ti o si pa a lase fun mi pe ki tan imole imo kiko ati kika ami isowoko naa kari aye. Lásìkò yìí, ní ọdún 2016, mo tún lọ sí inú oòrùn, mo ṣalábàápàdé ọkùnrin kan, Lámúrúdu, tí ó kọ́ mi ní ìró alífábẹ́ẹ̀tì náà, tí ó sì pa á láṣẹ fún mi pé kí tan ìmọ́lẹ̀ ìmọ̀ kíkọ àti kíkà àmì ìṣọwọ́kọ̀ náà kárí ayé. Mo maa n jo arugbo loju ala — ti yoo si re mi — bi mo ba ji loju oorun. Mo máa ń jọ arúgbó lójú àlá — tí yóò sì rẹ̀ mí — bí mo bá jí lójú oorun. O wa bere si ni di eru fun Oloye Oguntosin — o n re e latinu wa, o wi fun Ohun Agbaye. Ó wá bẹ̀rẹ̀ sí ní di ẹ̀rù fún Olóyè Ògúntósìn — ó ń rẹ̀ ẹ́ látinú wá, ó wí fún Ohùn Àgbáyé. O pinnu lati ro awon ala naa fun Onikoyi, Alajase ti Ajase ni Port-Novo, eni ti o la a loye pe ki o se bi a ti pa a lase loju ala. Ó pinnu láti rọ́ àwọn àlá náà fún Oníkòyí, Alájàṣẹ́ ti Àjàṣẹ́ ní Port-Novo, ẹni tí ó là á lóye pé kí ó ṣe bí a ti pa á láṣẹ lójú àlá. Latari idi eyi, o n se irinajo lati agbegbe kan de omiran ni Ile-Yoruba lati tan imo alifabeeti Oduduwa naa. Látàrí ìdí èyí, ó ń ṣe ìrìnàjò láti agbègbè kan dé òmíràn ní Ilẹ̀-Yorùbá láti tan ìmọ̀ alífábẹ́ẹ̀tì Odùduwà náà. Aworan-atohun awon olukoni ti o ko awon akekoo bi a ti se n ko alifabeeti Oduduwa ni yara-igbeko kan ni Bene: Àwòrán-àtohùn àwọn olùkọ́ni tí ó kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ bí a ti ṣe ń kọ alífábẹ́ẹ̀tì Odùduwà ní yàrá-ìgbẹ̀kọ́ kan ní Bẹ̀nẹ̀: Igbelaruge alifabeeti Yoruba naa Ìgbélárugẹ alífábẹ́ẹ̀tì Yorùbá náà Lodun 2017, Oloye Oguntosin, pelu awon oba Alase igba-keji orisa Ile-Yoruba nile ati leyin odi, se abewo to si Ogbeni Rauf Aregbesola, eni ti o fi igba kan ri je alakooso Ipinle Osun, ni olu ipinle naa th Osogbo, e one- ede Naijiria, lati beere fun atileyin fun alifabeeti Oduduwa tuntun naa. Lọ́dún 2017, Olóyè Ògúntósìn, pẹ̀lú àwọn ọba Aláṣẹ igbá-kejì òrìṣà Ilẹ̀-Yorùbá nílé àti lẹ́yìn odi, ṣe àbẹ̀wó to sí Ọ̀gbẹ́ni Rauf Arẹ́gbẹ́ṣọlá, ẹni tí ó fi ìgbà kan rí jẹ́ alákòóso Ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun, ní olú ìpínlẹ̀ náà th Òṣogbo, e one- èdè Nàìjíríà, láti béèrè fún àtìlẹ́yìn fún alífábẹ́ẹ̀tì Odùduwà tuntun náà. Aregbesola ni Minisita fun Eto Abele fun orile-ede Naijiria ni saa ti a wa yii. Arẹ́gbẹ́ṣọlá ni Mínísítà fún Ètò Abélé fún orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní sáà ti a wà yìí. Iwe ti a ko ranse si gomina ipinle Osun ni iranti awon ipinnu kiko alifabeeti tuntun naa ti ko tii wa si imuse. Ìwé tí a kọ ránṣẹ́ sí gómìnà ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun ní ìrántí àwọn ìpinnu kíkọ́ alífábẹ́ẹ̀tì tuntun náà tí kò tíì wá sí ìmúṣẹ. Odun meta ti lo, o bani lokan je, ileri ti gomina ana Aregbesola se lati ri daju wi pe alifabeeti tuntun naa je kiko ni awon ileewe ti o n be ni Iwo-oorun guusu ile Naijiria ko tii di mumu se. Ọdún mẹ́ta ti lọ, ó bani lọ́kàn jẹ́, ìlérí tí gómìnà àná Arẹ́gbẹ́ṣọlá ṣe láti rí dájú wí pé alífábẹ́ẹ̀tì tuntun náà jẹ́ kíkọ́ ni àwọn iléèwé tí ó ń bẹ ní Ìwọ̀-oòrùn gúúsù ilẹ̀ Nàìjíríà kò tíì di múmú ṣẹ. Lojuna ki alifabeeti Oduduwa naa o ba di ilumooka, Oloye Oguntosin ti ko iwe kan, o si ti ka aworan-atohun alalaye kan ti o tu perepeere isowoko alifabeeti tuntun naa sile — fun mutumuwa lati wo ni abalaabala lori ayelujara — bakan naa ni epatiri ise akonilogbon katuunu fun awon ewe ti ko s'owo lati pari i re naa o gbeyin. Lójúnà kí alífábẹ́ẹ̀tì Odùduwà náà ó ba di ìlúmọ̀ọ́ká, Olóyè Ògúntósìn ti kọ ìwé kan, ó sì ti ká àwòrán-àtohùn alálàyé kan tí ó tú pẹrẹpẹ́ẹ̀rẹ̀ ìṣọwọ́kọ alífábẹ́ẹ̀tì tuntun náà sílẹ̀ — fún mùtúmùwà láti wò ní abalaabala lórí ayélujára — bákan náà ni ẹ̀patìrì iṣẹ́ akọ́nilọ́gbọ́n kàtúùnù fún àwọn èwe tí kò s'ówó láti parí i rẹ̀ náà ò gbẹ́yìn. "Oloye Oguntosin n lo gbagbe YouTube, WhatsApp ati Egbe ori Facebook: ""Eko Aeebaejiogbe Oduduwa"" ati “Alifabeeti Oduduwa” fi se igbelaruge ati ko awon akekoo ti o nifee si kiko ilana isowoko naa." "Olóyè Ògúntósìn ń lo gbàgbé YouTube, WhatsApp àti Ẹgbẹ́ orí Facebook: ""Ẹ̀kọ́ Aèébáèjìogbè Odùduwà"" àti “Alífábẹ́ẹ̀tì Odùduwà” fi ṣe ìgbélárugẹ àti kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí ó nífẹ̀ẹ́ sí kíkọ́ ìlànà ìṣọwọ́kọ náà." O ro gbogbo eni ti oran kan lati dide si ti igbelaruge awari ti yoo gba ilana isowoko Amunisin ti segbee ti yoo si fun iran Yoruba ni idanimo ti o to ti o ni se pelu idagbasoke ede. Ó rọ gbogbo ẹni tí ọ̀ràn kan láti dìde sí ti ìgbélárugẹ àwárí tí yóò gbá ìlànà ìṣọwọ́kọ Àmúnisìn tì sẹ́gbẹ̀ẹ́ tí yóò sì fún ìran Yorùbá ní ìdánimọ̀ tí ó tọ́ tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìdàgbàsókè èdè. "Okunrin oninuure kan, Sunday Adeniyi, se agbateru itejade 1,000 eda iwe igbeko ""Alifabeeti Aeebaejiogbe Oduduwa"" fun awon omo ileewe alakoobere." "Ọkùnrin onínúure kan, Sunday Adéníyì, ṣe agbátẹrù ìtẹ̀jáde 1,000 ẹ̀da ìwé ìgbẹ̀kọ́ ""Alífábẹ́ẹ̀tì Aèébáèjìogbè Odùduwà"" fún àwọn ọmọ iléèwé alákọ̀ọ̀bẹ̀rẹ̀." Ka si i: Sisonu sinu ogbufo: Idi ti Atumo Google se n kuna — ninu titumo ede Yoruba — ati awon ede miiran Kà sí i: Sísọnù sínú ògbufọ̀: Ìdí tí Atúmọ̀ Google ṣe ń kùnà — nínú títúmọ̀ èdè Yorùbá — àti àwọn èdè mìíràn Eda iwe eko alifabeeti naa wa ni ede Igbo, Hausa, English, ati Faranse leseese. Sibesibe, atileyin ki i po ju fun ipinkari alifabeeti naa. Ẹ̀da ìwé ẹ̀kọ́ alífábẹ́ẹ̀tì náà wà ní èdè Igbo, Hausa, English, àti Faransé lẹ́sẹẹsẹ. Síbẹ̀síbẹ̀, àtìlẹ́yìn kì í pọ̀ jù fún ìpínkárí alífábẹ́ẹ̀tì náà. Igbese ti o mu iwuri dani ni alifabeeti Oduduwa naa. Ìgbésẹ̀ tí ó mú ìwúrí dání ni alífábẹ́ẹ̀tì Odùduwà náà. Sugbon, sisun lati ilana Latiini si ilana tuntun ni yoo mu ipenija nla lowo. Ṣùgbọ́n, sísún láti ìlànà Látíìnì sí ìlànà tuntun ni yóò mú ìpèníjà ńlá lọ́wọ́. Ko je bo se je, ohun ti yoo mu ilosiwaju ati idagbasoke ba ede Yoruba ni alifabeeti Oduduwa — ohun ti iran Yoruba yoo pe ni tiwa-n-tiwa. Kò jẹ́ bó ṣe jẹ́, ohun tí yóò mú ìlọsíwájú àti ìdàgbàsókè bá èdè Yorùbá ni alífábẹ́ẹ̀tì Odùduwà — ohun tí ìran Yorùbá yóò pè ni tiwa-ń-tiwa. Oro ayalo ninu ede Yoruba: Bi ede se yi pada Ọ̀rọ̀ àyálò nínú èdè Yorùbá: Bí èdè ṣe yí padà Se akara ni o n pe abi bean cake? Ṣé àkàrà ni ò ń pè àbí bean cake? Akara tabi beans cake ni Naijiria je ounje aaro ni Naijiria, ojo 11, osu keje, odun 2013. Aworan lati owo Atimukoh lati ori i Wikimedia Commons, ase CC BY 2.0. Àkàrà tàbí beans cake ní Nàìjíríà jẹ́ oúnjẹ àárọ̀ ní Nàìjíríà, ọjọ́ 11, oṣù kéje, ọdún 2013. Àwòrán láti ọwọ́ Atimukoh láti orí i Wikimedia Commons, àṣẹ CC BY 2.0. Ajosepo laaarin oniruuru ede ti wa lati ayebaye. Àjọṣepọ̀ láàárín onírúurú èdè ti wà láti ayébáyé. "Fun akawe, ki a wo gbolohun bi i ""restaurant,"" ti o je oro ti a ya lati inu ede Faranse wa sinu ede Geesi." "Fún àkàwé, kí á wo gbólóhùn bí i ""restaurant,"" tí ó jẹ́ ọ̀rọ̀ tí a yá láti inú èdè Faransé wá sínú èdè Gẹ̀ẹ́sì." Lode oni, oro-ayalo yii — iyen gbolohun ti a gba lo lati inu ede kan si inu ede miiran lai tu imo re — ko l'onka ninu ede Geesi afi bi eni pe ki i se oro ti a ya lo. Lóde òní, ọ̀rọ̀-àyálò yìí — ìyẹn gbólóhùn tí a gbà lò láti inú èdè kan sí inú èdè mìíràn láì tú ìmọ̀ rẹ̀ — kò l'óǹkà nínú èdè Gẹ̀ẹ́sì àfi bí ẹni pé kì í ṣe ọ̀rọ̀ tí a yá lò. Awon ede ayalo wonyi waye latari abapade oniruuru eniyan kari aye, bi won se n sikiri, se oro Aje, ati karakata. Àwọn èdè àyálò wọ̀nyí wáyé látàrí àbápàdé onírúurú ènìyàn kárí ayé, bí wọ́n ṣe ń ṣíkiri, ṣe ọrọ̀ Ajé, àti káràkátà. Latari itakuroso ti o waye laaarin awon oniruuru eniyan wonyi, ede wonu ede, gbolohun ati apola oro di ayalo. Látàrí ìtàkùrọ̀sọ tí ó wáyé láàárín àwọn onírúurú ènìyàn wọ̀nyí, èdè wọnú èdè, gbólóhùn àti àpólà ọ̀rọ̀ di àyálò. Isele yii ko yo iran Yoruba sile. Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí kò yọ ìran Yorùbá sílẹ̀. O to egbeegberun eniyan 40 tio n fo ede Yoruba ni orile ede Naijiria, iru ede Yoruba ti dapo mo sapala ede Geesi, ti i se ede ijoba amunisin ana lati odun 1914 si 1960. Ó tó ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn 40 tíó ń fọ èdè Yorùbá ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, irú èdè Yorùbá ti dàpọ̀ mọ́ ṣapala èdè Gẹ̀ẹ́sì, tí í ṣe èdè ìjọba amúnisìn àná láti ọdún 1914 sí 1960. "O to idaji gbolohun ede Geesi ti a ya lo ninu ede Yoruba. Ki a wo oro bi i ""cup"" O di koopu." "Ó tó ìdajì gbólóhùn èdè Gẹ̀ẹ́sì tí a yà lò nínú èdè Yorùbá. Kí a wo ọ̀rọ̀ bí i ""cup"" Ó di kó̩ò̩pù." "A pe ""phone"" ni foonu, ""ball"" di boolu, ""television"" ni telifisoonu, ati bee bee lo." "A pe ""phone"" ní fóònù, ""ball"" di bó̩ò̩lù, ""television"" ni te̩lifís̩ó̩ò̩nù, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ." "Awon gbolohun ""ayalo"" wonyi mu ede Yoruba feju si i." "Àwọn gbólóhùn ""àyálò"" wọ̀nyí mú èdè Yorùbá fẹjú sí i." Bakan naa ni awon oro ayalo inu ede Hausa ti awon egbeegberun 44 eniyan ni Ariwa ile Naijiria n so lo sua. Bákan náà ni àwọn ọ̀rọ̀ àyálò inú èdè Hausa tí àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún 44 ènìyàn ní Àríwá ilẹ̀ Nàìjíríà ń sọ lọ sua. "Ede yii ya oke aimoye oro lo lati inu ede Larubawa, awon oro bi i alubarika (""ibukun""), albasa (""alubosa"") ati wahala (""iyonu"")." "Èdè yìí yá ọ̀kẹ́ àìmọye ọ̀rọ̀ lò láti inú èdè Lárúbáwá, àwọn ọ̀rọ̀ bí i àlùbáríkà (""ìbùkún""), àlbásà (""àlùbọ́sà"") àti wàhálà (""ìyọnu"")." Ohun ti o je iwuri ni ti awon oro ayalo ninu ede Yoruba ni bi awon eniyan se n lo won ninu itakuroso lojoojumo bi won se n san wo inu ede naa. Ohun tí ó jẹ́ ìwúrí ní ti àwọn ọ̀rọ̀ àyálò nínú èdè Yorùbá ni bí àwọn ènìyàn ṣe ń lò wọ́n nínú ìtàkùrọ̀sọ lójoojúmọ́ bí wọ́n ṣe ń ṣàn wọ inú èdè náà. "Wa a gbo gbolohun bi i, Ba omo yen mu boolu e tabi ""Help the child take the ball"" lede Geesi." "Wà á gbọ́ gbólóhùn bí i, Bá o̩mo̩ ye̩n mú bó̩ò̩lu è̩ tàbí ""Help the child take the ball"" lédè Gẹ̀ẹ́sì." Adi, omo-oro ti a fala si labe boolu je tiwantiwa ninu ede Yoruba, awon asafo mo bi won se n lo o. Adi, ọmọ-ọ̀rọ̀ tí a falà sí lábẹ́ bó̩ò̩lu jẹ́ tiwantiwa nínú èdè Yorùbá, àwọn aṣàfọ̀ mọ bí wọ́n ṣe ń lò ó. Ipenija kan ti ede Yoruba ni nipa ti oro ayalo o ju ti ogbufo oro wuuru ti awon asafo ede Yoruba maa n se lati tumo awon gbolohun ede Yoruba si ti Geesi ti won maa n lo ninu ipede dipo ojulowo ede Yoruba. Ìpèníjà kan tí èdè Yorùbá ní nípa ti ọ̀rọ̀ àyálò ò ju ti ògbufọ̀ ọ̀rọ̀ wuuru tí àwọn aṣàfọ̀ èdè Yorùbá máa ń ṣe láti túmọ̀ àwọn gbólóhùn èdè Yorùbá sí ti Gẹ̀ẹ́sì tí wọ́n máa ń lò nínú ìpèdè dípò ojúlówó èdè Yorùbá. Fun apeere, akara — ti awon omo Yoruba ti tumo si bean cake — paapaa ninu iforojomitoro-oro pelu alejo. Fún àpẹẹrẹ, àkàrà — tí àwọn ọmọ Yorùbá ti túmọ̀ sí bean cake — pàápàá nínú ìfọ̀rọ̀jomitoro-ọ̀rọ̀ pẹ̀lú àlejò. Lilo oro ni ede ponbele maa n mu ki asa — o gbooro — ti yoo si maa je ki ede o di itewogba. Lílo ọ̀rọ̀ ní èdè pọ́nbélé máa ń mú kí àṣà — ó gbòòrò — tí yóò sí máa jẹ́ kí èdè ó di ìtẹ́wọ́gbà. Bi a ba wo o bayii, ko s'eni je pe sushi Japan loruko miiran — sushi ni sushi n je. Bí a bá wò ó báyìí, kò s'ẹ́ni jẹ́ pe sushi Japan lórúkọ mìíràn — sushi ni sushi ń jẹ́. Bi eyi ba ri bee fun awon oro Yoruba naa, ede ati asa re, yoo gbile koja orile-ede Naijiria ati ibi ti won ti n fo ede Yoruba kari aye. Bí èyí bá rí bẹ́ẹ̀ fún àwọn ọ̀rọ̀ Yorùbá náà, èdè àti àṣà rẹ̀, yóò gbilẹ̀ kọjá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti ibi tí wọ́n ti ń fọ èdè Yorùbá kárí ayé. Fun apeere, amala je ounje ti o ile Yoruba lokiki, paapaa ni oke okun. Fún àpẹẹrẹ, àmàlà jẹ́ oúnjẹ tí ó ilẹ̀ Yorùbá lókìkí, pàápàá ní òkè òkun. Gbolohun yii ti ra pala wonu ilo oro ede miiran bi awon asafo Yoruba ba tenu mo on. Gbólóhùn yìí ti rá pálá wọnú ìlò ọ̀rọ̀ èdè mìíràn bí àwọn aṣàfọ̀ Yorùbá bá tẹnu mọ́ ọn. "Titumo re si ""yam flour"" din agbara ipede naa ku — yoo so ""ipo Yoruba nu.""" "Títúmọ̀ rẹ̀ sí ""yam flour"" dín agbára ìpèdè náà kù — yóò sọ ""ipò Yorùbá nù.""" "Bi a ba wo gbolohun ede Geesi ti a yi pada si ede Yoruba ""fanimorious"", ti o ti n lokiki ti o si ti wa ninu Iwe Itumo Igbalode." "Bí a bá wo gbólóhùn èdè Gẹ̀ẹ́sì tí a yí padà sí èdè Yorùbá ""fanimorious"", tí ó ti ń lókìkí tí ó sì ti wà nínú Ìwé Ìtumọ̀ Ìgbàlódé." O tumo si “bojumu,” tabi “rewa,” ti o suyo lati fanimora ti i se gbolohun Yoruba. Ó túmọ̀ sí “bójúmu,” tàbí “rẹwà,” tí ó súyọ láti fanimó̩ra tí í ṣe gbólóhùn Yorùbá. Eyi f'ara pe ibasepo fonoloji ati mofoloji: ede Yoruba ki i faye gba ihunpo konsonanti ati ki oro pari pelu konsonanti. Èyí f'ara pẹ́ ìbáṣepọ̀ fonọ́lọ́jì àti mọfọ́lọ́jì: èdè Yorùbá kì í fàyè gba ìhunpọ̀ kọ̀nsónántì àti kí ọ̀rọ̀ parí pẹ̀lú kọ̀nsónántì. Tori idi eyi, a fi afomo ipari -ious ede Geesi kun oro ipile Yoruba. Torí ìdí èyí, a fi àfòmọ́ ìparí -ious èdè Gẹ̀ẹ́sì kún ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ Yorùbá. Sibe, otito farahan wipe lati ara ede Yoruba ni o ti su yo. Igbega ni eyi je fun Yor Yoruba. Síbẹ̀, òtítọ́ farahàn wípé láti ara èdè Yorùbá ni ó ti sú yọ. Ìgbéga ni èyí jẹ́ fún Yor Yorùbá. Ni ko pe ko pe yii, ogoro ede Geesi bi a ti se n lo o ni Naijiria di afikun ninu iwe itumo ede Geesi ti Oxford. Ní kò pẹ́ kò pẹ́ yìí, ọ̀gọ̀rọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì bí a ti ṣe ń lò ó ní Nàìjíríà di àfikún nínú ìwé ìtúmọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì ti Oxford. Opon ede Yoruba yoo sun siwaju bi awon to n fo ede naa ba lowo si idagbasoke re; ilo re ninu ise ikoroyin pon dandan ni ibamu pelu bi aye se n lu jara won bi ajere lode oni. Ọpọ́n èdè Yorùbá yóò sún síwájú bí àwọn tó ń fọ èdè náà bá lọ́wọ́ sí ìdàgbàsókè rẹ̀; ìlò rẹ̀ nínú iṣẹ́ ìkọ̀ròyìn pọn dandan ní ìbámu pẹ̀lú bí ayé ṣe ń lu jára wọn bí ajere lóde òní. Ni ipari, eyi yoo tubo mu ki ise iwadii ede Niger-Congo o rinle. Ní ìparí, èyí yóò túbọ̀ mú kí iṣẹ́ ìwádìí èdè Niger-Congo ó rinlẹ̀. Sisonu sinu ogbufo: Idi ti Atumo Google se n kuna — ninu titumo ede Yoruba — ati awon ede miiran Sísọnù sínú ògbufọ̀: Ìdí tí Atúmọ̀ Google ṣe ń kùnà — nínú títúmọ̀ èdè Yorùbá — àti àwọn èdè mìíràn Opolopo ogbufo ti ero se ni ko nitumo. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ògbufọ̀ tí ẹ̀rọ ṣe ni kò nítumọ̀. Asamulo Egbe Wikimedia Orile-ede Naijiria, osu Owara odun 2018 lati ori Wikimedia Commons CC.BY.2.0. Aṣàmúlò Ẹgbẹ́ Wikimedia Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, oṣù Ọ̀wàrà ọdún 2018 láti orí Wikimedia Commons CC.BY.2.0. "Ede Geesi ti je gaba lori ibanisoro ti o n waye ni ori ero ayelukara-bi-ajere gege bi ede ""gbogbo agbaye"" fun itakuroso lati ibere pepe ero ayelujara." "Èdè Gẹ̀ẹ́sì ti jẹ gàba lórí ìbánisọ̀rọ̀ tí ó ń wáyé ní orí ẹ̀rọ ayélukára-bí-ajere gẹ́gẹ́ bí èdè ""gbogbo àgbáyé"" fún ìtàkùrọ̀sọ láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ẹ̀rọ ayélujára." Ninu osu Erele odun 2020, gege bi WebTech3 ti se fi han, idaji ibudo itakun agbaye to wa lori ayelujara ni a ko ni ede Geesi. Nínú oṣù Èrèlé ọdún 2020, gẹ́gẹ́ bí WebTech3 ti ṣe fi hàn, ìdajì ibùdó ìtakùn àgbáyé tó wà lórí ayélujára ni a kọ ní èdè Gẹ̀ẹ́sì. Amo bi opolopo eniyan ti o n so orisiirisii ede agbaye se n bo sori ayelukara-bi-ajere, o se eta ija fun ede eni — iraaye si isogbufo si oniruuru ede ti yoo se ni monawaa. Àmọ́ bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tí ó ń sọ oríṣìíríṣìí èdè àgbáyé ṣe ń bọ́ sórí ayélukára-bí-ajere, ó ṣẹ́ ẹtà ìjà fún èdè ẹni — ìráàyè sí ìṣògbufọ̀ sí onírúurú èdè tí yóò ṣẹ̀ ní mọnawáà. Opolopo ileese onimo ero ti se ise ribiribi ni ti isakosile awon oro ti ki i se ede Geesi sori ayelujara, ti o n se olulana oniruuru ede lori ero ayarabiasa lona igbalode. Google, Yoruba Names, Masakhane MT ati ALC je apeere awon ileese nla ati awon ileese kereje ti o sese bere ti o ti mu imo-ero sise po pelu awon ede ti ki i se ede Geesi. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iléeṣẹ́ onímọ̀ ẹ̀rọ ti ṣe iṣẹ́ ribiribi ní ti ìṣàkọsílẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ tí kì í ṣe èdè Gẹ̀ẹ́sì sórí ayélujára, tí ó ń ṣe olùlànà onírúurú èdè lórí ẹ̀rọ ayárabíàṣá lọ́nà ìgbàlódé. Google, Yoruba Names, Masakhane MT àti ALC jẹ́ àpẹẹrẹ àwọn iléeṣẹ́ ńlá àti àwọn iléeṣẹ́ kéréje tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ tí ó ti mú ìmọ̀-ẹ̀rọ ṣiṣẹ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn èdè tí kì í ṣe èdè Gẹ̀ẹ́sì. Ki osu Erele odun 2020 o to tenu bepo, Google filo wipe oun yoo fi ede tuntun marun-un kun ise Atumo Google re, awon ede naa ni Kinyarwanda, Uighur, Tatar, Turkmen ati Odia, leyin isinmi odun merin ti won fi ede tuntun kun un keyin. Kí oṣù Èrèlé ọdún 2020 ó tó tẹnu bepo, Google filọ̀ wípé òun yóò fi èdè tuntun márùn-ún kún iṣẹ́ Atúmọ̀ Google rẹ̀, àwọn èdè náà ni Kinyarwanda, Uighur, Tatar, Turkmen àti Odia, lẹ́yìn ìsinmi ọdún mẹ́rin tí wọ́n fi èdè tuntun kún un kẹ́yìn. Okunrin kan n wo bi eni ti o nidaamu nigba ti o n ka gbolohun oro lori ayelujara. Aworanllati owo Oladimeji Ajegbile, ase-atunlo lati ori Pexels. Ọkùnrin kan ń wò bí ẹni tí ó nídààmú nígbà tí ó ń ka gbólóhùn ọ̀rọ̀ lórí ayélujára. Àwòránlláti ọwọ́ Ọládiméjì Ajégbilẹ̀, àṣẹ-àtúnlò láti orí Pexels. Amo se o ti sira te asayan itumo ri ti o sakiyesi wipe, bakan, lo dara ju lo? Àmọ́ ṣe o ti ṣíra tẹ àṣàyàn ìtumọ̀ rí tí ó ṣàkíyèsí wípé, bákan, ló dára jù lọ? Bakan naa, lo ku die kaato, ko se deedee? Bákan náà, ló kù díẹ̀ káàtó, kò ṣe déédéé? Orisiirisii ariyanjiyan ati isoro lo maa n waye bi o ba kan iru itumo ede bayii ati riri i lo. Orísìírísìí àríyànjiyàn àti ìṣòro ló máa ń wáyé bí ó bá kan irú ìtumọ̀ èdè báyìí àti rírí i lò. Twitter maa n se itumo ede Yoruba si ede Geesi nipase lilo Atumo Google bi o ti se faye gba won, ti abajade re si ku die kaato nigbagbogbo — ti awon oro kookan si se deedee. Twitter máa ń ṣe ìtumọ̀ èdè Yorùbá sí èdè Gẹ̀ẹ́sì nípasẹ̀ lílo Atúmọ̀ Google bí ó ti ṣe fàyè gbà wọ́n, tí àbájáde rẹ̀ sì kù díẹ̀ káàtó nígbàgbogbo — tí àwọn ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan sì ṣe déédéé. Ohun ti o fa awon ipenija wonyi o ju pe ori ayelujara ni awon ileese onimo ero ti maa n se akojo ede won for ti won n fi se ogbufo gbolohun oro. Ohun tí ó fa àwọn ìpeníjà wọ̀nyí ó ju pé orí ayélujára ni àwọn iléeṣẹ́ onímọ̀ ẹ̀rọ ti máa ń ṣe àkójọ èdè wọn for tí wọ́n ń fi ṣe ògbufọ̀ gbólóhùn ọ̀rọ̀. Awon akojo gbolohun oro wonyi le sise fun awon ede kan, amo ede bi i Yoruba ati Igbo, je ede meji ni orile-ede Naijiria, ti ipenija yii ba, latari aipoto gbolohun oro ati gbolohun ti a o yan lorilabe daadaa ti yoo toka si iro ohun. Àwọn àkójọ gbólóhùn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí lè ṣiṣẹ́ fún àwọn èdè kan, àmọ́ èdè bí i Yorùbá àti Ìgbò, jẹ́ èdè méjì ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, tí ìpèníjà yìí bá, látàrí àìpọ̀tó gbólóhùn ọ̀rọ̀ àti gbólóhùn tí a ò yán lórílábẹ́ dáadáa tí yóò tọ́ka sí ìró ohùn. Lati fesi si ohun ti o fa sababi ti o fi gba Google ni odun merin ki o to se afikun ede tuntun marun-un kun tile, agbenuso ileese naa se isipaya: Láti fèsì sí ohun tí ó fa sábàbí tí ó fi gba Google ní ọdún mẹ́rin kí ó tó ṣe àfikún èdè tuntun márùn-ún kún tilẹ̀, agbẹnusọ iléeṣẹ́ náà ṣe ìṣípayá: Ori itakun agbaye ni Atumo Google ti maa n sa gbolohun ti a ti tumo jo, amo bi ede ko ba ni gbolohun oro ti o po to lori ayelujara, o nira fun ero wa lati se atileyin ti o lakaaki fun iru awon ede bee Orí ìtakùn àgbáyé ni Atúmọ̀ Google ti máa ń ṣa gbólóhùn tí a ti túmọ̀ jọ, àmọ́ bí èdè kò bá ní gbólóhùn ọ̀rọ̀ tí ó pọ̀ tó lórí ayélujára, ó nira fún ẹ̀rọ wa láti ṣe àtìlẹ́yìn tí ó lákaakì fún irú àwọn èdè bẹ́ẹ̀ Sibe, latari ilosiwaju abuda kiko ero lekoo wa, ati awon asise Itumo Google lofee, ecent advances in our machine a ti fi atileyin fun awon ede wonyi. Síbẹ̀, látàrí ìlọsíwájú àbùdá kíkọ́ ẹ̀rọ lẹ́kọ̀ọ́ wa, àti àwọn aṣiṣẹ́ Ìtumọ̀ Google lọ́fẹ̀ẹ́, ecent advances in our machine a ti fi àtìlẹ́yìn fún àwọn èdè wọ̀nyí. Bakan naa, opo eniyan ni ko mo bi a se n ko oro dajudanu — tabi pipe omo-oro — inu awon ede wonyi. Bákan náà, ọ̀pọ̀ ènìyàn ni kò mọ bí a ṣe ń kọ ọ̀rọ̀ dájúdánu — tàbí pípe ọmọ-ọ̀rọ̀ — inú àwọn èdè wọ̀nyí. Tori naa, ogbufo ti o kunju osuwon ko je akopo nitori ko si bi a se le da awon asise wonyi mo. Torí náà, ògbufọ̀ tí ó kúnjú òṣùwọ̀n kò jẹ́ àkópọ̀ nítorí kò sí bí a ṣe lè dá àwọn àṣìṣe wọ̀nyí mọ̀. Pupo ninu ogbufo ti ero se ni ko ni itumo, paapaa ju lo awon gbolohun ti o ro mo asa ti o ni ju itumo kan soso lo. Púpọ̀ nínú ògbufọ̀ tí ẹ̀rọ ṣe ni kò ní ìtumọ̀, pàápàá jù lọ àwọn gbólóhùn tí ó rọ̀ mọ́ àṣà tí ó ní ju ìtúmọ̀ kan ṣoṣo lọ. Fun apeere, gbolohun Yoruba bi i ayaba ati obabinrin ni itumo to yato. Fún àpẹẹrẹ, gbólóhùn Yorùbá bí i ayaba àti ọbabìnrin ní ìtumọ̀ tó yàtọ̀. "Opolopo ero ni i maa tu imo gbolohun mejeeji si ""queen""." "Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀rọ ní í máa tú ìmọ̀ gbólóhùn méjèèjì sí ""queen""." "Sibe, ti a ba ti ona ise-ati-asa wo o, o se koko lati so wi pe itumo ayaba and obabinrin yato sira won: Obabinrin tumo si ""queen"" lede Geesi nigba ti ayaba je ""wife of the king""." "Síbẹ̀, tí a bá ti ọ̀nà ìṣe-àti-àsà wò ó, ó ṣe kókó láti sọ wí pé ìtúmọ̀ ayaba and ọbabìnrin yàtọ̀ síra wọn: Ọbabìnrin túmọ̀ sí ""queen"" lédè Gẹ̀ẹ́sì nígbà tí ayaba jẹ́ ""wife of the king""." Pelu awon aisedeedee wonyi, imo-ero ti se iranwo fun idagbasoke awon ede Ile-Adulawo lori awon gbagede ori ayelujara, ti o ti mu iseda oro tuntun waye. Pẹ̀lú àwọn àìṣedéédéé wọ̀nyí, ìmọ̀-ẹ̀rọ ti ṣe ìrànwọ́ fún ìdàgbàsókè àwọn èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ lórí àwọn gbàgede orí ayélujára, tí ó ti mú ìṣẹ̀dá ọ̀rọ̀ tuntun wáyé. Ede Ile-Adulawo ti goke agba latari awon lilo awon ero igbalode tuntun bi i ero-ilewo ati ero opon ayarabiasa, ti o si n bi awon gbolohun tuntun ti a fi n pe awon irinse imo-ero tuntun wonyi. Èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ti gòkè àgbà látàrí àwọn lílo àwọn ẹ̀rọ ìgbàlódé tuntun bí i ẹ̀rọ-ìléwọ́ àti ẹ̀rọ ọpọ́n ayárabíàṣá, tí ó sì ń bí àwọn gbólóhùn tuntun tí a fi ń pe àwọn irinṣẹ́ ìmọ̀-ẹ̀rọ tuntun wọ̀nyí. Eyi si ti fe bi a ti se n lo awon ede wonyi loju. Èyí sì ti fẹ bí a ti ṣe ń lo àwọn èdè wọ̀nyí lójú. Latari awon ero tuntun wonyi, ipede opolopo ede Ile-Adulawo ti le kun si i. Látàrí àwọn ẹ̀rọ tuntun wọ̀nyí, ìpèdè ọ̀pọ̀lọpọ̀ èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ti lé kún sí i. "Fun apeere, ede Yoruba ni awon gbolohun ti o ni se pelu imo-ero bi i ero-amuletutu (""air conditioner""), ero-ibanisoro (""phone"") and ero-ilota (""grinder"")." "Fún àpẹẹrẹ, èdè Yorùbá ní àwọn gbólóhùn tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìmọ̀-ẹ̀rọ bí i ẹ̀rọ-amúlétutù (""air conditioner""), erọ-ìbánisọ̀rọ̀ (""phone"") and ẹ̀rọ-ìlọta (""grinder"")." "Ewewe, ede Igbo naa ni oro bi i ekwe nti (""telephone"") ati ugbo ala (""vehicle"")." "Ẹ̀wẹ̀wẹ̀, èdè Igbo náà ní ọ̀rọ̀ bí i ekwè nti (""telephone"") àti ugbọ̀ àlà (""vehicle"")." A seda awon oruko yii ni ibamu pelu ise ti won n se. A ṣẹ̀dá àwọn orúkọ yìí ní ìbámu pẹ̀lú iṣẹ́ tí wọ́n ń ṣe. Ninu eko imo igbohunsafefe ati eto ipolowo oja lede Yoruba, awon akekoo ti ko wi pe ero-amohunmaworan ni oopolopo eniyan n pe TV. Nínú ẹ̀kọ́ ìmọ̀ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ àti ètò ìpolówó ọjà lédè Yorùbá, àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ti kọ́ wí pé ẹ̀rọ-amóhùnmáwòrán ni oọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ń pe TV. Iseda oro yii fa awon oniruuru ibeere ati ero — awon akekoo kan jiyan wi pe a le pe ero-ayaworan naa ni ero-amohunmaworan nitori ise ti won n se. Ìṣẹ̀dá ọ̀rọ̀ yìí fa àwọn onírúurú ìbéèrè àti èrò — àwọn akẹ́kọ̀ọ́ kan jiyàn wí pé a lè pe ẹ̀rọ-ayàwòrán náà ní ẹ̀rọ-amóhùnmáwòrán nítorí iṣẹ́ tí wọ́n ń ṣe. Awon ipenija t'o tara imo-ero wa yii ni yoo mu idagbasoke ba ede — o maa n fa arojinle fun igbega ede ati imo-ero. Àwọn ìpèníjà t'ó tara ìmọ̀-ẹ̀rọ wá yìí ni yóò mú ìdàgbàsókè bá èdè — ó máa ń fa àròjìnlẹ̀ fún ìgbéga èdè àti ìmọ̀-ẹ̀rọ. "Lodun 2019, gege bi CNN ti se royin, Google si ibise iwadii AI akoko iru e si Accra, Ghana, ti o n lepa lati mu ki ""Atumo Google o gba awon ede Ile-Adulawo jo ki o lo geere""." "Lọ́dún 2019, gẹ́gẹ́ bí CNN ti ṣe ròyìn, Google ṣí ibiṣẹ́ ìwádìí AI àkọ́kọ́ irú ẹ̀ sí Accra, Ghana, tí ó ń lépa láti mú kí ""Atúmọ̀ Google ó gba àwọn èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ jọ kí ó lọ geere""." "Onimo ijinle nipa ise iwadii Moustapha Cisse, to je olori ise Google AI ni Ile-Adulawo, nigbagbo wi pe o to si ""ile ti o ni ju eka-ede 2,000 lo lati je anfaani ise,"" — CNN jabo." "Onímọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa iṣẹ́ ìwádìí Moustapha Cisse, tó jẹ́ olórí iṣẹ́ Google AI ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀, nígbàgbọ́ wí pé ó tọ́ sí ""ilẹ̀ tí ó ní ju ẹ̀ka-èdè 2,000 lọ láti jẹ́ àǹfààní iṣẹ́,"" — CNN jábọ̀." Mozilla ati BMZ kede ajumose won lati se agbateru ise akanse ti o da firigbagboo lori imo-ero alohun fun thei ede Ile-Adulawo. Pelu awon ise atinuda bi eleyii, ojo iwaju iwadii ede Ile-Adulawo dara. Mozilla àti BMZ kéde àjùmọ̀ṣe wọn láti ṣe agbátẹrù iṣẹ́ àkànṣe tí ó dá fìrìgbagbòó lórí ìmọ̀-ẹ̀rọ alohùn fún thei èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀. Pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ àtinudá bí eléyìí, ọjọ́ iwájú ìwádìí èdè Ilẹ̀-Adúláwọ̀ dára. Awon Ileejosin ni Greece ati Ariwa Macedonia ko lati yi owo awon ilana-isin won pada k'o ba ma faye gba ajakale arun COVID-19 t'o n ran ka Àwọn Iléèjọsìn ní Greece àti Àríwá Macedonia kọ̀ láti yí ọwọ́ àwọn ìlànà-ìsìn wọn padà k'ó ba má fàyè gba àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19 t'ó ń ràn ká """Ajo Ounje Ale Oluwa"", aworan ti a kun loda ni 1442 lati owo Fra Angelico. Aworan ti ko ni olohun lati ori Wikipedia." """Àjọ Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa"", àwòrán tí a kùn lódà ní 1442 láti ọwọ́ Fra Angelico. Àwòrán tí kò ní olóhun láti orí Wikipedia." Bi awon ti o ti ko arun COVID-19 se n poo si i ni Balkans, awon ile ijosin kan ko yi owo awon ilana isin ti o le mu ki arun Coronavirus o ran bi i papa inu oye pada. Bí àwọn tí ó ti kó àrùn COVID-19 ṣe ń pọ̀ọ́ sí i ní Balkans, àwọn ilé ìjọsìn kan kò yí ọwọ́ àwọn ìlànà ìsìn tí ó lè mú kí àrùn Coronavirus ó ràn bí i pápá inú ọyẹ́ padà. Ilana isin ti a mo si Jijeara ati mimu eje Oluwa tabi Ounje Ikeyin ni eyi ti awon omo leyin Kristi ti o n tele ilana isin atijo yoo maa pin waini ti a ti so di mimo mu pelu sibi kan naa, awon Ijo Agudaa maa n je ebe akara felefele ti won fi enu gba lowo alufaa. Ìlànà ìsìn tí a mọ̀ sí Jíjẹara àti mímu ẹ̀jẹ̀ Olúwa tàbí Oúnjẹ Ìkẹyìn ní èyí tí àwọn ọmọ lẹ́yìn Krístì tí ó ń tẹ̀lé ìlànà ìsìn àtijọ́ yóò máa pín wáìnì tí a ti sọ di mímọ́ mu pẹ̀lú ṣíbí kan náà, àwọn Ìjọ Àgùdàá máa ń jẹ ẹ̀bẹ àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí wọ́n fi ẹnu gbà lọ́wọ́ àlùfáà. Ajo Ilera Agbaye (WHO) ro wa lati jina gbegberegbe si ibi ti awon eroo ba piti si, ki a si karamasiki si ilera ara wa ki a ba din aranka arun eje ti eniyan le ko nipase ifowokan, ifarakan omi to sun lara elomiran, ati lati inu afefe. Àjọ Ìlera Àgbáyé (WHO) rọ̀ wá láti jìnà gbégbérégbé sí ibi tí àwọn èròó bá pitì sí, kí a sì káràmásíkì sí ìlera ara wa kí á ba dín àrànká àrùn ẹ̀jẹ̀ tí ènìyàn lè kó nípasẹ̀ ìfọwọ́kàn, ìfarakan omi tó sun lára ẹlòmíràn, àti láti inú afẹ́fẹ́. Ninu atejade ojo 9, Ileejosin Atijo Greek so wi pe oun ko ni yi owo ilana-isin pada ki o ba igbese aabo mu. Nínú àtẹ̀jáde ọjọ́ 9, Iléèjọsìn Àtijọ́ Greek sọ wí pé òun kò ní yí ọwọ́ ìlànà-ìsìn padà kí ó bá ìgbésẹ̀ ààbò mu. "Bakan naa ni o so wi pe ""a ko lee ko aarun coronavirus lati ara Jije ara-ati-mimu-eje Oluwa, ati pe ki awon omo Olorun o gbadura gidi nitori aarun apaniyan naa""." "Bákan náà ni ó sọ wí pé ""a kò leè kó ààrùn coronavirus láti ara Jíjẹ ara-àti-mímu-ẹ̀jẹ̀ Olúwa, àti pé kí àwọn ọmọ Ọlọ́run ó gbàdúrà gidi nítorí ààrùn apànìyàn náà""." Bisoopu ti GOC Klimis, ti Aarin gbungbun Peristeri, labe agbegbe to sun mo Athens, so wi pe oro-odi si Oluwa ni bi enikeni ba so pe ilana esin le mu ki aarun o ran: Bíṣọ́ọ̀pù ti GOC Klimis, ti Àárín gbùngbùn Peristeri, lábẹ́ agbègbè tó sún mọ́ Athens, sọ wí pé ọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa ni bí ẹnikẹ́ni bá sọ pé ìlànà ẹ̀sìn lè mú kí ààrùn ó ràn: Iye ni Ara-jije ati eje mimu. Ìyè ni Ara-jíjẹ àti ẹ̀jẹ̀ mímu. Ise iyanu ni. Iṣẹ́ ìyanu ni. Oro-odi si Oluwa ni lati ni igbagbo wi pe eniyan le tara Jije ara-ati-mimu-eje Oluwa ko aarun. Ọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa ni láti ní ìgbàgbọ́ wí pé ènìyàn lè tara Jíjẹ ara-àti-mímu-ẹ̀jẹ̀ Olúwa kó ààrùn. Eniyan 89 lo ti lugbadi COVID-19 ni Greece, laisi eni to ku. Ènìyàn 89 ló ti lùgbàdì COVID-19 ní Greece, láìsí ẹni tó kù. Awon alase Greek, ti o ti san awon ileewe pa, ti o si ti f'ofin de apejo loju ona ati dena ajakale, ro Ileejosin naa lati se atunwo. Àwọn aláṣẹ Greek, tí ó ti ṣán àwọn iléèwé pa, tí ó sì ti f'òfin de àpéjọ lójú ọ̀nà àti dènà àjàkálẹ̀, rọ Iléèjọsìn náà láti ṣe àtúnwò. Amo awon asoju ijoba tikarawon n tapa si ofin idena aarun yii. Lojo isinmi ajemesin kan lojo Ose to koja, aare ati awon onipo ninu isejoba re lo si isin kan. Àmọ́ àwọn aṣojú ìjọba tìkarawọn ń tàpá sí òfin ìdènà ààrùn yìí. Lọ́jọ́ ìsinmi ajẹmẹ́sìn kan lọ́jọ́ Ọ̀sẹ̀ tó kọjá, ààrẹ àti àwọn onípò nínú ìṣèjọba rẹ̀ lọ sí ìsìn kan. Ni ilu to mule gbe Greece, o jo pe North Macedonia, Ileejosin Atijo ti Macedonia – Ohrid Archbishopric naa n to ipase kan naa. Ní ìlú tó múlé gbe Greece, ó jọ pé North Macedonia, Iléèjọsìn Àtijọ́ ti Macedonia – Ohrid Archbishopric náà ń tọ ipasẹ̀ kan náà. Bi o tile je pe Ileejosin naa ko tii se ifilo kankan nipa ajakale naa, o si n fun awon omo ijo ni Ara je ati eje mu bi o ti maa n se. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Iléèjọsìn náà kò tíì ṣe ìfilọ̀ kankan nípa àjàkálẹ̀ náà, ó sì ń fún àwọn ọmọ ìjọ ní Ara jẹ àti ẹ̀jẹ̀ mu bí ó ti máa ń ṣe. "Iroyin kan nigba ti ojule ibudo itakun Prespa-Pelagonia Diocese se atejade ogbufo article aroko ibudo itakun to je ti Russia iyen Pravoslavie.ru (itumo ""Esin Igbagbo Atijo "") to n so wi pe ""ko le se e se ki awon onigbagbo o k'arun lati ara ilana-isin ijo""." "Ìròyìn kàn nígbà tí ojúlé ibùdó ìtakùn Prespa-Pelagonia Diocese ṣe àtẹ̀jáde ògbufọ̀ article àrọko ibùdó ìtakùn tó jẹ́ ti Russia ìyẹn Pravoslavie.ru (ìtumọ̀ ""Ẹ̀sìn Ìgbàgbọ́ Àtijọ́ "") tó ń sọ wí pé ""kò lè ṣe é ṣe kí àwọn onígbàgbọ́ ó k'árùn láti ara ìlànà-ìsìn ìjọ""." Alufaa Sergey Adonin ti Russia lo buwo lu apileko naa, eni to so pe oun ni imo nipa iseda eda oniye aifojuri pelu iriri ise ni ileewosan. Àlùfáà Sergey Adonin ti Russia ló buwọ́ lu àpilẹ̀kọ náà, ẹni tó sọ pé òun ní ìmọ̀ nípa ìṣẹ̀dá ẹ̀dá oníyè àìfojúrí pẹ̀lú ìrírí iṣẹ́ ní iléèwòsàn. "O so siwaju si i ninu apileko naa wi pe lilo sibi kan naa bi won ti se fi lole ni ogorun-un odun keje aye Bizantium o fa ipalara, nitori ""igbagbo ninu Olorun n fi iso aabo bo alufaa ati omo ijo""." "Ó sọ síwájú sí i nínú àpilẹ̀kọ náà wí pé lílo ṣíbí kan náà bí wọn ti ṣe fi lọ́lẹ̀ ní ọgọ́rùn-ún ọdún kéje ayé Bizantium ò fa ìpalára, nítorí ""ìgbàgbọ́ nínú Ọlọ́run ń fi ìṣọ́ ààbò bo àlùfáà àti ọmọ ìjọ""." Ni North Macedonia, awon ti o n mu se ti ilana-isin naa ni ko si aburu ninu ilana ileejosin naa. Ní North Macedonia, àwọn tí ó ń mú ṣe ti ìlànà-ìsìn náà ní kò sí aburú nínú ìlànà iléèjọsìn náà. Fun apeere, atokun eto lori ero amohunmaworan to je adasa-atijo-mu-sinsin — ajijangbara eni to ti fi igba kan ri se ipolongo itako ibupa — funnu lori Twitter wi pe oun ti kopa ninu awon ilana-isin ajemesin to lewu: Fún àpẹẹrẹ, atọ́kùn ètò lórí ẹ̀rọ amóhùnmáwòrán tó jẹ́ adàṣà-àtijọ́-mú-ṣinṣin — ajìjàǹgbara ẹni tó ti fi ìgbà kan rí ṣe ìpolongo ìtako ìbupá — fúnnu lórí Twitter wí pé òun ti kópa nínú àwọn ìlànà-ìsìn ajẹmẹ́sìn tó léwu: Tuwiiti: Mo je Ara Oluwa mu eje Oluwa lojo Aiku to koja ninu Ileejosin Holy Annunciation ti o wa ninu Ileewosan ti Skopje ti n o si tun se e! Túwíìtì: Mo jẹ Ara Olúwa mu ẹ̀jẹ̀ Olúwa lọ́jọ́ Àìkú tó kọjá nínú Iléèjọsìn Holy Annunciation tí ó wà nínú Iléèwòsàn ti Skopje tí n ó sì tún ṣe é! Ki ni isoro re? Kí ni ìṣòro rẹ̀? Akole adari: Pelu gbogbo ebe ajo to n ri si eto ilera: Awon onigbagbo je Ara mu eje Oluwa lai foya fun aarun coronavirus. Àkọlé adarí: Pẹ̀lú gbogbo ẹ̀bẹ̀ àjọ tó ń rí sí ètò ìlera: Àwọn onígbàgbọ́ jẹ Ara mu ẹ̀jẹ̀ Olúwa láì fòyà fún ààrùn coronavirus. "Sladjana Velkov, eni to gbajumo gege bi alatako-ibupa to n sise ni Serbia ati Ariwa Macedonia, so lai pe yii wi pe nnkan ko ""le toyen"" ati pe ""ofinkin lasan ni, eyi ti ko yato si ofinkin ti a ti mo tele, to maa n se awon agbalagba tabi awon ti ilera ara won ko pe to""." "Sladjana Velkov, ẹni tó gbajúmọ̀ gẹ́gẹ́ bí alátakò-ìbupá tó ń ṣiṣẹ́ ní Serbia àti Àríwá Macedonia, sọ láì pẹ́ yìí wí pé nǹkan kò ""le tóyẹn"" àti pé ""ọ̀fìnkìn lásán ni, èyí tí kò yàtọ̀ sí ọ̀fìnkìn tí a ti mọ̀ tẹ́lẹ̀, tó máa ń ṣe àwọn àgbàlagbà tàbí àwọn tí ìlera ara wọn kò pé tó""." Ni orile-ede Italy, nibi ti 631 emi eeyan 631 ti bo ti awon ti o to 10,000 ti lugbadi arun naa, asamulo kan tuwiiti: Ní orílẹ̀-èdè Italy, níbi tí 631 ẹ̀mí èèyàn 631 ti bọ́ tí àwọn tí ó tó 10,000 ti lùgbàdì àrùn náà, aṣàmúlò kan túwíìtì: Bi a ba ka a ni menimeji, o ti to eni meje ti o ti ko arun COVID-19 ni North Macedonia; 25 ni Slovenia; 13 ni Croatia; mefa ni Albania; fi marun-un ni Serbia; marun-un ni Bosnia; odo ni Montenegro. Bí á bá kà á ní méníméjì, ó ti tó ẹni méje tí ó ti kó àrùn COVID-19 ní North Macedonia; 25 ní Slovenia; 13 ní Croatia; mẹ́fà ní Albania; fi márùn-ún ní Serbia; márùn-ún ní Bosnia; òdo ní Montenegro. O ti to eni 28 to ti ko o ni Romania, mefa ni Bulgaria. Ó ti tó ẹni 28 tó ti kó o ní Romania, mẹ́fà ní Bulgaria. Onigbagbo nibi gbogbo Onígbàgbọ́ níbi gbogbo Ile aye ti ri bi coronavirus akoko iru e se le ran nibi ipejo ajemesin. Ilé ayé ti rí bí coronavirus àkọ́kọ́ irú ẹ̀ ṣe lè ràn níbi ìpéjọ ajẹmẹ́sìn. Losu to koja, opo eniyan ti o to 7,400 ni a gbo wi pe o ti ni arun apaniyan COVID-19 ni South Korea — orile-ede ti o jo pe o ti n gba arun naa mole — ri arun naa lara Ileejosin egbe Shincheonji ti Jesu. Lóṣù tó kọjá, ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó tó 7,400 ni a gbọ́ wí pé ó ti ní àrùn apànìyàn COVID-19 ní South Korea — orílẹ̀-èdè tí ó jọ pé ó ti ń gbá àrùn náà mọ́lẹ̀ — rí àrùn náà lára Iléèjọsìn ẹgbẹ́ Shincheonji ti Jésù. A fi esun odaran kan egbe naa — ti won maa n pe ni igbe-imule — olori egbe naa ti i se eni 8-odun wa sita lati se itoro aforiji. A fi ẹ̀sùn ọ̀daràn kan ẹgbẹ́ náà — tí wọ́n máa ń pè ní igbẹ́-ìmùlẹ̀ — olórí ẹgbẹ́ náà tí í ṣe ẹni 8-ọdún wá síta láti ṣe ìtọrọ àforíjì. Ni tire, Ajo Ilana-isin Atijo ti Korea se ifilo nipa awon ayipada to de ba isin re ni ibamu pelu afilele Ileese Eto Ilera: Ní tirẹ̀, Àjọ Ìlànà-ìsìn Àtijọ́ ti Korea ṣe ìfilọ̀ nípa àwọn àyípadà tó dé bá ìsìn rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú àfilélẹ̀ Iléeṣẹ́ Ètò Ìlera: 1. Gbogbo onigbagbo yoo wo ibomubenu lasiko ti isin ba n lo lowo. 1. Gbogbo onígbàgbọ́ yóò wọ ìbomúbẹnu lásìkò tí ìsìn bá ń lọ lọ́wọ́. 2. Ki won o wo Ileejosin, won yoo fi apakokoro to wa lenu abawole Ileejosin ra owo won. 2. Kí wọ́n ó wọ Iléèjọsìn, wọ́n yóò fi apakòkòrò tó wà lẹ́nu àbáwọlé Iléèjọsìn ra ọwọ́ wọn. 3. Won ko ni gba enikan lowo. 3. Wọn kò ní gba ẹnìkan lọ́wọ́. 4. Won ko ni f'enu ko Alufaa ijo lowo. 4. Wọn kò ní f'ẹnu ko Àlùfáà ìjọ lọ́wọ́. 5. Won ko ni fenu ko awon Ere, amo won o teriba niwaju won. 5. Wọn kò ní fẹnu ko àwọn Ère, àmọ́ wọn ó tẹríba níwájú wọn. 6. Won ko ni lo awon iwe adura nigba isin. 6. Wọn kò ní lo àwọn ìwé àdúrà nígbà ìsìn. 7. Won ko ni gba Akara lowo Alufaa ijo, amo funra won bi won ba n jade kuro ninu ileejosin. 7. Wọn kò ní gba Àkàrà lọ́wọ́ Àlùfáà ìjọ, àmọ́ fúnra wọn bí wọ́n bá ń jáde kúrò nínú iléèjọsìn. 8. Ounje Apeje Ife ko ni je pinpin lojo Aiku. 8. Oúnjẹ Àpèjẹ Ifẹ̀ kò ní jẹ́ pínpín lọ́jọ́ Àìkú. 9. Awon ipade elegbejegbe ati ti awon to n ko isin Olorun ko ni waye. 9. Àwọn ìpàdé ẹlẹ́gbẹ́jẹgbẹ́ àti ti àwọn tó ń kọ́ ìsìn Ọlọ́run kò ní wáyé. Awon ile ijosin kan ni Ile Geesi ti n se ayipada si ilana isin won, bi i ijo Aguda ti Italy. Àwọn ilé ìjọsìn kan ní Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ti ń ṣe àyípadà sí ìlànà ìsìn wọn, bí i ìjọ Àgùdà ti Italy. Ajo esin igbagbo Croatia naa en ti s'ofin to da le arun naa, ni France, ibi irinajo mimo kan ni ilu Lourdes ti di titi pa. Àjọ ẹ̀sìn ìgbàgbọ́ Croatia náà en ti ṣ'òfin tó dá lé àrùn náà, ní France, ibi ìrìnàjò mímọ kan ní ìlú Lourdes ti di títì pa. "Ileejosin Ilana-isin Atijo ti Romania fi ofin kan sita ""to je awon igbese ti eniyan yoo tele bi ajakale ba dukoko"":" "Iléèjọsìn Ìlànà-ìsìn Àtijọ́ ti Romania fi òfin kan síta ""tó jẹ́ àwọn ìgbésẹ̀ tí ènìyàn yóò tẹ̀lé bí àjàkálẹ̀ bá dúkokò"":" Awon onigbagbo tiberubojo arun apaniyan naa ti sojo s'okan won yoo pa ifenuko awon ere inu ile ijosin lara. Àwọn onígbàgbọ́ tíbẹ̀rùbojo àrùn apànìyàn náà ti sojo s'ọ́kan wọn yóò pa ìfènuko àwọn ère inú ilé ìjọsìn lára. Bi o ba wu won, won lee so fun alufaa wi pe sibi ti won ni awon fe lo fi gba Eje Oluwa mu. Bí ó bá wù wọ́n, wọ́n leè sọ fún àlùfáà wí pé ṣíbí ti wọn ni àwọn fẹ́ lò fi gba Ẹ̀jẹ̀ Olúwa mu. Leyin ti Italy pase pe ki gbogbo origun mereerin ilu o di sise pa, awon alamuulegbe, bi i Ile Olominira Czech naa gbe awon agbekale kan lojo 10, osu Erena ti won san awoniileewe pa. Lẹ́yìn tí Italy pàṣẹ pé kí gbogbo orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ìlú ó di sísé pa, àwọn alámùúlégbè, bí i Ilẹ̀ Olómìnira Czech náà gbé àwọn àgbékalẹ̀ kan lọ́jọ́ 10, oṣù Ẹrẹ́nà tí wọ́n ṣán àwọniiléèwé pa. Ijoba North Macedonia kede ipo ilu o f'ara ro, o si ti awon jeleosinmi, ileewe, titi kan ileewe giga ju lo Ifasitii pa fun ose meji. Ìjọba North Macedonia kéde ipò ìlú ò f'ara rọ, ó sì ti àwọn jẹ́léósinmi, iléèwé, títí kan iléèwé gíga jù lọ Ifásitìi pa fún ọ̀sẹ̀ méjì. Check Ye awon ise akanse Ohun Agbaye lori arapa COVID-19 lagbaaye. Check Yẹ àwọn iṣẹ́ àkànṣe Ohùn Àgbáyé lórí arapa COVID-19 lágbàáyé. Orile-Ede Naijiria fi ofin de irin-ajo lojuna isamojuto awon to ti ko kokoro aifojuri COVID 19 Orílẹ̀-Èdè Nàìjíríà fi òfin de ìrìn-àjò lójúnà ìṣàmójútó àwọn tó ti kó kòkòrò àìfojúrí COVID 19 Ifofinderinajo awon orile-ede 13 ti eniyan to ti ko COVID-19 ju 1,000 lo Ìfòfindèrìnàjò àwọn orílẹ̀-èdè 13 tí ènìyàn tó ti kó COVID-19 ju 1,000 lọ Aworan lati owo Pete Linforth ni Pixabay. Ilo aworan pelu ase Pixabay, fun ilo gbogboogbo. Àwòrán láti ọwọ́ Pete Linforth ní Pixabay. Ìlò àwòrán pẹ̀lú àṣẹ Pixabay, fún ìlò gbogboògbò. Ye akosile akanse Global Voices wo lori ipa COVID-19 lagbaaye. Yẹ àkọsílẹ̀ àkànṣe Global Voices wò lórí ipa COVID-19 lágbàáyé. Gege bi ajo ti o n kapa itankale arun ni Naijiria se so, awon eeyan marun-un miiran ni won ti fidi re mule pe won ti ko kokoro arun COVID-19, aropo iye awon ti won ni arun naa ni Naijiria wa je mejo. Gẹ́gẹ́ bí àjò tí ó ń kápá ìtànkálẹ̀ àrùn ní Nàìjíríà ṣe sọ, àwọn èèyàn márùn-ún mìíràn ni wọ́n ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé wọ́n ti kó kòkòro àrùn COVID-19, àròpọ̀ iye àwọn tí wọ́n ní àrùn náà ní Nàìjíríà wá jẹ́ mẹ́jọ. "Iye awon eni ti o ni kokoro arun naa di mejo ni ojo meji leyin ti dokita E. Osagie Ehanire fidi i re mule ni ojo 16, osu Erena pe won ti ri eni keta ti o ko kokoro aifojuri COVID-19, iyen ""omo orile-ede Naijiria kan ti o le ni eni ogbon ti o sese de lati United Kingdom ni ojo 13, osu Erena""." "Iye àwọn ẹni tí ó ní kòkòrò àrùn náà di mẹ́jọ ní ọjọ́ méjì lẹ́yìn tí dókítà E. Osagie Ehanire fìdí i rẹ múlẹ̀ ní ọjọ́ 16, oṣù Ẹrẹ́na pé wọ́n ti rí ẹni kẹ́ta tí ó kó kòkòrò àìfojúrí COVID-19, ìyen ""ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kan tí ó lé ní ẹni ọgbọ̀n tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti United Kingdom ní ọjọ́ 13, oṣù Ẹrẹ́na""." Alaisan naa ya ara re soto fun ojo 14 ni ilu Eko, laaarin asiko yii ni o bere si i ni ami aisan iba ati iko. Aláìsàn náà ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ fún ọjọ́ 14 ní ìlú Èkó, láàárín àsìkò yìí ni ó bẹ̀rẹ̀ sí i ní àmì àìsàn ibà àti ikọ̀. Alaisan naa wa ni ile iwosan ti won ti n setoju Kokoro akoran ni Yaba, ni Ipinle Eko. Aláìsàn náà wà ní ilé ìwòsàn tí wọ́n ti ń ṣètọ́jú Kòkòro àkóràn ní Yaba, ní Ìpínlẹ̀ Èkó. Ara re ti n bale, o si n dahun si itoju daadaa. Ara rẹ̀ ti ń balẹ̀, ó sì ń dáhùn sí ìtọ́jú dáadáa. Bi i iye awon eniyan ti o ko kokoro arun COVID-19 se n po si i ni Naijiria, ijoba apapo ti gbo ohun ti awon araalu so ni ojo 18, osu Erena nipa fifi ofin de awon ti o n rin irin ajo lati orile ede 13 bi i: China, Italy, Iran, South Korea, Spain, Japan, France, Germany, Norway, United States, United Kingdom, Netherlands ati Switzerland ti o ni ju eniyan 1000 lo ti o ti ko kokoro arun Korona lati ma wo orile-ede Naijiria. Bí í iye àwọn ènìyàn tí ó kó kòkòrò àrùn COVID-19 ṣe ń pọ̀ sí i ni Nàìjíríà, ìjọba àpapọ̀ ti gbọ́ ohun tí àwọn aráàlú sọ ní ọjọ́ 18, oṣù Ẹrẹ́na nípa fífi òfin de àwọn tí ó ń rin ìrìn àjò láti orílẹ̀ èdè 13 bí i: China, Italy, Iran, South Korea, Spain, Japan, France, Germany, Norway, United States, United Kingdom, Netherlands àti Switzerland tí ó ní ju ènìyàn 1000 lọ tí ó ti kó kòkòrò àrùn Kòrónà láti má wọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Awon ti won ti wo Naijiria tele lati awon orile ede ti a daruko yii gbodo ya ara won soto fun ojo 14. Àwọn tí wọ́n ti wọ Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ láti àwọn orílẹ̀ èdè tí a dárúkọ yìí gbọ́dọ̀ ya ara wọn sọ́tọ̀ fún ọjọ́ 14. Ojo 27 ni osu Erele ni a fidi re mule pe omo orile ede Italy kan ti o rin irinajo wa si orile ede Naijiria je eni akoko ti o ni kokoro arun COVID-19. Ọjọ́ 27 ni oṣù Èrèlé ní a fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé ọmọ orílẹ̀ èdè Italy kan tí ó rìn ìrìnàjò wá sí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tí ó ní kòkòrò àrùn COVID-19. Ka si i: Omo orile ede Italy kan ti o rin irinajo wa si orile ede Naijiria ni o koko ni kokoro arun COVID-19 Kà sí i: Ọmọ orílẹ̀ èdè Italy kan tí ó rìn ìrìnàjò wá sí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ni ó kọ́kọ́ ní kòkòrò àrùn COVID-19 Eni keji ti a fidi re mule pe o ni kokoro arun yii, gege bi NCDC se so je eni ti o rinna pade eni akoko ti o ko arun naa, ti ara re si ti ya bayii leyin ti ayewo meji ti fi han pe ayewo naa ko si lara re mo. Ẹni kejì tí a fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé ó ní kòkòrò àrùn yìí, gẹ́gẹ́ bí NCDC ṣe sọ jẹ́ ẹni tí ó rìnnà pàdé ẹni àkọ́kọ́ tí ó kó àrùn náà, tí ara rẹ̀ sì ti yá báyìí lẹ́yìn tí àyẹ̀wò méjì ti fi hàn pé àyẹ̀wò náà kò sí lára rẹ̀ mọ́. Enikeji yii o ni arun naa mo, won si ti fi i sile ki o maa lo sile ni ojo 13 osu Erena, odun 2020, gege bii ajo NCDC se so. Ẹnìkejì yìí ò ní àrùn náà mọ́, wọ́n sì ti fi í sílẹ̀ kí ó máa lọ sílé ní ọjọ́ 13 oṣù Ẹrẹ́na, ọdún 2020, gẹ́gẹ́ bíi àjọ NCDC ṣe sọ. Bi won se n boju to arun COVID-19 ko te opo araalu lori ayelujara lorun, won si ti n beere fun awon igbese ti o lagbara lati dekun itankale arun naa ni orile ede Naijiria. Bí wọ́n ṣe ń bójú tó àrùn COVID-19 kò tẹ́ ọ̀pọ̀ aráàlú lórí ayélujára lọ́rùn, wón sì ti ń béèrè fún àwọn ìgbésẹ̀ tí ó lágbára láti dẹ́kun ìtànkálẹ̀ àrùn náà ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. "Omo ilu lori ayelujara, Ayobami kede pe igbese NCDC fale. O gba won nimoran pe ""ki won dekun sise asehan lori ayelujara ki won si bere ise!""" "Ọmọ ìlú lórí ayélujára, Ayobami kéde pé ìgbésẹ̀ NCDC falẹ̀. Ó gbà wọ́n nímọ̀ràn pé ""kí wọ́n dẹ́kun ṣíṣe àṣehàn lórí ayélujára kí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́!""" "Gideon so pe ""o ye ki o ba wa leru"" pe sise ayewo fun kokoro arun COVID-19 n fale ni Naijiria." "Gideon sọ pé ""ó yẹ kí ó bà wá lẹ́rù"" pé ṣíṣe àyẹ̀wò fún kòkòrò àrùn COVID-19 ń falẹ̀ ní Nàìjíríà." """E fi ofin de awon arinrin-ajo ti o fe wole lati awon orile ede miiran"" paapaa ju lo awon ti o wa lati awon orile ede ti arun naa ti gbile, akoroyin Bayo Olupohunda naa tenumo:" """Ẹ fi òfin de àwọn arìnrìn-àjò tí ó fẹ́ wọlé láti àwọn orílẹ̀ èdè mìíràn"" pàápàá jù lọ àwọn tí ó wá láti àwọn orílẹ̀ èdè tí àrùn náà ti gbilẹ̀, akọ̀ròyìn Bayo Olupohunda náà tẹnumọ:" Dr. Whitewalker naa tenpele mo on pe ko si ohun ti o buru ninu fifi ofin de awon arinrin-ajo ni akoko ti won sise isadinku itankale arun lati le dekun akoran ni asiko itankale arun bi i iru eyi. Dr. Whitewalker náà tẹnpẹlẹ mọ́ ọn pé kò sí ohun tí ó burú nínú fífi òfin de àwọn arìnrìn-àjò ní àkókò tí wọ́n ṣiṣẹ́ ìṣàdínkù ìtànkálẹ́ àrùn láti lè dẹ́kun àkóràn ní àsìkò ìtànkálẹ́ àrùn bí i irú èyí. "Dr. Chikwe Ihekweazu, olori ajo NCDC, bebe pe awon n ""gbiyanju GIDI lati ri i pe awon se gbogbo ohun ti o ye ki awon se"":" "Dr. Chikwe Ihekweazu, olórí àjọ NCDC, bẹ̀bẹ̀ pé àwọn ń ""gbìyànjú GIDI láti rí i pé àwọn ṣe gbogbo ohun tí ó yẹ kí àwọn ṣe"":" Ni ojo 17 osu Erena, ile igbimo asofin agba ti koko so pe ki won fi ofin de awon oko ofurufu ti o n bo lati awon orile ede ti arun naa ti gbile bi i United Kingdom ati China, ki won to duro di ojo keji ki won to fi ofin naa mule. Ní ọjọ́ 17 oṣù Ẹrẹ́na, ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ti kọ́kọ́ sọ pé kí wọ́n fi òfin de àwọn ọkọ̀ òfurufú tí ó ń bọ̀ láti àwọn orílẹ̀ èdè tí àrùn náà ti gbilẹ̀ bí i United Kingdom àti China, kí wọ́n tó dúró di ọjọ́ kejì kí wọ́n tó fi òfin náà múlẹ̀. Cable Nigeria jabo gbogbo awon ti won wa lati awon orile-ede ti arun naa ti gbile ni won maa ya soto pelu abojuto fun ojo merinla. Cable Nigeria jábọ̀ gbogbo àwọn tí wọ́n wá láti àwọn orílẹ̀-èdè tí àrùn náà ti gbilẹ̀ ni wọ́n máa yà sọ́tọ̀ pẹ̀lú àbójútó fún ọjọ́ mẹ́rìnlá. Ijoba apapo si fi ofin de fifun awon eniyan ni visa Naijiria. Ìjọba àpapọ̀ sì fi òfin de fífún àwọn ènìyàn ní visa Nàìjíríà. Ifofinderinajo naa bere ni abameta ojo 21, osu Erena, odun 2020, yoo si wa fun ose merin ti o se e se ki won sun un siwaju leyin apero. Ìfòfindèrìnàjò náà bẹ̀rẹ̀ ní àbámẹ́ta ọjọ́ 21, oṣù Ẹrẹ́nà, ọdún 2020, yóò sì wà fún ọ̀sẹ̣̀ mẹ́rin tí ó ṣe é ṣe kí wọ́n sún un síwájú lẹ́yìn àpérò. Ka si i: COVID-19 ni ile Adulawo: ‘Igbaradi ti a ko ri iru re ri’ bi awon orile-ede se n mura sile fun itankale arun Kà sí i: COVID-19 ní ilẹ̀ Adúláwọ̀: ‘Ìgbáradì tí a kò rí irú rẹ̀ rí’ bí àwọn orílẹ̀-èdè ṣe ń múra sílẹ̀ fún ìtànkálẹ̀ àrùn Opo awon orile-ede ni ile Adulawo ti n gbe igbese lati se adinku itankale kokoro arun COVID-19. Ọ̀pọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè ní ilẹ̀ Adúláwọ̀ ti ń gbé ìgbésẹ̀ láti ṣe àdínkù ìtànkálẹ̀ kòkòrò àrùn COVID-19. Lara awon igbese yii ni fifi ofin de irin-ajo lati awon orile ede ti kokoro arun COVID-19 naa ti gbile lati ma se wo orile ede won. Lára àwọn ìgbésẹ̀ yìí ni fífi òfin de ìrìn-àjò láti àwọn orílẹ̀ èdè tí kòkòrò àrùn COVID-19 náà ti gbilẹ̀ láti má ṣe wọ orílẹ̀ èdè wọn. Isamojuto ti ko peye to Ìṣàmójútó tí kò péye tó Awon ijabo kan wa nipa bi isamojuto awon osise eleto ilera ko se peye to lori awon to ni kokoro arun COVID-19 ni orile-ede Naijiria. Àwọn ìjábọ̀ kan wà nípa bí ìṣàmójútó àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera kò ṣe péye tó lórí àwọn tó ní kòkòrò àrùn COVID-19 ni orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Obinrin kan ti o je eni odun 70 ti o ti lo osu marun-un ni United Kingdom pada si Naijiria ni ojo 11 osu Erena. Obìnrin kan tí ó jẹ́ ẹni ọdún 70 tí ó ti lo oṣù márùn-ún ní United Kingdom padà sí Nàìjíríà ní ọjọ́ 11 oṣù Ẹrẹ́na. Leyin igba die ti o de, o bere si ni ami aisan kokoro arun COVID-19 bi i otutu ati ikun ti o po lapoju ni ojo 13, osu Erena, won si sare gbe lo si Teaching Hospital ti ipinle Enugu (ESUTH) Colliery Parklane, ni guusu ila-oorun Naijiria. Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ tí ó dé, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní àmì àìsàn kòkòrò àrùn COVID-19 bí i òtútù àti ikun tí ó pọ̀ lápọ̀jù ní ọjọ́ 13, oṣù Ẹrẹ́na, wọ́n sì sáré gbé lọ sí Teaching Hospital ti ìpínlẹ̀ Enugu (ESUTH) Colliery Parklane, ní gúúsù ìlà-oòrùn Nàìjíríà. Won ya a soto ni ESUTH Colliery Parklane, won si fi ayewo ti won se fun un sowo si ajo NCDC ni ojo 14, osu Erena fun ayewo. Wọ́n yà á sọ́tọ̀ ní ESUTH Colliery Parklane, wọ́n sì fi àyẹ̀wọ̀ tí wọ́n ṣe fun un ṣọwọ́ sí àjọ NCDC ní ọjọ́ 14, oṣù Ẹrẹ́na fún àyẹ̀wò. Ni ojo 15, osu Erena, obinrin naa ku leyin ti ajo NCDC jabo pe ko ni kokoro arun COVID-19. Ní ọjọ́ 15, oṣù Ẹrẹ́na, obìnrin náà kú lẹ́yìn tí àjọ NCDC jábọ̀ pé kò ní kòkòrò àrùn COVID-19. "Bee, ninu leta ti won ko si gomina ipinle Enugu, omo obinrin naa fesun kan awon osise ile iwosan naa pe ""tabuku"" iya oun, won gbe e sinu ""ile akoku"" ti o kun fun koriko." "Bẹ́ẹ̀, nínú lẹ́tà tí wọ́n kọ sí gómìnà ìpínlẹ̀ Enugu, ọmọ obìnrin náà fẹ̀sùn kan àwọn òṣìṣẹ́ ilé ìwòsàn náà pé ""tàbùkù"" ìyá òun, wọ́n gbé e sínú ""ilé àkọ́kù"" tí ó kún fún koríko." Oro enikan ti o ni kokoro arun COVID-19 ti won ko se abojuto to peye fun waye ni ipinle Eko ti o je olu-ilu idokoowo ni orile-ede Naijiria. Ọ̀rọ̀ ẹnìkan tí ó ní kòkòrò àrùn COVID-19 tí wọn kò ṣe àbójútó tó péye fún wáyé ní ìpínlẹ̀ Èkó tí ó jẹ́ olú-ìlú ìdókòòwò ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ni ojo 17, osu Erena, David Hundeyin ti o je akoroyin pelu News Wire, jabo nipa isamojuto ti ko gunrege to lori oro eni ti won furasi pe o ni kokoro arun COVID-19 ni ile ise Dangote ni Ibeju-Lekki, ni Ipinle Eko, ti o si ti n fa ipaya laaarin awon osise ibe. Ní ọjọ́ 17, oṣù Ẹrẹ́na, David Hundeyin tí ó jẹ́ akọ̀ròyìn pẹ̀lú News Wire, jábọ̀ nípa ìṣàmójútó tí kò gúnrégé tó lórí ọ̀rọ̀ ẹni tí wọ́n furasí pé ó ní kòkòrò àrùn COVID-19 ní ilé iṣẹ́ Dangote ní Ibeju-Lekki, ní Ìpínlẹ̀ Èkó, tí ó sì ti ń fa ìpayà láàárín àwọn òṣìṣẹ́ ibẹ̀. Ni ojo kejila osu Erena, osise ileese Dangote kan ti o je omo ile India ti o n tun opa omi se wa si orile-ede Naijiria lati Mumbai, leyin ti o duro die ni Cairo, ni orile-ede Egypt. Ní ọjọ́ kejìlá oṣù Ẹrẹ́nà, òṣìṣẹ́ iléeṣẹ́ Dangote kan tí ó jẹ́ ọmọ ilẹ̀ India tí ó ń tún ọ̀pá omi ṣe wá sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti Mumbai, lẹ́yìn tí ó dúró díẹ̀ ní Cairo, ní orílẹ̀-èdè Egypt. "Iwadii Hudeyin fi han pe okunrin naa ti o n tun opa omi se bere si i ni ""iba, iko gbigbe, ofun didun ati aile mi dele "", ni ojo keji ti o de lati India." "Ìwádìí Hudeyin fi hàn pé ọkùnrin náà tí ó ń tún ọ̀pá omi ṣe bẹ̀rẹ̀ sí i ní ""ibà, ikọ́ gbígbẹ, ọ̀fun dídùn àti àìlè mí délẹ̀ "", ní ọjọ́ kejì tí ó dé láti India." "Sibe, ""ko ti i han boya enikeni ni ileese Dangote ti gbiyanju lati kan si"" awon eleto ilera ti oro naa kan." "Síbẹ̀, ""kò tí ì hàn bóyá ẹnikẹ́ni ní iléeṣẹ́ Dangote ti gbìyànjú láti kàn sí"" àwọn elétò ìlera tí ọ̀rọ̀ náà kàn." "Hudeyin soro siwaju pe ile ise naa n lo anfaani ""ayika ofin ti ko munadoko to"" ni Naijiria ""lati fi ere tire siwaju"", eyi si n fi emi awon osise re ati gbogbo awujo sinu ewu." "Hudeyin sọ̀rọ̀ síwájú pé ilé iṣẹ́ náà ń lo àǹfààní ""àyíká òfin tí kò múnádóko tó"" ní Nàìjíríà ""láti fi èrè tirẹ̀ síwájú"", èyí sì ń fi ẹ̀mí àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àwùjọ sínú ewu." Iroyin yii mu ki ileese naa gbe ero won jade pe awon ti gbe alaisan naa lo si ile iwosan ti won ti n setoju kokoro Akoran ni Yaba, ni ipinle Eko. Ìròyìn yìí mú kí iléeṣẹ́ náà gbé èrò wọn jáde pé àwọn ti gbé aláìsàn náà lọ sí ilé ìwòsàn tí wọ́n ti ń ṣètọ́jú kòkòrò Àkóràn ní Yaba, ní ìpínlẹ̀ Èkó. Ona wo ni arun COVID-19 n gba se atunse si eto iselu ati eyin-ola Orile-ede China lagbaaye? Ọ̀nà wo ni àrùn COVID-19 ń gbà ṣe àtúnṣe sí ètò ìṣèlú àti ẹ̀yìn-ọ̀la Orílẹ̀-èdè China lágbàáyé? "Aworan to n fi aala-ile orile-ede China han lori omo oro merin ti kika re je 武汉肺炎 ti o tumo si ""arun edoforo Wuhan"" (ti o si je lilo ni ede Chinese), gege bi a ti se mo ajakale naa ni ibere pepe, ki o to yi oruko pada si COVID-19." "Àwòrán tó ń fi ààlà-ilẹ̀ orílẹ̀-èdè China hàn lórí ọmọ ọ̀rọ̀ mẹ́rin tí kíkà rẹ̀ jẹ́ 武汉肺炎 tí ó túmọ̀ sí ""àrùn ẹ̀dọ̀fóró Wuhan"" (tí ó ṣì jẹ́ lílo ní èdè Chinese), gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe mọ àjàkálẹ̀ náà ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ó tó yí orúkọ padà sí COVID-19." A gba ase lati lo aworan. A gba àṣẹ láti lo àwòrán. Ohun ti o bere ninu oja ounje inu odo, gege bi i oran ailera ibile, ti wa di nnkan to ranka Orile-ede China. Ohun tí ó bẹ̀rẹ̀ nínú ọjà oúnjẹ inú odò, gẹ́gẹ́ bí i ọ̀ràn àìlera ìbílẹ̀, ti wá di nǹkan tó rànká Orílẹ̀-èdè China. Leyin ifesemule ijeyo kokoro aifojuri korona ni Wuhan ninu Osu Kejila Odun 2019, opolopo isele lo se ni sise-n-tele lo su yo to si fi awujo ile Chinese lakalaka ti o si tun doju ipenija ko idurosinsin eto iselu Beijing. Lẹ́yìn ìfẹsẹ̀múlẹ̀ ìjẹyọ kòkòrò àìfojúrí kòrónà ní Wuhan nínú Oṣù Kejìlá Ọdún 2019, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìṣẹ̀lẹ̀ ló ṣẹ̀ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé ló ṣú yọ tó sì fi àwùjọ ilẹ̀ Chinese làkàlàkà tí ó sì tún dojú ìpèníjà kọ ìdúróṣinṣin ètò ìṣèlú Beijing. Kikundun isakoso iroyin ti fun ijoba lorun, ati ijoba ibile ati ijoba apapo ni aarin gbungbun, lo maa n fa idaduro fun agbejade iroyin ti yoo se ara ilu lanfaani fun ose pipe. Kíkúndùn ìṣàkóso ìròyìn ti fún ìjọba lọ́rùn, àti ìjọba ìbílẹ̀ àti ìjọba àpapọ̀ ní àárín gbùngbùn, ló máa ń fa ìdádúró fún àgbéjáde ìròyìn tí yóò ṣe ará ìlú láǹfààní fún ọ̀sẹ̀ pípẹ́. Nigba ti won wa so ji lati se ikede lori awon ona ti yoo dekun itanka ajakale naa, o ti bo sori, nitori ayeye odun tuntun iran Chinese olodoodun ti gberaso. Nígbà tí wọ́n wá sọ jí láti ṣe ìkéde lórí àwọn ọ̀nà tí yóò dẹ́kun ìtànká àjàkálẹ̀ náà, ó ti bọ́ sórí, nítorí ayẹyẹ ọdún tuntun ìran Chinese ọlọ́dọọdún ti gbérasọ. Awon Dokita ati awon onimo ijinle si n se iwadii ati iforojomitoro-oro lori ohun ti o le je orisun arun ti won mo nigba naa lohun-un gege bi kokoro aifojuri korona ti Wuhan, ti o pada wa se okunfa COVID-19, kokoro aifojuri to n mu ki eniyan ma lee mi sokesodo ti o si n fa arun edoforo. Àwọn Dókítà àti àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ sì ń ṣe ìwádìí àti ìfọ̀rọ̀jomitoro-ọ̀rọ̀ lórí ohun tí ó lè jẹ́ orísun àrùn tí wọ́n mọ̀ nígbà náà lọ́hùn-ún gẹ́gẹ́ bí kòkòrò àìfojúrí kòrónà ti Wuhan, tí ó padà wá ṣe okùnfà COVID-19, kòkòrò àìfojúrí tó ń mú kí ènìyàn má leè mí sókèsódò tí ó sì ń fa àrùn ẹ̀dọ̀fóró. Idamoran ohun ti o le fa sababi arun naa kan fi ye wi pe kokoro aifojuri korona je yo latari eran ejo tabi eran adan ti awon ara China maa n je l'ounje, ti won n ta ni oja Huanan wet ni agbegbe Wuhan nibi ti opolopo ni ero wi pe ibe ni orisun kokoro aifojuri yii. Ìdámọ̀ràn ohun tí ó lè fa sábàbí àrùn náà kan fi yé wí pé kòkòrò àìfojúrí kòrónà jẹ yọ látàrí ẹran ejò tàbí ẹran àdán tí àwọn ará China máa ń jẹ l'óúnjẹ, tí wọ́n ń tà ní ọjà Huanan wet ní agbègbè Wuhan níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní èrò wí pé ibẹ̀ ni orísun kòkòrò àìfojúrí yìí. Ibeere kan ti o nilo idahun ni ti ona itankale arun yii: boya o lee ranka lati ara eeyan kan si ikeji, ati iye eeyan meloo lo lee ko aisan yii latara eni ti o ba ti ni i. Ìbéèrè kan tí ó nílò ìdáhùn ni ti ọ̀nà ìtànkálẹ̀ àrùn yìí: bóyá ó leè rànká láti ara èèyàn kan sí ìkejì, àti ìyè èèyàn mélòó ló leè kó àìsàn yìí látara ẹni tí ó bá ti ní i. Eri lati imo ilera to fesemule se isipaya arankan lati ara eniyan kan si ikeji, ti o fi je wi pe kokoro naa yoo ti wa lagoo ara fun igba die ki eni ti o ko o o to maa ri awon aami re lara, ti eyi o si mu mimo eni ti o ba ti lu gude arun naa rorun. Ẹ̀rí láti ìmọ̀ ìlera tó fẹsẹ̀múlẹ̀ ṣe ìṣípayá àrànkán láti ara ènìyàn kan sí ìkejì, tí ó fi jẹ́ wí pé kòkòrò náà yóò ti wà lágọ̀ọ́ ara fún ìgbà díẹ̀ kí ẹni tí ó kó o ó tó máa rí àwọn ààmì rẹ̀ lára, tí èyí ò sì mú mímọ ẹni tí ó bá ti lu gúdẹ àrùn náà rọrùn. Ni ti bi arun naa ti n ran, eyi ti awon onimo nipa ajakale arun n pe ni “onka ipile ibisi“, gba pe o wa laaarin 2 si 3 ni ipari Osu Kin-in-ni, eni ti o ni i yoo ko o ran eni meji si meta, sugbon ifikunlukun ati iwadii ko duro, iyen bi awon iwifun-alalaye ti o wulo ba wa ni arowoto. Ní ti bí àrùn náà ti ń ràn, èyí tí àwọn onímọ̀ nípa àjàkálẹ̀ àrùn ń pè ní “òǹkà ìpìlẹ̀ ìbísí“, gbà pé ó wà láàárín 2 sí 3 ní ìparí Oṣù Kìn-ín-ní, ẹni tí ó ní i yóò kó o ran ẹni méjì sí mẹ́ta, ṣùgbọ́n ìfikùnlukùn àti ìwádìí kò dúró, ìyẹn bí àwọn ìwífún-alálàyè tí ó wúlò bá wà ní àrọ́wọ́tó. Bi onka awon ti won ti ni kokoro yii se n lo soke si i lojoojumo, aaringbungbun Orile-ede China ti i se Hubei ati Olu-ilu re ti i se Wuhan ti ni idojuko to gogo lori eto ilera, ti apapo awon ti won n gbe lagbegbe yii si je egberun-lona-egberun ni ilopo 60. Bí òǹkà àwọn tí wọ́n ti ní kòkòrò yìí ṣe ń lọ sókè sí i lójoojúmó, àáríngbùngbùn Orílẹ̀-èdè China tí i ṣe Hubei àti Olú-ìlú rẹ̀ tí í ṣe Wuhan ti ní ìdojúkọ tó gogò lórí ètò ìlera, tí àpapọ̀ àwọn tí wọ́n ń gbé lágbègbè yìí sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún-lọ́nà-ẹgbẹ́rùn ní ìlọ́po 60. Bi iye awon ti o ti ko arun yii se n po kaakiri Orile-ede China, awon osise eleto ilera ti wa digbi, ti won si tun kona mo eto ilera ti ko suwabo to fun itoju awon oke aimoye arugbo to kun ilu. Bí iye àwọn tí ó ti kó àrùn yìí ṣe ń pọ̀ káàkiri Orílẹ̀-èdè China, àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera ti wà digbí, tí wọ́n sì tún kóná mọ́ ètò ìlera tí kò sùwábọ̀ tó fún ìtọ́jú àwọn ọ̀kẹ́ àìmọye arúgbó tó kún ìlú. Sugbon arun kokoro aifojuri korona Wuhan naa ki i se ikolu eto ilera lasan, o je akoko otito eto iselu ti o lakaaki. Ṣùgbọ́n àrùn kòkòrò àìfojúrí kòrónà Wuhan náà kì í ṣe ìkọlù ètò ìlera lásán, ó jẹ́ àkókò òtítọ́ ètò ìṣèlú tí ó lákaakì. Igbekele ijoba ti o so fun awon ara ilu wi pe ko s'ewu l'oko afi giri aparo ni ibere pepe, titi ti epa o fi boro mo, ti awon ara ilu ko si ni ifokantan ninu awon ijoba won mo, ati pe, ki i se ni agbegbe Hubei nikan ni eyi ti sele. Ìgbẹ́kẹ̀lé ìjọba tí ó sọ fún àwọn ará ìlú wí pé kò s'éwu l'óko àfi gìrì àparò ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, títí tí ẹ̀pa ò fi bóró mọ́, tí àwọn ará ìlú kò sì ní ìfọkàntán nínú àwọn ìjọba wọn mọ́, àti pé, kì í ṣe ní agbègbè Hubei nìkan ni èyí ti ṣẹlẹ̀. Awon ara ilu bu enu ate lu ijoba Beijing fun owo yepere ti won fi mu oro ajakale arun eemi SARS to su yo ni odun 2002 si 2003, bi o ti se fi iroyin to peye lori re pamo fun Ajo Eleto Ilara Lagbaaye (WHO). Àwọn ará ìlú bu ẹnu àtẹ́ lu ìjọba Beijing fún ọwọ́ yẹpẹrẹ tí wọ́n fi mú ọ̀rọ̀ àjàkálẹ̀ àrùn èémí SARS tó ṣú yọ ní ọdún 2002 sí 2003, bí ó ti ṣe fi ìròyìn tó péye lórí rẹ̀ pamọ́ fún Àjọ Elétò Ìlara Lágbàáyé (WHO). Olori Orile-ede China agba Xi Jinping dake roro lori ajakale arun yii ayafi igba ti o di ojo 20, Osu Kin-in-ni Odun, ti o kede fun ara ilu leyin osu kan ti arun naa ti n sose, pe oran naa ti koja afenuso. Olórí Orílẹ̀-èdè China àgbà Xi Jinping dákẹ́ rọrọ lórí àjàkálẹ̀ àrùn yìí àyàfi ìgbà tí ó di ọjọ́ 20, Oṣù Kìn-ín-ní Ọdún, tí ó kéde fún ará ìlú lẹ́yìn oṣù kan tí àrùn náà ti ń ṣọṣẹ́, pé ọ̀ràn náà ti kọjá àfẹnusọ. Agbara lori isakoso atejade iroyin fese mule rinrin ni orile-ede China, ati pe, iwoyaaja eto karakata pelu Orile-ede Amerika, ati bi oro-aje won se n denukole, bi won ba se yanju isoro kokoro aifojuri korona ti Wuhan naa ni yoo fori le ni odun 2020. Agbára lórí ìṣàkóso àtẹ̀jáde ìròyìn fẹsẹ̀ múlẹ̀ rìnrìn ní orílẹ̀-èdè China, àti pé, ìwọ̀yáàjà ètò káràkátà pẹ̀lú Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, àti bí ọrọ̀-ajé wọn ṣe ń dẹnukọlẹ̀, bí wọ́n bá ṣe yanjú ìṣòro kòkòrò àìfojúrí kòrónà ti Wuhan náà ni yóò forí lé ní ọdún 2020. Awon Ile Ise ero-ibanisoro ni Mozambique ati Cape Verde te pepe eto edinwo fun ayelujara lori ero alagbeeka lati mu ki awon omo-ilu o duro sile Àwọn Ilé Iṣẹ́ ẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ ní Mozambique àti Cape Verde tẹ́ pẹpẹ ètò ẹ̀dínwó fún ayélujára lórí ẹ̀rọ alágbèéká láti mú kí àwọn ọmọ-ìlú ó dúró sílé Oju ona Santa Maria, Cape Verde. Aworan lati owoo Miccaela, Wikimedia Commons. CC-BY 3.0 Ojú ọ̀nà Santa Maria, Cape Verde. Àwòrán láti ọwọ́ọ Miccaela, Wikimedia Commons. CC-BY 3.0 Ye akanse ise ti Ohun Agbaye’ ti se lori ipa ti kokoro aifojuri korona COVID-19 n ko lagbaaye Yẹ àkànṣe iṣẹ́ tí Ohùn Àgbáyé’ ti ṣe lórí ipa tí kòkòrò àìfojúrí kòrónà COVID-19 ń kó lágbàáyé Gege bi ase konilegbele se n mule ni ile Adulawo latari ajakale arun COVID-19, awon ile ise ero-ibanisoro ti Ipinle ni Orile-ede Mozambique ati Cape Verde n fun awon ara ilu ni edinwo lori owo-ilo-ayelujara ni ori ero-ibanisoro alagbeeka. Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ kónílégbélé ṣe ń múlẹ̀ ní ilẹ̀ Adúláwọ̀ látàrí àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19, àwọn ilé iṣẹ́ ẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ ti Ìpínlẹ̀ ní Orílẹ̀-èdè Mozambique àti Cape Verde ń fún àwọn ará ìlú ní ẹ̀dínwó lórí owó-ìlò-ayélujára ní orí ẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ alágbèéká. Di asiko yii, Orile-ede Mozambique ti ni akosile eniyan 10 ti o ti ko arun COVID-19, sugbon ti ko ti i si eni ti o ti ba aisan naa lo, amo eni 6 lo ti ko arun naa ni Cape Verde ti enikan si ti di eni ebora n ba jeun. Di àsìkò yìí, Orílẹ̀-èdè Mozambique ti ní àkọsílẹ̀ ènìyàn 10 tí ó ti kó àrùn COVID-19, ṣùgbọ́n tí kò tí ì sí ẹni tí ó ti bá àìsàn náà lọ, àmọ́ ẹni 6 ló ti kó àrùn náà ní Cape Verde tí ẹnìkan sì ti di ẹni ẹbọra ń bá jẹun. Ni ose ti o koja, Orile-ede mejeeji ti pase ofin pajawiri ilu-o-f'ara-ro olosu kan latari ajakale aisan to gbaye kan, o si se e se ki won se afikun-un re. Ní ọ̀sẹ̀ tí ó kọjá, Orílẹ̀-èdè méjèèjì ti pàṣẹ òfin pàjáwìrì ìlú-ò-f'ara-rọ olóṣù kan látàrí àjàkálẹ̀ àìsàn tó gbayé kan, ó sì ṣe é ṣe kí wọ́n ṣe àfikún-un rẹ̀. Gege bi ile ise oniroyin kan ti Orile-ede Portugal Lusa ti royin: Gẹ́gẹ́ bí ilé iṣẹ́ oníròyìn kan ti Orílẹ̀-èdè Portugal Lusa ti ròyìn: Itumo Itunwi-oro Oloro gan-an Ìtúmọ̀ Ìtúnwí-ọ̀rọ̀ Ọlọ́rọ̀ gan-an Lonii Ile Ise ero-ibanisoro ti Cape Verde mejeeji, CV Movel ati Unitel T+, se ifilo ipolongo alajumose ti yoo mu ki MB egberun 2 o je ti awon ara ilu fun iwuri lati lee mu won duro sile lojuna idina itanka ajakale arun COVID-19 lawujo. Lónìí Ilé Iṣẹ́ ẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ ti Cape Verde méjèèjì, CV Móvel àti Unitel T+, ṣe ìfilọ̀ ìpolongo alájúmọ̀ṣe tí yóò mú kí MB ẹgbẹ̀rún 2 ó jẹ́ ti àwọn ará ìlú fún ìwúrí láti leè mú wọn dúró sílé lójúnà ìdíná ìtànká àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19 láwùjọ. Ti akolee re je “Fica em Casa” (“ebun iduro sile” ni ede Yoruba), ipolongo naa ni awon ile ise mejeeji gbe jade sori ero agborokaye ti a ko bayii pe awon ti f'orikori lati “sise ajamose” ti yoo mu ki awon ara orile Cape Verde “o jokoo sile”. Tí àkọ́lée rẹ̀ jẹ́ “Fica em Casa” (“ẹ̀bùn ìdúró sílé” ní èdè Yorùbá), ìpolongo náà ni àwọn ilé iṣẹ́ méjèèjì gbé jáde sórí ẹ̀rọ agbọ́rọ̀káyé tí a kọ báyìí pé àwọ́n ti f'oríkorí láti “ṣiṣẹ́ àjàmọ̀ṣe” tí yóò mú kí àwọn ará orílẹ̀ Cape Verde “ó jókòó sílé”. Ebun pataki yii wa fun onibaara ile ise mejeeji, ati pe ni afikun si MB egberun 2 ti won yoo fun won, owo ipe ofe fun iseju 15 yoo wa lofo fun pipe eyikeyii opo ero ibanisoro orile-ede naa ti o si gbodo je lilo ki o to d'ojo 30, Osu Kerin. Ẹ̀bùn pàtàkì yìí wà fún oníbàárà ilé iṣẹ́ méjèèjì, àti pé ní àfikún sí MB ẹgbẹ̀rún 2 tí wọ́n yóò fún wọn, owó ìpè ọ̀fẹ́ fún ìsẹ́jú 15 yóò wà lófò fún pípe èyíkéyìí òpó ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ orílẹ̀-èdè náà tí ó sì gbọdọ̀ jẹ́ lílò kí ó tó d'ọjọ́ 30, Oṣù Kẹrin. COVID-19: Ipolongo anfaani iranwo MB egberun 2 lati mu ki awon ara ilu Cape Verde o jokoo kale ki ofin konilegbele o ba f'eserinle. COVID-19: Ìpolongo àǹfààní ìrànwọ́ MB ẹgbẹ̀rún 2 láti mú kí àwọn ará ìlú Cape Verde ó jókòó kalé kí òfin kónílégbélé ó bá f'ẹsẹ̀rinlẹ̀. Ogoro ara ilu Cape Verde ti yo suti enu si ipolongo yii, nitori segesege ni afefe ero ayelujara naa maa n se: Ọ̀gọ̀rọ̀ ará ìlú Cape Verde ti yọ ṣùtì ẹnu sí ìpolongo yìí, nítorí ségesège ni afẹ́fẹ́ ẹ̀rọ ayélujára náà máa ń ṣe: Awada nla ni!!! Àwàdà ńlá ni!!! Eni meloo ninu ara ilu Cape Verde l'o ni afefe ero ayelujara to ja geere? Ẹni mélòó nínú ará ìlú Cape Verde l'ó ní afẹ́fẹ́ ẹ̀rọ ayélujára tó já geere? Ni Cape Verde, agbegbe erekusu ti o ni eeyan to to egberun 560, ti ida 57 won n lo ero-ayelujara, iyen gege bi iwadii ti Ile Ifowopamo Agbaye se ni odun 2017 ti se fi han. Ní Cape Verde, agbègbè erékùṣù tí ó ní èèyàn tó tó ẹgbẹ̀rún 560, tí idà 57 wọn ń lo ẹ̀rọ-ayélujára, ìyẹn gẹ́gẹ́ bí ìwádìí tí Ilé Ìfowópamọ́ Àgbáyé ṣe ní ọdún 2017 ti ṣe fi hàn. Lodun naa, ida 50 ni ida awon to n lo ayelujara to poju lagbaaye. Lọ́dún náà, ìdá 50 ni ìdá àwọn tó ń lo ayélujára tó pọ̀jù lágbàáyé. "Ni Mozambique, nibi ti awon eniyan ti o n lo ayelujara o ti to nnkan – Ile Ifowopamo Agbaye kan yii naa fi han ninu iwadii pe ida 10 awon ara ilu ninu eeyan egbeegberun lo ni ero-ayelujara ni arowoto – ile ise ero ibanisoro TmCel ti o je ti omo oniluu naa ti se ifilole ipolongo ""konilegbele"" yii kan naa." "Ní Mozambique, níbi tí àwọn ènìyàn tí ó ń lo ayélujára ò ti tó nǹkan – Ilé Ìfowópamọ́ Àgbáyé kan yìí náà fi hàn nínú ìwádìí pé ìdá 10 àwọn ará ìlú nínú èèyàn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ló ní ẹ̀rọ-ayélujára ní àrọ́wọ́tó – ilé iṣẹ́ ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ TmCel tí ó jẹ́ ti ọmọ onílùú náà ti se ìfilọ́lẹ̀ ìpolongo ""kónílégbélé"" yìí kan náà." Ipolongo naa kun fun awon okan-o-jokan anfaani ebun ofe lati GB 1 si GB 5, ti owoo re je 25 si 100 meticals (0.37 si 1.50 owo US). Ìpolongo náà kún fún àwọn ọ̀kan-ò-jọ̀kan àǹfààní ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ láti GB 1 sí GB 5, tí owóo rẹ̀ jẹ́ 25 sí 100 meticals (0.37 sí 1.50 owó US). Mu anfaani ebun #StayAtHome yii lo fun 25 meticals laaarin osu kan. Mú àǹfààní ẹ̀bùn #StayAtHome yìí lò fún 25 meticals láàárín oṣù kan. Te *219# lati se asayan ebun ti o fe, ki o si duro sile pelu TmCel. Fun alaye lekununrere kan si: Tẹ *219# láti se àṣàyàn ẹ̀bùn tí ó fẹ́, kí o sì dúró sílé pẹ̀lú TmCel. Fún àlàyé lẹ́kùnúnrẹ́rẹ́ kàn sí: Bi-o-ti-le-je-pe anfaani ebun je ohun atewo gba lawujo, die lara awon onsamulo gbagede Twitter se agbejade awon ibeere kan: Bí-ó-ti-lẹ̀-jẹ́-pé àǹfààní ẹ̀bùn jẹ́ ohun àtẹ́wọ́ gbà láwùjọ, díẹ̀ lára àwọn òǹṣàmúlò gbàgede Twitter se àgbéjáde àwọn ìbéèrè kan: Igbese ti o daa ni. Ìgbésẹ̀ tí ó dáa ni. Se o je ojulowo bakan naa? Sé ó jẹ́ ojúlówó bákan náà? Diduro sile yii ki i se ohun to ba awon onise owo ati onise igbemiiro ti o n gbe ni Mozambique ati Cape Verde lara mu rara. Ajafetoo omo-eniyan Tomas Queface tuwiiti: Dídúró sílé yìí kì í se ohun tó bá àwọn onísẹ́ ọwọ́ àti oníṣẹ́ ìgbẹ́mìíró tí ó ń gbé ní Mozambique àti Cape Verde lára mú rárá. Ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọ-ènìyàn Tomás Queface túwíìtì: Aisan #coronavirus yii ti sipaya iwa aidogba ti o wa lawujo wa. Àìsàn #coronavirus yìí ti ṣípayá ìwà àìdọ́gba tí ó wà láwùjọ wa. Bi ofin konile o gbele #StayAtHome se je oore ofe fun awon kan, nise l'o n mu awon ti o rowohori lawujo fajuro latari fi f'owo mukan: ninuu diduro sile lai ri ounje je, tabi sisise ki alaafia ara o di fiafia tabi fifi ilera awon ara ilu to ku wewu. Bí òfin kónílé ó gbélé #StayAtHome ṣe jẹ́ oore ọ̀fẹ́ fún àwọn kan, níṣe l'ó ń mú àwọn tí ò rọ́wọ́họrí láwùjọ fajúro látàrí fi f'ọwọ́ múkan: nínúu dídúró sílé láì rí oúnjẹ jẹ, tàbí ṣíṣiṣẹ́ kí àlàáfíà ara ó di fíafìa tàbí fífi ìlera àwọn ará ìlú tó kù wéwu. COVID-19 se agbende isele-ateyinwa to buru jai nipa idanwo egbogi ni Ile-Adulawo COVID-19 ṣe àgbéǹde ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tó burú jáì nípa ìdánwò egbògi ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ Ile-Adulawo ki i se iyara ayewo' Ilẹ̀-Adúláwọ̀ kì í ṣe iyàrá àyẹ̀wò' Oloye omo-ogun. 1st Class Marites Cabreza, olutoju omo ti o n sise pelu 354th Civil Affairs Brigade, Special Functioning Team, Combined Joint Task Force-Iho Ile-Adulawo, n toju alaisan lojo 29, osu keta, odun-un 2008, lasiko akanse ise iwosan ilu ni Goubetto, Djibouti. Olóyè ọmọ-ogun. 1st Class Marites Cabreza, olùtọ́jú ọmọ tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú 354th Civil Affairs Brigade, Special Functioning Team, Combined Joint Task Force-Ìho Ilẹ̀-Adúláwọ̀, ń tọ́jú aláìsàn lọ́jọ́ 29, oṣù kẹta, ọdún-un 2008, lásìkò àkànṣe iṣẹ́ ìwòsàn ìlú ní Goubetto, Djibouti. Aworan lati akata Omo-ogun Ofuurufu US Eka imo ero , Jeremy T. Lock. Ilo gbogboogbo. Àwòrán láti àkàtà Ọmọ-ogún Òfuurufú US Ẹ̀ka ìmọ̀ ẹ̀rọ , Jeremy T. Lock. Ìlò gbogboògbò. Ye akanse iroyin-in ‘Ohun Agbaye’ lori ipa ti COVID-19 n ko lagbaaye. Yẹ àkànṣe ìròyìn-in ‘Ohùn Àgbáyé’ lórí ipa tí COVID-19 ń kó lágbàáyé. Aree panpala bi o o lo o yago ti n sele laaarin awon onimo ijinle ati onise iwadii ko seyin igbese lati se ayewo awon oogun ti won ro pe o le wo arun COVID-19 san lara omo eniyan ti n da gbonmisii-omi-o-too sile ni Ile-Adulawo. Arée pànpàlà bí o ò lọ ó yàgò tí ń ṣẹlẹ̀ láàárín àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ àti oníṣẹ́ ìwádìí kò ṣẹ̀yìn ìgbésẹ̀ láti ṣe àyẹ̀wò àwọn oògùn tí wọ́n rò pé ó lè wo àrùn COVID-19 sàn lára ọmọ ènìyàn ti ń dá gbọ́nmisíi-omi-ò-tóo sílẹ̀ ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀. Lojo 1, osu kerin, awon onise iwadii omo ile Faranse meji, Onisegun Jean-Paul Mira, ati Camille Locht, da a labaa lori eto kan ni ori ero-amohunmaworan wi pe Ile-Adulawo ni o ye ki won o ti koko dan egbogi ajesara ti yoo ka apa arun kokoro aifojuri korona san wo, gege bi Al-Jazeera ti se jiyin iroyin naa. Lọ́jọ́ 1, oṣù kẹrin, àwọn oníṣẹ́ ìwádìí ọmọ ilẹ̀ Faransé méjì, Oníṣègùn Jean-Paul Mira, àti Camille Locht, dá a lábàá lórí ètò kan ní orí ẹ̀rọ-amóhùnmáwòrán wí pé Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ni ó yẹ kí wọn ó ti kókó dán egbògi àjẹsára tí yóò ká apá àrùn kòkòrò àìfojúrí kòrónà sàn wò, gẹ́gẹ́ bí Al-Jazeera ti ṣe jíyìn ìròyìn náà. Onisegun Mira, olori eka itoju afeju ti Cochin Hospital ti o wa ni Paris, fi oro naa we “awon iwadii ayewo fun Arun Kogboogun EEDI, ti o je wi pe lara awon olowoo nabi ni a ti koko dan an wo, a gbiyanju awon nnkan kan nitori a mo daju wi pe won ki i da aabo bo ara won, ati pe o rorun fun arun ibalopo lati lugo si ara won.” Oníṣègùn Mira, olórí ẹ̀ka ìtọ́jú àfẹ́jù ti Cochin Hospital tí ó wà ní Paris, fi ọ̀rọ̀ náà wé “àwọn ìwádìí àyẹ̀wò fún Àrùn Kògbóògùn ÉÈDÌ, tí ó jẹ́ wí pé lára àwọn olówòo nàbì ni a ti kọ́kọ́ dán an wò, a gbìyànjú àwọn nǹkan kan nítorí a mọ̀ dájú wí pé wọn kì í dá ààbò bo ara wọn, àti pé ó rọrùn fún àrùn ìbálòpọ̀ láti lúgọ sí ara wọn.” Awon onise iwadii mejeeji menu loro nigba ti asogba oro kan waye lori isayewo egbogi ajesara BCG fun iko-awupeje ni Yuroopu ati Australia lati mo boya yoo sise iwosan fun kokoro aifojuri korona akoko iru e. Àwọn oníṣẹ́ ìwádìí méjèèjì mẹ́nu lọ́rọ́ nígbà tí àsọgbà ọ̀rọ̀ kan wáyé lórí ìṣàyẹ̀wò egbògi àjẹsára BCG fún ikọ́-àwúpẹ̀jẹ̀ ní Yúróòpù àti Australia láti mọ̀ bóyá yóò ṣiṣẹ́ ìwòsàn fún kòkòrò àìfojúrí kòrónà àkọ́kọ́ irú ẹ̀. Ni Australia, ayewo ti n lo lori awon onise ilera egberun 4. Ní Australia, àyẹ̀wò ti ń lọ lórí àwọn oníṣẹ́ ìlera ẹgbẹ̀rún 4. Isesi awon onise iwadii wonyi je gbohungbohun isele-ateyinwa olojo pipe ti o ni se pelu idanwo ati fifowoola gba omo Adulawo ni oju, ti o se wi pe awon adari Ile-Adulawo ti padi-apo-po pelu awon ileese apooogunta — ti o fi Yuroopu tabi ile Amerika se ibugbe — lati wa se ayewo ni ara awon ti ko ri ja je lawujo. Ìṣesí àwọn oníṣẹ́ ìwádìí wọ̀nyí jẹ́ gbohùngbohùn ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá ọlọ́jọ́ pípẹ́ tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìdánwò àti fífọwọ́ọlá gbá ọmọ Adúláwọ̀ ní ojú, tí ó ṣe wí pé àwọn adarí Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ti pàdí-àpò-pọ̀ pẹ̀lú àwọn iléeṣẹ́ apooògùntà — tí ó fi Yúróòpù tàbí ilẹ̀ Amẹ́ríkà ṣe ibùgbé — láti wá ṣe àyẹ̀wò ní ara àwọn tí kò rí já jẹ láwùjọ. "Lesekese ni isorosi awon onise iwadii wonyi ri idalebi ati ibinu awon eniyan, ti o mu apola oro kan, ""Omo ile-Adulawo ki i se eku emo."" gbajumo lori ero-agborokaye." "Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni ìṣọ̀rọ̀sí àwọn oníṣẹ́ ìwádìí wọ̀nyí rí ìdálẹ́bi àti ìbínú àwọn ènìyàn, tí ó mú àpólà ọ̀rọ̀ kan, ""Ọmọ ilẹ̀-Adúláwọ̀ kì í ṣe eku ẹmọ́."" gbajúmọ̀ lórí ẹ̀rọ-agbọ́rọ̀káyé." Irawo agbaboolu omo orile-ede Ivory Coast Didier Drogba tuwiiti: Ìràwọ̀ agbábọ́ọ̀lù ọmọ orílẹ̀-èdè Ivory Coast Didier Drogba túwíìtì: "Nigba ti o di ojo 3, Osu Kerin, Onisegun Mira ti se itoro aforiji fun awon oro ti o so, amo leyin ti awon egbe SOS Racisme ko eyin si i ni o se eyi. Osisee onisegun Locht, bakan naa, da awon ehonu ori Twitter danu gege bi i ""iroyin eleje "", nitori wi pe awon oro naa ko ri bi won ti se n so o." "Nígbà tí ó di ọjọ́ 3, Oṣù Kẹrin, Oníṣègùn Mira ti ṣe ìtọrọ àforíjì fún àwọn ọ̀rọ̀ tí ó sọ, àmọ́ lẹ́yìn tí àwọn ẹgbẹ́ SOS Racisme kọ ẹ̀yìn sí i ni ó ṣe èyí. Òṣìṣẹ́ẹ oníṣègùn Locht, bákan náà, da àwọn ẹ̀hónú orí Twitter dànù gẹ́gẹ́ bí i ""ìròyìn ẹlẹ́jẹ́ "", nítorí wí pé àwọn ọ̀rọ̀ náà kò rí bí wọ́n ti ṣe ń sọ ọ́." "Ni aarin ose yen kan naa, onimo nipa arun aifojuri omo orile-ede Congo Jean-Jacque Muyembe, ti o n lewaju ninu igbogunti ajakale arun iba ida eje Ebola ni orile-ede Ilu Ijoba Awaarawa Olominira Congo, filo wi pe DR Congo ""ti se tan lati kopa ninu irufe idanwo egbogi ti yoo pa kokoro aifojuri korona ti ko ba a waye lojo iwaju"", bi News 24 ti jabo." "Ní àárín ọ̀sẹ̀ yẹn kan náà, onímọ̀ nípa àrùn àìfojúrí ọmọ orílẹ̀-èdè Congo Jean-Jacque Muyembe, tí ó ń léwájú nínú ìgbógunti àjàkálẹ̀ àrùn ibà ìdà ẹ̀jẹ̀ Ebola ní orílẹ̀-èdè Ìlú Ìjọba Àwaarawa Olómìnira Congo, filọ̀ wí pé DR Congo ""ti ṣe tán láti kópa nínú irúfẹ́ ìdánwò egbògi tí yóò pa kòkòrò àìfojúrí kòrónà tí kò bá à wáyé lọ́jọ́ iwájú"", bí News 24 ti jábọ̀." Muyembe, olori igbimo amusese lori ajakaye arun naa ati Ileese eto ilera orile-ede naa, so nibi apero awon oniroyin kan: Muyembe, olórí ìgbìmọ̀ amúṣẹ́ṣe lórí àjàkáyé àrùn náà àti Iléeṣẹ́ ètò ìlera orílẹ̀-èdè náà, sọ níbi àpérò àwọn oníròyìn kan: Won ti yan wa lati se awon ayewo wonyi... Wọ́n ti yàn wá láti ṣe àwọn àyẹ̀wò wọ̀nyí... Ilu Isokan Amerika tabi Canada tabi ni China ni a o ti se egbogi ajesara naa. Ìlú Ìṣọ̀kan Amẹ́ríkà tàbí Canada tàbí ní China ni a ó ti ṣe egbògi àjẹsára náà. Awa ni eni ayan fun ise ayewo naa nibi. Àwa ni ẹni ayàn fún iṣẹ́ àyẹ̀wò náà níbí. Leekan si i, awon oro wonyi fa irunu awon omo Congo ati awon omo ori ayelujara jakejado ile aye ti won da Onisegun Muyembe ni ebi nitori o faramo isayewo egbogi ni DR Congo, nibi ti iye awon ti o ti ko arun COVID-19 ko ti i fi bee po. Lẹ́ẹ̀kan sí i, àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fa ìrúnú àwọn ọmọ Congo àti àwọn ọmọ orí ayélujára jákèjádò ilé ayé tí wọ́n dá Oníṣègùn Muyembe ní ẹ̀bí nítorí ó faramọ́ ìṣàyẹ̀wò egbògi ní DR Congo, níbi tí iye àwọn tí ó ti kó àrùn COVID-19 kò tí ì fi bẹ́ẹ̀ pọ̀. Laaarin wakati die, Onisegun Muyembe yannana oroo re ninu aworan-atohun kan, ti o fi idii re mule wi pe o di igba ti won ba ti koko ye ise egbogi naa wo ni US ati China ni yoo to je lilo ni DR Congo: Láàárín wákàtí díẹ̀, Oníṣègùn Muyembe yànnàná ọ̀rọ̀ọ rẹ̀ nínú àwòrán-àtohùn kan, tí ó fi ìdíi rẹ̀ múlẹ̀ wí pé ó di ìgbà tí wọ́n bá ti kọ́kọ́ yẹ iṣẹ́ egbògi náà wò ní US àti China ni yóò tó jẹ́ lílò ní DR Congo: Isele-ateyinwa to buru jai nipa idanwo egbogi ni Ile-Adulawo Ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tó burú jáì nípa ìdánwò egbògi ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ "Idanwo egbogi ni Ile-Adulawo — ti o saba maa n waye labe etan ""ifee gbogboogbo” ti o pon dandan ni ojuna ati wa iwosan fun arun asekupani bi i arun yirunyirun ati arun kogboogun HIV/AIDS — ti lu agogo itaniji iwa-omoluwabi fun ainiye odun — paapaa ju lo lori igbase lowo awon eniyan ki won o to se idanwo ati ilana iseto ilera onitulaasi." "Ìdánwò egbògi ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ — tí ó sábà máa ń wáyé lábẹ́ ẹ̀tàn ""ìfẹ́ẹ gbogboògbò” tí ó pọn dandan ní ojúnà àti wá ìwòsàn fún àrùn aṣekúpani bí i àrùn yírùnyírùn àti àrùn kògbóògùn HIV/AIDS — ti lu agogo ìtanijí ìwà-ọmọlúwàbí fún àìníye ọdún — pàápàá jù lọ lórí ìgbàṣẹ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn kí wọn ó tó ṣe ìdánwò àti ìlànà ìṣètò ìlera onítúláàsì." Awon ileese ti o je asiwaju ninu eto ilera lagbaaye bi i Ajo Eleto Ilera Agbaye, Ajo Asakoso Arun ti orile-ede Amerika ati Ileese Eto Ilera Ijoba Apapo ni o maa n ko owo sile fun iru awon ise bayii. Àwọn iléeṣẹ́ tí ó jẹ́ asíwájú nínú ètò ìlera lágbàáyé bí i Àjọ Elétò Ìlera Àgbáyé, Àjọ Aṣàkóso Àrùn ti orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà àti Iléeṣẹ́ Ètò Ìlera Ìjọba Àpapọ̀ ni ó máa ń kó owó sílẹ̀ fún irú àwọn iṣẹ́ báyìí. Ni orile-ede Zimbabwe, ni aarin awon odun ti o re koja ki a to wo Egbaa odun, o le ni 17,000 awon obinrin ti o ni arun kogboogun ni o se idanwo lai fi ase fun awon eleto idanwo wi pe awon fi owo si i ki won o lo awon fun ise iwadii ayewo egbogi-agbogunti itanka arun kogboogun AZT lagoo ara ti CDC, WHO ati NIH ko owo le lori. Ní orílẹ̀-èdè Zimbabwe, ní àárín àwọn ọdún tí ó ré kọjá kí a tó wọ Ẹgbàá ọdún, ó lé ní 17,000 àwọn obìnrin tí ó ní àrùn kògbóògùn ni ó ṣe ìdánwò láì fi àṣẹ fún àwọn elétò ìdánwò wí pé àwọn fi ọwọ́ si í kí wọn ó lo àwọn fún iṣẹ́ ìwádìí àyẹ̀wò egbògi-agbógunti ìtànká àrùn kògbóògùn AZT lágọ̀ọ́ ara tí CDC, WHO àti NIH kó owó lé lórí. Bakan naa ewe, agba oje ileese apooogunta Pfizer dan oogun kan wo ti a pe ni Trovan ni ara awon ewe 200 ni Ipinle Kano, orile-ede Naijiria, nigba ti ajakale arun yirunyirun se yo. Bákan náà ẹ̀wẹ̀, àgbà ọ̀jẹ̀ iléeṣẹ́ apooògùntà Pfizer dán oògùn kan wò tí a pè ní Trovan ní ara àwọn èwe 200 ní Ìpínlẹ̀ Kano, orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, nígbà tí àjàkálẹ̀ àrùn yírùnyírùn ṣẹ́ yọ. Opolopo idile ni o pe Pfizer ni ejo lori aigbase lowo awon ki won o to lo awon omo awon fun idanwo. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdílé ni ó pe Pfizer ní ẹjọ́ lórí àìgbàṣẹ lọ́wọ́ àwọn kí wọn ó tó lo àwọn ọmọ àwọn fún ìdánwò. Idanwo egbogi ki i se eyi ti o da lori isele-ateyinwa nipa ti eleyameya ati ifipamunisin nikan — bakan naa ni o n se okunfaa isoro aifokan tan laaarin awon asoju eto ilera ati ara ilu. Ìdánwò egbògi kì í ṣe èyí tí ó dá lórí ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá nípa ti ẹlẹ́yàmẹyà àti ìfipámúnisìn nìkan — bákan náà ni ó ń ṣe okùnfàa ìṣòro àìfọkàn tán láàárín àwọn aṣojú ètò ìlera àti ará ìlú. "Patrick Malloy ko si inu apileko ajemakada ti a pe akolee re ni, ""Eroja Ise-iwadii ati Ibokuusoro: Igbeyewo ironu nipa eto Iselu-toun Oro-aje ti o ni se pelu isoogun igbalode ni aye ifipamunisin ni Tanganyika"" pe ""Ati ifipamunisin ati isoogun igbalode ni i jo n parapo se, ti ik-in-ni n kin ilosiwaju ikeji leyin.""" "Patrick Malloy kọ sí inú àpilẹ̀kọ ajẹmákadá tí a pe àkọ́lée rẹ̀ ní, ""Èròjà Iṣẹ́-ìwádìí àti Ìbókùúsọ̀rọ̀: Ìgbéyẹ̀wò ìrònú nípa ètò Ìṣèlú-tòun Ọrọ̀-ajé tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìṣoògùn ìgbàlódé ní ayé ìfipámúnisìn ní Tanganyika"" pé ""Àti ìfipámúnisìn àti ìṣoògùn ìgbàlódé ní í jọ ń parapọ̀ ṣe, tí ìk-ín-ní ń kín ìlọsíwájú ìkejì lẹ́yìn.""" "Lati ayee amodi si aye iru awon ""ajakale-arun bawon-onni"", awon asoju ijoba ifipamunisin saba maa n fi awon Omo Adulawo se ohun elo fun idanwo lai gba ase, Malloy ko pe ""...eje Omo Adulawo ni o dara ju lo lati fi bo ise iwadii egbogi aye ijoba amunisin""." "Láti ayée àmòdi sí ayé irú àwọn ""àjàkálẹ̀-àrùn báwọ̀n-ọnnì"", àwọn aṣojú ìjọba ìfipámúnisìn sábà máa ń fi àwọn Ọmọ Adúláwọ̀ ṣe ohun èlò fún ìdánwò láì gba àṣẹ, Malloy kọ pé ""...ẹ̀jẹ̀ Ọmọ Adúláwọ̀ ni ó dára jù lọ láti fi bọ́ iṣẹ́ ìwádìí egbògi ayé ìjọba amúnisìn""." O tesiwaju ninu oroo re: Ó tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ọ rẹ̀: Ni Tanganyika ati ni apa ibomiran ni Ile-Adulawo, eyi tumo si wi pe ni igbakuugba ni awon amunisin lee ke si awon ti won n je gaba le lori lati yanda awon padi eje, ti o duro fun eya abuda ara won fun asoju eto ilera ti yoo je lilo fun idanwo. Ní Tanganyika àti ní apá ibòmíràn ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀, èyí túmọ̀ sí wí pé ní ìgbàkúùgbà ni àwọn amúnisìn leè ké sí àwọn tí wọ́n ń jẹ gàba lé lórí láti yànda àwọn pádi ẹ̀jẹ̀, tí ó dúró fún ẹ̀yà àbùdá ara wọn fún aṣojú ètò ìlera tí yóò jẹ́ lílò fún ìdánwò. "Awon isele bawonyi ko yato si gboyii-soyii oro ti awon eniyan n je ni enu ni Ila-oorun Ile-Adulawo nipa ""awon egbe "" ti o n sise fun awon Oyinbo ti isee ti won ko ju ki won o maa ji Omo Adulawo gbe lo lati gba eje ti won yoo fi se oogun kan bi ojia ti a pe ni mumiani." "Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ báwọ̀nyí kò yàtọ̀ sí gbọ́yìí-sọ̀yìí ọ̀rọ̀ tí àwọn ènìyàn ń jẹ ní ẹnu ní Ìlà-oòrùn Ilẹ̀-Adúláwọ̀ nípa ""àwọn ẹgbẹ́ "" tí ó ń ṣiṣẹ́ fún àwọn Òyìnbó tí iṣẹ́ẹ ti wọn kò ju kí wọn ó máa jí Ọmọ Adúláwọ̀ gbé lọ láti gba ẹ̀jẹ̀ tí wọn yóò fi ṣe oògùn kan bí òjíá tí a pè ní mumiani." Oro iperi ni edee Swahili akawe oogun naa ni “amuje” tabi “agbeje-fun-iwosan” — ti o ti di “imori-eni-sabe” bayii. Ọ̀rọ̀ ìperí ní èdèe Swahili àkàwé oògùn náà ni “amùjẹ̀” tàbí “agbẹ̀jẹ̀-fún-ìwòsàn” — tí ó ti di “ìmórí-ẹni-sábẹ̀” báyìí. Isele-ateyinwa ti o buru jai yii ti gbin eso aifokan tan ninu awon egbogi ajesara, isayewo ati idan oogun wo ni Ile-Adulawo, ti o si n farahan ninu ise awon asoju eto ilera ti o n sise papo pelu ijoba ati awon ileese alooogunta ni agbaye. Ìṣẹ̀lẹ̀-àtẹ̀yìnwá tí ó burú jáì yìí ti gbin èso àìfọkàn tán nínú àwọn egbògi àjẹsára, ìṣàyẹ̀wò àti ìdán oògùn wò ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀, tí ó sì ń farahàn nínú iṣẹ́ àwọn aṣojú ètò ìlera tí ó ń ṣiṣẹ́ papọ̀ pẹ̀lú ìjọba àti àwọn iléeṣẹ́ alooògùntà ní àgbáyé. Idanwo oogun arun yirunyirun igbaa nni ni Kano, orile-edee Naijiria, gbin opolopo ainigbagbo ti ko mu ki ipolongo idanwo oogun arun romolaparomolese o rinle. Ìdánwò oògùn àrùn yírùnyírùn ìgbàa nnì ní Kano, orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà, gbin ọ̀pọ̀lọpọ̀ àìnígbágbọ̀ tí kò mú kí ìpolongo ìdánwò oògùn àrùn rọmọlápárọmọlẹ́sẹ̀ ó rinlẹ̀. Aheso nipa egbogi ajesara agbogunti arun romolaparomolese fon ka si igboro. Awon aheso oro naa di pinpin ka bi iroyin ti o se atona eto imulo ijoba agbegbe ti o f'ofin de iloo egbogi arun romolaparomolese ni orile-edee Naijiria ni odun-un 2003. Àhesọ nípa egbògi àjẹsára agbógunti àrùn rọmọlápárọmọlẹ́sẹ̀ fọ́n ká sí ìgboro. Àwọn àhesọ ọ̀rọ̀ náà di pínpín ká bí ìròyìn tí ó ṣe atọ́nà ètò ìmúlò ìjọba agbègbè tí ó f'òfin de ìlòo egbògi àrùn rọmọlápárọmọlẹ́sẹ̀ ní orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà ní ọdún-un 2003. Imularada leyin ‘ori fifo’ ifipamunisin Ìmúláradá lẹ́yìn ‘orí fífọ́’ ìfipámúnisìn Pelu ohun ti a ti so, ki ni gbogbo iwonyi yoo fa fun idanwo egbogi arun COVID-19 ni Ile-Adulawo ? Pẹ̀lú ohun tí a ti sọ, kí ni gbogbo ìwọ̀nyí yóò fà fún ìdánwò egbògi àrùn COVID-19 ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ? "Awon eniyan ni ori ayelujara ati ajijangbara gbogbo lo ti penupo wi pe ""awon Omo Adulawo ki i se eku emo oyinbo""." "Àwọn ènìyàn ní orí ayélujára àti ajìjàngbara gbogbo ló ti pẹnupọ̀ wí pé ""àwọn Ọmọ Adúláwọ̀ kì í ṣe eku ẹmọ́ òyìnbó""." "Oga agba Ajo Eto Ilera Agbaye (WHO) Tedros Adhanom Ghebreyesus ti pe ihuwasi awon onisegun mejeeji naa si ""ori fifo "" ti o da lori “laakaye ifipamunisin”, o si fi lede:" "Ọ̀gá àgbà Àjọ Ètò Ìlera Àgbáyé (WHO) Tedros Adhanom Ghebreyesus ti pe ìhùwàsí àwọn oníṣègùn méjèèjì náà sí ""orí fífọ́ "" tí ó dá lórí “làákàyè ìfipámunisìn”, ó sì fi léde:" Ko lee je Ile Adulawo ati pe ki i se Ile Adulawo ni yoo je ibi idanwo fun eyikeyii irufe egbogi. Kò leè jẹ́ Ilẹ̀ Adúláwọ̀ àti pé kì í ṣe Ilẹ̀ Adúláwọ̀ ni yóò jẹ́ ibi ìdánwò fún èyíkéyìí irúfẹ́ egbògi. Sibe, iberubojo ati aifokan tan idanwo egbogi ti mu ki dida awon eni ti o ti lugbade arun afomo kokoro aifojuri korona mo lawujo ati isayewo o nira fun awon osise eleto ilera. Síbẹ̀, ìbẹ̀rùbojo àti àìfọkàn tán ìdánwò egbògi ti mú kí dídá àwọn ẹni tí ó ti lùgbàdè àrùn àfòmọ́ kòkòrò àìfojúrí kòrónà mọ́ láwùjọ àti ìṣàyẹ̀wò ó nira fún àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera. Ni orile-edee Cote d'Ivoire ni ojo 6, Osu kerin, awon afehonuhan ti ina bo ibi ayewo arun COVID-19 kan, idi ti won fi se bee ni wi pe agbegbe ti ero po si ni won sori ibi ayewo naa si ti ko si bojumu. Ní orílẹ̀-èdèe Côte d'Ivoire ní ọjọ́ 6, Oṣù kẹrin, àwọn afẹ̀hónúhàn ti iná bọ ibi àyẹ̀wò àrùn COVID-19 kan, ìdí tí wọ́n fi ṣe bẹ́ẹ̀ ni wí pé agbègbè tí èró pọ̀ sí ni wọ́n sọrí ibi àyẹ̀wò náà sí tí kò sì bójúmu. "Ileese BBC jabo wi pe, ""ikolu naa “mu ‘ni ranti ihuwasi awon eniyan ni asiko ti arun iba Ebola n ja roinroin ni Iwo-oorun ati Aarin gbungbun Ile Adulawo nibi ti awon kan ti ya bo awon onise eto ilera, pelu imufuradani wi pe won n ko arun naa wo adugboo awon, bokanran-an ki won fun awon ni itoju ti o letike""." "Iléeṣẹ́ BBC jábọ̀ wí pé, ""ìkọlù náà “mú ‘ni rántí ìhùwàsí àwọn ènìyàn ní àsìkò tí àrùn ibà Ebola ń jà rọ̀ìnrọ̀ìn ní Ìwọ̀-oòrùn àti Àárín gbùngbùn Ilẹ̀ Adúláwọ̀ níbí tí àwọn kan ti ya bo àwọn oníṣẹ́ ètò ìlera, pẹ̀lú ìmúfuradání wí pé wọn ń kó àrùn náà wọ àdúgbòo àwọn, bókànràn-an kí wọ́n fún àwọn ní ìtọ́jú tí ó lẹ́tikẹ""." "Ju bee lo, ninu rogbodiyan ajakale-arun iba Ebola odun-un 2018 ni DR Congo, awon ayewokan ayewokan ti a se ni ara awon eni ti o ti lu gude arun Ebola ""ti o tele alakale iwa-omoluwabi kan"" — labe itonaa Onisegun Muyembe ati ijoba orile-edee DR Congo — doola emi awon eniyan nikeyin." "Jù bẹ́ẹ̀ lọ, nínú rògbòdìyàn àjàkálẹ̀-àrùn ibà Ebola ọdún-un 2018 ní DR Congo, àwọn àyẹ̀wòkan àyẹ̀wòkàn tí a ṣe ní ara àwọn ẹni tí ó ti lu gúdẹ àrùn Ebola ""tí ó tẹ̀lé àlàkalẹ̀ ìwà-ọmọlúwàbí kan"" — lábẹ́ ìtọ́nàa Oníṣègùn Muyembe àti ìjọba orílẹ̀-èdèe DR Congo — dóòlà ẹ̀mí àwọn ènìyàn níkẹyìn." Nigba ti o maa fi di Osu Kokanla odun-un 2019, ti a ti se ayewo fun omo orile edee Congo ti o ju egberun lo, a fi onte lu egbogi ajesara kan. Nígbà tí ó máa fi di Oṣù Kọkànlá ọdún-un 2019, tí a ti ṣe àyẹ̀wò fún ọmọ orílẹ̀ èdèe Congo tí ó ju ẹgbẹ̀rún lọ, a fi òǹtẹ̀ lu egbògi àjẹsára kan. O ye ki WHO o se ikede wi pe arun iba ida eje Ebola ko si ni DR Congo mo ni ojo 12 Osu Kerin, sugbon leyin 50 ojo ti ko si eni ti o lugbadii arun yii, omokunrin ti ojo orii re je odun 26 ko arun iba ida eje Ebola o si file s'aso bora ni ojo 10 Osu Kerin. Ó yẹ kí WHO ó ṣe ìkéde wí pé àrùn ibà ìdà ẹ̀jẹ̀ Ebola kò sí ní DR Congo mọ́ ní ọjọ́ 12 Oṣù Kẹrin, ṣùgbọ́n lẹ́yìn 50 ọjọ́ tí kò sí ẹni tí ó lùgbàdìi àrùn yìí, ọmọkùnrin tí ọjọ́ oríi rẹ̀ jẹ́ ọdún 26 kó àrùn ibà ìdà ẹ̀jẹ̀ Ebola ó sì filẹ̀ ṣ'aṣọ bora ní ọjọ́ 10 Oṣù Kẹrin. Ni bayii, ni afikun Ebola ati awuyewuye oro eto omoniyan ti o n m'igboro titi lowolowo, orile-edee DR Congo ni lati ko oju si didekun igbodikan ajakale-arun kokoro aifojuri korona ti o n gbile bi ogede. Ní báyìí, ní àfikún Ebola àti awuyewuye ọ̀rọ̀ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn tí ó ń m'ìgboro tìtì lọ́wọ́lọ́wọ́, orílẹ̀-èdèe DR Congo ní láti kọ ojú sí dídẹ́kun ìgbodikan àjàkálẹ̀-àrùn kòkòrò àìfojúrí kòrónà tí ó ń gbilẹ̀ bí ọ̀gẹ̀dẹ̀. Awon igbese 62 ti o n gbero lati wa egbogi ajesara fun arun COVID-19 lo n lo lowo. Ayewo ati idanwo egbogi ajesara ti yoo sise de gongo ti a gbe se lona ti o ba iwa-omoluwabi mu maa n gba asiko. Àwọn ìgbésẹ̀ 62 tí ó ń gbèrò láti wá egbògi àjẹsára fún àrùn COVID-19 ló ń lọ lọ́wọ́. Àyẹ̀wò àti ìdánwò egbògi àjẹsára tí yóò ṣiṣẹ́ dé góńgó tí a gbé ṣe lọ́nà tí ó bá ìwà-ọmọlúwàbí mu máa ń gba àsìkò. Nje awon ileese apooogunta nla yoo diro mo awon ofin iwa-omoluwabi ni Ile-Adulawo bi won ti se n se bi won ba n se idanwo ni Ile oyinbo? Ǹjẹ́ àwọn iléeṣẹ́ apooògùntà ńlá yóò dìrọ̀ mọ́ àwọn òfin ìwà-ọmọlúwàbí ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ bí wọ́n ti ṣe ń ṣe bí wọ́n bá ń ṣe ìdánwò ní Ilẹ̀ òyìnbó? Ni Burundi, awon akoroyin merin ti a fi satimole n duro de ipinnu ejo kotemilorun Ní Burundi, àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin tí a fi sátìmọ́lé ń dúró de ìpinnu ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn Esun ilowosi idukoko mo aabo ilu ni a fi kan awon akoroyin naa Ẹ̀sùn ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú ni a fi kan àwọn akọ̀ròyìn náà Ileese Oniroyin naa ni Bujumbura, nibi ti a yo awon ile igbohunsafefe kuro lori ila. Ojo 19 osu Ebibi 2010. Iléeṣẹ́ Oníròyìn náà ní Bujumbura, níbi tí a yọ àwọn ilé ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ kúrò lórí ìlà. Ọjọ́ 19 oṣù Èbìbí 2010. Awon akoroyin merin — Agnes Ndirubusa, Christine Kamikazi, Terence Mpozenzi ati Egide Harerimana — ni a da lejo igbese lati yepere aabo ilu ti a si ran won lo si ewon ninu osu Kin-in-ni odun-un 2020. Àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rin — Agnès Ndirubusa, Christine Kamikazi, Térence Mpozenzi àti Egide Harerimana — ni a dá lẹ́jọ́ ìgbésẹ̀ láti yẹpẹrẹ ààbò ìlú tí a sì rán wọn lọ sí ẹ̀wọ̀n nínú oṣù Kìn-ín-ní ọdún-un 2020. Awon mereerin ti o n sise pelu iwe iroyin Iwacu ko fi meni pe meji nise ni won so wi pe awon ko se sofin. Àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìwé ìròyìn Iwacu kò fi méní pe méjì níṣe ni wọn sọ wí pé àwọn kò ṣẹ̀ sófin. Ni bayii won n duro de ipinnu ejo kotemilorun lori atimole won, leyin igbejo ojo 6 osu Karun-un. Ní báyìí wọ́n ń dúró de ìpinnu ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn lórí àtìmọ́lé wọn, lẹ́yìn ìgbẹ́jọ ọjọ́ 6 oṣù Karùn-ún. Antoine Kaburahe, oludasile iwe iroyin ti o n gbe ni eyin odi, ko: Antoine Kaburahe, olùdásílẹ̀ ìwé ìròyìn tí ó ń gbé ní ẹ̀yin odi, kọ: Ni yajoyajo: Opin igbejo ni Bubanza. Iwacu bori. Ní yàjóyàjó: Òpin ìgbẹ́jọ́ ní Bubanza. Iwacu bọ́rí. Esun ti a ka si awon akoroyin naa lorun ki i se tiwon. Ẹ̀sùn tí a kà sí àwọn akọ̀ròyìn náà lọ́rùn kì í ṣe tiwọn. Isee won ni awon akoroyin naa n se: ikoroyinjo. Iṣẹ́ẹ wọn ni àwọn akọ̀ròyìn náà ń ṣe: ìkóròyìnjọ. Okan-an bale ! Ọkàn-án balẹ̀ ! Amo adajo ko tii dajo, abalo-babo oro di leyin osu kan. Àmọ́ adájọ́ kò tíì dájọ́, àbálọ-bábọ̀ ọ̀rọ̀ di lẹ́yìn oṣù kan. E duro sinsin! Ẹ dúró ṣinṣin! Atimole fun ikoroyinjo Àtìmọ́lé fún ìkóròyìnjọ Ni ojo 22, osu Owara, awon eso alaabo Burundi wa a ko pelu egbe agbeborin alatako ijoba kan — ti a n pe ni RED-Tabara, ti o fi Democratic Republic of Congo se ile — ni agbegbe ibode igbo Kibira. Ní ọjọ́ 22, oṣù Ọ̀wàrà, àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò Burundi wà á kò pẹ̀lú ẹgbẹ́ agbébọrìn alátakò ìjọba kan — tí à ń pè ní RED-Tabara, tí ó fi Democratic Republic of Congo ṣe ilé — ní agbègbè ibodè igbó Kibira. Awon egbe olote agbeborin ti maa n fi ibi yii kiri agbegbe naa. Àwọn ẹgbẹ́ ọlọ́tẹ̀ agbébọrìn ti máa ń fi ibí yìí kiri àgbègbè náà. Ninu ija akata naa, awon agbeborin 14 ni iku pa, ti eso alaabo 10 si ba a lo. Nínú ìjà akátá náà, àwọn agbébọrìn 14 ni ikú pa, tí ẹ̀ṣọ́ aláàbò 10 sì bá a lọ. Ni ojo yen naa, awon olopaa fi awon akoroyin Iwacu merin ati awako won Adolphe Masabaakiza si atimole, nigba ti won lo koroyin jo ni adugbo Musigati, ni Bubanza, nibi ti won ti fe ba awon eniyan ti o sa kuro ni adugbo nigba ti ija naa be sile. Ní ọjọ́ yẹn náà, àwọn ọlọ́pàá fi àwọn akọ̀ròyìn Iwacu mẹ́rin àti awakọ̀ wọn Adolphe Masabaakiza sí àtìmọ́lé, nígba tí wọn lọ kóròyìn jọ ní àdúgbò Musigati, ní Bubanza, níbi tí wọ́n ti fẹ́ bá àwọn ènìyàn tí ó sá kúrò ní àdúgbò nígbà tí ìjà náà bẹ́ sílẹ̀. Lakooko, a fi won si atimole lai fi esun kan won, ti a si lu Christine Kamikazi nigba ti won mu won. Lákọ̀ọ́kọ́, a fi wọn sí àtìmọ́lé láì fi ẹ̀sùn kàn wọ́n, tí a sì lu Christine Kamikazi nígbà tí wọ́n mú wọn. Olopaa gba ero-ibanisoro ati awon ohun elo ise won ti awon otelemuye si beere fun gbolohun ifiwole si ori ero won lati ye e wo finnifinni. Ọlọ́pàá gba ẹ̀rọ-ìbánisọ̀rọ̀ àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ wọn tí àwọn ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ sí béèrè fún gbólóhùn ìfiwọlé sí orí ẹ̀rọ wọn láti yẹ̀ ẹ́ wò fínnífínní. Awon akoroyin naa di eni ti a n gbe kiri lo si tubu miiran ti ko sunwon. Àwọn akọ̀ròyìn náà di ẹni tí à ń gbé kiri lọ sí túbú mìíràn tí kò sunwọ̀n. "Ni ojo 26 osu Kewaa, ni Bubanza, a jaja fesun ""Ilowosi idukoko mo aabo ilu"" kan won." "Ní ọjọ́ 26 oṣù Kẹwàá, ní Bubanza, a jàjà fẹ̀sùn ""Ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú"" kàn wọ́n." Ni ojo 31, osu Kewaa, abanirojo naa fi eri eyi lele o si fesun kan won ni pe won mo si ikolu awon koloransi eda naa. Ní ọjọ́ 31, oṣù Kẹwàá, abánirojọ̀ náà fi ẹ̀rí èyí lélẹ̀ ó sì fẹ̀sùn kàn wọ́n ní pé wọ́n mọ̀ sí ìkọlù àwọn kọ̀lọ̀rànsí ẹ̀dá náà. Awon ileese ni eka-o-jeka ni o ti pe fun idasile won, titi kan Human Rights Watch, International Federation of Journalists, Olucome, African Journalists’ Federation ati Ajo Burundaise des Radiodiffuseurs. Àwọn iléeṣẹ́ ní ẹ̀ka-ò-jẹ̀ka ni ó ti pè fún ìdásílẹ̀ wọn, títí kan Human Rights Watch, International Federation of Journalists, Olucome, African Journalists’ Federation àti Àjọ Burundaise des Radiodiffuseurs. Sibe, Ileese Igbohunsafefe Apapo so wi pe awon ko tii le so si oran naa bayii. Síbẹ̀, Iléeṣẹ́ Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ Àpapọ̀ sọ wí pé àwọn kò tíì lè sọ sí ọ̀ràn náà báyìí. Iwacu bu enu ate ohun ti ajo naa so, ni pe won ko fesun kankan kan won nigba ti won mu won ati pe ojuse ajo naa ni lati gbeja awon akoroyin. Iwacu bu ẹnu àtẹ́ ohun tí àjọ náà sọ, ní pé wọn kò fẹ̀sùn kankan kàn wọ́n nígbà tí wọ́n mú wọn àti pé ojúṣe àjọ náà ni láti gbèjà àwọn akọ̀ròyìn. Opo awon eniyan ni o gbe leyin awon akoroyinnaa ti won si fi owo bo ifesunkan lori ero-ayelujara. Awon ileese oniroyin rii gege bi ifoju-eto si ominira oniroyin gbole, ti Iwacu si n to okun oran naa lo pekipeki. Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn ní ó gbè lẹ́yìn àwọn akọ̀ròyìnnáà tí wọ́n sì fi ọwọ́ bọ ìfẹ̀sùnkàn lórí ẹ̀rọ-ayélujára. Àwọn iléeṣẹ́ oníròyìn ríi gẹ́gẹ́ bí ìfojú-ẹ̀tọ̀ sí òmìnira oníròyìn gbolẹ̀, tí Iwacu sì ń tọ okùn ọ̀ràn náà lọ pẹ́kípẹ́kí. Akoroyin Esdras Ndikumana tuwiiti: Akọ̀ròyìn Esdras Ndikumana túwíìtì: "Burundi: awon akoroyin Iwacu merin (ati awako won) ni a fi esun ""ilowosi idukoko mo aabo ilu"" kan nitori won lo ko iroyin ikolu ti o wa saye ti won si di ero ogba ewon Bubanza (Aworan lati owo Yaga)" "Burundi: àwọn akọ̀ròyìn Iwacu mẹ́rin (àti awakọ̀ wọn) ni a fi ẹ̀sùn ""ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú"" kàn nítorí wọ́n lọ kó ìròyìn ìkọlù tí ó wá sáyé tí wọ́n sì di ẹ̀rọ ọgbà ẹ̀wọ̀n Bubanza (Àwòrán láti ọwọ́ Yaga)" Leyin ti won ti ni ejo ti o fi awon si inu atimole naa ko te awon lorun, a da ojo igbejo won si ojo 18, osu Kokanla, kayefi ni o je fun won nigba ti won gbe won lo sile ejo ni ojo 11, osu Kokanla ki won o wa gbowo ponyin rojo niwaju adajo — lai si awon agbejoro. Lẹ́yìn tí wọ́n ti ní ẹjọ́ tí ó fi àwọn sí inú àtìmọ́lé náà kò tẹ́ àwọn lọ́rùn, a dá ọjọ́ ìgbẹ́jọ́ wọn sí ọjọ́ 18, oṣù Kọkànlá, kàyéfì ni ó jẹ́ fún wọn nígbà tí wọ́n gbé wọn lọ sílé ẹjọ́ ní ọjọ́ 11, oṣù Kọkànlá kí wọn ó wá gbọ́wọ́ pọ̀nyìn rojọ́ níwájú adájọ́ — láì sí àwọn agbẹ́jọ́rò. Won ko won ko fesi nitori ko si awon agbejoro won nikale, won si da won pada si atimole, ki ojo 18 ti a da fun igbejo o ko. Wọ́n kọ̀ wọn kò fèsì nítorí kò sí àwọn agbẹ́jọ́rò wọn níkàlẹ̀, wọ́n sì dá wọn padà sí àtìmọ́lé, kí ọjọ́ 18 tí a dá fún ìgbẹ́jọ́ ó kò. Ni ojo 20 osu Kokanla, ipinnu de ti wi pe awon akoroyin mereerin yoo pada sinu atimole, amo won da awako sile. Ní ọjọ́ 20 oṣù Kọkànlá, ìpinnu dé tí wí pé àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin yóò padà sínú àtìmọ́lé, àmọ́ wọ́n dá awakọ̀ sílẹ̀. Idajo ti a fun won to odun 15 ninu ewon. Ìdájọ́ tí a fún wọn tó ọdún 15 nínú ẹ̀wọ̀n. Aare Pierre Nkurunziza so nibi apejo awon akoroyin kan ti o wa saye ni ojo 26 osu Kejila wi pe ohun ohun ko ni fe didiju mori dajo amo o digba ti a ba ti sanpa ti ko se e san mo ni oun yoo to ka a leri, pelu pe o le fi ase ti o n be ni ikawo re da ejo naa nu. Ààrẹ Pierre Nkurunziza sọ níbi àpéjọ àwọn akọ̀ròyìn kan tí ó wá sáyé ní ọjọ́ 26 oṣù Kejìlá wí pé ohun ohun kò ní fẹ́ dídijú mọ́rí dájọ́ àmọ́ ó dìgbà tí a bá ti ṣánpá tí kò ṣe é ṣán mọ́ ni òun yóò tó ká a lérí, pẹ̀lú pé ó lè fi àṣẹ tí ó ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ da ẹjọ́ náà nù. Lojo 30, osu Kin-in-in ni Bubanza, a ran to awon akoroyin mereerin naa lo si ewon odun meji ati abo pelu ki enikookan o sanwo itanran egbeegberun owo francs ($521 owo orile ede Amerika) labe ofin 16 ti Ofin Odaran, ti awako si gba ile-e re lai sanwo itanran. Lọ́jọ́ 30, oṣù Kìn-ín-ín ní Bubanza, a rán to àwọn akọ̀ròyìn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà lọ sí ẹ̀wọ̀n ọdún méjì àti àbọ̀ pẹ̀lú kí ẹnìkọ̀ọ̀kan ó sanwó ìtanràn ẹgbẹẹgbẹ̀rún owó francs ($521 owó orílẹ̀ èdè Amẹ́ríkà) lábẹ́ òfin 16 ti Òfin Ọ̀daràn, tí awakọ̀ sì gba ilé-e rẹ̀ láì sanwó ìtanràn. "Idajo naa ko fi han ni pato wi pe awon akoroyin naa mo ohunkohun nipa isele naa, latari eyi esun naa yira pada di ""igbese ilowosi idukoko mo aabo ilu ti ko se e se"", iyen ni pe — won pete lati dunmorurumoruru mo aabo ilu amo o soro lati gbe se." "Ìdájọ́ náà kò fi hàn ní pàtó wí pé àwọn akọ̀ròyìn náà mọ ohunkóhun nípa ìṣẹ̀lẹ̀ náà, látàrí èyí ẹ̀sùn náà yíra padà di ""ìgbésẹ̀ ìlọ́wọ́sí ìdúkokò mọ́ ààbò ìlú tí kò ṣe é ṣe"", ìyẹn ni pé — wọ́n pète láti dúnmọ̀rurumọ̀ruru mọ́ ààbò ìlú àmọ́ ó ṣòro láti gbé ṣe." Iwacu salaye wi pe awon akoroyin naa lo sibi isele naa leyin ti awon alase ti fi lede, won gba iwe ase ko si si ofin ti o ni kenikan o maa de agbegbe isele naa. Iwacu ṣàlàyé wí pé àwọn akọ̀ròyìn náà lọ síbi ìṣẹ̀lẹ̀ náà lẹ́yìn tí àwọn aláṣẹ tí fi léde, wọ́n gba ìwé àṣẹ kò sì sí òfin tí ó ní kẹ́nìkan ó máa dé agbègbè ìṣẹ̀lẹ̀ náà. "Eri kan soso ti won ri dimu ti o ko awon akoroyin naa si yawuyawu ni atejise ori WhatsApp ti okan lara awon akoroyin naa fi sowo si oree re kan, ti o so wi pe awon fe lo ""ran awon olote ijoba naa lowo ""." "Ẹ̀rí kan ṣoṣo tí wọ́n rí dìmú tí ó kó àwọn akọ̀ròyìn náà sí yáwúyáwú ni àtẹ̀jíṣẹ́ orí WhatsApp tí ọ̀kan lára àwọn akọ̀ròyìn náà fi ṣọwọ́ sí ọ̀rẹ́ẹ rẹ̀ kan, tí ó sọ wí pé àwọn fẹ́ lọ ""ran àwọn ọlọ́tẹ̀ ìjọba náà lọ́wọ́ ""." Amo efe lasan ni won fi se — ijoba ti maa n saba ko awon alatako, egbe oloselu ati awon agbebonrin papo lati jare iru igbese bayii. the atejise naa ni a fi kan won mole. Àmọ́ ẹ̀fẹ̀ lásán ni wọ́n fi ṣe — ìjọba ti máa ń sábà kó àwọn alátakò, ẹgbẹ́ olóṣèlú àti àwọn agbébọnrìn papọ̀ láti jàre irú ìgbésẹ̀ báyìí. the àtẹ̀jíṣẹ́ náà ni a fi kàn wọ́n mọ́lẹ̀. Reporters Without Borders (RSF) so wi pe awon akoroyin naa letoo lati jabo iroyin ti o kan gbogbo ilu gbongbon lai foya igbesan, papaa ni igbaradi ibo orile-edee Burundi ojo 20 osu karun-un ti o n bo lona. Reporters Without Borders (RSF) sọ wí pé àwọn akọ̀ròyìn náà lẹ́tọ̀ọ́ láti jábọ̀ ìròyìn tí ó kan gbogbo ìlú gbọ̀ngbọ̀n láì fòyà ìgbẹ̀san, papàá ní ìgbaradì ìbò orílẹ̀-èdèe Burundi ọjọ́ 20 oṣù karùn-ún tí ó ń bọ̀ lọ́nà. Won ko iwe ifesunkanni kan ti o n pe fun idasile won, eyi ti eniyan ti o to 7,000 towobo ni ibere osu Karun-un. Wọ́n kọ ìwé ìfẹ̀sùnkànni kan tí ó ń pè fún ìdásílẹ̀ wọn, èyí tí ènìyàn tí ó tó 7,000 tọwọ́bọ̀ ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù Karùn-ún. Awon igba-keji ajo European Union, Igbimo ijoba Yuroopu, ati awon agba UN nipa eto omoniyan wa lara awon ti o ti pe fun idasile won. Àwọn igbá-kejì àjọ European Union, Ìgbìmọ̀ ìjọba Yúróòpù, àti àwọn àgbà UN nípa ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn wà lára àwọn tí ó ti pè fún ìdásílẹ̀ wọn. Lojo 20 osu Keji, awon akoroyin naa ni idajo naa ko-te awon lorun, ti won so wi pe alaise ni won n fiya je, ati ayipada pajawiri ti o deedee ba esun ti won koko fi kan won. Lọ́jọ́ 20 oṣù Kejì, àwọn akọ̀ròyìn náà ní ìdájọ́ náà kò-tẹ́ àwọn lọ́rùn, tí wọ́n sọ wí pé aláìṣẹ̀ ni wọ́n ń fìyà jẹ, àti àyípadà pàjáwìrì tí ó déédéé bá ẹ̀sùn tí wọ́n kọ́kọ́ fi kàn wọ́n. Lojo 6, osu karun-un, awon akoroyin naa foju han nile ejo kotemilorun kan, leyin ti won ti fi ewon osu mefa jura. Lọ́jọ́ 6, oṣù karùn-ún, àwọn akọ̀ròyìn náà fojú hàn nílé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn kan, lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ẹ̀wọ̀n oṣù mẹ́fà jura. "Ni ifesipada si esun naa latari ise-ije ori WhatsApp, ni eyi ti akoroyin kan so wi pe awon olote naa n bo wa ""di alaafia lowo ""." "Ní ìfèsìpadà sí ẹ̀sùn náà látàrí iṣẹ́-ìjẹ́ orí WhatsApp, ní èyí tí akọ̀ròyìn kan sọ wí pé àwọn ọlọ́tẹ̀ náà ń bọ̀ wá ""dí àlàáfíà lọ́wọ́ ""." RFI tun oro agbejoro won, Clement Retirakiza wi, wipe kko si eri ti daju nipa esun ti a fi kan awon akoroyin naa, won kan fe fi owo ola gba alaise loju ni. RFI tún ọ̀rọ̀ agbẹ́jọ́rò wọn, Clément Retirakiza wí, wípé kkò sí ẹ̀rí tí dájú nípa ẹ̀sùn tí a fi kan àwọn akọ̀ròyìn náà, wọ́n kàn fẹ́ fi ọwọ́ ọlá gba aláìṣẹ̀ lójú ni. Ojo ti pe ti Iwacu ti wa gedegbe gege bi ohun ti o fajuro si jagidijagan iselu — oun ni ileese oniroyin ti o keyin leyin igbesele odun-un 2015. Ọjọ́ ti pẹ́ tí Iwacu ti wà gedegbe gẹ́gẹ́ bí ohùn tí ó fajúro sí jágídíjàgan ìṣèlú — òun ni iléeṣẹ́ oníròyìn tí ó kẹ́yìn lẹ́yìn ìgbẹ́sẹ̀lé ọdún-un 2015. Isele ateyinwa nipa ijiya akoroyin Ìṣẹ̀lẹ̀ àtẹ̀yìnwá nípa ìjìyà akọ̀ròyìn Leyin eto idibo ti o da wahala sile ti odun-un After 2015 — eyi ti o gbe Nkurunziza pada sipo fun igba keta ti awon eniyan so wi pe o tase agbere sofin — ifipagbajoba ti ko yori si re. Ise awon akoroyin de polukumusu. Lẹ́yìn ètò ìdìbò tí ó dá wàhálà sílẹ̀ ti ọdún-un After 2015 — èyí tí ó gbé Nkurunziza padà sípò fún ìgbà kẹta tí àwọn ènìyàn sọ wí pé ó tasẹ̀ àgbẹ̀rẹ̀ sófin — ìfipágbàjọba tí kò yọrí sí rẹ. Iṣẹ́ àwọn akọ̀ròyìn de polúkúmuṣu. Opolopo ileese agbohunsafefe — ti awon eniyan feran fun ekunrere iroyin ti ko figbakanbokan ni Burundi — ni a san pa. Opolopo akoroyin llo juba ehoro ti awon miiran bii Esdras Ndikumana je mo-yo-iya Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iléeṣẹ́ agbóhùnsáfẹ́fẹ́ — tí àwọn ènìyàn fẹ́ràn fún ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìròyìn tí kò figbákanbọ̀kan ní Burundi — ni a ṣán pa. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ akọ̀ròyìn lló júbà ehoro tí àwọn mìíràn bíi Esdras Ndikumana jẹ mo-yó-ìyà Ogoro awon akoroyin ni o ti ni iriri iya lowo awon eso agbofinro ilu, paapaa ju lo bi won n ba ko iroyin ti o “pon dandan” jo. Ọ̀gọ̀rọ àwọn akọ̀ròyìn ni ó ti ní ìrírí ìyà lọ́wọ́ àwọn ẹ̀sọ́ agbófinró ìlú, pàápàá jù lọ bí wọ́n ń bá kó ìròyìn tí ó “pọn dandan” jọ. Ni ipari odun 2015, olopaa pa onyaworan Christophe Nkezabahizi pelu awon omo-lebi meta, ni asiko ibo ti ifehonu wa saye. Ní ìparí ọdún 2015, ọlọ́pàá pa òǹyàwòrán Christophe Nkezabahizi pẹ̀lú àwọn ọmọ-lẹ́bí mẹ́ta, ní àsìkò ìbò tí ìfẹ̀hónú wá sáyé. Ninu osu Keje odun 2016, Jean Bigirimana di awati, o se e se ki o je wi pe ileese otelemuye (SNR) lo gbe e, lai je ki awon olopaa o se iwadii ifinidiikoko bo se ye. Nínú oṣù Keje ọdún 2016, Jean Bigirimana di àwátì, ó ṣe é ṣe kí ó jẹ́ wí pé iléeṣẹ́ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ (SNR) ló gbé e, láì jẹ́ kí àwọn ọlọ́pàá ó ṣe ìwádìí ìfínìdíikókò bó ṣe yẹ. Lodun yii, ni ojo 16 osu Kin-in-ni, akoroyin Blaise-Pascal Kararumiye pelu Radio Isanganiro (Meeting Point Radio) di ero akanran olopaa leyin iroyin kan nipa owo ijoba ibile kan. Lojo 28, osu kerin, olopaa kan na akoroyin Jackson Bahati nibi ti o ti n sise ikoroyin jo. Lọ́dún yìí, ní ọjọ́ 16 oṣù Kìn-ín-ní, akọ̀ròyìn Blaise-Pascal Kararumiye pẹ̀lú Radio Isanganiro (Meeting Point Radio) di èrò akánrán ọlọ́pàá lẹ́yìn ìròyìn kan nípa owó ìjọba ìbílẹ̀ kan. Lọ́jọ́ 28, oṣù kẹrin, ọlọ́pàá kan na akọ̀ròyìn Jackson Bahati níbi tí ó ti ń ṣiṣẹ́ ìkóròyìn jọ. Awon ileese oniroyin agbaye naa o gbeyin, a gbese le ise BBC ati VOA ni 2019. RSF to Burundi si ipo 160 ninu orileede 180 fun ominira oniroyin — o fi 15 lati 2015. Àwọn iléeṣẹ́ oníròyìn àgbáyé náà ò gbẹ́yìn, a gbẹ́sẹ̀ lé iṣẹ́ BBC ati VOA ní 2019. RSF to Burundi sí ipò 160 nínú orílẹ̀èdè 180 fún òmìnira oníròyìn — ó fi 15 láti 2015. Awon obinrin ni Naijiria koju ado-oloro agbeselero agbawi oro iselu lori ero-ayelujara Àwọn obìnrin ní Nàìjíríà kojú àdó-olóró àgbẹ́sẹ̀léró àgbàwí ọ̀rọ̀ ìṣèlú lórí ẹ̀rọ-ayélujára #BringBackOurGirls ati #ArewaMeToo se atunto si igbawi eto iselu ni orile ede Naijiria #BringBackOurGirls àti #ArewaMeToo ṣe àtúntò sí ìgbàwí ètò ìṣèlú ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà Awon omo egbe Mother's Savings Club, Naijiria. I'm Aworan lati owo Karen Kasmauski / USAID ni Ile-Adulawo ni ori United States government work, public domain. Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Mother's Savings Club, Nàìjíríà. I'm Àwòrán láti ọwọ́ Karen Kasmauski / USAID ní Ilẹ̀-Adúláwọ̀ ní orí United States government work, public domain. Ni Naijiria, ado-oloro agbeselero ni gbagede agbawi oro oselu. Ní Nàìjíríà, àdó-olóró àgbẹ́sẹ̀léró ni gbàgede àgbàwí ọ̀rọ̀ òṣèlú. Agbawi ati oro iselu saba maa n fi ti oro esin ati eleyameya se. Àgbàwí àti ọ̀rọ̀ ìṣèlú sábà máa ń fi ti ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn àti ẹlẹ́yàmẹyà ṣe. "Awon alagbawi ti o gbajumo lori ero-alatagba — paapaa ju lo lori Twitter — ni lati le fi ara gba opolopo gbas gbos (ede adalu-mo-Geesi Naijiria fun ""ikanse"") ni ori ero-ayarabiasa." "Àwọn alágbàwí tí ó gbajúmọ̀ lórí ẹ̀rọ-alátagbà — pàápàá jù lọ lórí Twitter — ní láti lè fi ara gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ gbas gbos (èdè àdàlù-mọ́-Gẹ̀ẹ́sì Nàìjíríà fún ""ìkànṣẹ́"") ní orí ẹ̀rọ-ayárabíàṣá." Awon alagbawi ti o je obinrin — ni afikun si tite awon ohun idanimo ti o n mu ipalara wa mole — bakan naa ni won n koju ikolu ti o ti ara ikoriira tegbintegbin eya je yo. Àwọn alágbàwí tí ó jẹ́ obìnrin — ní àfikún sí títẹ àwọn ohun ìdánimọ̀ tí ó ń mú ìpalára wá mọ́lẹ̀ — bákan náà ni wọ́n ń kojú ìkọlù tí ó ti ara ìkórìíra tẹ̀gbintẹ̀gbin ẹ̀yà jẹ yọ. Bawo ni awon alagbawi l'obinrin ni Naijiria se n farada ikoro ori ero-ayelujara bii isoro alufansa sini, oro ikoriira tegbintegbin ati imoomo yi-oro won da? Báwo ni àwọn alágbàwí l'óbìnrin ní Nàìjíríà ṣe ń farada ìkorò orí ẹ̀rọ-ayélujára bíi ìsọ̀rọ àlùfànṣá síni, ọ̀rọ̀ ìkórìíra tẹ̀gbintẹ̀gbin àti ìmọ̀ọ́mọ̀ yí-ọ̀rọ̀ wọn dà? Bawo ni won se n tesiwaju ninu ise won tabi fonrere ise won? Báwo ni wọ́n ṣe ń tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ wọn tàbí fọnrere iṣẹ́ wọn? Awon ajijagbara ori ero alatagba meji ni Naijiria fi iriri awon agbawi ati ikoriira iwa abo han: #BringBackOurGirls, ti Dokita Oby Ezekwesili je asiwaju; ati #ArewaMeToo, ti Fakhriyyah Hashim je agbateru, gbogbo won ni won ni iriri ikoriira tegbintegbin abo ninu agbo oselu ti o n fa ilosiwaju won seyin. Àwọn ajìjàgbara orí ẹ̀rọ alátagbà méjì ní Nàìjíríà fi ìrírí àwọn àgbàwí àti ìkórìíra ìwà abo hàn: #BringBackOurGirls, tí Dókítà Oby Ezekwesili jẹ́ aṣíwájú; àti #ArewaMeToo, tí Fakhriyyah Hashim jẹ́ agbátẹrù, gbogbo wọn ni wọ́n ní ìrírí ìkórìíra tẹ̀gbintẹ̀gbin abo nínú agbo òṣèlú tí ó ń fa ìlọsíwájú wọn sẹ́yìn. Ijagbara #BringBackOurGirls (#BBOG) Ìjàgbara #BringBackOurGirls (#BBOG) Odun mefa seyin, ni ojo 15, Osu Igbe odun 2014, o to 200 awon omodebinrin ti ojo ori won o ju odun 15 ati 18 lo, lati ileewe Giga Ijoba Obinrin ni Chibok eba Maidiguri, ni ariwa-ila-oorun Naijiria ni egbe afemisofo elesin Musulumi Boko Haram so di eni ti a fi tulaasi mu si igbesin. Ọdún mẹ́fà sẹ́yìn, ní ọjọ́ 15, Oṣù Igbe ọdún 2014, ó tó 200 àwọn ọmọdébìnrin tí ọjọ́ orí wọn ò ju ọdún 15 àti 18 lọ, láti iléèwé Gíga Ìjọba Obìnrin ní Chibok ẹ̀bà Maidiguri, ní àríwá-ìlà-oòrùn Nàìjíríà ni ẹgbẹ́ afẹ̀míṣòfò èlẹ́sìn Mùsùlùmí Boko Haram sọ di ẹni tí a fi túláàsì mú sí ìgbẹ̀sìn. Ijinigbe awon omodebinrin Chibok naa se okunfa ilowosi awon orile ede kari agba nla aye. Ìjínigbé àwọn ọmọdébìnrin Chibok náà ṣe okùnfà ìlọ́wọ́sí àwọn orílẹ̀ èdè kárí àgbá ńlá ayé. Ileese oniroyin BBC jabo wi pe ninu osu Igbe odun 2014, #BringBackOurGirls naa gbajumo ni ori Twitter pelu nnkan bii awon eniyan egbeegberun 3.3 ti o tun tuwiiti naa tuwiiti, ida 27 awon tuwiiti wonyi ni o wa lati Naijiria, ida 26 lati orile ede Amerika ati ida 11 lati Ile Geesi. Iléeṣẹ́ oníròyìn BBC jábọ̀ wí pé nínú oṣù Igbe ọdún 2014, #BringBackOurGirls náà gbajúmọ̀ ní orí Twitter pẹ̀lú nǹkan bíi àwọn ènìyàn ẹgbẹẹgbẹ̀rún 3.3 tí ó tún túwíìtì náà túwíìtì, ìdá 27 àwọn túwíìtì wọ̀nyí ni ó wá láti Nàìjíríà, ìdá 26 láti orílẹ̀ èdè Amẹ́ríkà àti ìdá 11 láti Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì. Dokita Oby Ezekwesili n dahun ibeere nibi eto awon obinrin ajo UN pelu awon alakooso ipolongo #BringBackOurGirls. Dókítà Oby Ezekwesili ń dáhùn ìbéèrè níbi ètò àwọn obìnrin àjọ UN pẹ̀lú àwọn alákòóso ìpolongo #BringBackOurGirls. Aworan lati owo UN Women/Ryan Brown, ojo 14, osu Owewe odun 2014. (CC BY-NC-ND 2.0) Àwòrán láti ọwọ́ UN Women/Ryan Brown, ọjọ́ 14, oṣù Ọ̀wẹwẹ̀ ọdún 2014. (CC BY-NC-ND 2.0) Dokita Obiageli (Oby) Ezekwesili, igba-keji aare Ile ifowopamo Agbaye igba kan, ati minisita eto eko orile ede Naijiria nigba kan ri, bere si tuwiiti nipa awon omodebinrin Chibok ni ojo ti won ji won gbe gan-an gan-an. Dókítà Obiageli (Oby) Ezekwesili, igbá-kejì ààrẹ Ilé ìfowópamọ́ Àgbáyé ìgbà kan, àti mínísítà ètò ẹ̀kọ́ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nígbà kan rí, bẹ̀rẹ̀ sí túwíìtì nípa àwọn ọmọdébìnrin Chibok ní ọjọ́ tí wọ́n jí wọn gbé gan-an gan-an. Isele kan ti o ti sele ti awon ajinigbe ji awon omodekunrin gbe ni ileewe Koleji ijoba Apapo ti Buni Yadi ni Ipinle Yobe, ariwa-ila-oorun Naijiria lojo 25, osu Erele odun 2014 lo si i loju si ipolongo yii. Ìṣẹ̀lẹ̀ kan tí ó ti ṣẹlẹ̀ tí àwọn àjínigbé jí àwọn ọmọdékùnrin gbé ní iléèwé Kọ́lẹ̀jì ìjọba Àpapọ̀ ti Buni Yadi ní Ìpínlẹ̀ Yobe, àríwá-ìlà-oòrùn Nàìjíríà lọ́jọ́ 25, oṣù Èrèlé ọdún 2014 ló ṣí i lójú sí ìpolongo yìí. Awon omodekunrin kankandinlogota ni o ti ara ota ibon ati ogbe obe ku, nigba ti ina si jo awon miiran pa. Àwọn ọmọdékùnrin kankàndínlọ́gọ́ta ni ó ti ara ọta ìbọn àti ọgbẹ́ ọbẹ̀ kú, nígbà tí iná sì jó àwọn mìíràn pa. Sibesibe, afi igba ti o di ojo 23, osu Igbe, nigba ti ajo UNESCO gba a lalejo ni Port Harcourt, ibi ti o kun fun epo-robi ni agbegbe Niger Delta, ni o ti ke gbajare fun idasile awon omodebinrin ti o fi di ohun ti gbogbo orile ede agbaye gba bi igba oti: Síbẹ̀síbẹ̀, àfi ìgbà tí ó di ọjọ́ 23, oṣù Igbe, nígbà tí àjọ UNESCO gbà á lálejò ní Port Harcourt, ibi tí ó kún fún epo-rọ̀bì ní agbègbè Niger Delta, ni ó ti ké gbàjarè fún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọdébìnrin tí ó fi di ohun tí gbogbo orílẹ̀ èdè àgbáyé gbà bí igbá ọtí: Ni ojo 7 osu Ebibi odun 2014, aya aare orile-ede Amerika ogabinrin Michelle Obama se atejade aworan kan ti o ti mu ami “E da awon omodebinrin wa pada” #BringBackOurGirls lowo. Ní ọjọ́ 7 oṣù Èbìbí ọdún 2014, aya ààrẹ orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ọ̀gábìnrin Michelle Obama ṣe àtẹ̀jáde àwòrán kan tí ó ti mú àmì “Ẹ dá àwọn ọmọdébìnrin wa padà” #BringBackOurGirls lọ́wọ́. Bakan naa ni o tari aworan-olohun kan lati inu Ile Funfun sita — ti igbese yii si so isele ijinigbe naa di oran ti gbogbo agbaye fe ri abalo-babo re. Bákan náà ni ó tari àwòrán-olóhùn kan láti inú Ilé Funfun síta — tí ìgbésẹ̀ yìí sì sọ ìṣẹ̀lẹ̀ ìjínigbé náà di ọ̀ràn tí gbogbo àgbáyé fẹ́ rí àbálọ-bábọ̀ rẹ̀. Odun meji ni o gba awon omo ogun orile ede Naijiria lati gba omodebinrin kan sile, ninu osu Okudu odun-un 2016. Ọdún méjì ni ó gba àwọn ọmọ ogun orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti gba ọmọdébìnrin kan sílẹ̀, nínú oṣù Òkúdù ọdún-un 2016. Nigba ti o maa fi di osu Owara odun-un 2016, awon omodebinrin 21 darapo mo awon molebi won. Ni osu Ebibi 2017, iko Boko Haram da awon omodebinrin 82 sile ninu igbesin. Nígbà tí ó máa fi di oṣù Ọ̀wàrà ọdún-un 2016, àwọn ọmọdébìnrin 21 darapọ̀ mọ́ àwọn mọ̀lẹ́bí wọn. Ní oṣù Èbìbí 2017, ikọ̀ Boko Haram dá àwọn ọmọdébìnrin 82 sílẹ̀ nínú ìgbẹ̀sìn. Sibesibe, o to omodebinrin 112 ti o di awati bi abere ti o si jo pe awon 13 ti segbe, iyen gege bi iwadii odun 2018 kan se to pinpin. Síbẹ̀síbẹ̀, ó tó ọmọdébìnrin 112 tí ó di àwátì bí abẹ́rẹ́ tí ó sì jọ pé àwọn 13 tí ṣègbé, ìyẹn gẹ́gẹ́ bí ìwádìí ọdún 2018 kan ṣe tọ pinpin. Ezekwesili ati ajosepo awon eniyan kan ni o da igbese ija fun eto awon omodebinrin #BBOG ti o ko awon eniyan jo lagbaaye fun idasile awon omodebinrin Chibok. Ezekwesili àti àjọṣepọ̀ àwọn ènìyàn kan ni ó dá ìgbésẹ̀ ìjà fún ẹ̀tọ́ àwọn ọmọdébìnrin #BBOG tí ó kó àwọn ènìyàn jọ lágbàáyé fún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọdébìnrin Chibok. Nigba ti o se, igbese naa yirapada di igi araba ti enikan ko lee si nidii ti o fi ara da igbagede eto ilu Naijiria t'o roro. Nígbà tí ó ṣe, ìgbésẹ̀ náà yírapadà di igi àràbà tí ẹnìkan kò leè ṣí nídìí tí ó fi ara da igbàgede ètò ìlú Nàìjíríà t'ó rorò. Amo sa o, aseyori akitiyan yii ko seyin-in inawonara Ezekwesili. Àmọ́ ṣá o, àṣeyọrí akitiyan yìí kò ṣẹ̀yìn-in ìnáwónára Ezekwesili. Ni were ki eto idibo aare odun 2015 o wa saye ni isele ijinigbe awon omodebinrin Chibok se, ti eyi si mu ki awon kan o maa fi oju igbeleyin egbe oloselu kan wo igbawi ti Ezekwesili n ba ka lori ayelujara. Ní wéré kí ètò ìdìbò ààrẹ ọdún 2015 ó wá sáyé ni ìṣẹ̀lẹ̀ ìjínigbé àwọn ọmọdébìnrin Chibok ṣẹ̀, tí èyí sì mú kí àwọn kan ó máa fi ojú ìgbèlẹ́yìn ẹgbẹ́ olóṣèlú kan wo ìgbàwí tí Ezekwesili ń bá ká lórí ayélujára. Bi won ti fi oju otito inu re gbole ni won fa gbogbo aso iyii re ya perepere. Bí wọ́n ti fi ojú òtítọ́ inú rẹ̀ gbolẹ̀ ni wọ́n fa gbogbo aṣọ iyìi rẹ̀ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Awon miiran so wipe gbogbo kukugege akitiyan #BBOG re ko ju ki o ba lenu ninu iselu lo. Àwọn mìíràn sọ wípé gbogbo kùkùgẹ̀gẹ̀ akitiyan #BBOG rẹ kò ju kí ó ba lẹ́nu nínú ìṣèlú lọ. "Reno Omokri, oluranlowo aare ana, fi esun kan Ezekwesili wi pe egbe oloselu APC ni o n lo o fi ba ijoba ti o wa lori apere je ati lati ""yepere"" ijoba Aare Jonathan, nipa eyi naa ni o fi lana fun APC lati ""gba opa ase""." "Reno Omokri, olùrànlọ́wọ́ ààrẹ àná, fi ẹ̀sùn kan Ezekwesili wí pé ẹgbẹ́ olóṣèlú APC ni ó ń lò ó fi ba ìjọba tí ó wà lórí àpèré jẹ́ àti láti ""yẹpẹrẹ"" ìjọba Ààrẹ Jonathan, nípa èyí náà ni ó fi lànà fún APC láti ""gba ọ̀pá àṣẹ""." "Ni odun-un 2014 awon alatileyin Aare ana aare Jonathan ati egbe oloselu Peoples’ Democratic Party (PDP) fi ""awon okan-o-jokan iro "" lede ni ori ero-ayelujara lati tako Ezekwesili. Dokita naa so ninu atejade aworan-olohun Twitter kan ti ojo 14, osu Igbe ni isaami odun mefa ti awon omodebinrin naa ti di awati wi pe: “ki a ma puro won tabuku mi, won si se keeta." "Ní ọdún-un 2014 àwọn alátìlẹ́yìn Ààrẹ àná ààrẹ Jonathan àti ẹgbẹ́ olóṣèlú Peoples’ Democratic Party (PDP) fi ""àwọn ọ̀kan-ò-jọ̀kan irọ́ "" léde ní orí ẹ̀rọ-ayélujára láti tako Ezekwesili. Dókítà náà sọ nínú àtẹ̀jáde àwòrán-olóhùn Twitter kan ti ọjọ́ 14, oṣù Igbe ní ìsààmì ọdún mẹ́fà tí àwọn ọmọdébìnrin náà ti di àwátì wí pé: “kí á má purọ́ wọ́n tàbùkù mi, wọ́n sì ṣe kèéta." Awon elenu eke so wi pe igbonara ai ri ipo ninu ijoba Jonathan lo n mu Ezekwesili tepele mo igbaruku ti oran awon omo ti ajinigbe ji gbe. Àwọn ẹlẹ́nu èké sọ wí pé ìgbónára àì rí ipò nínú ìjọba Jonathan ló ń mú Ezekwesili tẹpẹlẹ mọ́ ìgbárùkù ti ọ̀ràn àwọn ọmọ tí ajínigbé jí gbé. "Bi o ti se so, awon ti o ko enu egbin si i lori ayelukara-bi-ajere lero ""wi pe tori ki won ba fi oun j'oye minisita ni oun o fi menu kuro loran awon omodebinrin Chibok""." "Bí ó ti ṣe sọ, àwọn tí ó kọ ẹnu ẹ̀gbin sí i lórí ayélukára-bí-ajere lérò ""wí pé torí kí wọ́n ba fi òun j'òye mínísítà ni òun ò fi mẹ́nu kúrò lọ́ràn àwọn ọmọdébìnrin Chibok""." Bawo ni yo se je bee leyin ti mo ko ipo minisita ni odun meta seyin ki awon omodebinrin Chibok o to di igbesin? Báwo ni yó ṣe jẹ́ bẹ́ẹ̀ lẹ́yìn tí mo kọ ipò mínísítà ní ọdún mẹ́ta sẹ́yìn kí àwọn ọmọdébìnrin Chibok ó tó di ìgbẹ̀sìn? Ezekwesili wi ninu aworan-olohun Twitter naa. Ezekwesili wí nínú àwòrán-olóhùn Twitter náà. O di okan ninu awon ondije si ipo aare odun-un 2018, sugbon o ju owo sile nigba o ya. Ó di ọ̀kan nínú àwọn òǹdíje sí ipò ààrẹ ọdún-un 2018, ṣùgbọ́n ó ju ọwọ́ sílẹ̀ nígbà ó yá. "Ni ori Twitter, Ezekwesili mu ibanuje re wa si iranti: ""Edun okan ni fun mi pe awon omode ti a ran nile iwe di pipa bi eran de ibi wi pe awon obi won ko le da awon omo won mo ""." "Ní orí Twitter, Ezekwesili mú ìbànújẹ́ rẹ̀ wá sí ìrántí: ""Ẹ̀dùn ọkàn ni fún mi pé àwọn ọmọdé tí a rán nílé ìwé di pípa bí ẹran dé ibi wí pé àwọn òbí wọn kò lè dá àwọn ọmọ wọn mọ̀ ""." Amo isaata ti oloselu nipa igbese ipolongo #BBOG ti gbe ibinu toun t'ibanuje re mi. Àmọ́ ìṣààta ti olóṣèlú nípa ìgbésẹ̀ ìpolongo #BBOG ti gbé ìbínú tòun t'ìbánújẹ́ rẹ̀ mì. #ArewaMeToo ati NorthNormal #ArewaMeToo àti NorthNormal Ni ojo 3, osu Erele odun-un 2019, odobinrin kan ti oruko re n je Khadijah Adamua gbojugboya lati tuwiiti nipa ilokulo ajemara ti orekunrin re igba kan lo oun. Ní ọjọ́ 3, oṣù Èrèlé ọdún-un 2019, ọ̀dọ́bìnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Khadijah Adamua gbójúgbóyà láti túwíìtì nípa ìlòkulò ajẹmára tí ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ ìgbà kan lo òun. Adamua, eni ti o n gbe ni ipinle Kano ti i se ariwa-ila-oorun orile ede Naijiria, ti saaju ko buloogu nipa iriri re ti o banileru. Adamua, ẹni tí ó ń gbé ní ìpínlẹ̀ Kano tí í ṣe àríwá-ìlà-oòrùn orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ti ṣáájú kọ búlọ́ọ̀gù nípa ìrírí rẹ̀ tí ó banilẹ́rù. Omo Naijiria rere Fakhriyyah Hashim tuwiiti atileyin re fun Adamua pelu lilo ami #ArewaMeToo: Ọmọ Nàìjíríà rere Fakhriyyah Hashim túwíìtì àtìlẹ́yìn rẹ̀ fún Adamua pẹ̀lú lílo àmì #ArewaMeToo: #ArewaMeToo di eda igbese Emi Naa agbaye #MeToo ni ariwa Naijiria. (Arewa ni ede-iperi fun “Ariwa” ni ede Hausa) — ti o tan iji asogba oro lori ifipabanilopo ati iru awon iwa-ipa si awon obinrin ni ori ero ayelukara-won-bi-ajere. #ArewaMeToo di ẹ̀dà ìgbésẹ̀ Èmi Náà àgbáyé #MeToo ní àríwá Nàìjíríà. (Árẹ̀wá ni èdè-ìperí fún “Àríwá” ní èdè Haúsá) — tí ó tan ìjì àsọgbà ọ̀rọ̀ lórí ìfipábánilòpọ̀ àti irú àwọn ìwà-ipá sí àwọn obìnrin ní orí ẹ̀rọ ayélukára-wọn-bí-ajere. Iwa-ipa si obinrin wopo jakejado orile-edee Naijiria. Sibe, Relief Web so wi pe ni aarin osu Belu odun-un 2014 ati osu Seere odun un 2015, ariwa-ila-oorun Naijiria, paapaa ju lo Ipinle Borno, ni akosile iwa-ipa si obinrin ti po jojo. Ìwà-ipá sí obìnrin wọ́pọ̀ jákèjádò orílẹ̀-èdèe Nàìjíríà. Síbẹ̀, Relief Web sọ wí pé ní àárín oṣù Belu ọdún-un 2014 àti oṣù Ṣẹẹrẹ ọdún un 2015, àríwá-ìlà-oòrùn Nàìjíríà, pàápàá jù lọ Ìpínlẹ̀ Borno, ní àkọsílẹ̀ ìwà-ipá sí obìnrin ti pọ̀ jọjọ. Ni agbegbe ariwa ti awon Musulumi po si ju lo, asogba nipa ori oro eewo wonyi soro, ti o maa papa so awon ti o n jiya ipalara si ipa keke. Ní agbègbè àríwá tí àwọn Mùsùlùmí pọ̀ sí jù lọ, àsọgbà nípa orí ọ̀rọ̀ èèwọ̀ wọ̀nyí ṣòro, tí ó máa pàpà sọ àwọn tí ó ń jìyà ìpalára sì ìpa kẹ́kẹ́. Ibinu #ArewaMeToo ni ori ero-ayelujara se atona iyide ifehonuhan ita gbangba NorthNormal ni Bauchi, Kano, ati Niger. Ìbínú #ArewaMeToo ní orí ẹ̀rọ-ayélujára ṣe àtọ́nà ìyíde ìfẹ̀hònúhàn ìta gbangba NorthNormal ní Bauchi, Kano, àti Niger. Iyide olojo meeedogun ti NorthNormal wa saye ninu osu Belu odun t'o koja ni awon ipinle mejo ni oke Oya ati ni Abuja. Ìyíde ọlọ́jọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ti NorthNormal wá sáyé nínú oṣù Belu ọdún t'ó kọjá ní àwọn ìpínlẹ̀ mẹ́jọ ní òkè Ọya àti ní Abuja. "Won ri ipa rere latari iyide ti awon asofin ""si ri idi ti o fi ye ki awon gbo si awon odo ibile "" lenu tori won n “le iwaju ninu ija fun VAPP,” Hashim salaye oro." "Wọ́n rí ipa rere látàrí ìyíde tí àwọn aṣòfin ""sì rí ìdí tí ó fi yẹ kí àwọn gbọ́ sí àwọn ọ̀dọ̀ ìbílẹ̀ "" lẹ́nu torí wọ́n ń “lé iwájú nínú ìjà fún VAPP,” Hashim ṣàlàyé ọ̀rọ̀." "Hashim tesiwaju wi pe,” sibe, ni Ipinle Sokoto, ijoba n ko awon ti o n yide NorthNormal""." "Hashim tẹ̀síwájú wí pé,” síbẹ̀, ní Ìpínlẹ̀ Sokoto, ìjọba ń kó àwọn tí ó ń yíde NorthNormal""." Awon olopaa se okan lara awon olori ibile ti i se alagbeekale iyide naa sibasibo. Àwọn ọlọ́pàá ṣe ọ̀kan lára àwọn olórí ìbílẹ̀ tí í ṣe alágbèékalẹ̀ ìyíde náà ṣìbáṣìbo. Leyin wa, oba Sokoto, ti i se olori awon Musulumi orile ede Naijiria fagile iwode. Lẹ́yìn wá, ọba Sokoto, tí í ṣe olórí àwọn Mùsùlùmí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà fagilé ìwọ́de. "Gege bi Hashim ti se wi, NorthNormal suyo lati ara ami #ArewaMeToo, ti o si ni eta meji: igbawi fun ""isamulo Ifofinde Iwa-ipa si awon Eniyan (VAPP)"", ati ilewaju ninu itakuroso ""oniruuru iwa-ipa si obinrin ati asa ifipabanilopo jakejado ariwa Naijiria""." "Gẹ́gẹ́ bí Hashim ti ṣe wí, NorthNormal súyọ láti ara àmì #ArewaMeToo, tí ó sì ní èta méjì: ìgbàwí fún ""ìṣàmúlò Ìfòfinde Ìwà-ipá sí àwọn Ènìyàn (VAPP)"", àti ìléwájú nínú ìtàkùrọ̀sọ ""onírúurú ìwà-ipá sí obìnrin àti àṣà ìfipábánilòpọ̀ jákèjádò àríwá Nàìjíríà""." Aba Ofin Iwa-ipa si Awon Eniyan (Ifofinde) odun-un 2015 di titowobo lojo 23, osu Ebibi, odun-un 2015. Àbà Òfin Ìwà-ipá sí Àwọn Ènìyàn (Ìfòfindè) ọdún-un 2015 di títọwọ́bọ̀ lọ́jọ́ 23, oṣù Èbìbí, ọdún-un 2015. Labe Aba VAPP — ilosiwaju ofin ijiya ese orile ede Naijiria — aba iwa-ipa si awon obinrin je ese labe ofin. Lábẹ́ Àbá VAPP — ìlọsíwájú òfin ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà — àbá ìwà-ipá sí àwọn obìnrin jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ lábẹ́ òfin. Lara re ni ifipabanilopo, nina aya, ifipale aya jade nile, ifipa so obinrin di adabukata gbo tabi ijiya ti oro-aje, asa opo ti o n fa ipalara, didabe fun obinrin tabi gige ida, ati/tabi ikosile omo. Lára rẹ̀ ni ìfipábánilòpọ̀, nína aya, ìfipálé aya jáde nílé, ìfipá sọ obìnrin di adábùkátà gbọ́ tàbí ìjìyà ti ọrọ̀-ajé, àṣà opó tí ó ń fa ìpalára, dídábẹ́ fún obìnrin tàbí gígé ida, àti/tàbí ìkọ̀sílẹ̀ ọmọ. Ni Naijiria, ewon gbere ni ijiya ifipabanilopo. Omode le fi ara gba ewon odun 14. Ní Nàìjíríà, ẹ̀wọ̀n gbére ni ìjìyà ìfipábánilòpọ̀. Ọmọdé lè fi ara gbá ẹ̀wọ̀n ọdún 14. Bi o ba je oran ifipabanilopo eni pupo, ewon odun 20 ni awon elese yoo fi gbara lai san owo itanran. Bí ó bá jẹ́ ọ̀ràn ìfipábánilòpọ̀ ẹni púpọ̀, ẹ̀wọ̀n ọdún 20 ni àwọn ẹlẹ́sẹ̀ yóò fi gbára láì san owó ìtanràn. Sibe, Abala 47 ti Aba ofin VAPP fi lele wi pe Abuja, olu ilu orile ede Naijiria nikan ni ofin yii ti f'ese rinle. NorthNormal ati awon ileese miiran ti n polongo ki gbogbo igbimo asofin ipinle 36 o so aba yii d'ofin. Síbẹ̀, Abala 47 ti Àbá òfin VAPP fi lélẹ̀ wí pé Abuja, olú ìlú orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nìkan ni òfin yìí ti f'ẹsẹ̀ rinlẹ̀. NorthNormal àti àwọn iléeṣẹ́ mìíràn ti ń polongo kí gbogbo ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ 36 ó sọ àbá yìí d'òfin. Atako awon alagbawi Àtakò àwọn alágbàwí Odun kan leyin ti #ArewaMeToo gba igboro, Hashim so fun Ohun Agbaye wi pe adi igbawi won ti o tu “ibaje awujo jade,” o si tun ni arapa tire. Ọdún kan lẹ́yìn tí #ArewaMeToo gba ìgboro, Hashim sọ fún Ohùn Àgbáyé wí pé adi ìgbàwí wọn tí ó tú “ìbàjẹ́ àwùjọ jáde,” ó sì tún ní arapa tirẹ̀. "Hashim ni iriri iyolenu lori ayelujara nigba ti egbe re koju ""enikan ti o maa ba awon omode lo ni sisentele kiri adugbo"" eni ti o n sise ni ileese isuna-owo gege bi igbawi ori ayelujara won." "Hashim ní ìrírí ìyọlẹ́nu lórí ayélujára nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kojú ""ẹnìkan tí ó máa bá àwọn ọmọdé lò ní ṣísẹ̀ntẹ̀lé kiri àdúgbò"" ẹni tí ó ń ṣiṣẹ́ ní iléeṣẹ́ ìṣúná-owó gẹ́gẹ́ bí ìgbàwí orí ayélujára wọn." O so fun Ohun Agbaye: Ó sọ fún Ohùn Àgbáyé: A se ifilole ipolongo tako re [abomode sun], ki o ba gba iwe iyoninise lati owo minisita; awon kan ko fe bee tori idi eyi ni won se gbe igbese ipolongo iyolenu ori ayelujara lati so #ArewaMeToo di eyi ti o lodi si ofin. A ṣe ìfilọ́lẹ̀ ìpolongo tako rẹ̀ [abọ́mọdé sùn], kí ó bá gba ìwé ìyọniníṣẹ́ láti ọwọ́ mínísítà; àwọn kan kò fẹ́ bẹ́ẹ̀ torí ìdí èyí ni wọ́n ṣe gbé ìgbésẹ̀ ìpolongo ìyọlẹ́nu orí ayélujára láti sọ #ArewaMeToo di èyí tí ó lòdì sí òfin. Gege bi Hashim se so, awon ayonilenu gbero lati so ArewaMeToo di ohun ti o tase agere si ofin nipa siso ArewaMeToo po mo LGBTQ [obinrin-to-n-fe-obinrin, okunrin-ti-o-n-fe-okunrin, awon abo ati ako ti o yira pada di ako tabi abo ati awon eniyan ti o se ajeji ti ko si ni ibamu] ati ete won sise bi iyolenu ori ayelujara se n lekun si i. Gẹ́gẹ́ bí Hashim ṣe sọ, àwọn ayọnilẹ́nu gbèrò láti sọ ArewaMeToo di ohun tí ó tasẹ̀ àgẹ̀rẹ̀ sí òfin nípa síso ArewaMeToo pọ̀ mọ́ LGBTQ [obìnrin-tó-ń-fẹ́-obìnrin, ọkùnrin-tí-ó-ń-fẹ́-ọkùnrin, àwọn abo àti akọ tí ó yíra padà di akọ tàbí abo àti àwọn ènìyàn tí ó ṣe àjèjì tí kò sí ní ìbámu] àti ète wọ́n ṣiṣẹ́ bí ìyọlẹ́nu orí ayélujára ṣe ń lékún sí i. Ni orile ede Naijiria, igbeyawo laaarin okunrin ati okunrin lodi sofin bee naa ni abe ofin Seria ati ofin ifiyaje elese, ibalopo iho idi ati ibalopo laaarin obinrin ati obinrin ni ijiya ni awon ipinle kan. Ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ìgbéyàwó láàárín ọkùnrin àti ọkùnrin lòdì sófin bẹ́ẹ̀ náà ní abẹ́ òfin Sẹ́ríà àti òfin ìfìyàjẹ ẹlẹ́sẹ̀, ìbálòpọ̀ ihò ìdí àti ìbálòpọ̀ láàárín obìnrin àti obìnrin ní ìjìyà ní àwọn ìpínlẹ̀ kan. Nipase dida igbese ipolongo Hashim papo mo eto LGBTQ, awon eniyan ni ori ero-ayelujara lo ipolongo won po won si pe #ArewaToo ati NorthNormal ni ohun ti ko to. Nípasẹ̀ dída ìgbésẹ̀ ìpolongo Hashim papọ̀ mọ́ ẹ̀tọ́ LGBTQ, àwọn ènìyàn ní orí ẹ̀rọ-ayélujára lọ́ ìpolongo wọn po wọ́n sì pe #ArewaToo àti NorthNormal ní ohun tí kò tọ́. Bi-o-ti-wu-ki-o-ri, Ohun Agbaye ko ri aye si awon tuwiiti ti o so igbese ipolongo Hashim ni ija fun eto LGBTQ. Bí-ó-ti-wù-kí-ó-rí, Ohùn Àgbáyé kò rí àyè sí àwọn túwíìtì tí ó sọ ìgbésẹ̀ ìpolongo Hashim ní ìjà fún ẹ̀tọ́ LGBTQ. Sibe, Hashim se atejade awon oro ireti si ori Twitter: Síbẹ̀, Hashim ṣe àtẹ̀jáde àwọn ọ̀rọ̀ ìrètí sí orí Twitter: Fakhriyyah Hashim, okan lara awon oludasile #ArewaToo ati NorthNormal (a gba ase lati lo aworan re. Fakhriyyah Hashim, ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ #ArewaToo àti NorthNormal (a gba àṣẹ láti lo àwòrán rẹ̀. O so wi pe gbogbo iriri yii ran oun lowo lati “ni ifarada ti o po”: Ó sọ wí pé gbogbo ìrírí yìí ran òun lọ́wọ́ láti “ní ìfarada tí ó pọ̀”: Iriri mi nipa igbohunsoke lori oro oselu ni ori Twitter fun isejoba ti o dara, ti ko mi ni ifarada, amo iyen ko mu mi gbaradi fun okan-o-jokan itako ti a foju ri latari ipolongo ArewaMeToo ati NorthNormal. Ìrírí mi nípa ìgbóhùnsókè lórí ọ̀rọ̀ òṣèlú ní orí Twitter fún ìṣèjọba tí ó dára, ti kọ́ mi ní ìfaradà, àmọ́ ìyẹn kò mú mi gbaradì fún ọ̀kan-ò-jọ̀kan ìtakò tí a fojú rí látàrí ìpolongo ArewaMeToo àti NorthNormal. Amope mo fi gbogbo re se osun mo fi para n o si je ki o fa mi seyin, mo bere si ni i ni irewesiokan nipa isejoba Ariwa orile ede Naijiria ati bi won se fi owo mu iwa ifipabanilo... Àmọ́pé mo fi gbogbo rẹ̀ ṣe osùn mo fi para n ò sì jẹ́ kí ó fà mí sẹ́yìn, mo bẹ̀rẹ̀ sí ní í ní ìrẹ̀wẹ̀síọkàn nípa ìṣèjọba Àríwá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àti bí wọ́n ṣe fi ọwọ́ mú ìwà ìfipábánilò... Leyin ikolu kookan, a maa n ni okun ati agbara lati tesiwaju nitori itako mu wa ri bi asa idake roro ti se rinle to ni awujo ati pe bi a ba fi aye gba ipanumo, a je wi pe oko iparun ni a n fi ori le. Lẹ́yìn ìkọlù kọ̀ọ̀kan, a máa ń ní okun àti agbára láti tẹ̀síwájú nítorí ìtakò mú wa rí bí àṣà ìdákẹ́ rọrọ ti ṣe rinlẹ̀ tó ní àwùjọ àti pé bí a bá fi àyè gba ìpanumọ́, a jẹ́ wí pé oko ìparun ni à ń fi orí lé. O seni laaanu, Hashim ati Ezekwesili si n janpata pelu iya “aisi aanu omolakeji” ti o diro mo oran iwa ijiya awon obinrin lori ayelujara ati loju aye tooto. Ó ṣeni láàánú, Hashim àti Ezekwesili ṣì ń janpata pẹ̀lú ìyà “àìsí àánú ọmọlàkejì” tí ó dìrọ̀ mọ́ ọ̀ràn ìwà ìjìyà àwọn obìnrin lórí ayélujára àti lójú ayé tòótọ́. "Ni ti Hashim, ""imoomo saata igbese ti o n gbero lati fi ohun fun awon ti o n jiya ifarapa"" nira lati gba mu." "Ní ti Hashim, ""ìmọ̀ọ́mọ̀ ṣààta ìgbésẹ̀ tí ó ń gbèrò láti fi ohùn fún àwọn tí ó ń jìyà ìfarapa"" nira láti gbá mú." "Aroko yii je okan lara akanse ise, ""Orisun idanimo: ofin gbagede ori ero-ayelujara bi ajere ti n gbegi dina idagbasoke oro siso ni Ile Adulawo""." "Àròkọ yìí jẹ́ ọ̀kan lára àkànṣe iṣẹ́, ""Orísun ìdánimọ̀: òfin gbàgede orí ẹ̀rọ-ayélujára bí ajere tí ń gbégi dínà ìdàgbàsókè ọ̀rọ̀ sísọ ní Ilẹ̀ Adúláwọ̀""." Atejade yii se ibeere ipa idanimo oro ikoriira tegbintegbin tabi iyasotooto ti o da firigbagboo lori ede tabi agbegbe ile aye, asiwifun ati iyolenu (paapaa ju lo iyolenu awon ajafetoo omoniyan ati akoroyin l'obinrin) lori ero ayelujara bi ajere ti o wopo ni orile ede Ile Adulawo meje: Algeria, Cameroon, Ethiopia, Nigeria, Sudan, Tunisia ati Uganda. Àtẹ̀jáde yìí ṣe ìbéèrè ipa ìdánimọ̀ ọ̀rọ̀ ìkórìíra tẹ̀gbintẹ̀gbin tàbí ìyàsọ́tọ̀ọ̀tọ̀ tí ó dá fìrìgbagbòó lórí èdè tàbí agbègbè ilẹ̀ ayé, àṣìwífún àti ìyọlẹ́nu (pàápàá jù lọ ìyọlẹ́nu àwọn ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọnìyàn àti akọ̀ròyìn l'óbìnrin) lórí ẹ̀rọ ayélujára bí ajere tí ó wọ́pọ̀ ní orílẹ̀ èdè Ilẹ̀ Adúláwọ̀ méje: Algeria, Cameroon, Ethiopia, Nigeria, Sudan, Tunisia àti Uganda. Africa Digital Rights Fund ti Collaboration on International ICT Policy for East and Southern Africa (CIPESA) ni o kowo fun a kanse ise yii. Africa Digital Rights Fund ti Collaboration on International ICT Policy for East and Southern Africa (CIPESA) ni ó kówó fún à kànṣe iṣẹ́ yìí. Ni awon ilu ti o wa labe isakoso Assad ni ile Syria, awon alakooso so bayii pe ‘ko si isele aarun korona kankan’ Ní àwọn ìlú tí ó wà lábẹ́ ìsàkóso Assad ní ilẹ̀ Syria, àwọn alákòóso sọ báyìí pé ‘kò sí ìṣẹ̀lẹ̀ ààrùn kòrónà kankan’ Leyin odun mesan-an ogun abele to gbona girigiri, eto ilera ni orile-ede Syria o se bee gbopon mo. Lẹ́yìn ọdún mẹ́sàn-án ogun abẹ́lẹ́ tó gbóná girigiri, ètò ìlera ní orílẹ̀-èdè Syria ò ṣe bẹ́ẹ̀ gbópọn mọ́. Ni awon ilu ti o wa labe isakoso Aare Bashar al-Assad, awon Alase won ti tako isele aarun COVID-19. Ní àwọn ìlú tí ó wà lábẹ́ ìsàkóso Ààrẹ Bashar al-Assad, àwọn Aláṣẹ wọn ti tako ìṣẹ̀lẹ̀ ààrun COVID-19. Gege bi Fafiti John Hopkins so, Orile-ede ohun ti sawari isele Ojilenirinwo-dinkan pelu iku eniyan mokanlelogun titi di ojo keeedogun osu Agemo. Gẹ́gẹ́ bí Fáfitì John Hopkins ̣ sọ, Orílẹ̀-èdè ọ̀hún ti sàwárí ìsẹ̀lẹ̀ Òjìlénírinwó-dínkan pẹ̀lú ikú ènìyàn mọ́kànlélógún títí di ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún osù Agẹmọ. Sugbon awon iroyin ti o wa nile bayii ti se afihan bi ile naa se taku wonle ti won si n se idaniloju pe aarun COVID-19 wa loooto. Ṣùgbọ́n àwọn ìròyìn tí ó wà nílẹ̀ báyìí tí ṣe àfihàn bí ilẹ̀ náà ṣe takú wọnle tí wọ́n sì ń ṣẹ́ ìdánilójú pé ààrùn COVID-19 wà lóòótọ́. Walid Abdullah omo odun metalelogun, so o di mimo pe ile yii tile se e debi pe won n daba gbigba emi awon alaaare ti won ba funra si pe won ni COVID-19. Walid Abdullah ọmọ ọdún mẹ́tàlélógún, sọ ọ́ di mímọ̀ pé ìlẹ̀ yìí tilè ṣe é débi pé wọ́n ń dába gbígba ẹ̀mí àwọn aláàárẹ̀ tí wọ́n bá funra sí pé wọ́n ní COVID-19. Ohun Agbaye n lo orukokoruko lati daabo bo. Ohùn Àgbáyé ń lo orúkọkórúkọ láti dààbò bó. Ninu itakuroso pelu Ohun Agbaye lori ago, Abdullah se e ni alaye pe ni ojo ketala osu ebibi, oun pe Ile iwosan Apapo ti Daraa ni iha Guusu ile Syria lati fi isele aarun korona kan to won leti. Nínú ìtàkùrọsọ pẹ̀lú Ohùn Àgbáyé lórí ago, Abdullah ṣe é ní àlàyé pé ní ọjọ́ kẹtàlá ọsù èbìbí, òun pé Ilé ìwòsàn Àpapọ̀ ti Daraa ní ìha Gúúsù ilẹ̀ Syria láti fi ìṣẹ̀lẹ̀ ààrun kòrónà kan tó wọn létí. "Gege bi Abdullah se so, nigba ti o beere igbese ti o ye ni gbigbe, osise ijoba ti o gbe ipe naa so pe "" Yinbon pa a, a ko ni iwosan fun""" "Gẹ́gẹ́ bí Abdullah ṣe sọ, nígbà tí ó bèèrè ìgbésè tí ó yẹ ní gbígbé, òṣìṣẹ́ ìjọba tí ó gbé ìpè náà sọ pé "" Yìnbọn pà á, a kò ní ìwòsàn fún""" O yara fi opin si ipe naa. Ó yára fi òpin sí ìpè náà. Daju, ko si oro ninu yiyin ibon pa eni ti a fura si pe o ni arun COVID-19. Dájú, kò sí ọ̀rọ̀ nínú yíyin ìbọn pa ẹni tí a fura sí pé ó ní àrun COVID-19. "Abdullah so fun Ohun Agbaye ""Iku nipase COVID-19 san ju dida ese wo ile iwosan ijoba lo""" "Abdullah sọ fún Ohùn Àgbáyé ""Ikú nípasẹ̀ COVID-19 sàn ju dídá ẹsẹ̀ wọ ilé ìwòsàn ìjọba lọ""" Eri ibanilokanje eleyii tun kin in leyin lati awon orisun miiran. Èrí ìbanilọ́kanjẹ́ eléyìí tún kín in lẹ́yìn láti àwọn orísun mìíràn. "Atejade ojo kewaa, osu Erena kan ti The Voice of the Capital, Iwe iroyin Olominira kan ni ile Syria so di mimo, pe awon eleto ilera lati Ile-ise Eto Ilera ile Syria so pe ""Ise Imo-on-mosekupani n waye ni ile iwosan ijoba Al-Mujtahid ni olu ilu ile naa, Damascus, fun awon ti won ni igbagbo pe won ni arun ohun ni tooto, nipa fifun won ni apoju oogun ti o maa n rani niy""e." "Àtẹ̀jáde ọjọ́ kẹwàá, oṣù Ẹrénà kan ti The Voice of the Capital, Iwé ìròyìn Olómìnira kan ní ilẹ̀ Syria sọ di mímọ̀, pé àwọn elétò ìlera láti Ilé-iṣẹ́ Ètò Ìlera ilẹ̀ Syria sọ pé ""Iṣẹ́ Ìmọ̀-ọ́n-mọ̀ṣekúpani ń wáyé ní ilé ìwòsàn ìjọba Al-Mujtahid ní olú ìlú ilẹ̀ náà, Damascus, fún àwọn tí wọ́n ní ìgbàgbọ́ pé wọ́n ní àrùn ọ̀hún ní tòótọ́, nípa fífún wọn ní àpọ̀jù oògùn tí ó máa ń rani níy""è." Eyi pelu fi ara han ni ori ikanni alatagba: Èyí pẹ̀lú fi ara hàn ní orí ìkànnì alátagbà: Elomiiran lati ile iwosan Mouwasat ni Damascus ni oro re tun je didi mo owo ninu atejade kan naa ti o so pe: Ẹlòmìíràn láti ilé ìwòsàn Mouwasat ni Damascus ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ tún jẹ́ dídì mọ́ ọwọ́ nínú àtẹ̀jáde kan náà tí ó sọ pé: """Ise Imo-on-mosekupani n waye ni ibi kolofin patapata, awon dokita ti won se ise itopinpin arun ohun ni won si n se e""." """Iṣẹ́ Ìmọ̀-ọ́n-mọ̀ṣekúpani ń wáyé ní ibi kọ́lọ́fín pátápátá, àwọn dókìtà tí wọ́n ṣe iṣẹ́ ìtọpinpin àrùn ọ̀hún ni wọ́n sì ń ṣe é""." Igbese saa isejoba Assad si idekun arun COVID-19 yii buru jai, o fi ara jo ete ti won lo nigba Ogun abele Assad ti o gba emi eniyan ti o le die ni milionu, ti Egberun lona ogorun-un ti o wa latimole pare sibe, ti milionu marun-un abo-o-le si di ogunlende kaakiri awon orile-ede agbaye. Ìgbésẹ̀ sáà ìṣèjọba Assad sí ìdẹ́kun àrùn COVID-19 yìí burú jáì, ó fi ara jọ ète tí wọ́n lò nígbà Ogun abẹ́lé Assad tí ó gba èmí ènìyàn tí ó lé díẹ̀ ní mílíọ̀nù, tí Ẹgbẹ̀rún lónà ọgọ́rùn-ún tí ó wà látìmọlé parẹ́ síbẹ̀, tí mílíọ́nù márùn-ún àbọ̀-ó-lẹ́ sì di ogunléndé káàkiri àwọn orílẹ̀-èdè àgbáyé. Ibesile Ajakale Arun ati Itesiwaju Isejoba Ìbẹ́sílẹ̀ Àjàkálẹ̀ Àrùn àti Ìtèsíwájú Ìsèjọba Saa isejoba Assad yii ti so opolopo awon ilu ti o yi i ka sinu idaamu ti o fi mo orile-ede Iran naa, pelu bi o se je pe ile Syria ni opolopo awon ilu ti o yi i ka fi n mi. Sáà ìṣèjọba Assad yìí ti sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tí ó yí i ká sínú ìdààmú tí ó fi mọ́ orílẹ̀-èdè Iran náà, pẹ̀lú bí ó ṣe jẹ́ pé ilẹ̀ Syria ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú tí ó yí i ká fi ń mí. Ni osu Erele, Orile-ede Iran di okan ninu awon orile-ede ti Covid-19 ti sose julo, ibi ti aarun naa gba wo ile won ni o seese ki o je Lebanon, Iraq ati Syria, nibi ti ifarayira ti sele nipase ajosepo awon Ologun. Ní osù Èrèlé, Orílẹ̀-èdè Iran di ọ̀kan nínú àwọn orílè-èdè tí Covid-19 ti ṣọṣẹ́ jùlo, ìbi tí ààrùn náà gbà wọ ilẹ̀ wọn ni ó ṣeéṣe kí ó jẹ́ Lebanon, Iraq àti Syria, níbi tí ìfarayíra ti ṣelẹ̀ nípasẹ̀ àjọṣepọ̀ àwọn Ológun. Ni afikun, awon Arinrinajo-esin ati awon Arinrinajo-igbafe lati Iran naa tesiwaju lati maa se abewo si awon ojubo ni Damascus titi di ose kini osu erena (march) gege bi Zaki Mechy ti o je ara awon Onkowe March Study ti London School of Economics and Political Science (LSE) se so. Ní àfikún, àwọn Arìnrìnàjò-ẹ̀sin àti àwọn Arìnrìnàjò-ìgbafẹ́ láti Iran náà tẹ̀síwájú láti máa ṣe àbẹ̀wọ̀ sí àwọn ojúbọ ní Damascus títí di ọ̀ṣẹ̀ kíní osù ẹrénà (march) gẹ́gẹ́ bí Zaki Mechy tí ó jẹ́ ara àwọn Òǹkòwé March Study ti London School of Economics and Political Science (LSE) ṣe sọ. Sibe, Isejoba Assad n tepele mo siso ofege iroyin ati iro lorisirisi bee ni o tun se adinku iye awon eniyan ti won ti ni COVID-19. Síbẹ̀, Ìṣèjọba Assad ń tẹpẹlẹ mọ́ sísọ òfegè ìròyìn àti irọ́ lórìṣirísi bẹ́ẹ̀ ni ó tún ṣe àdínkù iye àwọn ènìyàn tí wọ́n ti ní COVID-19. Ni iforowanilenuwo pelu eka iroyin ijoba ile Syria ni ojo ketala Osu Erena, Minisita eto ilera ile naa Nizar Al-Yaziji kojale lori pe ko si isele COVID-19 ni ile Syria, o so pe: Ní ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwọ̀ pẹ̀lú ẹ̀ka ìròyìn ìjọba ilẹ̀ Syria ní ọjọ́ kẹtàlá Osù Ẹrẹ́nà, Mínísítà ètò ilera ilẹ̀ náà Nizar Al-Yaziji kọ̀jálẹ̀ lórí pé kò sí ìṣẹ̀lẹ̀ COVID-19 ní ilẹ̀ Syria, ó sọ pé: """A dupe lowo Olorun pe awon Eka Ologun ti fo ile Syria mo kuro lowo arunkarun:”" """A dúpé̩ ló̩wó Ọló̩run pé àwọn È̩ka Ológun ti fọ ilè̩ Syria mó kúrò ló̩wó̩ àrùnkárùn:”" Minisita eto ilera ile Syria ko tile kede isele aarun COVID-19 akoko ile naa titi di ojo kejilelogun Osu Erena (March 22), eyi si n fa ibinu ati itutosoke foju gba a ni aarin awon omo ile Syria ti won se akiyesi pe isejoba Assad n paro, o si n tako iroyin ododo. Mínísítà ètò ìlera ilè̩ Syria kò tilè̩ kéde ìṣè̩lè̩ ààrùn COVID-19 àkó̩kó̩ ilè̩ náà títí di ọjó̩ kejìlélógún Osù Ẹré̩nà (March 22), èyí si ń fa ìbínú àti ìtutọ́sókè fojú gbà á ní àárín àwọn ọmọ ilẹ̀ Syria tí wọ́n ṣe àkíyèsí pé ìṣèjọba Assad ń parọ́, ó si ń tako ìròyìn ododo. "Ninu iwe apileko ti won fi si ori ero alatagba-oniroyin kan ni ile naa, okan ninu awon ara ilu fesi si oro Yaziri, o so pe “se o ko so ninu oro re tele pe gbogbo arun ni o ti je fifo kuro ni""" "Nínú ìwé àpilẹ̀kọ tí wọ́n fi sí orí ẹ̀rọ alátagbà-oníròyìn kan ní ilẹ̀ náà, ọ̀kan nínú àwọn ará ìlú fèsì sí ọ̀rọ̀ Yaziri, ó sọ pé “ṣé o kò sọ nínú ọ̀rọ̀ rẹ tẹ́lẹ̀ pé gbogbo àrùn ni ó ti jẹ́ fífọ̀ kúrò ni""" Sibe naa isejoba yii ti bere si ni si se adiku onka iye awon ti won ni arun naa ninu atejade won. Síbẹ̀ náà ìṣèjọba yìí ti bẹ̀rẹ̀ sí ní sí ṣe àdíkù òǹkà iye àwọn tí wọ́n ní àrùn náà nínú àtẹ̀jáde wọn. Ninu atejade kan ti ojo kini osu Igbe Ajo ti o pe fun Atunse Isejoba Syria ati awon Egbe Alatako kesi awon orile-ede agbaye lati fina mo isejoba ohun, pe ki won o gbe ooto onka iye awon ti won ni arun COVID-19 jade. Nínú àtẹjáde kan tí ọjọ́ kíní osù Igbe Àjọ tí ó pè fún Àtúnṣe Ìṣejọba Syria àti àwọn Ẹgbẹ́ Alátakò késí àwọn orílẹ̀-èdè àgbáyé láti fíná mọ́ ìṣejọba ọ̀hún, pé kí wọn ó gbé òótọ́ òǹkà iye àwọn tí wọ́n ní àrùn COVID-19 jáde. O gbe ero re jade lori iye ti o ye ki o je ooto, ajo naa ko bayii pe: Ó gbé èrò rẹ̀ jáde lórí iye tí ó yẹ kí ó jẹ́ òótọ́, àjọ náà kọ báyìí pé: Eto ilera ti o ti denu kole Ètò ìlera tí ó ti dẹnu kọlẹ̀ Gbigba pe ajakale aarun yii wa loooto bu isejoba Assad ku nitori pe ohun ni yoo je ki awon alase won o fi tipa gba looto pe won ko ni eka eto ilera. Gbígbà pé àjàkálẹ̀ ààrun yìí wà lóòótọ́ bu ìsejọba Assad kù nítorí pé òhun ni yóò jẹ́ kí àwọn aláṣe wọn ó fi tipá gbà lóòtọ́ pé wọn kò ní èka ètò ìlera. Gege bi London School of Economics and Political Science (LSE) se so, apapo iye awon alaaare COVID-19 ti won le wo ni ile naa ko ju egberun mefa aabo lo (6500) ninu ogoro eniyan ti o to milionu metadinlogun abo ti o n gbe ni ile naa. Gẹ́gẹ́ bí London School of Economics and Political Science (LSE) ṣe sọ, àpapọ̀ iye àwọn aláàárẹ̀ COVID-19 tí wọ́n le wò ní ilẹ̀ náà kò ju ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ààbọ̀ lọ (6500) nínú ọ̀gọ̀rọ̀ èníyán tí ó tó mílíọ̀nù mẹ́tàdínlógún àbọ̀ tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà. O ni bi iye awon alaare ba ti ju iye yii lo, ipa orile-ede naa ti pin niyen, omi si le teyin wogbin lenu. Ó ní bí iye àwọn aláàrẹ́ bá ti ju iye yìí lọ, ipá orílè-èdè náà ti pin nìyẹn, omi sì le tẹ̀yìn wọ̀gbín lẹ́nu. Ni asiko ogun abele naa, awon ologun ti se ikolu ti o lagbara si eka eto ilera won. Ní àsìkò ogun abélé náà, àwọn ológun ti ṣe ìkọlù tí ó lágbára sí ẹ̀ka ètò ìlera wọn. Akosile lati odo Ajo WHO ati Ile-ise eto ilera ile Syria so o di mimo pe mejidinlogota nikan ni eto ise re pe ninu ile iwosan ijoba okanlelaaadofa ti o wa ni ile naa. Àkọsílẹ̀ láti ọdọ̀ Àjọ́ WHO àti Ilé-iṣẹ́ ètò ilera ilẹ̀ Syria sọ ọ́ di mímọ̀ pé méjìdínlọ́gọ́ta nìkan ni ètò iṣẹ́ rẹ̀ pé nínú ilé ìwòsàn ìjọba ọ̀kànléláàádọ́fà tí ó wà ní ilẹ̀ náà. Akosile yii tun fi han pe o to ida aadorin ninu ogorun-un awon osise eleto ilera ile naa ti won ti kuro lati di atipo ati ogunlende si ile ibomiiran. Àkọsílẹ̀ yìí tún fi hàn pé ó tó ìdá àádọ́rin nínú ọgọ́rùn-ún àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera ilẹ̀ náà tí wọ́n ti kúrò láti di àtìpó àti ogúnléndé sí ilẹ̀ ibòmìíràn. COVID-19 wa lara ajalu ti o n kuju omoniyan COVID-19 wà lára àjálù tí ó ń kujú ọmọnìyàn O seese ki o je pe ohun ti o je idojuko awon omo ile Syria julo ni bi awon ajalu yii se ro lu ara won; ogun, ajakale-arun ati iyan. Ó ṣeéṣe kí ó jẹ́ pé ohun tí ó jẹ́ ìdojúkọ àwọn ọmọ ilẹ̀ Syria jùlọ ni bí àwọn àjálù yìí ṣe rọ́ lu ara wọn; ogun, àjàkálẹ̀-àrùn àti iyàn. Ajo Isokan Agbaye se ikilo ni ojo kerindinlogbon osu Okudu pe Syria n foju wina ebi apafeeeku, igbese nikia si nilo lati deena itankale COVID-19 Àjọ Ìsọkan Àgbáyé ṣe ìkìlọ̀ ní ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n osù Okudù pé Syria ń fojú winá ebi àpafẹ́ẹ̀ẹ́kú, ìgbẹ́sẹ̀ níkíá sì nílò láti dèènà ìtànkálẹ̀ COVID-19 Gege bi Ajo Eleto Ounje Agbaaye se so, owongogo ba ounje pelu ida mokanla iye re tele ni osu Ebibi yato si ti osu Igbe, o si won si i ni iwon metalelaaadoje nigba ti won gbe e wo si ti odun 2019. Gẹ́gẹ́ bí Àjọ Elétò Ounjẹ Àgbááyé ṣe sọ, òwọ́ngọ́gọ́ bá ounjẹ pẹ̀lú ìdá mọ́kànlá iye rẹ̀ tẹ́lẹ̀ ní oṣù Èbìbí yàtọ̀ sí ti oṣù Igbe, ó sì wọ́n sí i ní ìwọ̀n mẹ́tàléláàádóje nígbà tí wọ́n gbé e wò sí ti ọdun 2019. "Gege bi eto oro aje won se denukole. Ali al-Ahmed (orukokoruko ni eyi naa, gege bi eni yii se beere fun idaabobo oruko re) lati ilu Daraa so fun Ohun Agbaye ni ori ago pe ""nnkan buru jai, ko si iru ise ti o le se, koda ki won o maa san Egberun mewaa owo ile Syria (laarin Dola kan si marun-un) fun eniyan, ko le too na""." "Gẹ́gẹ́ bí ètò ọrọ̀ ajẹ́ wọ́n ṣe dẹnukọlẹ̀. Ali al-Ahmed (orúkọkórúkọ ni èyí náà, gẹ́gẹ́ bí ẹni yìí ṣe bèèrè fún ìdáàbòbò orúkọ rẹ̀) láti ìlu Daraa sọ fún Ohùn Àgbáyé ní orí ago pé ""nǹkan burú jáì, kò sí irú iṣẹ́ tí o lè ṣe, kódà kí wọn ó máa san Egbẹ̀rún mẹ́wàá owó ilẹ̀ Syria (láàrin Dọ́là kan sí márùn-ún) fún ènìyàn, kò le tóó ná""." Ahmed ni opo awon eru ni awon eniyan ti ko sile laigba latari owongogo owo igberu. Ahmed ní ọ̀pọ̀ àwọn ẹrù ni àwọn ènìyàn ti kọ̀ sílẹ̀ láìgbà látàri ọ̀wọ́ngógó owó ìgbẹrù. Lasiko ti eto ilera won ti denikole yii lataari ewu ogun ti o wu won ti eto oro aje ti o fori sanpon si ti so opo omo ile Syria di Akusee, Ajakale aarun ti o ja kiri yii tun ti ti ilu yii sinu ewu aikasi ati idibaje. Lásìkò tí ètò ìlera wọn ti dẹnikọlẹ̀ yìí látàari ewu ogun tí ó wu wọ́n tí ètò ọ̀rọ̀ ajé tí ó forí sánpọ́n sì ti sọ ọ̀pọ̀ ọmọ ilè Syria di Akúṣẹ̀ẹ́, Àjàkálẹ̀ ààrùn tí ò jà kiri yìí tún ti ti ìlú yìí sínú ewu àìkàsí àti ìdibàjẹ́. Idanowo YKS n lo lowo pelu milionu meji abo akekoo laduruu gbogbo ikilo: Ijinasira-eni lawujo gan-an di awati. Ìdánowò YKS ń lọ lọ́wọ́ pẹ̀lú mílíọ́nù méjì àbọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ ládúrúu gbogbo ìkìlọ̀: Ìjìnàsíra-ẹni láwùjo gan-an di àwátì. Aigboraeniye Idanwo YKS tuntun: iwa rere Àìgbọ́raẹniyé Ìdànwò YKS tuntun: ìwà rere Ki i se COVID-19 nikan ni faminfa ti o yi Idanowo YKS ka ni odun 2020. Kì í ṣe COVID-19 nìkan ni famínfà tí ó yí Ìdánowò YKS ká ní ọdún 2020. Opolopo awon oro lo ti n ja ranhinranhin lati ibeere osu keje eyi ti o niise pelu iwe ayoka fun idanwo ede Turkish. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀rọ̀ ló ti ń jà rànhìnrànhìn láti ìbẹ̀ẹ̀rẹ̀ oṣù keje èyí tí ó nííṣe pẹ̀lú ìwé àyọkà fún ìdánwò èdè Turkish. Okan ninu awon ibeere abe re toka si “Fırtınadayım, (mo wa ninu iji), orin olorin taka-n-sufee kan Mabel Matiz omo egbe LGBTQ. Ọ̀kan nínú àwọn ìbéèrè abẹ́ rẹ̀ tọ́ka sí “Fırtınadayım, (mo wà nínú ìjì), orin olórin tàka-n-súfèé kan Mabel Matiz ọmọ ẹgbẹ́ LGBTQ. Ibeere lori itumo “Gozumun gordugu, gogsumun bildigi ile bir degil” (ti a le tu si ohun ti oju mi ri ko ni ohun ti aya mi mo) ti n da awon ikanni awujo ru gudugudu nitori Mabel je eni ti awon odo mo bi eni mo owo (Opo awon fonran re ni o maa n ni oluwo ti o to aadota milionu) ati ise re lori awon ohun ti o jemo ako ati abo. Ìbéèrè lórí ìtumọ̀ “Gözümün gördüğü, göğsümün bildiği ile bir değil” (tí a le tú sí ohun tí ojú mi rí kọ́ ni ohun tí aya mí mọ̀) ti ń da àwọn ìkànnì àwùjọ rú gùdùgùdù nítorí Mabel jẹ́ ẹni tí àwọn ọdọ́ mọ̀ bí ẹni mọ owó (Ọ̀pọ̀ àwọn fọ́nrán rẹ̀ ní ó máa ń ní olùwò tí ó tó àádọ́ta mílíọ́nù) àti ìṣe rẹ̀ lórí àwọn ohun tí ó jẹmọ́ akọ àti abo. Ni ibamu pelu faminfa ori ikanni Twitter, Halis Aygun Aare Center for Measurement, Selection and Placement (OSYM), eka ijoba ti o boju to iseto idanwo so ninu iforowanilenuwo pelu agba osise iroyin kan, Yeni Akit. Nibe ni o ti so pe won yoo se iwadii oro naa, gbogbo awon ti won ba si lowo ninu fifi iwe naa si abe idanwo ohun ni won yoo le kuro lenu ise. Ní ìbámu pẹ̀lú fàmínfà orí ìkànni Twitter, Halis Aygün Ààrẹ Center for Measurement, Selection and Placement (ÖSYM), ẹ̀ka ìjọba tí ó bójú tó ìṣètò ìdánwò sọ nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwọ̀ pẹ̀lú àgbà òṣìṣẹ́ ìròyìn kan, Yeni Akit. Níbẹ̀ ni ó ti sọ pé wọn yóò ṣe ìwádìí ọ̀rọ̀ náà, gbogbo àwọn tí wọ́n bá sì lọ́wọ́ nínú fífi ìwé náà si abẹ́ ìdánwò ọ̀hún ni wọ́n yóò lé kúrò lẹ́nu iṣẹ́. Idanwo YKS odun 2020 kese jari kakakiri awon ibudo idanwo mejidinnigba (188) ni isi eemeta, ti awon akopa ninu re si n lo bii milionu meji abo. Ìdánwò YKS ọdún 2020 kẹ́sẹ járí kákàkiri àwọn ibùdó ìdánwò méjìdínnígbà (188) ní ìṣí ẹ̀ẹ̀mẹta, tí àwọn akópa nínú rẹ̀ sì ń lọ bíi mílíọ́nù méjì àbọ̀. Awon idanwo re je eyi ti awon onimo akada kaakiri awon fafiti orile-ede wa seto. Àwọn ìdánwò rẹ̀ jẹ́ èyí tí àwọn onímọ̀ akadá káàkiri àwọn fáfitì orílẹ̀-èdè wa ṣètò. Ikiyesi awon eko ile ati ogbon ibagbepo lawujo fun awon ile-iwe giga wa maa n je kikiyesi. Ìkíyèsí àwọn ẹ̀kọ́ ilé àti ọgbọ́n ìbágbépò láwùjọ fùn àwọn ilé-ìwé gíga wa máa ń jẹ́ kíkíyèsí. Won ti fi idi iwadii lole lori akoonu awon ibeere ti o niise pelu idanwo ede Turkish ti idanwo YKS odun 2020 [eyi ka okan ninu awon abala idanwo YKS]. Wọ́n ti fi ìdí ìwádìí lọ́lẹ̀ lórí àkóónú àwọn ìbéèrè tí ó nííṣe pẹ̀lú ìdánwò èdè Turkish ti ìdánwò YKS ọdún 2020 [èyí ká ọ̀kan nínú àwọn abala ìdánwò YKS]. Awon osise ti eyi ba si mo lori ni won yoo di gbigbon danu kuro ninu iseto idanwo. Àwọn òṣìṣẹ́ tí èyí bá ṣí mọ́ lórí ni wọn yóò di gbígbọ́n dànù kúrò nínú ìṣètò ìdánwò. Fun awon asamulo ikanni Twitter kan, idajo yii ko to: Fún àwọn asàmúlò ìkànnì Twitter kan, ìdájọ́ yìí kò tó: [Oke] Aare OSYM soro fun igba akoko leyin idanwo! “ [Òkè] Ààrẹ ÖSYM sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lẹ́yìn ìdánwò! “ Won ti fi idi iwadii lole lati wo ibi ti isoro naa ti wowa. Wọ́n ti fi ìdí ìwádìí lọ́lẹ̀ láti wo ibi tí ìṣòro náà ti wọ́wá. Awon ti won ba lowo ninu re yoo di gbigbon danu kuro ninu iseto idanwo.” Àwọn tí wọ́n bá lọ́wọ́ nínú rẹ̀ yóò di gbígbọ́n dànù kúrò nínú ìṣètò ìdánwò.” [Isale] Ko to [la ti yo o] nikan, Aare ti ko ka nnkan si naa gbodo je yiyo kuro ninu isakoso gbogbo ki oju re le wale. [Ìsàlẹ̀] Kò tó [lá ti yọ ọ́] nìkan, Ààrẹ tí kò ka nǹkan sí náà gbọdọ̀ jẹ́ yíyọ kúrò nínú ìṣàkósọ gbogbo kí ojú rẹ̀ le wálẹ̀. Owo awon alenuloro lawujo naa tun ri wi si ipinnu ati seto iru ibeere bayii: Ọ̀wọ́ àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ láwùjọ náà tún rí wí sí ìpinnu àti ṣètò irú ìbéèrè báyìí: Ninu idanwo YKS2020 ti o waye lonii, e ko ri elomiiran fi se apejuwe fun awon omode wonyi afi okunrin onibalopo-akosiako nni Mabel Matiz Nínú ìdánwò YKS2020 tí ó wáyé lónìí, ẹ kò rí ẹlòmìíràn fi ṣe àpèjúwe fún àwọn ọmọdé wọ̀nyí àfi ọkùnrin oníbálòpọ̀-akọsíakọ nnì Mabel Matiz (Eniyan ti o gbe akole ti o fi n polongo pe “Onibalopo-akosiako ni awa” Ki ni e n gbiyanju lati se? (Ènìyàn tí ó gbé àkólé tí ó fi ń polongo pé “Oníbálòpọ̀-akọsíakọ ni àwa” Kí ni ẹ̀ ń gbìyànjú láti ṣe? Ero awon asamulo ikanni Twitter ko sokan pelu bi awon miiran se n toka si awon aseyori Mabel Matiz ati bi o se lokiki si: Èrò àwọn aṣàmúlò ìkànni Twitter kò ṣọ̀kan pẹ̀lú bí àwọn mìíràn ṣe ń tọ́ka sí àwọn àṣeyọrí Mabel Matiz àti bí ó ṣe lókìkí sí: Eyin omo igbimo asewadii. Mo fe ki e wo awon fonran Mabel Matiz. Nitori pe a ko ni elere miiran ti o ti se amulo asa wa to bayii ni opo odun seyin. Idi niyen ti mabelmatiz se je isura wa. Èyin ọmọ ìgbìmọ̀ aṣèwádìí. Mo fẹ́ kí ẹ wo àwọn fọ́nrán Mabel Matiz. Nítorí pé a kò ní eléré mìíràn tí ó ti ṣe àmúlò àṣà wa tó báyìí ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn. Ìdí nìyẹn tí mabelmatiz ṣe jẹ́ ìsúra wa. Awon netizen pe akiyesi si i pe fifi oju sun olorin ti o je onibalopo-akosiako, awon oloselu yoo pa awon oro ti o se koko ti: Àwọn netizen pé àkíyèsí sí i pé fífi ojú sun olórin tí ó jẹ́ oníbálòpọ̀-akọsíakọ, àwọn olóṣèlú yóò pa àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ṣe kókó tì: Ko si eni ti o figbe ta lori awon afipabanilopo, sibe iwadii Mabel Matiz ni won n gba bi eni n gba igba oti. Kò sí ẹni tí ó figbe ta lórí àwọn afipábánilòpọ̀, síbẹ̀ ìwádìí Mabel Matiz ni wọ́n ń gbà bí ẹni ń gba igbá ọtí. E so pe “idaabo bo ise wa” sugbon Mabel Matiz ni eni ti o se igbejade asa wa julo. Ẹ sọ pé “ìdààbò bo ìṣe wa” ṣùgbọ́n Mabel Matiz ni ẹni tí ó ṣe ìgbéjáde àṣà wa jùlọ. O wa ye ki iwadii o da le awon eyi ti o tabuku Mabel Matiz ti won si seleyameya re. Ó wa yẹ kí ìwádìí ó dá lé àwọn èyí tí ó tàbùkù Mabel Matiz tí wọ́n sì ṣẹlẹ́yàmẹ́yá rẹ̀. Esi Mabel Matiz si aigboraeniye naa. Èsì Mabel Matiz sí àìgbọ́raẹniyé náà. Ni ojo keta osu keje, bi faminfa naa se n gbona si i, Matiz pada la ohun: Ní ọjọ́ kẹta oṣù keje, bí fàmínfà náà ṣe ń gbóná sí i, Matiz padà la ohùn: E nle o:) Inu mi dun pe orin mi je lilo fun iru idanwo pataki bi eyi. Ẹ ǹlẹ́ o:) Inú mi dùn pé orin mi jẹ́ lílò fún irú ìdánwò pàtàkì bí èyí. Ni bayii, iyalenu loje fun mi bi igbeaye mi se di ohun ti o kan idanwo ti a n so yii. Ní báyìí, ìyàlẹ́nu lójẹ́ fún mi bí ìgbéayé mi ṣe di ohun tí ó kan ìdánwò tí à ń sọ yìí. E wo ohun ti a fi dan mi wo..bi a se gbe aami kan ni ifegbekegbe pelu oruko mi. Ẹ wo ohun tí a fi dán mi wò..bí a ṣe gbé ààmi kan ní ìfẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́ pẹ̀lú orúkọ mi. Ko buru, Idanwo aye ko lopin:) Iyan tun di atungun wayi. Kò burú, Ìdánwò ayé kò lópin:) Iyán tún di àtúngún wàyí. Mo ka opolopo awon atejade ti o segbe leyin mi. Mo ka ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àtẹjáde tí ó ṣègbè lẹ́yín mi. Ohun ti mo fe so ninu orin yen yemi, mo nimo pe o ye eyin naa, ara mi si tun ya gaga si i. Òhun tí mo fẹ́ sọ nínú orin yẹn yémi, mó nímọ̀ pé ó yé ẹ̀yin náà, ara mi sì tún yá gágá sí i. N o tesiwaju lati maa ko orin si i, lati maa so itan ati lati je omo orile-ede yii. N ó tẹ̀síwájú láti máa kọ orin sí i, láti máa sọ ìtàn àti láti jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè yìí. Ka tun pade ninu idanwo miiran... Ká tún pàdé nínú ìdánwò mìíràn… Matiz si lokiki sibe: leyin ojo kan ti Aygun soro safefe. Matiz sì lókìkí síbẹ̀: lẹ́yìn ọjọ́ kan tí Aygun sọ̀rọ̀ sáfẹ́fẹ́. O gba ami-eye meji ninu idije ami-eye kan nipase ibo ti o poju. Ó gba àmì-ẹ̀yẹ méjì nínú ìdíje àmì-ẹ̀yẹ kan nípasẹ̀ ìbò tí ó pọ̀jù. O gba ami-eye ipele meji. Ó gba àmì-ẹyẹ ipele méjì. “Orin ti musemuse re da muse julo” ati “Olorin okunrin ti musemuse re da muse julo” ni idije amieye Pantene Golden Butterfly eleekerindinlaaadota iru re. “Orin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ” àti “Olórin ọkùnrin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ” ní ìdíje àmìẹyẹ Pantene Golden Butterfly ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínláàádọ́ta irú rẹ̀. Eyi fi han pe opo eniyan ni won wa leyin re tako oro ibalopo-akosiako ti ijoba ati awon alenuloro ti ijoba n so. Èyí fi hàn pé ọ̀pọ̀ ènìyá̀n ni wọ́n wà lẹ́yìn rẹ tako ọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀-akọsíakọ tí ìjọba àti àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ tí ìjọba ń sọ. Ni ojo karun osu keje, Mabel Matix tun tuwiiti: Ní ọjọ́ karùn oṣù keje, Mabel Matix tún túwíìtì: Mo gba ami-eye “Fonran orin ti musemuse re da muse julo” ati “Olorin okunrin ti musemuse re da muse julo” ninu idije ami-eye Pantene Golden Butterfly eleekerindinlaaadota iru re Mo gba àmì-ẹyẹ “Fọ́nrán orin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ” àti “Olórin ọkùnrin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ” nínú ìdíje àmì-ẹyẹ Pantene Golden Butterfly ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínláàádọ́ta irú rẹ̀ . Inu mi dun! E se gan eyin olugbo mi gbogbo. Maa fe lati dupe lowo Erhan Arik ati DOP Meryem Yavuz. Awon ti won dari fonran [orin mi] “I Have a Red in My Wipe” tele. . Inú mi dùn! Ẹ ṣé gan ẹ̀yin olùgbọ́ mi gbogbo. Màá fẹ́ láti dúpẹ́ lọ́wọ́ Erhan Arik àti DOP Meryem Yavuz. Àwọn tí wọ́n darí fọ́nrán [orin mi] “I Have a Red in My Wipe” tẹ́lẹ̀. Ni orile-ede Turkey, egbeegberun meji abo awon akekoo ni won jokoo se idanwo igbaniwole si Ifasiti Ní orílẹ̀-èdè Turkey, ẹgbẹẹgbẹ̀rún méjì àbọ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ni wọ́n jókòó ṣe ìdánwò ìgbaniwọlẹ́ sí Ifásitì Idanwo odun yii waye ninu aigboraeniye—ati pe ki i se nitori ajakale Ìdánwò ọdún yìí wáyé nínú àìgbọ́raẹniyé—àti pé kì í ṣe nítorí àjàkálẹ̀ Atejade itumo 15 Ogun 2020 8:07 GMT Àtẹ̀jáde ìtúmọ̀ 15 Ògún 2020 8:07 GMT Aworan oju iwo aworan-olohun ori YouTube ti orin kan lati owo Mabel Matiz pelu oro orin naa ni aarin aigboraeniye ti o suyo latari Idanwo Igbaniwole si Ile Eko Giga (YKS): Àwòrán ojú ìwò àwòrán-olóhùn orí YouTube ti orin kan láti ọwọ́ Mabel Matiz pẹ̀lú ọ̀rọ̀ orin náà ní àárín àìgbọ́raẹniyé tí ó súyọ látàrí Ìdánwò Ìgbaniwọlé sí Ilé Ẹ̀kọ́ Gíga (YKS): """Gozumun gordugu, gogsumun bildigi ile bir degil"" (ohun ti oju mi ri ko ni okan mi mo "")" """Gözümün gördüğü, göğsümün bildiği ile bir değil"" (ohun tí ojú mi rí kọ́ ni ọkàn mi mọ̀ "")" Ni orile-ede Turkey, orile-ede ti o le ni egbeegberun metalelogorin eniyan (83 million), eniyan ni lati peregede ninu idanwo igbaniwole ti won n pe ni Yuksekogretim Kurumları Sınavı ni ede ile Turkey lati wole si Fafiti. Ní orílẹ̀-èdè Turkey, orílẹ̀-èdè tí ó lé ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún mẹ́tàlélọ́gọ́rin ènìyàn (83 million), ènìyàn ní láti peregedé nínú ìdánwò ìgbaniwọlé tí wọn ń pè ní Yükseköğretim Kurumları Sınavı ní èdè ilẹ̀ Turkey láti wọlé sí Fáfitì. Pelu bi ajakele COVID-19 se n ja ranhin ranhin, idanwo yii si je sise lojutaye, egbeegberun meji abo eniyan (2.5 million) ni won jokoo se idanwo naa. Pẹ̀lú bí àjàkẹ́lẹ̀ COVID-19 ṣe ń jà rànhìn rànhìn, ìdánwò yìí sì jẹ́ ṣíṣe lójútáyé, ẹgbẹẹgbẹ̀rún méjì àbọ̀ ènìyàn (2.5 million) ni wọ́n jókòó ṣe ìdánwò náà. Ni ojo 26 osu Keta, ajo awon ile-iwe giga ile naa kede ojo idanwo YKS yii gege bi ojo 25 si ojo 26 osu Keje. Ní ọjọ́ 26 osù Kẹta, àjọ àwọn ilé-ìwé gíga ilẹ̀ náà kéde ọjọ́ ìdánwò YKS yìí gẹ́gẹ́ bi ọjọ́ 25 sí ọjọ́ 26 oṣù Keje. Sugbon ni ojo 4 osu karun-un, Aare ile Turkey Recep Erdogan yi ojo naa si ojo 27 si ojo 28 osu Keje. Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ 4 oṣù karùn-ún, Ààrẹ ilẹ̀ Turkey Recep Erdoğan yí ọjọ́ náà sí ọjọ́ 27 sí ọjọ́ 28 oṣù Keje. Ayipada yii ati aidaju idanwo yii ti n ko awon eniyan ile Turkey lominu, ni aarin igboro ilu ati ni ori awon ero alatagba lori pe: Àyípadà yìí àti àìdájú ìdánwò yìí ti ń kọ àwọn ènìyàn ilẹ̀ Turkey lóminú, ní ààrín ìgboro ìlú àti ní orí àwọn èrọ alátagbà lórí pé: Bawo ni ojo yiyi se ni ipa lori ironu awon akekoo ti won n mura sile de idanwo lati bi osu meloo kan? Báwo ni ọjọ́ yíyí ṣe ní ipá lórí ìrònú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí wọn ń múra sílẹ̀ de ìdánwò láti bí osù mélòó kan? Bawo ni awon alakale ati ofi ideena itankale COVID-19 yoo se di titele (Jijinna sira eni lawujo, iwon igbona/tutu, ilo aso ibomu) bi a ba n ko eniyan ti o to milionu meji abo papo. Báwo ni àwọn àlàkalẹ̀ àti òfi ìdèènà ìtànkálẹ̀ COVID-19 yóò ṣe di títẹ̀lé (Jíjìnnà síra ẹni láwùjọ, ìwọn ìgbọ́nà/tutù, ìlò ạṣọ ìbomú) bí a bá ń kó ènìyàn tí ó tó mílíọ́nù méjì àbọ̀ papọ̀. Ni odun 2019, ida merinlelaaadorin o le die ni awon olusedanwo ti won pegede ninu idanwo naa, nigba ti ida mokandinlogoji pegede si ipele ikeji idanwo naa. Ní ọdún 2019, ìdá mẹ́rìnléláàádọ́rin ó lé díẹ̀ ni àwọn olùṣèdánwò tí wọ́n pegedé nínú ìdánwò náà, nígbà tí ìdá mọ́kàndínlógójì pegedé sí ìpele ìkejì ìdánwò náà. Orile-ede Turkey se akosile isele COVID-19 akoko won ni ojo 11 osu keta odun, ni igba ti o fi maa di ojo 15 osu keje eniyan egberun marun-un abo ti padanu emi won si owo aarun naa bee si ni iye eniyan ti o ti ni aarun naa ti le ni igba egberun. Orílẹ̀-èdè Turkey ṣe àkọsílẹ̀ ìṣẹ̀lẹ̀ COVID-19 àkọ́kọ́ wọn ní ọjọ́ 11 oṣù kẹta ọdún, ní ìgbà tí ó fi máa di ọjọ́ 15 oṣù keje ẹ̀nìyàn ẹgbẹ̀rún márùn-ún àbọ̀ ti pàdánù ẹ̀mí wọn sí ọwọ́ ààrùn náà bẹ́ẹ̀ sì ni iye ènìyàn tí ó ti ní ààrùn náà ti lé ní igba ẹgbèrún. Ni ojo 1 osu keje, Ijoba gunle awon igbese idekun lorisirisi: Ní ọjọ́ 1 oṣù keje, Ìjọba gùnlé àwọn ìgbéṣẹ̀ ìdẹ́kun lóríṣiríṣi: Awon ile oko-owo bi ile ounje, awon oko owo ero ayelujara, ile isafihan ere, gbongan ayeye igbeyawo ti won ti pa fun bii osu meta ni won ti tun si pada bayii, amo sa pelu atele ijijina sira eni lawujo. Àwọn ilé oko-òwò bi ilé ounjẹ, àwọn oko òwò ẹ̀rọ ayélujára, ilé ìṣàfihàn eré, gbọ̀ngàn ạyẹyẹ ìgbeyàwó tí wọ́n tì pa fún bíi oṣù mẹ́ta ni wọ́n ti tún ṣí padà báyìí, àmọ́ ṣá pẹ̀lú àtẹ̀lé ìjíjìnà síra ẹni láwùjọ. Awon olubewo bayii nilo lati maa bo imu wo, won yoo si maa se ayewo igbona/tutu won. Àwọn olùbẹ̀wò báyìí nílò láti máa bo imú wọ, wọn yóò sì máa ṣe àyẹ̀wò ìgbóná/tutù wọn. Bi awon akekoo tile fi ipe sita pe ki idanwo YKS o di sisun siwaju, ijoba o teti ninu alakale re: Bí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tilẹ̀ fi ìpè síta pé kí ìdánwò YKS ó di sísún síwájú, ìjọba ò tẹ̀tì nínú àlàkalẹ̀ rẹ̀: Ni ipari osu keje milionu meji abo ni o jokoo se idanwo naa.. Ní ìparí oṣù keje mílíọ̀nù méjì àbọ̀ ni ó jókòó ṣe ìdánwò náà.. Gege bi a se ri i ni inu tuwiiti yii, ti o niise pelu asuju lori imunitele ijinna si ara eni lawujo: Gẹ́gẹ́ bí a ṣe rí i ní inú túwíìtì yìí, tí ó nííṣe pẹ̀lú àsujù lórí ìmúnitẹ̀lẹ́ ìjìnnà sí ara ẹni láwùjọ: Idanowo YKS n lo lowo pelu milionu meji abo akekoo laduruu gbogbo ikilo: Ijinasira-eni lawujo gan-an di awati. Ìdánowò YKS ń lọ lọ́wọ́ pẹ̀lú mílíọ́nù méjì àbọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ ládúrúu gbogbo ìkìlọ̀: Ìjìnàsíra-ẹni láwùjo gan-an di àwátì. Aigboraeniye Idanwo YKS tuntun: iwa rere Àìgbọ́raẹniyé Ìdànwò YKS tuntun: ìwà rere Ki i se COVID-19 nikan ni faminfa ti o yi Idanowo YKS ka ni odun 2020. Kì í ṣe COVID-19 nìkan ni famínfà tí ó yí Ìdánowò YKS ká ní ọdún 2020. Opolopo awon oro lo ti n ja ranhinranhin lati ibeere osu keje eyi ti o niise pelu iwe ayoka fun idanwo ede Turkish. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀rọ̀ ló ti ń jà rànhìnrànhìn láti ìbẹ̀ẹ̀rẹ̀ oṣù keje èyí tí ó nííṣe pẹ̀lú ìwé àyọkà fún ìdánwò èdè Turkish. Okan ninu awon ibeere abe re toka si “Fırtınadayım, (mo wa ninu iji), orin olorin taka-n-sufee kan Mabel Matiz ti i se LGBTQ “Fırtınadayım” (“I am in the storm”): Ọ̀kan nínú àwọn ìbéèrè abẹ́ rẹ̀ tọ́ka sí “Fırtınadayım, (mo wà nínú ìjì), orin olórin tàka-n-súfèé kan Mabel Matiz tí í ṣe LGBTQ “Fırtınadayım” (“I am in the storm”): Ibeere lori itumo “Gozumun gordugu, gogsumun bildigi ile bir degil” (ti a le tu si ohun ti oju mi ri ko ni ohun ti aya mi mo) ti n da awon ikanni awujo ru gudugudu nitori Mabel je eni ti awon odo mo bi eni mo owo (opo awon aworan-atohun re ni o maa n ni iwo ti o to aadota milionu) ati ise re lori awon ohun ti o jemo akosebiabo. Ìbéèrè lórí ìtumọ̀ “Gözümün gördüğü, göğsümün bildiği ile bir değil” (tí a le tú sí ohun tí ojú mi rí kọ́ ni ohun tí aya mí mọ̀) ti ń da àwọn ìkànnì àwùjọ rú gùdùgùdù nítorí Mabel jẹ́ ẹni tí àwọn ọdọ́ mọ̀ bí ẹni mọ owó (ọ̀pọ̀ àwọn àwòrán-àtohùn rẹ̀ ní ó máa ń ní ìwò tí ó tó àádọ́ta mílíọ́nù) àti ìṣe rẹ̀ lórí àwọn ohun tí ó jẹmọ́ akọ́ṣebíabo. Ni ibamu pelu faminfa ori ikanni Twitter, Halis Aygun Aare Center for Measurement, Selection and Placement (OSYM), eka ijoba ti o boju to iseto idanwo so ninu iforowanilenuwo pelu agba osise iroyin kan, Yeni Akit. Ní ìbámu pẹ̀lú fàmínfà orí ìkànni Twitter, Halis Aygün Ààrẹ Center for Measurement, Selection and Placement (ÖSYM), ẹ̀ka ìjọba tí ó bójú tó ìṣètò ìdánwò sọ nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwọ̀ pẹ̀lú àgbà òṣìṣẹ́ ìròyìn kan, Yeni Akit. Nibe ni o ti so pe won yoo se iwadii oro naa, gbogbo awon ti won ba si lowo ninu fifi iwe naa si abe idanwo ohun ni won yoo le kuro lenu ise: Níbẹ̀ ni ó ti sọ pé wọn yóò ṣe ìwádìí ọ̀rọ̀ náà, gbogbo àwọn tí wọ́n bá sì lọ́wọ́ nínú fífi ìwé náà si abẹ́ ìdánwò ọ̀hún ni wọ́n yóò lé kúrò lẹ́nu iṣẹ́: Idanwo YKS odun 2020 kese jari kakakiri awon ibudo idanwo mejidinnigba (188) ni isi eemeta, ti awon akopa ninu re si n lo bii milionu meji abo. Ìdánwò YKS ọdún 2020 kẹ́sẹ járí kákàkiri àwọn ibùdó ìdánwò méjìdínnígbà (188) ní ìṣí ẹ̀ẹ̀mẹta, tí àwọn akópa nínú rẹ̀ sì ń lọ bíi mílíọ́nù méjì àbọ̀. Awon idanwo re je eyi ti awon onimo akada kaakiri awon fafiti orile-ede wa seto. Àwọn ìdánwò rẹ̀ jẹ́ èyí tí àwọn onímọ̀ akadá káàkiri àwọn fáfitì orílẹ̀-èdè wa ṣètò. Ikiyesi awon eko ile ati ogbon ibagbepo lawujo fun awon ile-iwe giga wa maa n je kikiyesi. Ìkíyèsí àwọn ẹ̀kọ́ ilé àti ọgbọ́n ìbágbépò láwùjọ fùn àwọn ilé-ìwé gíga wa máa ń jẹ́ kíkíyèsí. Awon osise ti eyi ba si mo lori ni won yoo di gbigbon danu kuro ninu iseto idanwo. Àwọn òṣìṣẹ́ tí èyí bá ṣí mọ́ lórí ni wọn yóò di gbígbọ́n dànù kúrò nínú ìṣètò ìdánwò. Fun awon asamulo ikanni Twitter kan, idajo yii ko to: Fún àwọn asàmúlò ìkànnì Twitter kan, ìdájọ́ yìí kò tó: [Oke] Aare OSYM soro fun igba akoko leyin idanwo! [Òkè] Ààrẹ ÖSYM sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lẹ́yìn ìdánwò! """Won ti fi idi iwadii lole lati wo ibi ti isoro naa ti wowa. Awon ti won ba lowo ninu re yoo di gbigbon danu kuro ninu iseto idanwo.""" """Wọ́n ti fi ìdí ìwádìí lọ́lẹ̀ láti wo ibi tí ìṣòro náà ti wọ́wá. Àwọn tí wọ́n bá lọ́wọ́ nínú rẹ̀ yóò di gbígbọ́n dànù kúrò nínú ìṣètò ìdánwò.""" [Isale] Ko to [la ti yo o] nikan, Aare ti ko ka nnkan si naa gbodo je yiyo kuro ninu isakoso gbogbo ki oju re le wale. [Ìsàlẹ̀] Kò tó [lá ti yọ ọ́] nìkan, Ààrẹ tí kò ka nǹkan sí náà gbọdọ̀ jẹ́ yíyọ kúrò nínú ìṣàkósọ gbogbo kí ojú rẹ̀ le wálẹ̀. Owo awon alenuloro lawujo naa tun ri wi si ipinnu ati seto iru ibeere bayii: Ọ̀wọ́ àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ láwùjọ náà tún rí wí sí ìpinnu àti ṣètò irú ìbéèrè báyìí: Ninu idanwo #YKS2020 ti o waye lonii, e ko ri elomiiran fi se apejuwe fun awon omode wonyi afi okunrin onibalopo-akosiako nni Mabel Matiz? Nínú ìdánwò #YKS2020 tí ó wáyé lónìí, ẹ kò rí ẹlòmìíràn fi ṣe àpèjúwe fún àwọn ọmọdé wọ̀nyí àfi ọkùnrin oníbálòpọ̀-akọsíakọ nnì Mabel Matiz? "(Eniyan ti o gbe akole ti o fi n polongo pe ""Onibalopo-akosiako ni awa""" "(Ènìyàn tí ó gbé àkólé tí ó fi ń polongo pé ""Oníbálòpọ̀-akọsíakọ ni àwa""" Ki ni e n gbiyanju lati se? Kí ni ẹ̀ ń gbìyànjú láti ṣe? Ero awon asamulo ikanni Twitter ko sokan pelu bi awon miiran se n toka si awon aseyori Mabel Matiz ati bi o se lokiki si: Èrò àwọn aṣàmúlò ìkànni Twitter kò ṣọ̀kan pẹ̀lú bí àwọn mìíràn ṣe ń tọ́ka sí àwọn àṣeyọrí Mabel Matiz àti bí ó ṣe lókìkí sí: Eyin omo igbimo asewadii. Mo fe ki e wo awon fonran Mabel Matiz. Èyin ọmọ ìgbìmọ̀ aṣèwádìí. Mo fẹ́ kí ẹ wo àwọn fọ́nrán Mabel Matiz. Nitori pe a ko ni elere miiran ti o ti se amulo asa wa to bayii ni opo odun seyin. Nítorí pé a kò ní eléré mìíràn tí ó ti ṣe àmúlò àṣà wa tó báyìí ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn. Idi niyen ti mabelmatiz se je isura wa. Ìdí nìyẹn tí mabelmatiz ṣe jẹ́ ìsúra wa. Awon eeyan lori ayelujara pe akiyesi si i pe fifi oju sun olorin ti o je onibalopo-akosiako, awon oloselu yoo pa awon oro ti o se koko ti: Àwọn èèyàn lórí ayélujára pé àkíyèsí sí i pé fífi ojú sun olórin tí ó jẹ́ oníbálòpọ̀-akọsíakọ, àwọn olóṣèlú yóò pa àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ṣe kókó tì: Ko si eni ti o figbe ta lori awon afipabanilopo, sibe iwadii Mabel Matiz ni won n gba bi eni n gba igba oti. Kò sí ẹni tí ó figbe ta lórí àwọn afipábánilòpọ̀, síbẹ̀ ìwádìí Mabel Matiz ni wọ́n ń gbà bí ẹni ń gba igbá ọtí. Eleyii ko gbogbo re nile: Eléyìí kó gbogbo rẹ̀ nílẹ̀: "E so pe ""idaabo bo ise wa"" sugbon Mabel Matiz ni eni ti o se igbejade asa wa julo." "Ẹ sọ pé ""ìdààbò bo ìṣe wa"" ṣùgbọ́n Mabel Matiz ni ẹni tí ó ṣe ìgbéjáde àṣà wa jùlọ." O wa ye ki iwadii o da le awon eyi ti o tabuku Mabel Matiz ti won si seleyameya re. #MabelMatizisnotalone [Atejade oke] Ó wa yẹ kí ìwádìí ó dá lé àwọn èyí tí ó tàbùkù Mabel Matiz tí wọ́n sì ṣẹlẹ́yàmẹ́yá rẹ̀. #MabelMatizisnotalone [Àtẹ̀jáde òkè] Esi Mabel Matiz si aigboraeniye naa Èsì Mabel Matiz sí àìgbọ́raẹniyé náà Ni ojo 3 osu Keje, bi faminfa naa se n gbona si i, Matiz pada la ohun: Ní ọjọ́ 3 oṣù Keje, bí fàmínfà náà ṣe ń gbóná sí i, Matiz padà la ohùn: E nle o:) Inu mi dun pe orin mi je lilo fun iru idanwo pataki bi eyi. Ẹ ǹlẹ́ o:) Inú mi dùn pé orin mi jẹ́ lílò fún irú ìdánwò pàtàkì bí èyí. Ni bayii, iyalenu loje fun mi bi igbeaye mi se di ohun ti o kan idanwo ti a n so yii. Ní báyìí, ìyàlẹ́nu lójẹ́ fún mi bí ìgbéayé mi ṣe di ohun tí ó kan ìdánwò tí à ń sọ yìí. E wo ohun ti a fi dan mi wo..bi a se gbe aami kan ni ifegbekegbe pelu oruko mi. Ẹ wo ohun tí a fi dán mi wò..bí a ṣe gbé ààmi kan ní ìfẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́ pẹ̀lú orúkọ mi. Ko buru, Idanwo aye ko lopin:) Kò burú, Ìdánwò ayé kò lópin:) Iyan tun di atungun wayi. Iyán tún di àtúngún wàyí. Mo ka opolopo awon atejade ti o segbe leyin mi. Mo ka ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àtẹjáde tí ó ṣègbè lẹ́yín mi. Ohun ti mo fe so ninu orin yen yemi, mo nimo pe o ye eyin naa, ara mi si tun ya gaga si i. Òhun tí mo fẹ́ sọ nínú orin yẹn yémi, mó nímọ̀ pé ó yé ẹ̀yin náà, ara mi sì tún yá gágá sí i. N o tesiwaju lati maa ko orin si i, lati maa so itan ati lati je omo orile-ede yii. N ó tẹ̀síwájú láti máa kọ orin sí i, láti máa sọ ìtàn àti láti jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè yìí. Ka tun pade ninu idanwo miiran... Ká tún pàdé nínú ìdánwò mìíràn... Matiz si lokiki sibe: leyin ojo kan ti Aygun soro safefe, o gba ami-eye meji ninu idije ami-eye kan nipase ibo ti o poju. Matiz sì lókìkí síbẹ̀: lẹ́yìn ọjọ́ kan tí Aygun sọ̀rọ̀ sáfẹ́fẹ́, ó gba àmì-ẹ̀yẹ méjì nínú ìdíje àmì-ẹ̀yẹ kan nípasẹ̀ ìbò tí ó pọ̀jù. O gba ami-eye ipele meji, “Orin ti musemuse re da muse julo” ati “Olorin okunrin ti musemuse re da muse julo” ni idije amieye Pantene Golden Butterfly eleekerindinlaaadota iru re. Ó gba àmì-ẹyẹ ipele méjì, “Orin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ” àti “Olórin ọkùnrin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ” ní ìdíje àmìẹyẹ Pantene Golden Butterfly ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínláàádọ́ta irú rẹ̀. Eyi fi han pe opo eniyan ni won wa leyin re tako oro ibalopo-akosiako ti ijoba ati awon alenuloro ti ijoba n so. Èyí fi hàn pé ọ̀pọ̀ ènìyá̀n ni wọ́n wà lẹ́yìn rẹ tako ọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀-akọsíakọ tí ìjọba àti àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ tí ìjọba ń sọ. Ni ojo 5 osu Keje, Mabel Matix tun tuwiiti: Ní ọjọ́ 5 oṣù Keje, Mabel Matix tún túwíìtì: "Mo gba ami-eye ""aworan-atohun orin ti musemuse re da muse julo"" ati “Olorin okunrin ti musemuse re da muse julo” ninu idije ami-eye Pantene Golden Butterfly eleekerindinlaaadota iru re, Inu mi dun!" "Mo gba àmì-ẹyẹ ""àwòrán-àtohùn orin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ"" àti “Olórin ọkùnrin tí mùṣèmúṣè rẹ̀ dá múṣé jùlọ” nínú ìdíje àmì-ẹyẹ Pantene Golden Butterfly ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínláàádọ́ta irú rẹ̀, Inú mi dùn!" E se gan eyin olugbo mi gbogbo. Ẹ ṣé gan ẹ̀yin olùgbọ́ mi gbogbo. Maa fe lati dupe lowo Erhan Arik ati DOP Meryem Yavuz, awon ti won dari aworan-atohun [orin mi] Màá fẹ́ láti dúpẹ́ lọ́wọ́ Erhan Arik àti DOP Meryem Yavuz, àwọn tí wọ́n darí àwòrán-àtohùn [orin mi] """I Have a Red in My Wipe"" clip tele." """I Have a Red in My Wipe"" clip tẹ́lẹ̀." ---Ajodun osise: Abenugan ile-igbimo asoju ro osise lati teramo ise fun abajade rere. ---Àjọ̀dún òṣìṣẹ́: Abẹnugan ilé-ìgbìmọ̀ as̩ojú rọ òṣìṣẹ́ láti tẹramọ́ iṣẹ́ fún àbájáde rere. Abenugan ile-igbimo asoju ti Naijiria, Femi Gbajabiamila, ti ki awon osise orile-ede yii ku oriire fun ti ajodun ayajo awon osise lagbaaye. Abẹnugan ilé-ìgbìmọ̀ aṣ̣ojú ti Nàìjíríà, Fẹ́mi Gbàjàbíàmílà, ti kí àwọn òṣìṣẹ́ orílẹ̀-èdè yìí kú orííre fún ti àjọ̀dún àyájọ́ àwọn òsìsẹ́ lágbàáyé. Ogbeni Gbajabiamila ni bo tile je pe ayeye yii waye laisi ariwo ni gbogbo agbaye nitori ase konile–gbele latari itankale aarun COVID-19, ohun ti a le ranti po nipa awon irubo ti awon osise Naijiria se. Ọ̀gbẹ́ni Gbàjàbíàmílà ní bó tilẹ̀ jẹ́ pé ayẹyẹ yìí wáyé láìsí ariwo ní gbogbo àgbáyé nítorí àṣe̩ kónílé–gbélé látàrí ìtànkálẹ̀ aàrun COVID-19, ohun tí a lè rántí pọ̀ nípa àwọn ìrúbọ ti àwọn òṣìṣẹ́ Nàìjíríà̀ ṣe. Ninu atejade to n sami ojo awon osise eyi ti Oludamoran re Pataki lori iroyin ati ikede fowosi, Lanre Lasisi, Abenugan gbosuba fun awon osise Naijiria nitori ifarajin ati ipa ribiribi ti won ko fun opo odun seyin, eyi to mu iyipada rere ba Naijiria. Nínú àtẹ̀jáde tó ń sàmì ọjọ́ àwọn òṣìṣẹ́ èyí tí Olùdámọ́ràn rẹ̀ Pàtàkì lórí ìròyìn àti ìkéde fo̩wó̩sí, Láńre Làsísì, Abẹnugan gbóṣùbà fún àwọn òṣìṣẹ́ Nàìjíríà nítorí ìfarajìn àti ipa ribiribi tí wọ́n kó fún ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn, èyí tó mú ìyípadà rere bá Nàìjíríà. Sibe, o ro awon osise Naijiria ki won tunbo maa so eso rere nisisinyi ati gbogbo igba, nitori aseyori ana nilo itesiwaju ki a sise sii ki orile-ede yii lee ni aseyori sii. Síbè̩, ó ro̩ àwọn òṣìṣé Nàìjíríà kí wọ́n túnbọ̀ máa so èso rere nísisìnyí àti gbogbo ìgbà, nítorí àṣeyorí àná nílò ìtẹ̀síwájú kí a ṣiṣẹ́ síi kí ọrílẹ̀-èdè yìí leè ní àṣeyọrí síi. ‘Mo fe ki awon osise Naijiria fun okan-akin, awon ti won ti fi gbogbo ipa won sise. ‘Mo fẹ́ kí àwọn òṣìṣé Nàìjíríà fún ọkàn-akin, àwọn tí wọ́n ti fi gbogbo ipá wọn ṣiṣé. Nitooto, Naijiria ati awon omo Naijiria fi yin yangan. Nítòótọ́, Nàìjíríà àti àwọn ọmọ Nàìjíríà fi yín yangàn. Mo ro awon osise Naijiria lati fikun okun won ni iru akoko idagbasoke orile ede wa yii. Mo rọ àwọn òṣìṣẹ́ Nàìjíríà láti fikún okun wọn ní irú àkókò ìdàgbàsókè orílẹ̀ èdè wa yìí. Won gbodo tesiwaju lati fi gbogbo agbara won se ise ti won n se fun anfaani orile ede’ Wọ́n gbọ́dọ̀ tẹ̀síwájú láti fi gbogbo agbára wọn ṣe iṣé tí wọ́n ń ṣe fún àǹfààní orílẹ̀ èdè’ --- Ayajo awon Osise: Olori ile-igbimo asofin agba ki awon osise Naijiria --- Àyájọ́ àwọn Òṣìṣẹ́: Olóri ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà kí àwọn òṣìṣẹ́ Nàìjíríà Aare ile-igbimo asofin agba ti Naijiria, Ahmad Lawan, ki awon osise orile-ede yii bi won se sowopo pelu awon akegbe won lagbaaye lati se ajodun ojo awon osise. Ààrẹ ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ti Nàìjíríà, Ahmad Lawan, kí àwọn òṣìṣẹ́ orílẹ̀-èdè yìí bí wọ́n ṣe sowó̩pò̩ pè̩lú àwọn akẹgbẹ́ wọn lágbàáyé láti s̩e àjọ̀dún o̩jó̩ àwọn òṣìṣẹ́. Asofin Lawan tun gbosuba fun awon osise fun gudugudu meje, yaya mefa ti won n se lati mu orile-ede kuro ninu osi ati aini idagbasoke ati kikoju awon ipenija amuniberu lenu ise oniruuru. Aṣòfin Lawan tún gbóṣùbà fún àwọn òṣìṣẹ́ fún gudugudu méje, yàyà mẹfà tí wọ́n ń ṣe láti mú orílẹ̀-èdè kúrò nínú òṣì àti àìní idàgbàsókè àti kíkojú àwo̩n ìpèníjà amúnibè̩rù lẹ́nu iṣẹ́ onírúurú. O mo riri ipa awon osise gege bii eni to n mu oro wa si awujo, o tenumo wipe eyi ni a se gbodo mo riri won ni gbogbo igba. Ó mọ rírì ipa àwọn òṣìṣẹ́ gẹ́gẹ́ bíi ẹni tó ń mú ọrọ̀ wá sí àwùjọ, ó tẹnumọ wípé èyí ni a ṣe gbọ́dọ̀ mo rírì wọn ní gbogbo ìgbà. "O tesiwaju pe ""ona to dara julo lati mo riri ipa ribiribi ti awon osise ko ni lati mojuto eto igbaye-gbadun won." "Ó tẹ̣̀síwájú pé ""ọ̀nà tó dára jùlọ̣ láti mọ̣ rírì ipa ribiribi tí àwọ̣̣n òṣìṣẹ́ kó ní láti mójútó ètò ìgbáyé-gbádùn wọ̣̣n." "Lawan so wipe, ""Gege bi ile-igbimo asofin, a ti setan lati fowosowopo pelu egbe awon osise lati sofin to lodi si iwa ibaje si osise lenu ise""." "Lawan sọ wípé, ""Gẹ̣́gẹ́ bí ilé-ìgbìmọ̀ aṣ̣òfin, a ti ṣ̣etán láti fọwọ̣́sowọ̣́pọ̀ pẹ̣̀lú ẹ̣̣gbẹ̣́ àwọ̣̣n òṣ̣ìṣ̣ẹ́ láti ṣòfin tó lòdì sí ìwà ìbàjẹ́ sí òṣìṣẹ lẹ́nu iṣẹ́""." Aare ile-igbimo asofin agba so wipe, gege bii ara akitiyan ile-igbimo asofin kesan-an lati fi okun fun eto oro aje ati lati mu igbe-aye awon eniyan dara sii, ti pinu lati mu ki eto isuuna odun yii see daadaa nipa titete bu owo lu iwe eto isuna odun 2020. Ààrẹ ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà sọ wípé, gégẹ́ bíi ara akitiyan ilé-ìgbìmọ aṣòfin kẹsàn-án láti fi okun fún ètò ọrọ̀ ajé àti láti mú ìgbé-ayé àwọn ènìyàn dára síi, ti pinu láti mú kí ètò ìsúúná ọdún yìí ṣee dáadáa nípa títètè bu ọwọ́ lu ìwé ètò ìsúná ọdún 2020. Ninu oro Asofin Lawan, ile-igbimo asofin agba bakan naa ti se atunse si awon ofin kookan lati ri wipe imulo eto isuna naa loo bi o ti ye. Nínu ọ̀rọ̀ Aṣòfin Lawan, ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà bakan náà ti ṣe àtúnṣe sí àwọn òfin kò̩ò̩kan láti ri wípé ìmúlò ètò ìsúná náà lo̩o̩ bí ó ti yẹ. O so wipe awon Asofin yoo maa lo ni ilana yii laiwo awon ipenija ajakale aarun COVID-19. Ó sọ wípé àwọn Aṣòfin yóò máa lọ ní ìlànà yìí láìwo àwọn ìpèníjà àjàkálẹ̀ ààrùn COVID-19. Aare ile-igbimo asofin se akiyesi wipe ayeye ojo awon osise ti odun yii waye lasiko ti gbogbo orile ede agbaye n koju ajakale aarun ojiiji COVID-19. Ààrẹ ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ṣe àkíyèsí wípé ayẹyẹ ọjọ́ àwọn òṣìṣẹ́ ti ọdún yìí wáyé lásìkò tí gbogbo orílẹ̀ èdè àgbáyé ń kojú àjàkálẹ̀ ààrùn òjiijì COVID-19. "O wipe ""Okan akinkanju ati emi ti kii ku ti awon eniyan Naijiria nii ni yoo ran ise ijoba lowo lati lee bori ajakale aarun naa""" "Ó wípé ""Ọkàn akínkanjú àti ẹ̀mí tí kìí kú tí àwọn ènìyàn Nàìjíríà níí ni yóò ran iṣẹ́ ìjọba lọ́wọ́ láti leè borí àjàkálẹ̀ ààrùn náà""" ”Aare ile igbimo asofin wa ro awon osise lorile ede Naijiria bi won se n sami ojo won, lati maa tele ilana eto ilera lawujo, fifi aaye saarin ara wa, ki a maa wo iboju, ki a maa lo oun elo ifowo apakokoro, ki a maa se imototo ara wa ati lati maa duro sile ki a si daabo bo ara wa. ”Ààrẹ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin wá rọ àwọn òṣìsẹ́ lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà bí wọ́n ṣe ń sàmì ọjọ́ wọn, láti máa tẹ́lé ìlànà ètò ìlera láwùjọ, fífi ààyè sáàrín ara wa, kí a máa wọ ìbòjú, kí a máa lo oun èlò ìfọwọ́ apakòkòrò, kí a máa ṣe ìmọ́tótó ara wa àti láti máa dúrọ sílé kí a sì dáàbò bo ara wa. --- COVID-19: Awon eniyan merinlelogun (24) miiran tun jeyo lorile ede Naijiria --- COVID-19: Àwọn ènìyàn mẹ́rìnlélógún (24) mìíràn tún jẹyọ lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà Awon eniyan merilelogun (24) miiran tun ti jeyo ti won ni aarun Corona (COVID 19) lorileede Naijiria, eyi to je ki iye awon to ni aarun Corona je ogbonleleedegbaa le meji (1932), nigba ti awon eniyan bi mokandinlogunleloodunrun (319) ti gba iwosan, ti awon eniyan mejidinlogota (58) si ti je Olorun nipe. Ajo to n gbogun ti ajakale aarun ti Naijiria (NCDC) lo kede yii lori ero Twitter won, @NCDC. gov. Àwọn ènìyàn mẹ́rìlélógún (24) mìíràn tún ti jẹyọ tí wọ́n ní ààrùn Corona (COVID 19) lórílé̩èdè Nàìjíríà, èyí tó jẹ́ kí iye àwọn tó ní ààrùn Corona jẹ́ o̩gbò̩nlélé̩è̩dé̩gbàá lé méjì (1932), nígbà tí àwọn ènìyàn bí mọ́kàndínlógúnlélọ́ọ̀dúnrún (319) ti gba ìwòsàn, tí àwọn ènìyàn méjìdínlọ́gọ́ta (58) sì ti jẹ́ Ọlọ́run nípè. Àjọ tó ń gbógun ti àjàkálẹ̀ aàrùn ti Nàìjíríà (NCDC) ló kéde yìí lórí ẹ̀rọ Twitter wọn, @NCDC. gov. --- COVID-19: A ti gba iroyin die lori isele ni Kano- Dokita Osagie --- COVID-19: A ti gba ìròyìn díẹ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ní Kánò- Dókítà Osagie Minisita fun eto ilera ti Naijiria, Dokita Osagie Ehanire ti ni awon ri iroyin die gba nipa isele oniruuru ni ipinle Kano. Mínísítà fún ètò ìlera ti Nàìjíríà, Dókítà Osagie Ehanire ti ní àwọn ri ìròyìn díẹ̀ gbà nípa ìṣẹ̀lẹ̀ onírúurú ní ìpínlẹ̀ Kánò. Minisita soro yii lasiko eto iforowanilenuwo ojoojumo ti igbimo ijoba apapo to n mojuto gbigbogun ti aarun COVID-19 n se pelu awon akoroyin niluu Abuja. Mínísítà sọ̀rọ̀ yìí lásìkò ètò ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò ojoojúmó tí ìgbìmọ̀ ìjọba àpapọ̀ tó ń mójútó gbígbógun ti aàrùn COVID-19 ń ṣe pẹ̀lú àwọn akọ̣̣̣̣̣̀ròyìn nílùú Àbújá. O tun tesiwaju pe awon si n reti gbogbo iroyin nipa isele iku ojiji to waye ni ipinle Kano, eleyii yoo ran igbese pipese eto iranwo irinse , awon onimo ati eto eko ti won yoo fun ipinle Kano lati dekun aarun COVID-19. Ó tún tẹ̀síwájú pé àwọ̣n ṣí ń retí gbogbo ìròyìn nípa ìṣẹ̣̀lẹ̀ ikú òjijì tó wáyé ní ìpínlẹ̣̀ Kánò, eléyìí yóò ràn ìgbéṣẹ̀ pípèsè ètò ìrànwọ́ ìrìnsẹ̀ , àwọn onímọ̀ àti ètò ẹ̣̀kọ́ tí wọn yóò fún ìpínlẹ̀ Kánò láti dẹ́kun aàrùn COVID-19. Dokita Ehanire , wa ro awon osise eto ilera lati maa tele eto ilana lati daabo bo ara won nigba gbogbo ki won maa baa lugbadi aarun COVID-19 tabi fi ara won sinu ewu. Dókítà Ehanire , wá rọ̣ àwọ̣n òṣìṣẹ̣́ ètò ìlera làti maa tẹ̀ḷé ètò ìlànà láti dáàbò bò ara wọn nígbà gbogbo kí wọ̣n máa bàa lùgbàdì aàrùn COVID-19 tàbí fi ara wọ̣n sínú ewu. --- Naijiria sawari awon alarun COVID-19 merinlelugba --- Nàìjíríà ṣàwárí àwọn alárùn COVID-19 mé̩rìnlélúgba Naijiria ti ni akosile eniyan merinlelugba ti won ni aarun korona ti a mo si COVID – 19, eyi to mu gbogbo akarun naa je ogbonleleedegbaa le meji (1932). Nàìjíríà ti ní àkosílẹ̀ ènìyàn mẹ́rìnlélúgba tí wọ́n ní ààrun kòrónà tí a mọ̀ sí COVID – 19, èyí tó mú gbogbo akárùn náà jé̩ o̩gbò̩nlélé̩è̩dé̩gbàá lé méjì (1932). Okooleloodunrun din okan (319) gba iwosan, mejidinlogota si ku. Okòóléló̩ò̩dúnrún dín ò̩kan (319) gba ìwòsàn, méjìdínlọ́gọ́ta sì kú. Ajo a-gbogun-ti-ajakale-aarun ti Naijiria (NCDC) lo so eyi lori ero abeyefo @NCCDCgov; Àjo̩ a-gbógun-ti-àjàkálẹ̀-ààrun ti Nàìjíríà (NCDC) ló so̩ èyí lórí ẹ̀rọ abẹ́yẹfò @NCCDCgov; Alarun COVID-19 merinlelugba ti farahan; Alárùn COVID-19 mé̩rìnlélúgba ti farahàn; Ogorin-Kano, marundinlaadota-Eko, mejila-Gombe, mesan-an-Bauchi, mesan-an-Sokoto, meje-Borno, meje-Edo, mefa-Rivers, mefa-Ogun, merin-Abuja, merin-Akwa Ibom, merin-Bayelsa, meta-Kaduna, meji-Oyo, meji-Delta, meji-Nasarawa, Okan-Ondo, Okan-Kebbi. Ni agogo mejila ku iseju mewaa, ogbon ojo osu igbe – 1932 alarun Covid-19 farahan ni Naijiria. Ọgọ́rin-Kano, márùndínláàdọ́ta-Èkó, méjìlá-Gombe, mẹ̩́sàn-án-Bauchi, mé̩sàn-án-Sokoto, méje-Borno, méje-Edo, méfà-Rivers, méfà-Ògùn, mẹ́rin-Àbújá, mẹ́rin-Akwa Ibom, mẹ́rin-Bayelsa, mẹ́ta-Kaduna, méjì-Òyó, méjì-Delta, méjì-Nasarawa, Ò̩kan-Òǹdó, Ò̩kan-Kebbi. Ní agogo méjìlá ku ìṣéjú mẹ́wàá, ọgbọ̀n ọjo oṣú igbe – 1932 alárùn Covid-19 farahàn ní Nàìjíríà. --- COVID-19: Iko osise minisita ti Kano sagbekale iroyin gba-a-gbe --- COVID-19: Ikò̩ òṣìṣé mínísítà ti Kano s̩àgbékalè̩ ìròyìn gbà-á-gbè̩ Iko osise minisita lori ise iwadii si Kano, ti se agbekale iroyin gba-a-gbe fun ile-ise ijoba apapo ti ilera, lori idi, okun ati ailera ona ti ipinle Kano se n dahun. Ikò̩ ọ̀ṣìṣẹ́ mínísítà lóri is̩é̩ ìwádìí sí Kano, ti s̩e àgbékalè̩ ìròyìn gbà-á-gbè̩ fun ilé-iṣẹ́ ìjọba àpapọ̀ ti ìlera, lórí ìdí, okun àti àìlera ọ̀nà tí ìpínlẹ̀ Kano ṣe ń dáhùn. Minisita fun ilera, Dokita Osagie Ehanire soyi ninu ipade apapo pelu awon oniroyin eyi ti igbimo ijoba apapo to n mojuto COVID-19 ni Abuja se. Mínísítà fún ìlera, Dókítà Osagie Ehanire sò̩yí nínú ìpàdé àpapọ̀ pẹ̀lú àwọn oníròyìn èyí tí ìgbìmọ̀ ìjọba àpapọ tó ń mójútó COVID-19 ní Àbújá ṣe. O ni bi ile-ise ijoba apapo se n reti iroyin kikun, iroyin gba-a-be yii yoo je atona ninu iranwo fun iko agbogunti Covid-19 ti Kano pelu eroja to ye, idanilekoo ati awon eniyan aranilowo. Ó ní bí ilé-iṣé ìjọba àpapọ s̩e ń retí ìròyìn kíkún, ìròyìn gbà-á-bè̩ yìí yóò jẹ́ ató̩nà nínú ìrànwọ́ fún ikò̩ agbógunti Covid-19 ti Kano pèlú èròja to ye̩, ìdánilé̩kò̩ó̩ àti àwo̩n ènìyàn araniló̩wó̩. “ Lara awon ohun iranwo ni kiko ati riran awon egbe onimo lati FMOH ati awon onimo nipa kokoro aarun lati ile-iwosan Irrua Specialist Hospital lati darapo mo egbe onimo ile-ise eto ilera ni ipinle Eko ti o ti n sise ni ipinle Kano nitori Gomina ipinle Kano” “ Lára àwọn ohun ìrànwọ́ ni kíkó àti rírán àwọn ẹgbẹ́ onímọ̀ láti FMOH àti àwọn onímọ̀ nípa kòkòrò ààrùn láti ilé-ìwòsàn Irrua Specialist Hospital láti darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ onímọ̀ ilé-iṣẹ́ ètò ìlera ní ìpínlẹ̀ Èkó tí ó ti ń ṣiṣẹ́ ní ìpínlẹ̀ Kano nítorí Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano” Gege bi idahun, o tun so pe awon onimo oniriiri yoo po jaburata ni ikale lati kin awon osise isaaju leyin ni ipinle Kano. Gé̩gé̩ bi ìdáhùn, ó tún so̩ pé àwọn onímọ̀ onírìírí yóò pò̩ jaburata ní ìkàlè̩ láti kin àwo̩n òs̩ìs̩é̩ ìs̩áájú lé̩yìn ní ìpínlẹ̀ Kano. “Egbe onisegun to n dahun ipe pajawiri lati FMOH ti kuro ni Abuja pelu awon ambulansi, marun-un ni ajo eso oju popo (FRSC) fi tore, lona lati lo si ipinle Kano fun idahun pajawiri latarii ase konilegbele. “E̩gbẹ́ oníṣègùn tó ń dáhùn ìpè pàjáwìrì lati FMOH ti kúrò ní Àbújá pẹ̀lú àwo̩n áḿbúlàǹsì, márùn-ún ni àjọ ẹ̀ṣọ́ ojú pópó (FRSC) fi to̩re̩, lọ́nà láti lọ sí ìpínlẹ̀ Kano fún ìdáhùn pàjáwìrì látàríi àṣẹ kónílégbélé. Dokita Ehanire tun sodi ti awon osise ilera se gbodo tele awon ilana ipara-eni-mo fun aarun ni gbogbo igba, ki won maa si fi emi won wewu. Dókítà Ehanire tún sọ̀dí tí àwọn òṣìṣé ìlera ṣe gbọ́dọ̀ tẹ̀lé àwọn ìlànà ìpara-ẹni-mọ́ fún ààrùn ní gbogbo ìgbà, kí wọ́n máa sì fi ẹ̀mí wọn wéwu. “A ko lee gba lati padanu awon osise pataki niru akoko bayii; gbogbo eniyan ni won gbodo toju pelu ifura to ga fun COVID-19 sugbon ki won toju gbogbo eniyan lai sojusaaju ki awon elomiran pelu aisan ma baa jiya aidasi tabi ki won ma toju won.” “A kò leè gbà láti pàdánù àwọn òṣìṣẹ́ pàtàkì nírú àkókò báyìí; gbogbo ènìyàn ni wọ́n gbọ́dọ̀ tó̩jú pẹ̀lú ìfura tó ga fún COVID-19 sùgbọ́n kí wọ́n tójú gbogbo ènìyàn láì s̩ojús̩àájú kí àwọn elòmíràn pẹ̀lú àìsàn má baà jìyà àìdásí tàbí kí wọ́n má tó̩jú wọn.” O wipe, “O je ohun aidara lati le awon eniyan lo laisi imoran nipa eto ilera tabi ki a fi itoju du eni ti o nilo itoju ni pajawiri.” Ó wípé, “Ó jẹ́ ohun àìdára láti lé àwọn ènìyàn lọ láìsí ìmọ̀ràn nípa ètò ìlera tàbí kí á fi ìtọ́jú du ẹni tí ó nílò ìtọ́jú ní pàjáwìrì.” --- Sisi awon ile-eko ko tii farahan - Minisita --- S̩ís̩í àwo̩n ilé-è̩kó̩ kò tíì farahàn - Mínísítà Minisita ipinle fun eto eko, Emeka Nwajiuba ni oun ko lee sojo tabi igba ti won yoo pada si ile-eko. Mínísítà ìpínlẹ̣̀ fún ètò ẹ̣̀kọ̣́, Emeka Nwajiuba ní òun kò leè sọjọ́ tàbí ìgbà tí wọn yóò padà ṣí ilé-è̩kó̩. Minisita tesiwaju pe sisi awon ile-eko yoo je ni sise-n-tele pelu bi Aare Muhammadu Buhari se n gbese kuro lori ase konile–gbele ti o wa lati kapa aarun korona. Mínísítà tẹ̣̀síwájú pé ṣíṣí àwọn ilé-è̩kó̩ yóò jẹ́ ní sísẹ̀-n-tẹ̀lé pẹ̀lú bí Ààrẹ Muhammadu Buhari ṣe ń gbẹ́sẹ̀ kúrò lórí àṣẹ kónílé–gbélé tí ó wà láti kápá ààrùn kòrónà. Nwajiuba, ninu oro re lojojumo ti so saaju wipe ijoba ko setan lati fi emi awon omo wewu, o wa kilo wipe ile-eko kokan ko gbodo bere eto eko nile-eko won ayafi ojo ti ijoba ba kede re pe ki ile-eko wole. Nwajiuba, nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ lójojúmọ́ ti sọ s̩áájú wípé ìjọ̣̣ba kò ṣetán láti fi ẹ̣̀mí àwọ̣̣̣̣n o̩mo̩ wéwu, ó wá kìlọ̀ wípé ilé-è̩kó̩ kọkan kò gbọdọ̀ bẹ̀rẹ̀ ètò ẹ̀kọ́ nílé-è̩kó̩ wọ̣̣n àyàfi ọjọ́ tí ìjọ̣̣ba bá kéde rẹ̀ pé kí ilé-è̩kó̩ wọlé. “Ni kukuru, ko si eyikeyi ninu awon ile-eko yii to le si leyin odi. “Ní kúkurú, kò sí èyíkèyí nínú àwo̩n ilé-è̩kó̩ yìí tó le s̩í lé̩yìn odi. Minisita tun so pe gbogbo awon idanwo igbaniwole ti won ti sun siwaju ni yoo di sise nigba ti ijoba ba ri daju pe gbogbo eto-eko ti won gbekale lo ye awon akekoo. Mínísítà tún so̩ pé gbogbo àwọ̣̣n ìdánwò ìgbaniwọlé tí wọ́n ti sún síwájú ni yóò di ṣíṣe nígbà tí ìjọba bá ri dájú pé gbogbo ètò-ẹ̀kọ́ tí wó̩n gbékalè̩ ló yé àwọn akẹ́kọ̀ó̩. Minisita se alaye pe idanwo awon akekoo oniweemewaa (WAEC) ati awon idanwo apapo (NECO) pelu NABTEB ni ko i di fifagile sugbon ti won sun siwaju. Mínísítà ṣe àlàyé pé ìdánwò àwọn akẹ́kọ̀ọ́ oníwèémẹwàá (WAEC) àti àwọn ìdánwò àpapọ̀ (NECO) pẹ̀lu NABTEB ni kò ì di fífagilé sùgbọ́n tí wó̩n sún síwájú. O soro nipa ipenija ti eko ori ayelujara ti a sese mu wole ati bi a se mu eto eko gbogboogbo ni ipinle lo. Ó sọ̀rọ̀ nípa ìpèníjà tí ẹ̀kọ́ orí ayélujára tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mú wọlé àti bí a ṣe mú ètò ẹ̀kọ́ gbogboogbò ní ìpínlẹ̀ lò. Gege bi o se so, “A mo wipe awon kan ko ni anfaani ati aiko ni anfaani yii nitori aiko ni ero to kun oju osuwon, awon kan le tesiwaju ninu eko won lori redio, awon kan lori telifisan, awon kan si n lo ero ayara-bi-asa pelu ayelujara, nitori naa a n se eyi pelu ajosisepo ijoba ipinle, eyi tumo si pe gbogbo alafo ti a fe di to niise pelu eko awon omo jakejado orile-ede yii, a nilo lati gba odo Gomina ipinle kookan nipase ajo eko alakoobere kariaye SUBEBS” Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe sọ, “A mọ̀ wípé àwọn kan kò ni àǹfààní àti àìkò ní àǹfààní yìí nítorí àìkò ní ẹ̀rọ tó kún ojú òsùwọ̀n, àwọn kan le tẹsíwájú nínú ẹ̀kọ́ wọn lórí rédíò, àwọn kan lórí te̩lifís̩àn, àwọn kan sì ń lo ẹ̀rọ ayára-bí-àsá pẹ̀lú ayélujára, nítorí náà à ń ṣe èyí pẹ̀lú àjọṣiṣẹ́pọ̀ ìjọba ìpínlẹ, èyí túmọ̀ sí pé gbogbo àlàfo tí a fe̩ dí tó nííṣe pẹ̀lú ẹ̀kọ́ àwọn ọmọ jákèjádò orílẹ̀-èdè yìí, a nílò láti gba ọ̀dọ̀ Gómìnà ìpínlẹ̀ kọ̀ọ̀kan nípaṣè àjọ ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ káríayé SUBEBS” """Ni bayii a ti ni eto ilana eko fun awon ipinle mokanlelogbon ninu ipinle merindinlogoji, eyi tumo si wipe lati ori redio tabi telifisan, ikoni ati ikekoo n lo, eyi je awon ilana ikekoo to dara fun ipinle kookan sugbon ijoba apapo ti se ilana lati ori ayelujara.”" """Ní báyìí a ti ní ètò ìlànà ẹ̣̀kọ̣́ fún àwọ̣̣n ìpínlẹ̀ mọ̣́kànlélọ̣́gbọ̀n nínú ìpínlẹ̀ mẹ̣̣́rìndínlógóji, èyí túmọ̀ sí wípé láti orí rédíò tàbí te̩lifís̩àn, ìkọ́ni àti ìkẹ́kọ̀ọ́ n lọ, èyí jẹ́ àwo̩n ìlànà ìkẹ́kò̩ọ́ tó dára fún ìpínlẹ kọ̀ọ̀kan sùgbọ́n ìjọba àpapọ̀ ti ṣe ìlànà láti orí ayélujára.”" Nwajiuba so wipe “Lilo awon SUBEB, ona ti a n gba momi ogbon won ni a se fi pin kiko ati mimo yii lori ero ayelujara. Ijoba apapo si so wipe won lee lo awon ile-ise igbohun safefe ti ipinle won to dara fun un”. Nwajiuba sọ wípé “Lílo àwo̩n SUBEB, ọ̀nà tí à ń gbà momi o̩gbó̩n wo̩n ni a ṣe fi pín kíkọ́ àti mímọ̀ yìí lórí ẹ̀rọ ayélujára. Ìjọba àpapọ̀ sì sọ wípé wọ́n leè lo àwọn ilé-iṣẹ́ ìgbóhùn sáfẹ́fẹ́ ti ìpínlẹ̀ wo̩n tó dára fún un”. Minisita safikun pe ajakale aarun COVID-19 ti ran awon olokoowo gbogbo lowo lati tunramu, o si ti ran enikookan lati bo soju ise. Mínísítà s̩àfikún pé àjàkálẹ̀ ààrùn COVID-19 ti ran àwọn olókoòwò gbogbo lọ́wọ́ láti túnramú, ó sì ti ran ẹnìkọ̀ọ̀kan láti bọ́ sójú iṣẹ́. Nigba to n soro lori imuduro eko lori ayelujara, minisita so wipe ijoba yoo tunbo samulo awon oluko akosemose ti yoo sasepe eto naa ti yoo lee mu u wulo leyin ipenija aarun korona to koju agbaaye. Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ lórí ìmúdúró ẹ̀kọ́ lórí ayélujára, mínísítà sọ wípé ìjọba yóò túnbọ̀ ṣàmúlò àwọn olùkọ́ akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ tí yóò ṣàṣepé ètò náà tí yóò leè mú u wúlò lẹ́yìn ìpèníjà ààrun kòrónà tó kojú àgbááyé. Bakan naa, ile-ise eko to n samojuto awon ile-eko ni olu-ilu FCTA, se ikilo fun awon ile-eko aladaani ti won n dajo iwole taamu keta fun 2019/2020 lori ero ayelujara fun awon obi ati akekoo. Bákan náà, ilé-iṣẹ́ ẹ̀kọ́ tó ń ṣàmójútó àwọn ilé-è̩kó̩ ní olú-ìlú FCTA, ṣe ìkìlọ̀ fún àwọn ilé-è̩kó̩ aládàáni tí wọ́n ń dájọ́ ìwọlé táàmù kẹta fún 2019/2020 lórí ẹ̀rọ ayélujára fún àwọn òbí àti akẹ́kọ̀ọ́. Akowe ile-ise ajo to n mojuto ile-eko, Umaru Marafa so ninu atejade ojo isegun wipe ko si ise ikekoo kokan ni ile-eko kookan lonakona to gbodo bere titi di igba ti ase sisi ile iwe ba jade. Akọ̀wé ilé-iṣẹ́ àjọ tó ń mójútó ilé-è̩kó̩, Umaru Marafa sọ nínú àtẹ̀jáde ọjọ́ ìṣẹ́gun wípé kò sí iṣẹ́ ìkẹ́kọ̀ọ́ kọ̀kan ní ilé-è̩kó̩ kọ̀ọ̀kan lọ́nàkọnà tó gbọ́dọ̀ bẹ̀rẹ̀ títí di ìgbà tí àṣẹ s̩ís̩í ilé ìwé bá jáde. Marafa so pe, “Itumo eyi ni pe nigba ti awon ile-eko yoo ba di sisi pada, ifilo ti o ye ni yoo ti wa lori taamu keji ti ko pari, ati ona ati runmo taamu keta bi o ti ye. Igbese to ba lodi si eyi seese ko koba eto eko awon ile-eko to kan. Marafa so̩ pé, “Ìtumò̩ èyí ni pé nígbà tí àwọn ilé-è̩kó̩ yóò bá di s̩ís̩í padà, ìfilọ̀ tí ó yé̩ ni yóò ti wà lórí táàmù kejì tí kò parí, àti ò̩nà àti runmó̩ táàmù kẹta bí ó ti yẹ. Ìgbésè̩ tó bá lòdì sí èyí ṣeéṣe kó kóbá ètò ẹ̀kọ́ àwọn ilé-è̩kó̩ tó kàn. Won ro awon oga ile-eko alaadani lati sowe-agbeje-mowo ki ile-eko won si wa latipa, ki won ma se si ni onakona titi ijoba yoo fi sohun miiran. Wó̩n ro̩ àwọn ọ̀gá ilé-è̩kó̩ aláàdáni láti sowé-agbéjé̩-mó̩wó̩ kí ilé-è̩kó̩ wò̩n sì wà látìpa, kí wọ́n má s̩e si ní ọ̀nàkọnà títí ìjò̩ba yóò fi sohun mìíràn. Awon ti won ba se lodi si ase yii yoo dojuko idajo ofin ponnbele; Àwọn tí wọ́n bá ṣe lòdì sí àṣẹ yìí yóò dojúkọ ìdájọ́ òfin pó̩nńbélé; Marafa tun so wipe ile-ise eko ijoba apapo ti pari gbogbo eto lati lee mu eto eko lori ayelujara wonu eto eko yala lori redio tabi telifisan ki awon akekoo lee maa sise nigbogbo igba ti konile gbele ba fiwa. Marafa tún sọ wípé ilé-iṣẹ́ ẹ̀kọ́ ìjọba àpapọ̀ ti parí gbogbo ètò láti leè mú ètò ẹ̀kọ́ lórí ayélujára w̩onú èto ẹ̀kọ́ yálà lóri rédíò tàbí te̩lifís̩àn kí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ leè máa ṣiṣẹ́ nígbogbo ìgbà tí kónílé gbélé bá fiwà. --- Ko gbodo si ile-iwe aladaani kankan to gbodo bere ise – Minisita FCT --- Kò gbọ̣̣̣̣̣dọ̣̀ ṣí ilé-ìwé aládàáni kankan tó gbọ̣́dọ̣̀ bẹ̣̀rẹ̣̀ isẹ̣́ – Mínísítà FCT Minisita fun olu-ilu Naijiria, Alhaji Muhammad Musa Bello ti sekilo fun gbogbo awon oludari ile-iwe aladaani to wa niluu Abuja ti won ti n so fun gbogbo awon obi ati akekoo pe won ko ni pe bere ise laipe fun saa keta fun ti odun 2019/2020 ti a wayii lati sora, ki won maa ba foju wina ofin ijoba. Mínísítà fún olú-ìlú Nàìjíríà, Alhaji Muhammad Músá Bello ti ṣ̣èkìlọ̀ fún gbogbo àwọ̣̣n olùdarí ilé-ìwé aládàáni tó wà nílùú Àbújá tí wọ́n ti ń sọ̣̣ fún gbogbo àwọ̣̣n òbí àti akẹ̣̣́kọ̣̀ọ́ pé wọ̣̣n kò ní pẹ́ bẹ̣̀rẹ̣̀ iṣ̣ẹ́ láìpẹ̣́ fún sáà kẹ̣̣ta fún ti ọ̣dún 2019/2020 tí a wàyìí láti ṣ̣ọ̣̣́ra, kí wọ̣̣́n máa ba fojụ winá òfin ìjọ̣̣ba. Akowe agba fun eto eko niluu Abuja, Umaru Marafa lo soro yii ninu atejade kan ti o gbe jade lojo isegun pe eto eko ko ni tii bere nile iwe kankan to wa niluu Abuja bayii ayafi ojo ti ile-ise akowe agba fun eto eko ba fowosi. Akọ̣̣̀wé àgbà fún ètò ẹ̣̣̀kọ́ nílùú Àbújá, Umaru Máráfá ló sọ̣̣̀rọ̣̣̀ yíì nínú àtẹ̀jáde kan tí ó gbé jáde lọ̣̣́jọ́ ìṣ̣ẹ̣̣́gun pé ètò ẹ̣̣̀kọ́ kò ní tíì bẹ̣̣̀rẹ̀ nílé ìwé kankan tó wà nílùú Àbújá báyìí àyàfi ọjọ́ tí ilé-iṣ̣ẹ́ akọ̀wé àgbà fún ètò ẹ̣̣̀kọ́ bá fọ̣̣wọ̣̣́si. """A n ro gbogbo awon oludari ile-eko aladaani lati je ki ile-eko wa ni titipa, won ko gbodo gbiyanju lati si ile-eko naa afi ti ase tabi ilana ba wa lati odo ile-ise FCTA.""" """À ń rọ̣̣ gbogbo àwọ̣̣n olùdarí ilé-è̩kó̩ aládàáni láti jẹ́ kí ilé-è̩kó̩ wà ní títìpa, wọn kò gbọ̣̣̣dọ̣̣̀ gbìyànjú láti ṣí ilé-è̩kó̩ náà àfi tí àṣ̣ẹ̣̣ tàbí ìlànà bá wá láti ọ̀dọ̀ ilé-iṣ̣ẹ́ FCTA.""" Gbogbo awon to ba tapa sofin yii ni yoo foju wina ofin ijoba. Gbogbo àwọ̣̣n tó bá tàpá ṣófin yìí ni yóò fojú winá òfin ìjọ̣̣ba. Marafa tesiwaju pe ile-ise FCTA ti o n mojuto eto eko ti se eto lati bere eto eko nipa lilo imo ayelujara, ati sise amulo telifisan lati fi ko awon akekoo ni akoko konile-gbele. Máràfá tẹ̀síwájú pé ilé-iṣ̣ẹ́ FCTA tí ó ń mójútó ètò ẹ̣̀kọ́ ti s̩e ètò láti bẹ̀rẹ̀ ètò ẹ̀kọ́ nípa lílo ìmọ̀ ayélujára, àti s̩ís̩e àmúlò te̩lifís̩àn láti fi kọ̣́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ní àkókò kónílé-gbélé. --- ORO AARE MUHAMMADU BUHARI LORI TELIFISAN SOMO NAIJIRIA --- Ọ̀RỌ̀ ÀÀRẸ MUHAMMADU BUHARI LÓRI TE̩LIFÍS̩ÀN SỌ́MỌ NÀÌJÍRÍÀ ORO AARE ORILE-EDE NAIJIRIA, MUHAMMADU BUHARI, NIPA OFIN KONILE-GBELE NI IPINLE EKO, OGUN ATI ILU ABUJA, FCT, LORI ITANKALE AARUN COVID- 19, NI EYI TI O WAYE NI ILU ABUJA LOJO AJE, OJO KETADINLOGBON, OSU KERIN ,ODUN 2020 (MONDAY, 27th APRIL, 2020). Ọ̀RỌ̀ ÀÀRẸ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀ̀ÌJÍRÍÀ, MUHAMMADU BUHARI, NÍPA ÒFIN KÓNÍLÉ-GBÉLÉ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ, ÒGÙN ÀTI ÌLÚ ÀBÚJÁ, FCT, LÓRI ÌTÀNKÁLẸ̀ ÀÀRÙN COVID- 19, NÍ ÈYÍ TÍ Ó WÁYÉ NÍ ÌLÚ ÀBÚJÁ LỌ́JỌ́ AJÉ, ỌJÓ̩ KẸTÀDÍNLỌ́GBỌ́N, OSÙ KẸRIN ,ỌDÚN 2020 (MONDAY, 27th APRIL, 2020). 1.Omo Naijiria 1.O̩mọ Nàìjíríà 2.Maa bere pelu gbigbosuba fun yin nitori iwa akinkanju ati ijoloooto yin eyi te safihan ninu ija ajumoja si ipenija ilera to gaju, to n koju iran wa. 2.Màá bẹ̀rẹ̀ pè̩lú gbígbós̩ùbà fun yín nítorí ìwà akínkanjú àti ìjólóòótọ́ yín èyí tẹ s̩àfihàn nínú ìjà àjùmò̩jà sí ìpèníjà ìlera tó gajù, tó ń kojú ìran wa. 3.Niwoyi ana, 26th April 2020, agbaye sawari awon alarun Covid-19 milionu meta, ti eedegbaarun lona egberun eniyan si ti gbawosan. O seni laaanu pe igba lona egberun eniyan lo tipase aarun naa papoda. 3.Níwòyí àná, 26th April 2020, àgbáyé s̩àwárí àwo̩n alárùn Covid-19 míĺiọ̣́nù mẹ́ta, tí ẹ̀ẹ́dẹ́gbààrún ló̩nà e̩gbè̩rún ènìyàn sì ti gbàwòsàn. Ó ṣeni láàánú pé igba ló̩nà e̩gbè̩rún ènìyàn ló tipasè̩ ààrùn náà papò̩dà. 4.Eto ilera ati oro aje opolopo orile ede ni o si n tiraka latari ajakale aarun kokoro korona. 4.Ètò ìlera àti ọrọ̀ ajé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdè ni ó sì ń tiraka látàrí àjàkálẹ́ ààrùn kòkòrò kòrónà. 5.Naijiria n tesiwaju lati maa mo awon ooto titun to n suyo lagbaaye lojoojumo. Lonii, n o so awon otito bo se je, n o si salaye awon eto wa fun awon osu to n bo nigbati a ti mo wipe awon ohun kan le yipada lawon ojo atose to n bo. 5.Nàìjíríà ń tẹ̀síwájú láti máa mọ àwọn òótọ́ titun tó ń súyo̩ lágbàáyé lójoojúmó̩. Lónìí, n ó sọ àwọn òtítọ́ bó ṣe jẹ́, n ó sì ṣàl̀àyé àwọn ètò wa fún àwọn oṣu tó ń bọ̀ nígb̀atí a tí mọ̀ wípé àwọn ohun kan lè yípadà láwọn ọjọ́ àtọ̀sẹ̀ tó ń bọ̀. 6.Ni deede ose meji seyin, onikorona okooleloodunrun le meta ni won sawari nipininle ogun ati olu-ilu. 6.Ní déédé ọ̀sẹ̀ méjì sẹ́yìn, oníkòrónà okòóléló̩ò̩dúnrún lé mé̩ta ni wó̩n s̩àwárí nípìnínlè̩ ogún àti olú-ìlú. 7.`Lowuuro yii, Naijiria ti lakosile aadorinleleegbefa-le-meta alarun nipininle mejilelogbon ati olu-ilu. O seni laanu pe ogoji lo ti papoda. 7.`Lówùúrọ̀ yìí, Nàìjíríà ti lákọsílẹ̀ àádó̩rinlélè̩é̩gbé̩fà-lé-mé̩ta alárùn nípìnínlè̩ méjìlélọ́gbọ̀n àti olú-ìlú. Ó ṣeni láànú pé ogójì ló ti papòdà. 8.Mo n lo anfaani yii lati fi ibanikedun wa han pelu awon ebi omo orile-ede Naijiria gbogbo ti won padanu awon ololufe won latari ajakale aarun COVID-19. Eyi je adanu wa papo, a si pin ninu ibanuje yin. 8.Mò ń lo àǹfààní yìí láti fi ìbánikẹ́dùn wa hàn pẹ̀lú àwọn ẹbí ọmọ orílè̩-èdè Nàìjíríà gbogbo tí wọ́n pàdánù àwọn olólùfẹ́ wọn látàrí àjàkálẹ̀ ààrùn COVID-19. Èyí jẹ́ àdánù wa papọ̀, a sì pín nínú ìbànújẹ́ yín. 9.Awoye ibere ni pe Naijiria maa ni egbaa akosile alarun ni osu akoko leyin ti won ri alarun akoko. 9.Àwòye ìbè̩rè̩ ni pé Nàìjíríà máa ní e̩gbàá àko̩sílè̩ alárùn ní oṣù àkọ́kọ́ lé̩yìn tí wọ́n rí alárùn àkó̩kó̩. 10.Eyi ni pe bi iye awon ti ayewo so pe won ni aarun korona ni ose meji seyin ti po to, awon ohun ta ti sagbekale ti mu eso rere jade lodi siwoye ana. 10.Èyí ni pé bí iye àwọn tí àyẹ̀wò so̩ pé wọ́n ní ààrùn kòrónà ní ọ̀sẹ̀ méjì sẹ́yìn ti pọ̀ tó, àwọn ohun ta ti ṣàgbékalè̩ ti mú èso rere jáde lòdì síwòye àná. 11.Iye alarun korona to toke okun wa ti dinku sida mokandinlogun ninu ogorun-un awon alarun titun, eyi fihan pe titi enubode seso rere. Opolopo ni awon omo Naijiria to n padabo wale. A o tesiwaju ninu titepele mo ilana gbigba awon asesede gege bi ona lati gbogun taarun yii. 11.Iye alárùn kòrónà tó tòkè òkun wá ti dínkù sìdá mó̩kàndínlógún nínú o̩gó̩rùn-ún àwo̩n alárùn titun, èyí fihàn pé títi e̩nubodè sèso rere. Ò̩pò̩lo̩pò̩ ni àwo̩n o̩mo̩ Nàìjíríà tó ń padabò̩ wálé. A ó tẹ̀síwájú nínú títe̩pe̩le̩ mó̩ ìlànà gbígba àwo̩n as̩è̩s̩è̩dé gé̩gé̩ bi ọ̀nà láti gbógun tààrùn yìí. 12.Lonii, ajo amojuto ajakale aarun lorile ede Naijiria ti fi owo si awon ile iyewo meedogun to le se ayewo fun eniyan to to eedegbetala lojumo jakejado orile ede. 12.Lónìí, àjọ amójútó àjàkálẹ̀ ààrùn lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti fi ọwọ́ sí àwọn ilé ìyẹ̀wò mẹ́ẹ̀dógún tó lè ṣe àyẹ̀wò fún ènìyàn tó tó è̩é̩dé̩gbè̩tàlá lójúmọ́ jákèjádò orílẹ̀ èdè. 13.Latari esi yin, ijoba ipinle Eko ati ilu Abuja pelu atileyin ajo agbogun ti ajakale aarun ti se agbekale ibudo igbayewo oniruuuru. Won tun sagbeyewo ete isayewo ni awon yara ayewo lati le mu ki ayewo sise po si pelu ibudo ayewo aladaani ti o koju osunwon ti won fowosi. 13.Látàrí èsì yín, ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó àti ìlú Àbújá pẹ̀lú àtìlẹ́yìn àjọ agbógun ti àjàkálẹ̀ ààrùn ti ṣe àgbékalẹ̀ ibùdó ìgbàyèwò onírúúurú. Wọ́n tún ṣàgbéyẹ̀wò ète ìs̩àyè̩wò ní àwo̩n yàrá àyè̩wò láti lè mú kí àyè̩wò s̩ís̩e pò̩ sí pè̩lú ibùdó àyè̩wò aládàáni tí ó kojú òs̩ùnwò̩n tí wó̩n fo̩wó̩sí. 14.Opo awon ile-itoju gidi ati ibudo iyasoto titun tibere ise jakejado orile-ede yii, eyi si mu ki iye ibusun fe to egbeedogun. 14.Ọ̀pọ̀ àwọn ilé-ìtójú gidi àti ìbùdó ìyàsọ́tọ̀ titun tìbè̩rè̩ iṣẹ́ jákèjádò orílẹ̀-èdè yìí, èyí sì mú kí iye ìbùsùn fé̩ tó ẹgbẹ̀é̩dógún. 15.Mo yin awon Gomina ipinle fundaasile ibudo idasi ni pajawiri nipininle, idasile awon ibudo itoju tuntun ati ete biba awon eniyan soro gidigidi lori ewu to wa. 15.Mo yin àwo̩n Gómìnà ìpínlẹ̀ fúndàásílẹ̀ ibùdó ìdásí ní pàjáwìrì nípìnínlẹ̀, ìdásílẹ̀ àwọn ibùdó ìtójú tuntun àti ète bíba àwo̩n ènìyàn sò̩rò̩ gidigidi lórí ewu tó wà. 16.Egberun mewaa osise ilera le, la ti ko. Fun aabo won, awon elo idaabobo miiran la ti fi sowo sawon ipinle. 16.E̩gbẹ̀rún mẹ́wàá òṣìṣẹ́ ìlera lé, la ti kọ́. Fún ààbò won, àwọn èlò ìdáàbòbò mìíràn la ti fi s̩o̩wó̩ sáwo̩n ìpínlẹ̀. 17.Nitooto a ti ni iriri awon ipenija kan, a duro digbi lori sisagbekale ipese ti o munadoko ki awon osise yii sise laisi ewu pelu isora pipe. 17.Nítòótọ́ a ti ní ìrírí àwọn ìpèníjà kan, a dúró digbi lóri s̩ís̩àgbékalè̩ ìpèsè tí ó múnádoko kí àwo̩n òs̩ìs̩é̩ yìí s̩is̩é̩ láìsí ewu pè̩lú ìs̩o̩ra pípé. 18.Ni mimu ileri ijoba wa se lati mu ki igbe aye awon osise ilera wa dara si, a ti fi owo si iwe adehun oloye fun ipese owo ifemiwewu ati awon owo miiran pelu awon egbe akosemose eka eto ilera ti o se koko. 18.́Ni mímú ìlérí ìjọba wa ṣe láti mú kí ìgbé ayé àwọn òṣìṣẹ́ ìlera wa dára si, a ti fi ọwọ́ sí ìwé àdéhùn olóye fún ìpèsè owó ìfẹ̀míwewu àti àwọn owó mìíràn pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ ẹ̀ka ètò ìlera tí ó ṣe kókọ. 19.A ti seto idojutofo fun awon osise ilera to n lewaju bii egberun marun-un. Nikoorita yii mo gbodo ki awon osise adojutofo fun atileyin won ni sise eyi laarin akoko die. 19.A ti s̩ètò ìdójútòfò fún àwọn òṣìṣẹ́ ìlera tó ń léwájú bíi ẹgbẹ̀rún márùn-ún. Níkòóríta yìí mo gbọ́dọ̀ kí àwọn òṣìṣẹ́ adójútòfò fún àtìlẹyìn wọn ní ṣíṣe èyí láàrín àkókò díè. 20.Naijiria si n gbaranlowo lati awon orile agbaye lati awon ile-ise kaakiri, egbe aladaani ati enikookan. Atileyin yii ti je kawon irinse atohun elo ta fi n doola emi, eyi to sowon ni agbaye ti wa fun Naijiria latipase awon ajo to n se irinse gidi ateto ijoba-si-ijoba. 20.Nàìj́iríà sì ń gbàrànlọ́wọ́ láti àwọn orílẹ̀ àgbáyé láti àwọn ilé-iṣẹ́ káàkiri, ẹgbẹ́ aládàáni àti ẹnìkọ̀ọ̀kan. Àtìlẹyìn yìí ti jẹ́ káwọn irinṣẹ́ àtohun èlò ta fi ń dóòlà ẹ̀mí, èyí tó sò̩wọ́n ní àgbáyé ti wà fún Nàìjírị́à látipaṣẹ̀ àwọn àjọ tó ń ṣe irinṣẹ́ gidi àtètò ìjọba-sí-ìjọba. 21.Pinpin ati igbooro awon ohun itura lasiko konile -gbele ti mo so ninu ikede isaaju si n tesiwaju laileeeru ninu. Mo mo isuni ti awon omo orile-ede yii to n reti re n koju. Mo ro gbogbo eyin anipin-in ninu re lati ni suuru bi a ti n wa ona to dara lati pin pelu awon ijoba ipinle. 21.Pínpín àti ìgbòòrò àwọn ohun ìtura lásìkò kónílé -gbélé tí mo sọ nínú ìkéde ìs̩áájú sì ń tẹ̀síwájú láìléèérú nínú. Mo mọ ìsúni tí àwọn ọmọ orílẹ-èdè yìí tó ń retí rẹ̀ ń kojú. Mo ṛo̩ gbogbo ẹ̀yin anípìn-ín nínú rẹ̀ láti ni ́sùúrù bí a ti ń wá ọ̀nà tó dára láti pín pẹ̀lu àwọn ìjọba ìpínlẹ̀. 22.Awon osise alaboo wa tesiwaju lati dide sipenija asiko ajoniloju yii. Bo tile je pe isele aabo ibudo iyasoto dun wa gan-an, mo fe fiye omo Naijiria pe aabo ati eso yin je akoko si wa, paapaa julo ni akoko lile oun aimo yii. 22.Àwọn òṣìṣẹ́ alábòò wa tẹ́síwájú láti dìde sípèníjà àsìkò ajo̩nilójú yìí. Bó tilè̩ jé̩ pé ìs̩è̩lè̩ ààbò ibùdó ìyàsó̩tò̩ dùn wá gan-an, mo fẹ́ fiyé ọmọ Nàìjíríà pé ààbò àti è̩s̩ó̩ yín jé̩ àkó̩kó̩ sí wa, pàápàá jùlọ ní àkókò líle òun àìmò̩ yìí. 23.Ba se n bojuto aabo emi ati dukia a ko ni faaye gba i-te-eto-omoniyan mole lati odo osise alaabo. Awon iroyin isele die ta a gbo je eyi to seni laaanu, mo si fe fi daa yin loju pe a o mu awon odaran naa lati koju idajo ofin. 23.Bá ṣe ń bójútó ààbò è̩mí àti dúkìá a kò ní fààyè gba ì-tẹ-ẹ̀tọ́-ọmọnìyàn mólẹ̀ láti ọ̀dọ̀ òṣìṣẹ́ aláàbò. Àwọn ìròyìn ìṣẹ̀lẹ̀ díẹ̀ tá a gbọ́ jẹ́ èyí tó ṣeni láàánú, mo sì fẹ́ fi dáa yín lójú pé a ó mú àwọn ọ̀daràn náà láti kojú ìdájọ òfin. 24.Mo ro gbogbo omo Naijiria lati tesiwaju ninu ifowosowopo ati ifoyehan ninu ipade won ati osise alaabo. Siwaju si, fun aabo won, mo ti pase pe ki won fun awon osise alaabo wonyi ni irinse idaabobo ara won lowo akoran aarun yii. 24.Mo rọ gbogbo ọmọ Nàìjíríà láti tẹ̀síwájú nínú ìfọwọ́sowọ́pọ̀ àti ìfòyehàn nínú ìpàdé wo̩n àti òṣìṣẹ́ aláàbò. Síwájú si, fún ààbò wọn, mo ti pàṣẹ pé kí wó̩n fún àwọn òṣìṣẹ́ aláàbò wọ̀nyí ní irinṣẹ́ ìdáàbòbò ara wo̩n lọ́wọ́ àkóràn ààrùn yìí. 25.Ba ti n tesiwaju lati mu adinkun ba idahun wa lawon ibudo tEko atAbuja, isele ni Kano laipe yii tun bami-ninu-je. Bo tile je pe iwadii kikun n tesiwaju, a ti pinnu lati safikun osise ijoba apapo, ohun elo ati iranwo peleke lati kin ati satileyin akitiyan ijoba ipinle, ni logan. 25.Bá ti ń tẹ̀síwájú láti mú àdínkùn bá ìdáhùn wa láwọn ibùdó tÈkó àtÀbújá, ìṣẹ̀lẹ̀ ní Kánò láìpẹ́ yìí tún bàmí-nínú-jẹ́. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwá̀díi kíkún ń tẹ̀síwájú, a ti pinnu láti s̩àfikún òṣìṣẹ́ ìjọba àpapọ̀, ohun èlò àti ìrànwó̩ peléke láti kín àti s̩àtìlẹ́yìn akitiyan ìjọba ìpínlẹ̀, ní ló̩gán. 26.Ni Kano, ati ipinle yooku to n sakosile alarun tuntun, iwadii akoko so pe awon esi ayewo yii nii se pelu irinajo ipinlesipininle ati itankale aarun niluu kan. 26.Ní Kánò, àti ìpínlẹ̀ yòókù tó ń s̩àkọsílẹ̀ alárùn tuntun, ìwádìí àkọ́kọ́ so pé àwọn èsì àyẹ̀wò yìí níí s̩e pè̩lú ìrìnàjò ìpínlẹ̀sípìnínlẹ̀ àti ìtànkálè̩ ààrùn nílùú kan. 27.Lati inu eyi, mo ro gbogbo omo Naijiria ki won o tesiwaju lati maa tele imoran awon iko amusese aare ati awon ajo ti o n mojuto aarun 27.Lati inú èyí, mo rọ gbogbo ọmọ Nàìjíríà kí wọ́n ó tẹ̀síwájú láti máa tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ikọ̀ amúṣẹ́ṣe ààrẹ àti àwọn àjo tí ó ń mójútó ààrùn 28.Awon eyi ni, fifowo loorekoore, jijina sira eni, lilo ibomu nigbangba, yiyago fun ode iwofun pelu irinajo ati yiyago fun ipejopo elero pupo. 28.Àwọn èyí ni, fífọwọ́ lóòrèkóòrè, jíjìnà síra e̩ni, lílo ìbomú nígbangba, yíyàgò fún òde ìwò̩fún pè̩lú ìrìnàjò àti yíyàgò fún ìpéjọpọ̀ elérò púpọ̀. 29.Eyin omo Naijiria, fun bi ose merin seyin lopolopo ibi lorileede wa labe ase konilegbele ti ijoba apapo tabi ti ijoba ipinle. Bi mo se so saaju, awon igbese yii se pataki ati pe o tun kopa ninu mimu adinku ba itankale Korona lorileede wa. 29.Ẹ̣̣̀yin ọmo Nàìjíríà, fún bí ọ̀sẹ̀ mẹ́rin sẹ́yìn lọ̀pọ̀lọpọ̀ ibì lórílẹ̀èdè wa lábẹ àṣẹ kónílégbélé ti ìjọba àpapọ̀ tàbí ti ìjọba ìpínlẹ̀. Bí mo s̩e sọ ṣáájú, àwọn ìgbésẹ̀ yìí ṣe pàtàkì àti pé ó tún kópa nínu mímú àdínkù bá ìtànkálè̩ Kòrónà lórílẹ̀èdè wa. 30.Sibesibe, iru ase konile gbele naa ti wa pelu eto isunna to po. Opolopo omo orileede wa ti padanu ona ijeun. Opolopo ise lo ti duro. Ko si orileede to le gba gbogbo akoba konile-gbele se nigba a n reti esi ayo lori abere ajesara. 30.Síbẹ̀síbẹ̀, irú àṣẹ kónílé gbélé náà ti wà pẹ̀lú ètò ìsúnná tó pọ̀. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ orílẹ̀èdè wa ti pàdánù ọ̀nà ìjẹun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ ló ti dúró. Kò sí orílẹ̀èdè tó lè gba gbogbo àkóbá kónílé-gbélé se nígbà à ń retí èsì ayò̩ lórí abẹ́rẹ́ àjẹsára. 31.Ninu oro asokeyin, mo ni ijoba apapo yoo sagbekale ete ati ofin ti yoo daabobo emi a si loraa igbe-aye. 31.Nínú ọ̀rọ̀ àsọkẹ́yìn, mo ní ìjọba àpapọ yóò ṣàgbékalẹ̀ ète àti òfin tí yóò dáàbòbò è̩mí á sì ló̩ràá ìgbé-ayé. 32.Laarin ose meji yii, ijoba apapo ati ipinle ti sise takuntakun papo lorii ona lati se idoogba didaboobo ilera ati titoju igbe aye, ni idogba pelu bi won ti n se ni gbaaye pelu iranti awon ohun iyato wa. 32.Láàrín ọ̀sẹ̀ méjì yìí, ìjọba àpapọ àti ìpínlẹ̀ ti ṣiṣẹ́ takuntakun papọ̀ lóríi ọ̀nà láti ṣe ìdó̩ó̩gba dídábòòbò ìlera àti tító̩jú ìgbé ayé, ní ìdó̩gba pẹ̀lu bí wọ́n ti ń ṣe ní gbàáyé pẹ̀lu ìrántí awon ohun ìyàtọ̀ wa. 33.A sagbeyewo bi awon ile-ise, oja, onisowo ati awon awako wa se lee tesiwaju ninu sise bakan naa ki won tele ilana ajo amojuto aarun lorileede yii lakale lori imototo ati jijinna sira eni. 33.A ṣàgbéyẹ̀wò bí àwọn ilé-iṣẹ, ọjà, oníṣòwò àti àwọn awakọ̀ wa ṣe leè tèsíwájú nínú ṣiṣẹ́ bákan náà kí wọ́n tèlé ìlànà àjo̩ amójútó ààrùn lórílèèdè yìí làkalè̩ lórí ìmó̩tótó àti jíjìnnà síra e̩ni. 34.A se agbeyewo itesiwaju ikekoo awon omo wa lai se akoba ilera won. 34.A ṣe àgbéyẹ̀wò ìtẹ̀síwájú ìké̩kò̩ó̩ àwo̩n o̩mo̩ wa láì s̩e àkóbá ìlera wo̩n. 35. A yiiri ona ti awon agbe wa se le gbin ki won si kore ni akoko ojo ki a le rip e ipese ounje ko ni akoba. Siwaju si, a tun soro lori igbounje alailewu lati igberiko lo si awon ile-ise isaayan re ati ibudo ijeun gboogi. 35. A yiiri ò̩nà tí àwo̩n àgbè̩ wa s̩e lè gbìn kí wó̩n sì kórè ní àkókò òjò kí á lè rip é ìpèsè oúnje̩ kò ní àkóbá. Síwájú sí, a tún sò̩rò̩ lóri ìgbóúnje̩ aláìléwu láti ìgbèríko lo̩ sí àwo̩n ilé-iṣẹ́ ìs̩ááyan rẹ̀ àti ibùdó ìje̩un gbòógì. 36.Afojusun wa ni ka wa ona ta a lo ti yoo je ki oro aje wa maa tesiwaju nigba ti a n wa idahun atewon sajaakale aarun korona. Ipinnu lile yii lawon olori gbogbo lagbaaaye n dojuko. 36.Àfojúsùn wa ni ká wá ò̩nà tá á lò ti yóò jé̩ kí o̩rò̩ ajé wa máa tè̩síwájú nígbà tí à ń wá ìdáhùn atè̩wò̩n sájàákálè̩ ààrùn kòrónà. Ìpinnu líle yìí làwo̩n olórí gbogbo lágbàááyé ń dojúko̩. 37.Nitori eyi ati iyanju awon iko aare lori COVID-19, orisirisi igbimo ijoba apapo to ti gbe oro isunna yewo ati igbimo awon gomina Naijiria, mo ti fowo si ki ofin konile-gbele niluu Abuja, Eko, ati ipinle Ogun ki o maa lole diedie ki o si bere lati ojo aje, ojo kerin, osu karun-un, 2020. 37.Nítorí èyí àti ìyànjú àwọn ikọ̀ ààrẹ lórí COVID-19, orísirísi ìgbìmọ̀ ìjọba àpapọ tó ti gbé ọ̀rọ̀ ìsúnná yẹ̀wò àti ìgbìmọ̀ àwọn gómìnà Nàìjíríà, mo ti fọwọ́ sí kí òfin kónílé-gbélé nílùú Àbújá, Èkó, àti ìpínlẹ̀ Ògùn kí ó máa lọlẹ̀ díẹ̀díẹ̀ kí ó sì bè̩rè̩ láti ọjọ́ ajé, ọjọ́ kẹrin, oṣù karùn-ún, 2020. 38.Sibe, ayewo sise ati sisawari awon alabaapade alarun korona yoo maa lo ni kankan, a o si mu ipadabosipo ba eto oro aje atokoowo lawon ibi kan. 38.Síbè̩, àyè̩wò s̩is̩é àti s̩ís̩àwárí àwo̩n alábàápàdé alárùn kòrónà yóò máa lo̩ ní kánkán, a ó sì mú ìpadàbòsípò bá ètò ọrọ̀ ajé àtokòòwò láwo̩n ibì kan. 39.Siwaju sii, ofin tuntun taa sagbekale kaakiri orileede niwonyi; 39.Síwájú síi, òfin tuntun táa s̩àgbékalè̩ káàkiri orílèèdè nìwọ̀nyí; a.Akoko aijade wa lati 8am si 6am. Eyi tumo si wipe ririn kaakiri yoo di eewo laarin akoko yii afi awon osise pataki. a.Àkókò àìjáde wà láti 8am si 6am. Èyí túmọ̀ sí wípé rírìn káàkiri yóò di èèwọ̀ láàrin àkókò yìí àfi àwọn òs̩ìs̩é̩ pàtàkì. b.Ko ni saaye fun irinajo alaisepataki laarin ipinlesiipinle titi di akoko aimo. b.Kò ní sááyè fún ìrìnàjò aláìs̩epàtàkì láarin ìpínlẹ̀síìpínlẹ̀ títí di àkókò àìmò̩. c.Gbigbe eru alamoojuto laarin ipinlesiipinle yoo wa die lati lee maa gbe awon eru lati ile-ise lo sodo awon ti yoo lo won. c.Gbígbé ẹrù alámòójútó láàrin ìpínlẹ̣̀síìpínlẹ̀ yóò wà díẹ̀ láti leè máa gbé àwọn ẹrù láti ilé-iṣé lọ sọ́dọ̀ àwọn tí yóò lò wọn. d.A o ri daju wipe a fi dandan si lilo iboju ni ita pelu bi a se n fi aaye saarin ara wa ati imototo. Ijoba ipinle, awon onile ise nla ati awon eleyinju aanu la ro lati se iranwo ni pipese awon aso ibomu fun awon omo orile ede yi. d.A ó ri dájú wípé a fi dandan sí lílo ìbòjú ní ìta pẹ̀lú bí a ṣe ń fi ààyè sáàrín ara wa àti ìmọ́tótó. Ìjọba ìpínlẹ̀, àwọn onílé iṣẹ́ ńlá àti àwọn ẹlẹ́yinjú àánú la rọ̀ láti ṣe ìrànwọ ní pípèsè àwọn aso ìbòmú fún àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè yí. 40.Nitori iyemeji, ofin konile-gbele niluu Abuja, ipinle Eko ati Ogun yoo wa titi di igba ti awon ofin miiran yoo fi beere lOjo aje, ojo kerin osu karun-un, 2020. 40.Nítorí iyèméjì, òfin kónílé-gbélé nílùú Àbújá, ìpínlẹ̀ Èkó àti Ògùn yóò wà títí di ìgbà tí àwọn òfin mìíràn yóó fi bẹ̀ẹ̀rẹ̀ lỌ́jọ́ ajé, ọjọ́ kẹrin oṣù karùn-ún, 2020. 41.Awon iko aare yoo pese awon alaye kan fun imura sile ijoba, awon olokoowo ati ile ise. 41.Àwọn ikọ̀ ààrẹ yóò pèsè àwọn àlàyé kan fún ìmúra sílẹ̀ ìjọba, àwọn olókoòwò àti ilé iṣẹ́. 42.Nibaamu awon ilana oke wonyi, ijoba ipinle lee yan lati faramo ati lati fee loju sii lori oniruuru isele arooto to ba suyo ki won saa ti wa nibaamu pelu ilana agbekale yii. 42.Níbàámu àwọn ìlànà òkè wò̩nyí, ìjọba ìpínlẹ̀ leè yàn láti faramọ́ àti láti fẹ̀ẹ́ lójú sii lórí onírúurú ìs̩è̩lè̩ àrò̩ò̩tò̩ tó bá súyo̩ kí wọ́n sáà ti wà níbàámu pẹ̀lú ìlànà àgbékalè̩ yìí. 43.Lati seranwo fun olokoowo atawon oloja wa, awon to wa nidii owo yoo dari ipese to ye kise lee tesiwaju, ka si muse padabo sipo. 43.Láti s̩èrànwó fún olókoòwò àtàwọn ọlọ́jà wa, àwọn tó wà nídìí owó yóò darí ìpèsè tó yẹ kíṣẹ́ leè tẹ̀síwájú, ká sì múṣẹ́ padàbò̩ sípò. 44.Awon ilana wonyi ko ni kan ipinle Kano. 44.Àwọn ìlànà wọ̀nyí kò ní kan ìpínlẹ̀ Kano. 45.Niti ipinle Kano, mo ti pase konile-gbele patapata fun ose meji ni kiakia. Ijoba apapo yoo ko awon eniyan, ohun elo ati awon irinse ti won nilo lati ran ipinle naa lowo ni kikapa ati bibori ajakale aarun korona yii pelu didena re lati maa ran lo si awon ipinle to mule tii. 45.Níti ìpínlẹ̀ Kano, mo ti pàṣẹ kónílé-gbélé pátápátá fún òṣẹ̀ méjì ní kíákíá. Ìjọba àpapọ̀ yóò kó àwọn ènìyàn, ohun èlò àti àwọn irinṣẹ́ tí wọ́n nílò láti ran ìpínlẹ̀ náà lọ́wọ́ ní kíkápá àti bíborí àjàkálẹ̀ ààrùn kòrónà yìí pè̩lú dídènà rè̩ láti máa ràn lọ sí àwọn ìpínlẹ̀ tó múlé tìí. 46.Leekan si, mo fe kawon osise to n lewaju jakejado orileede yii, awon ti won n fi ohun gbogbo wewu lojojumo lati bori ija yii. Sawon to ko aarun loju ise won, e fokanbale wipe ijoba yoo sohun gbogbo to gba lati ran eyin ati ebi yin lowo lakooko to le rekoja yii. Mo tun fe lo anfani yii lati fi daa yin loju wipe aabo ati igbe-aye alaafia yin lo je ijoba yii logun. 46.Léèkan si, mo fẹ́ káwọn òṣìṣẹ́ tó ń léwájú jákèjádò orílèèdè yìí, àwọn tí wọ́n ń fi ohun gbogbo wéwu lójojúmọ́ láti borí ìjà yìí. Sáwọn tó kó ààrùn lójú iṣẹ́ wọn, ẹ fọkànbalẹ̀ wípé ìjọba yóò ṣohun gbogbo tó gbà láti ràn ẹ̀yin àti ẹbí yín lọ́wọ́ lákòókò tó le rékọjá yìí. Mo tún fẹ́ lo àǹfàní yìí láti fi dáa yín lójú wípé ààbò àti ìgbé-ayé àlàáfíà yín ló jẹ ìjọba yìí lógún. 47.Mo tun mo riri atileyin ta ti rigba lati odo awon Oba wa, awon egbe omoleyin Kristi ni Naijiria, ajo to gaju to n ri si Islam ati awon ajo elesin pelu awon olori agbegbe. Ifowosowopo ati atileyin yin ti ran aseyori ti a ni lowo 47.Mo tún mo rírì àtìlẹyìn ta ti rígbà láti ọ̀dọ̀ àwọn Ọba wa, àwọn ẹgbẹ́ ọmọlẹ́yìn Krístì ní Nàìjíríà, àjọ tó gajù tó ń rí sí Islam àti àwọn àjọ ẹlẹ́sìn pẹ̀lú àwọn olórí agbègbè. Ìfọwọ́sowọ́pọ̀ àti àtìlẹyìn yín ti ran àseyọrí tí a ní lọ́wó 48.Maa ro gbogbo yin lati jowo tesiwaju lati maa soro lori aarun Korona ni aarin awon olujosin ati awon olugbe agbegbe yin wipe ki won kiyesi gbogbo imoran ati imototo lawujo. 48.Màá rọ gbogbo yín láti jọ̀wọ́ tẹ̀síwájú láti máa sọ̀rọ̀ lórí ààrùn Kòrónà ní àárín àwọn olùjọ́sìn àti àwọn olùgbé agbègbè yín wípé kí wọ́n kíyèsí gbogbo ìmọ̀ràn àti ìmọ́tótó láwùjọ. 49.Mo dupe lowo egbe awon gomina, iko igbimo ijoba apapo amojuto aarun COVID-19 fun ise ribiribi titi doni. Pelu ifowosowopo yii, mo ni idaniloju pe, aseyori yoo wa. 49.Mo dúpẹ̣́ lọ̣́wọ́ ẹ̣̣gbẹ̣́ àwọ̣n gómìnà, ikò̩ ìgbìmọ̀ ìjọba àpapọ̀ amójútó ààrùn COVID-19 fún iṣ̣ẹ́ ribiribi títí dòní. Pẹ̣̀lú ìfọwọ́sowọ́pọ̀ yìí, mo ní ìdánilójú pé, àseyọrí yóò wà. 50.Mo tun fe dupe lowo awon ile-ise nla, alaaanu, ajo isokan agbaye, ajo alawo funfun, ore orileede yii, akoroyin atawon oluranlowo wa fun atileyin ti won n se fun wa. 50.Mo tún fẹ́ dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọ̣̣n ilé-iṣ̣ẹ́ ńlá, aláàánú, àjọ̣ ìṣ̣ọ̣̣kan àgbáyé, àjọ̣ aláwọ̀ funfun, ọ̣̀rẹ́ orílèèdè yìí, akọ̣̣ròyìn àtàwọ̣̣n olùrànlọ̣́wọ́ wa fún àtìlẹ́yìn tí wọ̣̣n ń ṣ̣̣e fún wa. 51.Nipaari, maa tun dupe lowo gbogbo awon omo Naijiria leekan si fun suuru ati ifowosowopo lasiko ipenija yii. Mo fi da yin loju pe ijoba yoo sa gbogbo ipa re lati gbegbeese nipa didaabo bo emi atiwalaaye gbogbo tonile-talejo orileede yii. 51.Nípàárí, màá tún dúpẹ́ lọ̣́wọ́ gbogbo àwọ̣̣n ọ̣̣mọ̣ Nàìjíríà lé̩è̩kan si fún sùúrù àti ìfọ̣̣wọ̣́sowọ̣́pọ̀ lásìkò ìpèníjà yìí. Mo fi da yín lójú pé ìjọ̣̣ba yóò sa gbogbo ipá rẹ̀ láti gbégbèésẹ̀ nípa dídáàbò bò ẹ̀mí àtìwàláàyè gbogbo tonílé-tàlejò orílèèdè yìí. 52.Mo dupe pe e feti sile fun mi, kOlorun bukun fun orileede Naijiria. 52.Mo dúpẹ́ pé ẹ fetí sílẹ̀ fún mi, kỌ̣lọ́run bùkún fún orílèèdè Nàìjíríà. --- Aabo omo Naijiria lo je mi logun julo – Aare Buhari --- Ààbò ọ̣̣mọ̣ Nàìjíríà ló jẹ̣ mí lógún jùlọ – Ààrẹ Buhari "Aare orileede Naijiria, Muhammadu Buhari ti so pe eto aabo omo orileede Naijiria lo je oun logun julo ""paapaa julo ni asiko ti ipenija ati airotele wonyi wa""." "Ààrẹ orílèèdè Nàìjíríà, Muhammadu Buhari ti sọ pé ètò ààbò ọmọ orílèèdè Nàìjíríà ló jẹ òun lógún jùlọ ""pàápàá jùlọ̣ ní àsìkò tí ìpèníjà àti àìròtẹ́lẹ̀ wọ̀nyí wà""." Aare soyi lori telifisan lasiko to n ba omo Naijiria soro lojo Aje, 27th of April, 2020. Ààrẹ̣ sọ̀yí lórí te̩lifís̩àn lásìkò tó ń bá ọ̣̣mọ̣ Nàìjíríà sọ̣̀rọ̀ lọ̣́jọ́ Ajé, 27th of April, 2020. Aare Buhari nijooba oun ri saabo emi ati dukia awon eniyan, ijoba oun ko si ni faaye gba iwa tite etoomoniyan loju latowo awon agbofinro. Ààrẹ Buhari níjọ̀ó̩ba òun rí sáàbò ẹ̣̀mí àti dúkìá àwọ̣̣n ènìyàn, ìjọba òun kò sì ní fààyè gba ìwà títẹ̣ ẹ̣̀tọ́ọ̣̣́mọ̣̣nìyàn lójú látọ̣wọ́ àwọ̣̣n agbófinró. """Iroyin ti mo gbo banuje lopolopo, mo fi n da omo orileede Naijiria loju pe, awon elese ko ni lo laijiya labe ofin.""" """Ìròyìn tí mo gbọ́ banújẹ́ lọ̣̣́pọ̣̀lọ̣̣pọ̣̀, mo fi ń dá ọmọ orílèèdè Nàìjíríà lójú pé, àwọn ẹ̣̣lẹ̣́sẹ̀ kò ní lọ̣ láìjìyà lábẹ́ òfin.""" Aare wa ro gbogbo omo orileede Naijiria lati fowosowopo pelu awon agbofinro lasiko ipade pelu won. Ààrẹ wá rọ̣ gbogbo ọ̣̣mọ̣ orílèèdè Nàìjíríà láti fọ̣̣wọ̣́sowọ̣́pọ̣̀ pẹ̣̣̀lú àwọ̣̣n agbófinró lásìkò ìpàdé pè̩lú wọ̣̣n. --- COVID-19: Aare Buhari pase eto konile-gbele nipininle Kano --- COVID-19: Ààrẹ Buhari pàṣ̣ẹ ètò kónílé-gbélé nípìnínlẹ̀ Kánò Aare Naijiria, Muhammadu Buhari ti pase keto konile-gbele bere nipininle Kano, Ariwa Iwo-Oorun Naijiria latari bawon eniyan se n kuku ojiji nipininle naa. Ààrẹ̣ Nàìjíríà, Muhammadu Buhari ti pàṣ̣ẹ kétò kónílé-gbélé bẹ̣̀rẹ̀ nípìnínlẹ̀ Kánò, Àríwá Ìwọ̣̀-Oòrùn Nàìjíríà látàrí báwọ̣̣n ènìyàn se ń kúkú òjijì nípìnínlẹ̀ náà. Aare Buhari so oro yii lori ero a-mohun-maworan pe eto konile-gbele ohun yoo wa fun ose meji gbako ni kankan, ni ipinle Kano. Ààrẹ Buhari so̩ ọ̣̀rọ̣̀ yíi lórí ẹ̣̀rọ̣ a-móhùn-máwòrán pé ètò kónílé-gbélé ọ̣̀hún yóò wà fún ọ̣̀sẹ̀ méjì gbáko ní kánkán, ní ìpínlẹ̣̀ Kánò. "Aare tun so pe ""Ijoba apapo yoo fawon irinse ati osise ranse si ipinle Kano lati ran ipinle ohun lowo, lona atidekun aarun Korona, ko ma baa tan lo si ipinle miiran to sun mo won.""" "Ààrẹ̣ tún sọ̣ pé ""Ìjọ̣̣ba àpapọ̀ yóò fàwọ̣̣n irinṣ̣ẹ́ àti òṣ̣ìṣ̣ẹ́ ránsẹ́ sí ìpínlẹ̀ Kánò láti ran ìpínlẹ̀ ọ̀hún lọ̣́wọ̣́, lọ̣́nà àtidẹ̣́kun ààrùn Kòrónà, kó má baà tàn lọ̣ sí ìpínlẹ̀ mìíràn tó sún mọ́ wọ̣̣n.""" Aare tun so pe awon arinrinajo lati ipinle kan lo si ipinle miiran lo fa itankale aarun ti o waye ni ipinle Kano. Ààrẹ̣ tún sọ̣ pé àwọ̣̣n arìnrìnàjò láti ìpínlẹ̀ kan lọ̣ sí ìpínlẹ̀ mìíràn ló fa ìtànkálẹ̀ ààrùn tí ó wáyé ní ìpínlẹ̀ Kánò. --- NIS gbomo Naijiria metala to n ti Togo bo --- NIS gbo̩mọ̣̣̣̣ Nàìjíríà mẹ́tàlá tó ń ti Tógò bò̩ Ile-ise amojuto arinrinajo Naijiria (NIS) ni awon omo orileede yii metala lawon ti ri gba lati orileede Lome, Togo ati Seme-Krake. Ile-iṣ̣ẹ́ amójútó arìnrìnàjò Nàìjíríà (NIS) ní àwọ̣̣n ọ̣̣mọ̣ orílèèdè yìí mẹ́tàlá làwọ̣̣n ti rí gbà láti orílèèdè Lòmè, Tógò àti Seme-Krake. Agbenuso NIS naa, ogbeni Sunday James lo soyi ninu atejade kan lojo Aiku niluu Abuja, lawon to pada wa sile je akosemose ti won lo sise nileese kan ni Togo. Agbẹnusọ̣ NIS náà, ọ̣̀gbẹ́ni Sunday James ló sọ̣̣̀yí nínú àtẹ̣̀jáde kan lọ̣́jọ́ Àìkú nílùú Àbújá, láwọ̣̣n tó padà wá sílé jẹ́ akọ́sẹ́mọsẹ́ tí wọ̣̣n lọ̣ ṣ̣iṣ̣ẹ́ nílées̩ẹ́ kan ni Tógò. Gege bi ogbeni James se so, o lawon eniyan metala ohun ni won ti fa fun eleeto ilera Eko fun ayewo Corona. Gẹ́gẹ́ bí ọ̣̀gbẹ́ni James ṣ̣e ṣ̣ọ, ó làwọ̣̣n ènìyàn mẹ́tàlá ọ̣̀hún ni wọ̣́n ti fà fún eléètò ìlera Èkó fún àyẹ̣̀wò Corona. "O ni, ""Bakan naa la tun so fun won pe ki won wa nigbeeele gege bilana ajo agbogun tajakale aarun (NCDC) se laa sile fun awon ti won ba sese de lati ile okeere, leyi lati dekun aarun Corona.""" "Ó ní, ""Bákan náà la tún sọ̣ fún wọ̣̣n pé kí wọ̣̣́n wà nígbèèélé gẹ́gẹ́ bílànà àjọ̣ agbógun tàjàkálẹ̀ ààrùn (NCDC) ṣ̣̣e làá sílẹ̀ fún àwọ̣̣n tí wọ̣́n bá ṣ̣ẹ̣̀ṣẹ̀ dé láti ilẹ̀ òkèèrè, lèyí láti dẹ́kun ààrùn Corona.""" James lenubode Seme-Krake je oju ona to gba Naijiria wole tabi jade, to si tun paala pelu orileede Benin. O ni NIS ko kaare lati mojuto awon enubode wonyi. James lẹ́nubodè Seme-Krake jẹ́ ojú ọ̀nà tó gba Nàìjíríà wọ̣̣lé tàbí jáde, tó sì tún pààlà pẹ̀lú orílèèdè Benin. Ó ní NIS kò káàrẹ́ láti mójútó àwọ̣̣n ẹ̣nubodè wọ̀nyí. O ni NIS maa mu awon ti o ba fe gba ona eburu lati wole si orile ede Naijiria, nitori naa iye awon to n gba enu ibode Seme-Krake ti peleke si. Ó ní NIS máa mú àwọ̣̣̣n tí ó bá fẹ́ gba ọ̀nà ẹ̀bùrú láti wọ̣̣̣lé sí orílè̩ èdè Nàìjíríà, nítorí náà iye àwo̩n tó ń gba e̩nu ibodè Seme-Krake ti peléke si. O ni adari NIS gbogbooogbo, iyen ogbeni Muhammad Babandede ti ro awon arinrinajo to n padabo wa si orileede Naijiria lati sora nipa gbigba ona eburu, nitori awon odaran ati onise-ibi ti o lee se won ni ijamba. Ó ní adarí NIS gbogboòògbò, ìye̩n ọ̀gbẹ́ni Muhammad Bàbándédè ti rọ̣ àwọ̣̣n arìnrìnàjò tó ń padabò̩ wá sí orílèèdè Nàìjíríà láti ṣ̣ọ̣́ra nípa gbígba ọ̀nà ẹ̀bùrú, nítorí àwọ̣n ọ̀daràn àti oníṣẹ́-ibi tí ó leè ṣe wọ̣̣̣́n ní ìjàmbá. --- Aare Buhari yoo bomo orileede soro lagogo mejo asale. --- Ààrẹ Buhari yóò bọ́mọ orílèèdè sọ̀rọ̀ lágogo mẹ́jọ àsálẹ́. Aare Muhammadu Buhari yoo ba omo orileede Naijiria soro lonii Monde, April 27, ni aago mejo ale. Ààrẹ Muhammadu Buhari yóò bá o̩mo̩ orílèèdè Nàìjíríà sọ̣̀rọ̣̀ lónìí Mó̩ńdè, April 27, ni aago mé̩jo̩ alé̩. Awon ile-ise Telifisan, Redio ati awon ero agbohunsafefe miiran ni won ro lati darapo mo ero alatagba amohunmaworan ti akoko ni orile ede Naijiria (NTA) ati asoromagbesi ijoba apapo (FRCN) fun ikede yii. Àwo̩n ilé-is̩é̩ Te̩lifís̩àn, Rédíò àti àwọn ẹ̀rọ agbóhùnsáfé̩fé̩ mìíràn ni wó̩n rò̩ láti darapọ̀ mọ́ ẹ̀rọ alátagbà amóhùnmáwòrán ti àkó̩kó̩ ní orílè̩ èdè Nàìjíríà (NTA) àti asọ̀rọ̀mágbèsì ìjọba àpapọ̀ (FRCN) fún ìkéde yìí. Ohun Naijiria naa yoo gbesafefe lori ero abeyefo. Ohun Nàìjíríà náà yóò gbesáfé̩fé̩ lórí ẹ̀rọ abẹ́yẹfò. E tele wa lori VON Social Media handles: Ẹ tèlé wa lórí VON Social Media handles: --- Aare Buhari yoo ba Naijiria soro lonii: Nje aare yoo fopin si ofin konile -gbele tabi yoo tun fi ojo kun un --- Ààrẹ Buhari yóò bá Nàìjíríà ṣ̣ọ̣̀rọ̀ lónìí: Ǹjẹ́ ààrẹ yóò fòpin ṣí òfin kónílé -gbélè tàbí yóò tún fi ọjọ́ kún un Aare Naijiria, Muhammadu Buhari yoo maa ba orileede Naijiria soro lonii yii, Monday, April 27, 2020 ni 8pm. Ààrẹ Nàìjíríà, Muhammadu Buhari yóò máa bá orílèèdè Nàìjíríà sọ̣̀rọ̣̀ lónìí yìí, Monday, April 27, 2020 ni 8pm. Gbogbo omo Naijiria ni won fe gbo ohun tii aare Buhari yoo so nipa eto konilegbele. Gbogbo ọ̣mọ̣̣ Nàìjíríà ni wọ̣́n fẹ́ gbọ́ ohun tíi ààrẹ Buhari yóò sọ̣ nípa ètò kónílégbélé. Oluranlowo aare lori iroyin ati ikede lo kede yii. Olùrànlọ̣́wọ́ ààrẹ lórí ìròyìn àti ìkéde ló kéde yìí. --- Ile-igbimo asoju yoo pada senuse ni April 28 --- Ilé-ìgbìmọ̀ aṣ̣ojú yóò padà sẹ̣́nusẹ́ ní April 28 Ile-igbimo asoju Naijiria yoo pada senuse lojo isegun leyin isinmi osu kan ti won wa latari aarun Covid-19 to sele lorile ede Naijiria. Ilé-ìgbìmọ̀ aṣ̣ojú Nàìjíríà yóò padà ṣ̣ẹ̣́nuṣ̣ẹ́ ló̩jó̩ ìs̩e̩gun lẹ̣́yìn ìsinmi oṣ̣̣ù kan tí wọ̣́n wà látàrí ààrùn Covid-19 tó ṣ̣ẹ̣̣lẹ̀ lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Lojo kerinlelogun, osu keta nile igbimo asoju koko bere isinmi olose meji won lati lee je kigbimo to n mojuto ile –asofin pese aabo to munadoko ti yoo dekun itankale aarun COIVD-19 nile-asofin ohun sugbon leyin ose kan ti won bere isinmi nijoba apapo pase pe ki eto konile-gbele bere niluu Abuja atawon ipinle meji taarun COIVD-19 n ba woya ija. Lọ̣́jọ́ kẹ̣̣rìnlélógún, oṣ̣ù kẹ̣̣ta nilé ìgbìmọ̀ asojú kọ́kọ́ bẹ̣̣̀rẹ̀ ìsinmi ọlọ́sẹ̀ méjì wọ̣́n láti leè jẹ́ kígbìmọ̀ tó ń mójútó ilé –asòfin pèsè ààbò tó múnádóko tí yóò dẹ̣́kun ìtànkálẹ̀ ààrùn COIVD-19 nilé-asòfin ọ̀hún sùgbọ̣́n lẹ̣́yìn ọ̣̀sẹ̀ kan tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìsinmi nìjọba àpapọ̀ pàsẹ pé kí ètò kónílé-gbélé bẹ̣̀rẹ̀ nílùú Àbújá àtàwọ̣n ìpínlẹ̀ méjì táàrùn COIVD-19 ń bá wọ̀yá ìjà. Ninu atejade kan takowe ile-igbimo asoju ohun, ogbeni Patrick Giwa gbejade lati gbawon omo igbimo asoju naa nimoran lati tele eto ilana tijoba apapo atajo to n gbogun tajakale aarun ni Naijiria la sile ateto ilana tile-igbimo asoju laa sile, leyii tawon yoo fi ranse sawon omo ile-igbimo asoju ohun. Nínú àtẹ̀jáde kan tákọ̀wé ilé-ìgbìmọ̀ asojú ọ̀hún, ọ̀gbẹ́ni Patrick Gíwá gbéjáde láti gbàwọ̣̣n ọ̣̣mọ̣̣ ìgbìmọ̀ aṣ̣ojú náà nímọ̀ràn láti tẹ̣̣̀lé ètò ìlànà tíjọ̣̣ba àpapọ̀ àtàjọ̣̣ tó ń gbógun tàjàkálẹ̀ ààrùn ní Nàìjíríà là sílẹ̀ àtètò ìlànà tílé-ìgbìmọ̀ aṣ̣ojú làà sílẹ̀, léyìí táwọ̣̣n yóò fi ránṣ̣ẹ́ sáwọ̣̣n ọ̣̣mọ̣̣ ilé-ìgbìmọ̀ asojú ọ̣̣̀hún. "Atejade naa ni kawon oluranlowo atosise ile-igbimo asofin si duro sile lati maa sise won ati pe ""a o pe won ta ba nilo iranlowo won funse pataki kan nileese.""" "Àtẹ̣̣̀jáde náà ní káwọ̣̣n olùrànlọ̣̣́wọ̣̣́ àtòṣ̣ìṣ̣ẹ́ ilé-ìgbìmọ̀ aṣ̣òfin sì dúró sílé láti máa ṣ̣iṣ̣ẹ́ wọ̣̣n àti pé ""a ó pè wọ̣̣́n ta bá nílò ìrànlọ́wọ́ wọ̣̣n fúnsẹ́ pàtàkì kan níléesẹ́.""" Tawon omo ile –igbimo asoju ohun ba wole, won yoo maa jiroro lori igbese lati gbogun ti aarun Corona ati lori eto oro aje orileede yii. Táwọ̣n ọ̣̣mọ̣̣ ilé –ìgbìmọ̀ aṣ̣ojú ọ̀hún bá wọ̣̣lé, wọ̣̣n yóò máa jíròrò lórí ìgbésẹ̀ láti gbógun ti ààrùn Corona àti lórí ètò ọ̣̀rọ̣̀ ajẹ́ orílèèdè yìí. --- Ijoba apapo n se iwadii alarun korona ni ipinle Kano- Minisita --- Ìjọba àpapọ̣̣̀ ń ṣe ìwádìí alárùn kòrónà ní ìpínlẹ̀ Kánò- Mínísítà Minisita fun eto ilera ni orile ede Naijiria, Osagie Ehanire, ti so pe ijoba apapo ati ijoba ipinle Kano ti n se iwadii ni Kano pelu ase won, o ni ile-ise ohun yoo ran awon adari awerii ninu iwadii. Mínísítà fún ètò ìlera ní orílè̩ èdè Nàìjíríà, Osagie Ehanire, ti sọ pé ìjọ̣̣ba àpapọ̣̣̀ àti ìjọ̣̣ba ìpínlẹ̀ Kánò ti ń s̩e ìwádìí ní Kano pè̩lú às̩e̩ wo̩n, ó ní ilé-is̩é ò̩hún yóò rán àwo̩n adarí awérìí nínú ìwádìí. Ehanire ni iko to n sise iwerii ninu iwadii yoo se ipade pelu gomina Kano lati so iru isele ohun, o si fi kun-un pe ko daju pe korona ni. Ehanire ní ikò̩ tó ń s̩is̩é̩ ìwé̩rìí nínú ìwádìí yóò ṣ̣e ìpàdé pẹ̣̣̀lú gómìnà Kánò láti so̩ irú ìs̩è̩lè̩ ọ̀hún, ó sì fi kún-un pé kò dájú pé kòrónà ni. Ehanire tun lawon iko naa yoo maa sayewo, iyasoto, itopinpin awon alarun ohun, lati mona ti won yoo gba lati meto idagbasoke bawon eto ilana ati yara ayewo to ti wa ni ipinle naa. Ehanire tún láwọ̣̣n ikọ̀ náà yóò máa ṣàyẹ̀wò, ìyàsọ̣́tọ̀, ìtọpinpin àwọ̣̣n alárùn ọ̀hún, láti mọ̀nà tí wọ̣̣n yóò gbà láti métò ìdàgbàsókè báwọ̣̣n ètò ìlànà àti yàrá àyẹ̀wò tó ti wá ní ìpínlẹ̀ náà. """Kano ko niriiri nipa aarun COVID-19 teleri, iyalenu lo si ye ko je fun wa baarun COVID-19 se tankale.""" """Kánò kò nírìírí nípa ààrùn COVID-19 tẹ̣́lẹ̣̀rí, ìyàlẹ̣̣́nu ló sì ye̩ kó jẹ́ fún wa báàrùn COVID-19 se tànkálẹ̀.""" O se e se, ki a lee dekun aarun yii ti a ba lo awon irinse ati awon eniyan to muna-doko. Ó se é se, kí a leè dẹ́kun ààrùn yìí tí a bá lo àwọ̣̣n irinṣẹ́ àti àwọ̣̣n ènìyàn tó múná-dóko. Minisita ni Eko to lero bii ipinle Kano lawon irinse to munadoko ati pe ipinle Eko tete dojuko aarun Corona nitori iriri ti won ni nipa aarun Ebola to sele lodun 2014. Mínísítà ní Èkó tó lérò bíi ìpínlẹ̀ Kánò láwọ̣̣n irinṣ̣ẹ́ tó múnádóko àti pé ìpínlẹ̀ Èkó tètè dojúkọ̣̣ ààrùn Corona nítorí ìrírí tí wọ̣̣́n ní nípa ààrùn Èbólà tó ṣ̣ẹ̣̣lẹ̀ lọ́dún 2014. Minisita tesiwaju pe awon eroja ati irinse tipininle Kano ni, bo tile je pe won n gbiyanju, a ko le fi ipinle Eko we ipinle Kano, nitori pe awon osise atirinse ti ipinle Eko ni, ipinle Kano ko nii. Mínísítà tẹ̣̣̀síwájú pé àwọ̣̣n èròjà àti irinṣ̣ẹ́ típìnínlẹ̀ Kánò ní, bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ̣́n ń gbìyànju, a kò le fi ìpínlẹ̀ Èkó wé ìpínlẹ̀ Kánò, nítorí pé àwọ̣̣n òṣ̣ìṣ̣é àtirinṣ̣ẹ́ tí ìpínlẹ̀ Èkó ní, ìpínlẹ̀ Kánò kò níi. Ehanire ni ogoji osise eto ilera ni won ti laarun korona ni Naijiria, sugbon ibi-ise ko ni won ti ko o. Ehanire ní ogójì òṣ̣ìṣ̣ẹ́ ètò ìlera ni wọ̣̣̣́n ti láárùn kòrónà ní Nàìjíríà, s̩ùgbó̩n ibi-is̩é̩ kó̩ ni wó̩n ti kó o.